< Isaiah 2 >
1 Èyí ni ohun tí Isaiah ọmọ Amosi rí nípa Juda àti Jerusalẹmu.
Det ord som Esaias, sønn av Amos, mottok i et syn om Juda og Jerusalem.
2 Ní ìgbẹ̀yìn ọjọ́ òkè tẹmpili Olúwa ni a ó fi ìdí rẹ̀ kalẹ̀ gẹ́gẹ́ bí olú nínú àwọn òkè, a ó sì gbé e ga ju àwọn òkè kéékèèké lọ, gbogbo orílẹ̀-èdè yóò sì máa sàn sínú un rẹ̀.
Og det skal skje i de siste dager, da skal fjellet der Herrens hus står, være grunnfestet på toppen av fjellene og høit hevet over alle høider, og alle hedningefolk skal strømme til det.
3 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn ni yóò wá, wọn yóò sì wí pé, “Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí á gòkè ńlá Olúwa, àti sí ilé Ọlọ́run Jakọbu. Òun yóò kọ́ wa ní ọ̀nà rẹ̀, kí àwa kí ó lè rìn ní ọ̀nà rẹ̀.” Òfin yóò jáde láti Sioni wá, àti ọ̀rọ̀ Olúwa láti Jerusalẹmu.
Og mange folkeslag skal gå avsted og si: Kom, la oss gå op til Herrens berg, til Jakobs Guds hus, så han kan lære oss sine veier, og vi ferdes på hans stier! For fra Sion skal lov utgå, og Herrens ord fra Jerusalem.
4 Òun ó ṣe ìdájọ́ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, yóò sì parí aáwọ̀ fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ènìyàn. Wọn yóò fi idà wọn rọ ọkọ́ ìtulẹ̀, wọn yóò sì fi ọ̀kọ̀ wọn rọ dòjé. Orílẹ̀-èdè kì yóò sì gbé idà sí orílẹ̀-èdè mọ́, bẹ́ẹ̀ ní wọn kì yóò kọ́ ogun jíjà mọ́.
Og han skal dømme mellem hedningefolkene og skifte rett for mange folkeslag, og de skal smi sine sverd om til hakker og sine spyd til vingårdskniver; et folk skal ikke lenger løfte sverd mot et annet, og de skal ikke mere lære å føre krig.
5 Wá, ẹ̀yìn ará ilé e Jakọbu, ẹ jẹ́ kí a rìn nínú ìmọ́lẹ̀ Olúwa.
Jakobs hus! Kom, la oss vandre i Herrens lys!
6 Ìwọ ti kọ àwọn ènìyàn rẹ sílẹ̀, ìwọ ilé Jakọbu. Wọ́n kún fún ìgbàgbọ́ tí kò lẹ́sẹ̀ nílẹ̀ tí ó ti ìlà-oòrùn wá, wọ́n ń wo iṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí àwọn Filistini, wọ́n ń pa ọwọ́ pọ̀ pẹ̀lú àwọn abọ̀rìṣà.
For du har forkastet ditt folk, Jakobs hus, fordi de er fulle av Østerlands kunster og spår av skyene som filistrene, og mennesker av fremmed ætt drar de inn i landet i mengde.
7 Ilẹ̀ wọn kún fún fàdákà àti wúrà, ìṣúra wọn kò sì ní òpin. Ilẹ̀ ẹ wọn kún fún ẹṣin, kẹ̀kẹ́ ogun wọn kò sì lópin.
Deres land blev fullt av sølv og gull, og det er ingen ende på dets skatter; deres land blev fullt av hester, og det er ingen ende på dets vogner;
8 Ilẹ̀ ẹ wọn kún fún ère, wọ́n sì ń foríbalẹ̀ fún iṣẹ́ ọwọ́ ara wọn, èyí tí ìka ọwọ́ àwọn tìkára wọn ti ṣe.
deres land blev fullt av avguder; de tilbeder sine henders verk, det deres fingrer har gjort.
