< Isaiah 19 >

1 Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ tí ó kan Ejibiti. Kíyèsi i, Olúwa gun àwọsánmọ̀ tí ó yára lẹ́ṣin ó sì ń bọ̀ wá sí Ejibiti. Àwọn ère òrìṣà Ejibiti wárìrì níwájú rẹ̀, ọkàn àwọn ará Ejibiti sì ti domi nínú wọn.
Le fardeau de l'Égypte. « Voici que Yahvé monte sur une nuée rapide, et il vient en Égypte. Les idoles de l'Égypte trembleront en sa présence, et le cœur de l'Égypte se fondra en lui.
2 “Èmi yóò rú àwọn ará Ejibiti sókè sí ara wọn arákùnrin yóò bá arákùnrin rẹ̀ jà, aládùúgbò yóò dìde sí aládùúgbò rẹ̀, ìlú yóò dìde sí ìlú, ilẹ̀ ọba sí ilẹ̀ ọba.
J'exciterai les Égyptiens contre les Égyptiens, et ils se battront chacun contre son frère, chacun contre son voisin, ville contre ville, et royaume contre royaume.
3 Àwọn ará Ejibiti yóò sọ ìrètí nù, èmi yóò sì sọ èrò wọn gbogbo di òfo; wọn yóò bá àwọn òrìṣà àti ẹ̀mí àwọn òkú sọ̀rọ̀, àwọn awoṣẹ́ àti àwọn abókùúsọ̀rọ̀.
L'esprit des Égyptiens s'affaiblira au dedans d'eux. Je détruirai leur conseil. Ils chercheront les idoles, les enchanteurs, ceux qui ont des esprits familiers, et les magiciens.
4 Èmi yóò fi Ejibiti lé agbára àwọn ìkà amúnisìn lọ́wọ́, ọba aláìláàánú ni yóò jẹ ọba lé wọn lórí,” ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Je livrerai les Égyptiens entre les mains d'un seigneur cruel. Un roi féroce dominera sur eux, dit le Seigneur, Yahvé des Armées.
5 Gbogbo omi inú odò ni yóò gbẹ, gbogbo ilẹ̀ àyíká odò ni yóò gbẹ tí yóò sì sáàpá.
Les eaux de la mer disparaîtront, et le fleuve sera épuisé et desséché.
6 Adágún omi yóò sì di rírùn; àwọn odò ilẹ̀ Ejibiti yóò máa dínkù wọn yóò sì gbẹ. Àwọn koríko odò àti ìrẹ̀tẹ̀ yóò gbẹ,
Les fleuves deviendront infects. Les ruisseaux d'Égypte diminueront et se dessécheront. Les roseaux et les drapeaux se dessécheront.
7 àwọn igi ipadò Naili pẹ̀lú, tí ó wà ní orísun odò, gbogbo oko tí a dá sí ipadò Naili yóò gbẹ dànù tí yóò sì fẹ́ dànù tí kò sì ní sí mọ́.
Les prairies sur le Nil, sur le bord du Nil, et tous les champs ensemencés sur le Nil, se dessèchent, sont chassés, et ne sont plus.
8 Àwọn apẹja yóò sọkún kíkorò, àti gbogbo àwọn tí ó ń ju ìwọ̀ sínú odò; odò náà yóò sì máa rùn.
Les pêcheurs se lamenteront, et tous ceux qui pêchent dans le Nil se lamenteront, et ceux qui étendent les filets sur les eaux se languiront.
9 Àwọn tí ó ń ṣiṣẹ́ pẹ̀lú ọ̀gbọ̀ yóò kọminú àwọn ahunṣọ ọ̀gbọ̀ yóò sọ ìrètí nù.
Et ceux qui travaillent le lin peigné, et ceux qui tissent des étoffes blanches, seront confus.
10 Àwọn tí ń ṣiṣẹ́ aṣọ yóò rẹ̀wẹ̀sì, gbogbo àwọn oníṣẹ́ oṣù ni àìsàn ọkàn yóò ṣe.
Les piliers seront brisés en morceaux. Tous ceux qui travaillent à gages auront l'âme affligée.
11 Àwọn oníṣẹ́ Ṣoani ti di aláìgbọ́n, àwọn ọlọ́gbọ́n olùdámọ̀ràn Farao ń mú ìmọ̀ràn àìgbọ́n wá. Báwo ló ṣe lè sọ fún Farao pé, “Mo jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn ọlọ́gbọ́n ènìyàn, ọ̀kan nínú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn àwọn ọba àtijọ́.”
Les princes de Tsoan sont complètement stupides. Le conseil des plus sages conseillers de Pharaon est devenu stupide. Comment peux-tu dire à Pharaon: « Je suis le fils des sages, le fils des anciens rois »?
12 Níbo ni àwọn ọlọ́gbọ́n ènìyàn rẹ wà báyìí? Jẹ́ kí wọn fihàn ọ́ kí wọn sì sọ ọ́ di mí mọ̀ ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti pinnu lórí Ejibiti.
Où sont donc tes sages? Qu'ils te le disent maintenant, et qu'ils sachent ce que l'Éternel des armées a décidé pour l'Égypte.
13 Àwọn ọmọ-aládé Ṣoani ti di aṣiwèrè, a ti tan àwọn ọmọ-aládé Memfisi jẹ; àwọn òkúta igun ilé tí í ṣe ti ẹ̀yà rẹ ti ṣi Ejibiti lọ́nà.
Les princes de Tsoan sont devenus des insensés. Les princes de Memphis ont été trompés. Ils ont égaré l'Égypte, eux qui sont la pierre angulaire de ses tribus.
