< Isaiah 20 >

1 Ní ọdún tí olórí ogun, tí Sagoni ọba Asiria rán an, wá sí Aṣdodu, ó kọlù ú ó sì kó o—
In the yeer wherynne Tharthan entride in to Azotus, whanne Sargon, the kyng of Assiriens, hadde sent hym, and he hadde fouyte ayens Azotus, and hadde take it;
2 ní àkókò náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa ti ẹnu Isaiah ọmọ Amosi jáde. Ó sọ fún un pé, “Mú aṣọ ọ̀fọ̀ kúrò ní ara rẹ kí o sì bọ́ sálúbàtà kúrò ní ẹsẹ̀ rẹ.” Ó sì ṣe bẹ́ẹ̀, ó ń lọ káàkiri ní ìhòhò àti láì wọ bàtà.
in that tyme the Lord spak in the hond of Isaye, the sone of Amos, and seide, Go thou, and vnbynde the sak fro thi leendis, and take awei thi schoon fro thi feet. And he dide so, goynge nakid and vnschood.
3 Lẹ́yìn náà ni Olúwa wí pé, “Gẹ́gẹ́ bí ìránṣẹ́ mi Isaiah ti lọ káàkiri ní ìhòhò àti láì wọ bàtà fún ọdún mẹ́ta, gẹ́gẹ́ bí àmì àti àpẹẹrẹ sí Ejibiti àti Kuṣi,
And the Lord seide, As my seruaunt Ysaie yede nakid and vnschood, a signe and greet wondur of thre yeer schal be on Egipt, and on Ethiopie;
4 bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni ọba Asiria yóò kó àwọn ìgbèkùn Ejibiti lọ ní ìhòhò àti láì wọ bàtà pẹ̀lú àwọn àtìpó Kuṣi, ọ̀dọ́ àti àgbà, pẹ̀lú ìbàdí ìhòhò—bí àbùkù Ejibiti.
so the kyng of Assiriens schal dryue the caitifte of Egipt, and the passyng ouer of Ethiopie, a yong man and an eld man, nakid and vnschood, with the buttokis vnhilid, to the schenschipe of Egipt.
5 Gbogbo àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé Kuṣi tí wọ́n sì ń fi Ejibiti yangàn ni ẹ̀rù yóò dé bá tí a ó sì dójútì wọ́n.
And thei schulen drede, and schulen be schent of Ethiopie, her hope, and of Egipt, her glorie.
6 Ní ọjọ́ náà àwọn ènìyàn tí ó ń gbé ní etí Òkun yóò wí pé, ‘Wo ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀ sí àwọn tí a ti gbẹ́kẹ̀lé, àwọn tí a sá tọ̀ lọ fún ìrànlọ́wọ́ àti ìtúsílẹ̀ láti ọwọ́ ọba Asiria! Báwo ni a ó ṣe sálà?’”
And a dwellere of this ile schal seie in that dai, This was our hope, to which we fledden for help, that thei schulden delyuere vs fro the face of the kyng of Assiryens; and hou moun we ascape?

< Isaiah 20 >