9 Nítorí náà ni a ó ṣe rẹ ènìyàn sílẹ̀ ìran ọmọ ènìyàn ni yóò sì di onírẹ̀lẹ̀, má ṣe dáríjì wọ́n.
Og mennesket blir bøiet, og mannen ydmyket - tilgi dem ikke!
10 Wọ inú àpáta lọ, fi ara pamọ́ nínú erùpẹ̀ kúrò nínú ìpayà Olúwa, àti ògo ọláńlá rẹ̀!
Gå inn i fjellet og skjul dig i støvet for Herrens gru og for hans høihets herlighet!
11 Ojú agbéraga ènìyàn ni a ó rẹ̀ sílẹ̀ a ó sì tẹrí ìgbéraga ènìyàn ba, Olúwa nìkan ṣoṣo ni a ó gbéga ní ọjọ́ náà.
Menneskets stolte øine blir ydmyket, og mennenes stolthet blir bøiet, og Herren alene er høi på den dag.
12 Olúwa àwọn ọmọ-ogun ní ọjọ́ kan ní ìpamọ́ fún gbogbo agbéraga àti ọlọ́kàn gíga nítorí gbogbo àwọn tí a gbéga (ni a ó rẹ̀ sílẹ̀),
For Herren, hærskarenes Gud, har satt en dag til dom over alt stolt og høit og over alt ophøiet, så det blir ydmyket,
13 nítorí gbogbo igi kedari Lebanoni, tó ga tó rìpó àti gbogbo óákù Baṣani,
både over alle Libanons sedrer, de høie og ophøiede, og over alle Basans eker
14 nítorí gbogbo òkè gíga ńlá ńlá àti àwọn òkè kéékèèké,
og over alle de høie fjell og over alle de stolte høider
15 fún ilé ìṣọ́ gíga gíga àti àwọn odi ìdáàbòbò,
og over hvert høit tårn og over hver fast mur
16 fún gbogbo ọkọ̀ àwọn oníṣòwò àwọn ọkọ̀ tí a ṣe lọ́ṣọ̀ọ́.
og over alle Tarsis-skib og over alt som er fagert å skue.
17 Ìgbéraga ènìyàn ni a ó tẹ̀ lórí ba a ó sì rẹ ìgbéraga ènìyàn sílẹ̀, Olúwa nìkan ṣoṣo ni a ó gbéga ní ọjọ́ náà,
Og menneskets overmot blir bøiet, og mennenes stolthet blir ydmyket, og Herren alene er høi på den dag.
18 gbogbo ère òrìṣà yóò pòórá.
Og avgudene - med dem er det helt forbi.
19 Àwọn ènìyàn yóò sálọ sínú ihò àpáta àti sínú ihò ilẹ̀ kúrò lọ́wọ́ ìpayà Olúwa àti ògo ọláńlá rẹ̀, nígbà tí ó bá dìde láti mi ayé tìtì.
Og folk skal gå inn i fjellhulene og i jordens revner for Herrens gru og for hans høihets herlighet, når han reiser sig for å forferde jorden.
20 Ní ọjọ́ náà ni àwọn ènìyàn yóò máa sọ àwọn ère fàdákà àti ère wúrà tí wọ́n ti yá fún bíbọ sí èkúté àti àwọn àdán.
På den dag skal menneskene kaste sine guder av sølv og gull, som de har gjort sig for å tilbede dem, bort til muldvarpene og flaggermusene
21 Wọn yóò sálọ sínú ihò ìsàlẹ̀ àpáta àti sínú ihò pàlàpálá àpáta kúrò lọ́wọ́ ìpayà Olúwa àti ògo ọláńlá rẹ̀, nígbà tí ó bá dìde láti mi ayé tìtì.
og gå inn i fjellkløftene og i berghulene for Herrens gru og for hans høihets herlighet, når han reiser sig for å forferde jorden.
22 Dẹ́kun à ń gba ènìyàn gbọ́, èémí ẹni tó wà ní ihò imú rẹ̀. Nítorí nínú kín ni a lè kà á sí?
Hold da op med å stole på mennesket, i hvis nese det bare er et pust! Hvad er han å akte for?