< Isaiah 2 >

1 Èyí ni ohun tí Isaiah ọmọ Amosi rí nípa Juda àti Jerusalẹmu.
Esto es lo que vio Isaías, hijo de Amoz, respecto a Judá y Jerusalén.
2 Ní ìgbẹ̀yìn ọjọ́ òkè tẹmpili Olúwa ni a ó fi ìdí rẹ̀ kalẹ̀ gẹ́gẹ́ bí olú nínú àwọn òkè, a ó sì gbé e ga ju àwọn òkè kéékèèké lọ, gbogbo orílẹ̀-èdè yóò sì máa sàn sínú un rẹ̀.
Sucederá en los últimos días que el monte de la casa de Yahvé se establecerá en la cima de los montes, y se elevará por encima de las colinas; y todas las naciones acudirán a ella.
3 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn ni yóò wá, wọn yóò sì wí pé, “Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí á gòkè ńlá Olúwa, àti sí ilé Ọlọ́run Jakọbu. Òun yóò kọ́ wa ní ọ̀nà rẹ̀, kí àwa kí ó lè rìn ní ọ̀nà rẹ̀.” Òfin yóò jáde láti Sioni wá, àti ọ̀rọ̀ Olúwa láti Jerusalẹmu.
Muchos pueblos irán y dirán, “Ven, subamos al monte de Yahvé, a la casa del Dios de Jacob; y nos enseñará sus caminos, y caminaremos por sus senderos”. Porque la ley saldrá de Sión, y la palabra de Yahvé desde Jerusalén.
4 Òun ó ṣe ìdájọ́ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, yóò sì parí aáwọ̀ fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ènìyàn. Wọn yóò fi idà wọn rọ ọkọ́ ìtulẹ̀, wọn yóò sì fi ọ̀kọ̀ wọn rọ dòjé. Orílẹ̀-èdè kì yóò sì gbé idà sí orílẹ̀-èdè mọ́, bẹ́ẹ̀ ní wọn kì yóò kọ́ ogun jíjà mọ́.
Él juzgará entre las naciones, y decidirá sobre muchos pueblos. Convertirán sus espadas en rejas de arado, y sus lanzas en podaderas. La nación no levantará la espada contra la nación, ni aprenderán más la guerra.
5 Wá, ẹ̀yìn ará ilé e Jakọbu, ẹ jẹ́ kí a rìn nínú ìmọ́lẹ̀ Olúwa.
Casa de Jacob, venid y caminemos a la luz de Yahvé.
6 Ìwọ ti kọ àwọn ènìyàn rẹ sílẹ̀, ìwọ ilé Jakọbu. Wọ́n kún fún ìgbàgbọ́ tí kò lẹ́sẹ̀ nílẹ̀ tí ó ti ìlà-oòrùn wá, wọ́n ń wo iṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí àwọn Filistini, wọ́n ń pa ọwọ́ pọ̀ pẹ̀lú àwọn abọ̀rìṣà.
Porque has abandonado a tu pueblo, la casa de Jacob, porque se llenan desde el este, con los que practican la adivinación como los filisteos, y se dan la mano con los hijos de los extranjeros.
7 Ilẹ̀ wọn kún fún fàdákà àti wúrà, ìṣúra wọn kò sì ní òpin. Ilẹ̀ ẹ wọn kún fún ẹṣin, kẹ̀kẹ́ ogun wọn kò sì lópin.
Su tierra está llena de plata y oro, ni hay fin de sus tesoros. Sus tierras también están llenas de caballos, ni hay fin de sus carros.
8 Ilẹ̀ ẹ wọn kún fún ère, wọ́n sì ń foríbalẹ̀ fún iṣẹ́ ọwọ́ ara wọn, èyí tí ìka ọwọ́ àwọn tìkára wọn ti ṣe.
Su tierra también está llena de ídolos. Adoran el trabajo de sus propias manos, lo que sus propios dedos han hecho.
9 Nítorí náà ni a ó ṣe rẹ ènìyàn sílẹ̀ ìran ọmọ ènìyàn ni yóò sì di onírẹ̀lẹ̀, má ṣe dáríjì wọ́n.
El hombre es abatido, y la humanidad se humilla; por lo tanto no los perdones.
