< Isaiah 2 >

1 Èyí ni ohun tí Isaiah ọmọ Amosi rí nípa Juda àti Jerusalẹmu.
Ũyũ nĩguo ũhoro ũrĩa Isaia mũrũ wa Amozu onire ũkoniĩ Juda na Jerusalemu:
2 Ní ìgbẹ̀yìn ọjọ́ òkè tẹmpili Olúwa ni a ó fi ìdí rẹ̀ kalẹ̀ gẹ́gẹ́ bí olú nínú àwọn òkè, a ó sì gbé e ga ju àwọn òkè kéékèèké lọ, gbogbo orílẹ̀-èdè yóò sì máa sàn sínú un rẹ̀.
Matukũ-inĩ ma kũrigĩrĩria kĩrĩma kĩa hekarũ ya Jehova nĩgĩkahaandwo kĩrĩ kĩo kĩnene gatagatĩ ka irĩma iria ingĩ; nĩgĩkambarario igũrũ rĩa tũrĩma tũrĩa tũngĩ, nao andũ a ndũrĩrĩ nĩkuo magaathiiaga.
3 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn ni yóò wá, wọn yóò sì wí pé, “Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí á gòkè ńlá Olúwa, àti sí ilé Ọlọ́run Jakọbu. Òun yóò kọ́ wa ní ọ̀nà rẹ̀, kí àwa kí ó lè rìn ní ọ̀nà rẹ̀.” Òfin yóò jáde láti Sioni wá, àti ọ̀rọ̀ Olúwa láti Jerusalẹmu.
Ndũrĩrĩ nyingĩ nĩigathiĩ kuo ikiugaga atĩrĩ, “Ũkai, twambate tũthiĩ kĩrĩma-inĩ kĩa Jehova, tũthiĩ nyũmba ya Ngai wa Jakubu. Nĩagatũruta ũhoro wa mĩthiĩre yake, nĩgeetha tũgeragĩre njĩra ciake.” Nĩgũkorwo Zayuni nĩgũkoima ũtaarani, nakuo Jerusalemu kuume ndũmĩrĩri ya Jehova.
4 Òun ó ṣe ìdájọ́ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, yóò sì parí aáwọ̀ fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ènìyàn. Wọn yóò fi idà wọn rọ ọkọ́ ìtulẹ̀, wọn yóò sì fi ọ̀kọ̀ wọn rọ dòjé. Orílẹ̀-èdè kì yóò sì gbé idà sí orílẹ̀-èdè mọ́, bẹ́ẹ̀ ní wọn kì yóò kọ́ ogun jíjà mọ́.
Nake nĩagatuithanagia ndũrĩrĩ ciira, na aiguithanie irĩndĩ nyingĩ. Hiũ ciao cia njora magaacithondeka ituĩke mĩraũ ya kũrĩma, namo matimũ mao mamathondeke matuĩke hiũ cia gũceeha mĩtĩ. Gũtirĩ rũrĩrĩ rũgaacooka kũrũa na rũrĩrĩ rũrĩa rũngĩ na rũhiũ rwa njora, o na kana merute ũhoro wa mbaara hĩndĩ ĩngĩ.
5 Wá, ẹ̀yìn ará ilé e Jakọbu, ẹ jẹ́ kí a rìn nínú ìmọ́lẹ̀ Olúwa.
Atĩrĩrĩ wee nyũmba ya Jakubu, ũkaai tũthiiage tũmũrĩkĩirwo nĩ ũtheri wa Jehova.
6 Ìwọ ti kọ àwọn ènìyàn rẹ sílẹ̀, ìwọ ilé Jakọbu. Wọ́n kún fún ìgbàgbọ́ tí kò lẹ́sẹ̀ nílẹ̀ tí ó ti ìlà-oòrùn wá, wọ́n ń wo iṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí àwọn Filistini, wọ́n ń pa ọwọ́ pọ̀ pẹ̀lú àwọn abọ̀rìṣà.
Wee nĩũtiganĩirie andũ aku, o acio a nyũmba ya Jakubu. Nao marũmĩtie mũno mĩtugo na irĩra cia andũ a mwena wa irathĩro; maragũraga ta Afilisti, na makagĩa thiritũ na andũ matooĩ Ngai.
7 Ilẹ̀ wọn kún fún fàdákà àti wúrà, ìṣúra wọn kò sì ní òpin. Ilẹ̀ ẹ wọn kún fún ẹṣin, kẹ̀kẹ́ ogun wọn kò sì lópin.
Bũrũri wao ũiyũrĩte betha na thahabu, igĩĩna ciao itingĩthira. Bũrũri wao ũiyũrĩte mbarathi; na ngaari ciao cia ita itingĩtarĩka.
8 Ilẹ̀ ẹ wọn kún fún ère, wọ́n sì ń foríbalẹ̀ fún iṣẹ́ ọwọ́ ara wọn, èyí tí ìka ọwọ́ àwọn tìkára wọn ti ṣe.
Bũrũri wao ũiyũrĩte mĩhianano ya kũhooywo; mainamagĩrĩra wĩra wa moko mao, o indo iria mathondekete na ciara ciao.
9 Nítorí náà ni a ó ṣe rẹ ènìyàn sílẹ̀ ìran ọmọ ènìyàn ni yóò sì di onírẹ̀lẹ̀, má ṣe dáríjì wọ́n.
Nĩ ũndũ ũcio mũndũ nĩakaharũrũkio, nacio iruka cia andũ iconorithio; ndũkanamarekere.
