< Isaiah 2 >

1 Èyí ni ohun tí Isaiah ọmọ Amosi rí nípa Juda àti Jerusalẹmu.
Słowo, które widział Izajasz, syn Amosa, dotyczące Judy i Jerozolimy.
2 Ní ìgbẹ̀yìn ọjọ́ òkè tẹmpili Olúwa ni a ó fi ìdí rẹ̀ kalẹ̀ gẹ́gẹ́ bí olú nínú àwọn òkè, a ó sì gbé e ga ju àwọn òkè kéékèèké lọ, gbogbo orílẹ̀-èdè yóò sì máa sàn sínú un rẹ̀.
Stanie się w dniach ostatecznych, że góra domu PANA będzie utwierdzona na szczycie gór i wywyższona ponad pagórki; i wszystkie narody popłyną do niej.
3 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn ni yóò wá, wọn yóò sì wí pé, “Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí á gòkè ńlá Olúwa, àti sí ilé Ọlọ́run Jakọbu. Òun yóò kọ́ wa ní ọ̀nà rẹ̀, kí àwa kí ó lè rìn ní ọ̀nà rẹ̀.” Òfin yóò jáde láti Sioni wá, àti ọ̀rọ̀ Olúwa láti Jerusalẹmu.
I pójdzie wiele ludów, i powie: Chodźcie, wstąpmy na górę PANA, do domu Boga Jakuba; on będzie nas uczył swoich dróg, a my będziemy kroczyli jego ścieżkami. Z Syjonu bowiem wyjdzie prawo, a słowo PANA z Jerozolimy.
4 Òun ó ṣe ìdájọ́ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, yóò sì parí aáwọ̀ fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ènìyàn. Wọn yóò fi idà wọn rọ ọkọ́ ìtulẹ̀, wọn yóò sì fi ọ̀kọ̀ wọn rọ dòjé. Orílẹ̀-èdè kì yóò sì gbé idà sí orílẹ̀-èdè mọ́, bẹ́ẹ̀ ní wọn kì yóò kọ́ ogun jíjà mọ́.
On będzie sądził wśród narodów i karcił wielu ludzi. I przekują swe miecze na lemiesze, a swoje włócznie na sierpy. Naród przeciw narodowi nie podniesie już miecza i nie będą się już ćwiczyć do wojny.
5 Wá, ẹ̀yìn ará ilé e Jakọbu, ẹ jẹ́ kí a rìn nínú ìmọ́lẹ̀ Olúwa.
Domu Jakuba, chodźcie, postępujmy w światłości PANA.
6 Ìwọ ti kọ àwọn ènìyàn rẹ sílẹ̀, ìwọ ilé Jakọbu. Wọ́n kún fún ìgbàgbọ́ tí kò lẹ́sẹ̀ nílẹ̀ tí ó ti ìlà-oòrùn wá, wọ́n ń wo iṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí àwọn Filistini, wọ́n ń pa ọwọ́ pọ̀ pẹ̀lú àwọn abọ̀rìṣà.
Ale ty opuściłeś swój lud, dom Jakuba, gdyż pełen jest [obrzydliwości] wschodu i [są oni] wróżbitami jak Filistyni, a kochają się w cudzych synach.
7 Ilẹ̀ wọn kún fún fàdákà àti wúrà, ìṣúra wọn kò sì ní òpin. Ilẹ̀ ẹ wọn kún fún ẹṣin, kẹ̀kẹ́ ogun wọn kò sì lópin.
Ich ziemia jest pełna srebra i złota i nie ma końca ich skarbom. Ich ziemia jest pełna koni i nie ma końca ich rydwanom.
8 Ilẹ̀ ẹ wọn kún fún ère, wọ́n sì ń foríbalẹ̀ fún iṣẹ́ ọwọ́ ara wọn, èyí tí ìka ọwọ́ àwọn tìkára wọn ti ṣe.
Ich ziemia jest pełna bożków, [oni] oddają pokłon dziełom własnych rąk, które wykonały ich palce.
9 Nítorí náà ni a ó ṣe rẹ ènìyàn sílẹ̀ ìran ọmọ ènìyàn ni yóò sì di onírẹ̀lẹ̀, má ṣe dáríjì wọ́n.
Kłania się [przed nimi] prosty człowiek, poniża się też wielki; nie przebaczaj im.
