< Isaiah 2 >

1 Èyí ni ohun tí Isaiah ọmọ Amosi rí nípa Juda àti Jerusalẹmu.
Słowo, które widział Izajasz, syn Amosowy, nad Judą i nad Jeruzalemem.
2 Ní ìgbẹ̀yìn ọjọ́ òkè tẹmpili Olúwa ni a ó fi ìdí rẹ̀ kalẹ̀ gẹ́gẹ́ bí olú nínú àwọn òkè, a ó sì gbé e ga ju àwọn òkè kéékèèké lọ, gbogbo orílẹ̀-èdè yóò sì máa sàn sínú un rẹ̀.
I stanie się w ostateczne dni, że będzie przygotowana góra domu Pańskiego na wierzchu gór, i wywyższy się nad pagórkami, a zbieżą się do niej wszystkie narody.
3 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn ni yóò wá, wọn yóò sì wí pé, “Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí á gòkè ńlá Olúwa, àti sí ilé Ọlọ́run Jakọbu. Òun yóò kọ́ wa ní ọ̀nà rẹ̀, kí àwa kí ó lè rìn ní ọ̀nà rẹ̀.” Òfin yóò jáde láti Sioni wá, àti ọ̀rọ̀ Olúwa láti Jerusalẹmu.
I pójdzie wiele ludzi, mówiąc: Pójdźcie a wstąpmy na górę Pańską, do domu Boga Jakóbowego, a będzie nas uczył dróg swoich, i będziemy chodzili ścieszkami jego; albowiem z Syonu wyjdzie zakon, a słowo Pańskie z Jeruzalemu.
4 Òun ó ṣe ìdájọ́ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, yóò sì parí aáwọ̀ fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ènìyàn. Wọn yóò fi idà wọn rọ ọkọ́ ìtulẹ̀, wọn yóò sì fi ọ̀kọ̀ wọn rọ dòjé. Orílẹ̀-èdè kì yóò sì gbé idà sí orílẹ̀-èdè mọ́, bẹ́ẹ̀ ní wọn kì yóò kọ́ ogun jíjà mọ́.
I będzie sądził między narodami, a będzie karał wiele ludzi. I przekują miecze swe na lemiesze, a włócznie swe na sierpy; nie podniesie naród przeciw narodowi miecza, ani się będą ćwiczyć do bitwy.
5 Wá, ẹ̀yìn ará ilé e Jakọbu, ẹ jẹ́ kí a rìn nínú ìmọ́lẹ̀ Olúwa.
Domie Jakóbowy! pójdźcie, a chodźmy w światłości Pańskiej.
6 Ìwọ ti kọ àwọn ènìyàn rẹ sílẹ̀, ìwọ ilé Jakọbu. Wọ́n kún fún ìgbàgbọ́ tí kò lẹ́sẹ̀ nílẹ̀ tí ó ti ìlà-oòrùn wá, wọ́n ń wo iṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí àwọn Filistini, wọ́n ń pa ọwọ́ pọ̀ pẹ̀lú àwọn abọ̀rìṣà.
Aleś ty opuścił lud swój, dom Jakóbowy! gdyż są pełni obrzydliwości narodów wschodnich, i są wieszczkami jako Filistynowie, a w synach cudzych się kochali.
7 Ilẹ̀ wọn kún fún fàdákà àti wúrà, ìṣúra wọn kò sì ní òpin. Ilẹ̀ ẹ wọn kún fún ẹṣin, kẹ̀kẹ́ ogun wọn kò sì lópin.
I napełniona jest ziemia ich srebrem i złotem, a końca niemasz skarbom ich.
8 Ilẹ̀ ẹ wọn kún fún ère, wọ́n sì ń foríbalẹ̀ fún iṣẹ́ ọwọ́ ara wọn, èyí tí ìka ọwọ́ àwọn tìkára wọn ti ṣe.
Napełniona jest ziemia ich końmi, a końca niemasz wozom ich. Napełniona też jest ziemia ich bałwanami, robocie rąk swoich kłaniają się, które poczyniły palce ich.
9 Nítorí náà ni a ó ṣe rẹ ènìyàn sílẹ̀ ìran ọmọ ènìyàn ni yóò sì di onírẹ̀lẹ̀, má ṣe dáríjì wọ́n.
I kłania się pospolity człowiek, a uniża się i zacny mąż; przetoż nie odpuszczaj im.
