< Isaiah 18 >

1 Ègbé ni fún ilẹ̀ tí ó kún fún ariwo ìyẹ́ eṣú, ní àwọn ipadò Kuṣi,
Malheur à la terre fière de ses barques ailées, au delà des fleuves de l'Éthiopie!
2 tí ó rán àwọn ikọ̀ lórí Òkun lórí omi nínú ọkọ̀-ọpọ́n tí a fi eèsún papirusi ṣe. Ẹ lọ, ẹ̀yin ikọ̀ tí ó yára, sí àwọn ènìyàn gíga tí àwọ̀ ara wọn jọ̀lọ̀, sí àwọn ènìyàn tí a ń bẹ̀rù káàkiri, orílẹ̀-èdè aláfojúdi alájèjì èdè, tí odò pín ilẹ̀ rẹ̀ yẹ́lẹyẹ̀lẹ.
A cette terre, qui envoie des otages par la mer et des lettres sur les eaux! Car des messagers rapides s'en iront vers une nation superbe, vers un peuple étranger et cruel. Qui habite au delà? Une nation désespérée et foulée aux pieds. Alors les fleuves de leur terre
3 Gbogbo ẹ̀yin ènìyàn ayé, tí ó ń gbé orílẹ̀ ayé, nígbà tí a bá gbé àsíá kan sókè lórí òkè, ẹ ó rí i, nígbà tí a bá fun fèrè kan ẹ ó gbọ́ ọ.
Seront tous habités comme une région habitée. Leur terre sera comme un signal élevé sur la montagne, comme le son d'une trompette qui se fait entendre.
4 Èyí ni ohun tí Olúwa sọ fún mi: “Èmi yóò dákẹ́ jẹ́ẹ́, èmi yóò sì máa wo òréré láti ibùgbé e mi wá, gẹ́gẹ́ bí ooru gbígbóná nínú ìtànṣán oòrùn, gẹ́gẹ́ bí òjò-dídì ní àárín gbùngbùn ìkórè.”
Car le Seigneur m'a ainsi parlé: Il y aura sécurité dans ma ville, comme la lumière à l'ardeur de midi, comme le nuage de rosée un jour de moisson,
5 Nítorí, kí ìkórè tó bẹ̀rẹ̀, nígbà tí ìrudí bá kún, nígbà tí ìtànná bá di èso àjàrà pípọ́n. Òun yóò sì fi dòjé rẹ́ ẹ̀ka tuntun, yóò sì mu kúrò, yóò sì gé ẹ̀ka lulẹ̀.
Avant la coupe des blés, quand la fleur est passée, que le raisin hors de fleur commence à mûrir, et que les fleurs sont devenues des grains. Alors le Seigneur ôtera les jeunes pousses avec la faux, et il arrachera les sarments et il les coupera.
6 A ó fi wọ́n sílẹ̀ fún àwọn ẹyẹ òkè ńlá àti fún àwọn ẹranko búburú; àwọn ẹyẹ yóò fi wọ́n ṣe oúnjẹ nínú ẹ̀ẹ̀rùn àti àwọn ẹranko búburú nígbà òjò.
Et il les abandonnera aux oiseaux du ciel et aux bêtes fauves de la terre. Et tous les oiseaux du ciel viendront s'y rassembler, et toutes les bêtes fauves de la terre accourront contre l'Éthiopien.
7 Ní àkókò náà ni a ó mú ẹ̀bùn wá fún Olúwa àwọn ọmọ-ogun láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn gíga tí ẹran-ara wọn jọ̀lọ̀, láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn tí a bẹ̀rù níbi gbogbo, orílẹ̀-èdè aláfojúdi àti alájèjì èdè, ilẹ̀ ẹni tí omi pín sí yẹ́lẹyẹ̀lẹ— a ó mú àwọn ẹ̀bùn náà wá sí òkè Sioni, ibi tí orúkọ Olúwa àwọn ọmọ-ogun gbé wà.
En ce temps-là, des présents seront offerts au Seigneur, Dieu des armées, par un peuple contrit et opprimé, par un grand peuple, maintenant et par tous les siècles. Et c'est ce peuple qui espère aujourd'hui, que l'on foule aux pieds, qui habite la terre de ce côté du fleuve, dans le lieu où réside le nom du Seigneur, sur la montagne de Sion.

< Isaiah 18 >