10 Wọ inú àpáta lọ, fi ara pamọ́ nínú erùpẹ̀ kúrò nínú ìpayà Olúwa, àti ògo ọláńlá rẹ̀!
Toonyai rwaro-inĩ rwa ihiga, mwĩhithe tĩĩri-inĩ mũũrĩre kĩmakania kĩa Jehova na riiri wa ũnene wake!
11 Ojú agbéraga ènìyàn ni a ó rẹ̀ sílẹ̀ a ó sì tẹrí ìgbéraga ènìyàn ba, Olúwa nìkan ṣoṣo ni a ó gbéga ní ọjọ́ náà.
Maitho ma mũndũ mwĩtĩĩi nĩmagaconorithio, naguo mwĩtĩĩo wa andũ nĩũkaharũrũkio; no Jehova we wiki nĩwe ũgaatũũgĩrio mũthenya ũcio.
12 Olúwa àwọn ọmọ-ogun ní ọjọ́ kan ní ìpamọ́ fún gbogbo agbéraga àti ọlọ́kàn gíga nítorí gbogbo àwọn tí a gbéga (ni a ó rẹ̀ sílẹ̀),
Jehova Mwene-Hinya-Wothe arĩ na mũthenya aigĩte wa gũũkĩrĩra andũ arĩa othe etĩĩi na arĩa meĩkagĩrĩra, na arĩa othe metũũgagĩria (nao othe nĩmakanyiihio),
13 nítorí gbogbo igi kedari Lebanoni, tó ga tó rìpó àti gbogbo óákù Baṣani,
na okĩrĩre mĩtarakwa yothe ya Lebanoni, ĩrĩa mĩraihu na igũrũ na ĩkaneneha mũno, o na mĩgandi yothe ya Bashani,
14 nítorí gbogbo òkè gíga ńlá ńlá àti àwọn òkè kéékèèké,
na okĩrĩre irĩma iria ndaaya na igũrũ, na tũrĩma tuothe tũrĩa tũraihu.
15 fún ilé ìṣọ́ gíga gíga àti àwọn odi ìdáàbòbò,
na okĩrĩre mũthiringo o wothe mũraihu na igũrũ na rũthingo o ruothe rwakĩtwo rwa hinya,
16 fún gbogbo ọkọ̀ àwọn oníṣòwò àwọn ọkọ̀ tí a ṣe lọ́ṣọ̀ọ́.
na okĩrĩre marikabu ciothe cia Tarishishi, na marikabu ciothe iria njega mũno.
17 Ìgbéraga ènìyàn ni a ó tẹ̀ lórí ba a ó sì rẹ ìgbéraga ènìyàn sílẹ̀, Olúwa nìkan ṣoṣo ni a ó gbéga ní ọjọ́ náà,
Mwĩtũũgĩrio wa mũndũ nĩũkaharũrũkio, na mwĩtĩĩo wa andũ ũconorithio; no Jehova we wiki nĩwe ũgaatũũgĩrio mũthenya ũcio,
18 gbogbo ère òrìṣà yóò pòórá.
nayo mĩhianano ya kũhooywo nĩĩgathira biũ.
19 Àwọn ènìyàn yóò sálọ sínú ihò àpáta àti sínú ihò ilẹ̀ kúrò lọ́wọ́ ìpayà Olúwa àti ògo ọláńlá rẹ̀, nígbà tí ó bá dìde láti mi ayé tìtì.
Andũ makoorĩra ngurunga-inĩ cia ndwaro cia mahiga, o na marima-inĩ ma thĩ, moorĩre kĩmakania kĩa Jehova na riiri wa ũnene wake, hĩndĩ ĩrĩa akaarũgama athingithie thĩ.
20 Ní ọjọ́ náà ni àwọn ènìyàn yóò máa sọ àwọn ère fàdákà àti ère wúrà tí wọ́n ti yá fún bíbọ sí èkúté àti àwọn àdán.
Mũthenya ũcio andũ makooya mĩhianano yao ya betha, na mĩhianano yao ya thahabu, ĩrĩa methondekeire mamĩhooyage, mamĩikĩrie huko na huhu.
21 Wọn yóò sálọ sínú ihò ìsàlẹ̀ àpáta àti sínú ihò pàlàpálá àpáta kúrò lọ́wọ́ ìpayà Olúwa àti ògo ọláńlá rẹ̀, nígbà tí ó bá dìde láti mi ayé tìtì.
Nao makoorĩra ngurunga-inĩ cia ndwaro cia mahiga, na mahiga-inĩ marĩa macunjurĩte morĩre kĩmakania kĩa Jehova na riiri wa ũnene wake, hĩndĩ ĩrĩa akaarũgama, athingithie thĩ.
22 Dẹ́kun à ń gba ènìyàn gbọ́, èémí ẹni tó wà ní ihò imú rẹ̀. Nítorí nínú kín ni a lè kà á sí?
Tiga kwĩhoka mũndũ, ũrĩa mĩhũmũ yake ĩrĩ o maniũrũ-inĩ make. Nĩ ũndũ-rĩ, akĩrĩ wa bata ũrĩkũ?

< Isaiah 2 >