10 Wọ inú àpáta lọ, fi ara pamọ́ nínú erùpẹ̀ kúrò nínú ìpayà Olúwa, àti ògo ọláńlá rẹ̀!
Wejdź w skałę i ukryj się w prochu ze strachu przed PANEM i przed chwałą jego majestatu.
11 Ojú agbéraga ènìyàn ni a ó rẹ̀ sílẹ̀ a ó sì tẹrí ìgbéraga ènìyàn ba, Olúwa nìkan ṣoṣo ni a ó gbéga ní ọjọ́ náà.
Wyniosłe oczy człowieka ukorzą się, ludzka pycha będzie poniżona, a sam tylko PAN zostanie wywyższony w tym dniu.
12 Olúwa àwọn ọmọ-ogun ní ọjọ́ kan ní ìpamọ́ fún gbogbo agbéraga àti ọlọ́kàn gíga nítorí gbogbo àwọn tí a gbéga (ni a ó rẹ̀ sílẹ̀),
[Przyjdzie] bowiem dzień PANA zastępów przeciwko każdemu pysznemu i wyniosłemu, i przeciwko każdemu wywyższonemu, a [każdy] zostanie poniżony;
13 nítorí gbogbo igi kedari Lebanoni, tó ga tó rìpó àti gbogbo óákù Baṣani,
Przeciwko wszystkim cedrom Libanu, które są wysokie a wyniosłe, i przeciwko wszystkim dębom Baszanu;
14 nítorí gbogbo òkè gíga ńlá ńlá àti àwọn òkè kéékèèké,
Przeciwko wszystkim wysokim górom i przeciwko wszystkim wyniosłym pagórkom;
15 fún ilé ìṣọ́ gíga gíga àti àwọn odi ìdáàbòbò,
Przeciwko każdej wysokiej wieży i przeciwko każdemu murowi obronnemu;
16 fún gbogbo ọkọ̀ àwọn oníṣòwò àwọn ọkọ̀ tí a ṣe lọ́ṣọ̀ọ́.
Przeciwko wszystkim okrętom Tarszisz i przeciwko wszelkiemu pięknemu malarstwu.
17 Ìgbéraga ènìyàn ni a ó tẹ̀ lórí ba a ó sì rẹ ìgbéraga ènìyàn sílẹ̀, Olúwa nìkan ṣoṣo ni a ó gbéga ní ọjọ́ náà,
I wyniosłość człowieka będzie ugięta i pycha ludzka będzie poniżona, a sam tylko PAN zostanie wywyższony w tym dniu.
18 gbogbo ère òrìṣà yóò pòórá.
A bożki zniszczy doszczętnie.
19 Àwọn ènìyàn yóò sálọ sínú ihò àpáta àti sínú ihò ilẹ̀ kúrò lọ́wọ́ ìpayà Olúwa àti ògo ọláńlá rẹ̀, nígbà tí ó bá dìde láti mi ayé tìtì.
Wtedy wejdą do jaskiń skalnych i do jam podziemnych ze strachu przed PANEM i przed chwałą jego majestatu, gdy powstanie, by przerazić ziemię.
20 Ní ọjọ́ náà ni àwọn ènìyàn yóò máa sọ àwọn ère fàdákà àti ère wúrà tí wọ́n ti yá fún bíbọ sí èkúté àti àwọn àdán.
W tym dniu człowiek wrzuci kretom i nietoperzom swoje bożki srebrne i złote, które uczynił, aby oddawać im pokłon;
21 Wọn yóò sálọ sínú ihò ìsàlẹ̀ àpáta àti sínú ihò pàlàpálá àpáta kúrò lọ́wọ́ ìpayà Olúwa àti ògo ọláńlá rẹ̀, nígbà tí ó bá dìde láti mi ayé tìtì.
I wejdzie w szczeliny skalne i na szczyty opok ze strachu przed PANEM i przed chwałą jego majestatu, gdy powstanie, aby przerazić ziemię.
22 Dẹ́kun à ń gba ènìyàn gbọ́, èémí ẹni tó wà ní ihò imú rẹ̀. Nítorí nínú kín ni a lè kà á sí?
Przestańcie [polegać] na człowieku, którego tchnienie [jest] w jego nozdrzach. Za co bowiem ma być uznany?

< Isaiah 2 >