10 Wọ inú àpáta lọ, fi ara pamọ́ nínú erùpẹ̀ kúrò nínú ìpayà Olúwa, àti ògo ọláńlá rẹ̀!
Wnijdź w skałę, a skryj się w prochu przed strachem Pańskim, i przed chwałą majestatu jego.
11 Ojú agbéraga ènìyàn ni a ó rẹ̀ sílẹ̀ a ó sì tẹrí ìgbéraga ènìyàn ba, Olúwa nìkan ṣoṣo ni a ó gbéga ní ọjọ́ náà.
Oczy wyniosłe człowiecze zniżone będą, a wysokość ludzka nachylona będzie; ale sam Pan wywyższony będzie dnia onego.
12 Olúwa àwọn ọmọ-ogun ní ọjọ́ kan ní ìpamọ́ fún gbogbo agbéraga àti ọlọ́kàn gíga nítorí gbogbo àwọn tí a gbéga (ni a ó rẹ̀ sílẹ̀),
Albowiem dzień Pana zastępów przyjdzie na wszelkiego pysznego i wyniosłego, i na każdego wywyższonego, że będzie poniżony;
13 nítorí gbogbo igi kedari Lebanoni, tó ga tó rìpó àti gbogbo óákù Baṣani,
I na wszystkie cedry Libańskie wysokie a podniosłe, i na wszystkie dęby Basańskie;
14 nítorí gbogbo òkè gíga ńlá ńlá àti àwọn òkè kéékèèké,
I na wszystkie góry wysokie, i na wszystkie pagórki wyniosłe;
15 fún ilé ìṣọ́ gíga gíga àti àwọn odi ìdáàbòbò,
I na każdą wieżę wysoką, i na każdy mur obronny;
16 fún gbogbo ọkọ̀ àwọn oníṣòwò àwọn ọkọ̀ tí a ṣe lọ́ṣọ̀ọ́.
I na wszystkie okręty morskie, i na wszystkie malowania rozkoszne.
17 Ìgbéraga ènìyàn ni a ó tẹ̀ lórí ba a ó sì rẹ ìgbéraga ènìyàn sílẹ̀, Olúwa nìkan ṣoṣo ni a ó gbéga ní ọjọ́ náà,
I będzie nachylona wyniosłość człowiecza, a wywyższenie ludzkie zniżone będzie; ale sam Pan wywyższony będzie dnia onego.
18 gbogbo ère òrìṣà yóò pòórá.
Lecz bałwany ich do szczętu pokruszone będą.
19 Àwọn ènìyàn yóò sálọ sínú ihò àpáta àti sínú ihò ilẹ̀ kúrò lọ́wọ́ ìpayà Olúwa àti ògo ọláńlá rẹ̀, nígbà tí ó bá dìde láti mi ayé tìtì.
Tedy wnijdą do jaskiń skalnych, i do jam podziemnych przed strachem Pańskim, i przed chwałą majestatu jego, gdy powstanie, aby ziemię potarł.
20 Ní ọjọ́ náà ni àwọn ènìyàn yóò máa sọ àwọn ère fàdákà àti ère wúrà tí wọ́n ti yá fún bíbọ sí èkúté àti àwọn àdán.
Dnia onego wrzuci człowiek bałwany swe srebrne i bałwany swe złote, które mu naczyniono, aby się im kłaniał, w dziury kretów i nietoperzy.
21 Wọn yóò sálọ sínú ihò ìsàlẹ̀ àpáta àti sínú ihò pàlàpálá àpáta kúrò lọ́wọ́ ìpayà Olúwa àti ògo ọláńlá rẹ̀, nígbà tí ó bá dìde láti mi ayé tìtì.
I wnijdzie w rozpadliny skalne, i na wierzchołki opok przed strachem Pańskim, i przed chwałą majestatu jego, gdy powstanie, aby potarł ziemię.
22 Dẹ́kun à ń gba ènìyàn gbọ́, èémí ẹni tó wà ní ihò imú rẹ̀. Nítorí nínú kín ni a lè kà á sí?
Przestańcież ufać w człowieku, którego dech jest w nozdrzach jego; bo za cóż on ma być poczytany?

< Isaiah 2 >