14 Olúwa ti da ẹ̀mí òòyì sínú wọn; wọ́n mú Ejibiti ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n nínú ohun gbogbo tí ó ń ṣe, gẹ́gẹ́ bí ọ̀mùtí ti í ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n nínú èébì rẹ̀.
L'Éternel a mêlé au milieu d'elle un esprit de perversité; ils ont égaré l'Égypte dans toutes ses œuvres, comme un homme ivre titube dans son vomissement.
15 Kò sí ohun tí Ejibiti le ṣe— orí tàbí ìrù, ọ̀wá ọ̀pẹ tàbí koríko odò.
Il n'y aura plus pour l'Égypte d'ouvrage que tête ou queue, branche de palmier ou jonc, puisse faire.
16 Ní ọjọ́ náà ni àwọn ará Ejibiti yóò dàbí obìnrin. Wọn yóò gbọ̀n jìnnìjìnnì pẹ̀lú ẹ̀rù nítorí ọwọ́ Olúwa àwọn ọmọ-ogun tí a gbé sókè sí wọn.
En ce jour-là, les Égyptiens seront comme des femmes. Ils trembleront et auront peur à cause de l'agitation de la main de l'Éternel des armées, qu'il secoue sur eux.
17 Ilẹ̀ Juda yóò sì di ẹ̀rù fún Ejibiti; gbogbo àwọn tí a bá ti dárúkọ Juda létí wọn ni yóò wárìrì, nítorí ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun gbèrò láti ṣe sí wọn.
Le pays de Juda deviendra une terreur pour l'Égypte. Tous ceux à qui on en parlera seront effrayés, à cause des projets de l'Éternel des armées, qu'il forme contre lui.
18 Ní ọjọ́ náà ìlú márùn-ún ní ilẹ̀ Ejibiti yóò sọ èdè àwọn ará Kenaani, wọn yóò sì búra àtìlẹ́yìn fún Olúwa àwọn ọmọ-ogun. Ọ̀kan nínú wọn ni a ó sì máa pè ní ìlú ìparun.
En ce jour-là, il y aura au pays d'Égypte cinq villes qui parleront la langue de Canaan et qui jureront devant l'Éternel des armées. L'une d'elles sera appelée « la ville de la destruction ».
19 Ní ọjọ́ náà pẹpẹ kan yóò wà fún Olúwa ní àárín gbùngbùn Ejibiti, àti ọ̀wọ́n kan fún Olúwa ní etí bodè rẹ̀.
En ce jour-là, il y aura un autel à Yahvé au milieu du pays d'Égypte, et une colonne à Yahvé à sa frontière.
20 Yóò sì jẹ́ àmì àti ẹ̀rí sí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ní ilẹ̀ Ejibiti. Nígbà tí wọ́n bá ké pe Olúwa nítorí àwọn aninilára wọn, yóò rán olùgbàlà àti olùgbèjà kan sí wọn tí yóò sì gbà wọ́n sílẹ̀.
Ce sera un signe et un témoignage pour l'Éternel des armées dans le pays d'Égypte; car ils crieront à l'Éternel à cause des oppresseurs, et il leur enverra un sauveur et un défenseur, et il les délivrera.
21 Báyìí ni Olúwa yóò sọ ara rẹ̀ di mí mọ̀ fún àwọn ará Ejibiti àti ní ọjọ́ náà ni wọn yóò gba Olúwa gbọ́. Wọn yóò sìn ín pẹ̀lú ẹbọ ọrẹ ìyẹ̀fun, wọn yóò jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún Olúwa wọn yóò sì mú un ṣẹ.
Yahvé sera connu de l'Égypte, et les Égyptiens connaîtront Yahvé en ce jour-là. Oui, ils se prosterneront avec des sacrifices et des offrandes, ils feront un vœu à Yahvé et l'accompliront.
22 Olúwa yóò fi àjàkálẹ̀-ààrùn kan bá Ejibiti jà; yóò bá wọn jà yóò sì tún wò wọ́n sàn. Wọn yóò yípadà sí Olúwa, Òun yóò sì gbọ́ ẹ̀bẹ̀ wọn yóò sì wò wọ́n sàn.
Yahvé frappera l'Égypte, il la frappera et la guérira. Ils reviendront à Yahvé, qui sera imploré par eux et les guérira.
23 Ní ọjọ́ náà òpópónà kan yóò wá láti Ejibiti lọ sí Asiria. Àwọn ará Asiria yóò lọ sí Ejibiti àti àwọn ará Ejibiti lọ sí Asiria. Àwọn ará Ejibiti àti ará Asiria yóò jọ́sìn papọ̀.
En ce jour-là, il y aura une route de l'Égypte vers l'Assyrie; l'Assyrien entrera en Égypte, et l'Égyptien en Assyrie; et les Égyptiens se prosterneront avec les Assyriens.
24 Ní ọjọ́ náà Israẹli yóò di ẹ̀kẹta pẹ̀lú Ejibiti àti Asiria, àní orísun ìbùkún ní ilẹ̀ ayé.
En ce jour-là, Israël sera le troisième avec l'Égypte et avec l'Assyrie, une bénédiction sur la terre;
25 Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò bùkún wọn yóò wí pé, “Ìbùkún ni fún Ejibiti ènìyàn mi, Asiria iṣẹ́ ọwọ́ mi, àti Israẹli ìní mi.”
car l'Éternel des armées les a bénis, en disant: « Bénis soient l'Égypte, mon peuple, l'Assyrie, l'ouvrage de mes mains, et Israël, mon héritage. »

< Isaiah 19 >