10 Wọ inú àpáta lọ, fi ara pamọ́ nínú erùpẹ̀ kúrò nínú ìpayà Olúwa, àti ògo ọláńlá rẹ̀!
Entra en la roca, y esconderse en el polvo, ante el terror de Yahvé, y de la gloria de su majestad.
11 Ojú agbéraga ènìyàn ni a ó rẹ̀ sílẹ̀ a ó sì tẹrí ìgbéraga ènìyàn ba, Olúwa nìkan ṣoṣo ni a ó gbéga ní ọjọ́ náà.
Las miradas altivas del hombre serán abatidas, la arrogancia de los hombres será doblegada, y sólo Yahvé será exaltado en ese día.
12 Olúwa àwọn ọmọ-ogun ní ọjọ́ kan ní ìpamọ́ fún gbogbo agbéraga àti ọlọ́kàn gíga nítorí gbogbo àwọn tí a gbéga (ni a ó rẹ̀ sílẹ̀),
Porque habrá un día de Yahvé de los Ejércitos para todos los soberbios y arrogantes, y por todo lo que se levanta, y será traído bajo
13 nítorí gbogbo igi kedari Lebanoni, tó ga tó rìpó àti gbogbo óákù Baṣani,
para todos los cedros del Líbano, que son altos y elevados, por todos los robles de Basán,
14 nítorí gbogbo òkè gíga ńlá ńlá àti àwọn òkè kéékèèké,
por todas las altas montañas, por todas las colinas que se levantan,
15 fún ilé ìṣọ́ gíga gíga àti àwọn odi ìdáàbòbò,
por cada torre elevada, por cada muro fortificado,
16 fún gbogbo ọkọ̀ àwọn oníṣòwò àwọn ọkọ̀ tí a ṣe lọ́ṣọ̀ọ́.
para todos los barcos de Tarsis, y para todas las imágenes agradables.
17 Ìgbéraga ènìyàn ni a ó tẹ̀ lórí ba a ó sì rẹ ìgbéraga ènìyàn sílẹ̀, Olúwa nìkan ṣoṣo ni a ó gbéga ní ọjọ́ náà,
La altivez del hombre se inclinará, y la arrogancia de los hombres será abatida; y sólo Yahvé será exaltado en ese día.
18 gbogbo ère òrìṣà yóò pòórá.
Los ídolos desaparecerán por completo.
19 Àwọn ènìyàn yóò sálọ sínú ihò àpáta àti sínú ihò ilẹ̀ kúrò lọ́wọ́ ìpayà Olúwa àti ògo ọláńlá rẹ̀, nígbà tí ó bá dìde láti mi ayé tìtì.
Los hombres entrarán en las cuevas de las rocas, y en los agujeros de la tierra, ante el terror de Yahvé, y de la gloria de su majestad, cuando se levante para sacudir la tierra poderosamente.
20 Ní ọjọ́ náà ni àwọn ènìyàn yóò máa sọ àwọn ère fàdákà àti ère wúrà tí wọ́n ti yá fún bíbọ sí èkúté àti àwọn àdán.
En ese día, los hombres se desharán de sus ídolos de plata y sus ídolos de oro, que se han hecho para adorar, a los topos y a los murciélagos,
21 Wọn yóò sálọ sínú ihò ìsàlẹ̀ àpáta àti sínú ihò pàlàpálá àpáta kúrò lọ́wọ́ ìpayà Olúwa àti ògo ọláńlá rẹ̀, nígbà tí ó bá dìde láti mi ayé tìtì.
para entrar en las cavernas de las rocas, y en las hendiduras de las rocas desgarradas, ante el terror de Yahvé, y de la gloria de su majestad, cuando se levante para sacudir la tierra poderosamente.
22 Dẹ́kun à ń gba ènìyàn gbọ́, èémí ẹni tó wà ní ihò imú rẹ̀. Nítorí nínú kín ni a lè kà á sí?
Deja de confiar en el hombre, cuyo aliento está en sus narices; pues ¿de qué sirve?

< Isaiah 2 >