< Isaiah 17 >
1 Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ tí ó kan Damasku: “Kíyèsi i, Damasku kò ní jẹ́ ìlú mọ́ ṣùgbọ́n yóò padà di ààtàn.
Voilà que Damas va être retranchée du nombre des villes; elle sera en ruines,
2 Àwọn ìlú Aroeri ni a ó kọ̀sílẹ̀ fún àwọn agbo ẹran tí yóò máa sùn síbẹ̀, láìsí ẹni tí yóò dẹ́rùbà wọ́n.
Abandonnée pour toujours; les menus troupeaux s'y reposeront, et nul ne sera là pour les en chasser.
3 Ìlú olódi ni yóò pòórá kúrò ní Efraimu, àti agbára ọba kúrò ní Damasku; àwọn àṣẹ́kù Aramu yóò dá gẹ́gẹ́ bí ògo ti àwọn Israẹli,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Et il n'y aura plus de forteresse où Ephraïm puisse se réfugier; et il n'y aura plus de royauté pour Damas, ni pour le reste des Syriens. Car tu ne vaux pas mieux que les fils d'Israël; ta gloire ne vaut pas mieux que leur gloire: voilà ce que dit le Seigneur des armées.
4 “Ní ọjọ́ náà ni ògo Jakọbu yóò sá; ọ̀rá ara rẹ̀ yóò ṣòfò dànù.
En ce jour, la gloire de Jacob sera obscurcie, et les richesses qui font sa gloire seront ébranlées.
5 Yóò sì dàbí ìgbà tí olùkórè kó àwọn irúgbìn tí ó dúró jọ tí ó sì ń kórè irúgbìn pẹ̀lú apá rẹ̀— àti gẹ́gẹ́ bí ìgbà tí ènìyàn pa ọkà ní àfonífojì ti Refaimu.
Et ce sera comme lorsque un homme glane ou ramasse les grains des épis dans une vallée féconde.
6 Síbẹ̀síbẹ̀ irúgbìn díẹ̀ yóò ṣẹ́kù, gẹ́gẹ́ bí ìgbà tí a gbọn igi olifi, tí èso olifi méjì tàbí mẹ́ta ṣẹ́kù sórí ẹ̀ka tí ó ga jùlọ, mẹ́rin tàbí márùn-ún lórí ẹ̀ka tí ó so jù,” ni Olúwa wí, àní Ọlọ́run Israẹli.
Et des glanures y ont été laissées, comme les trois ou quatre olives de rebut qu'on laisse à la cime de l'arbre, comme les quatre ou cinq qui restent au bout des branches: voilà ce que dit le Seigneur, Dieu d'Israël.
7 Ní ọjọ́ náà, àwọn ènìyàn yóò gbójú sókè sí Ẹlẹ́dàá wọn, wọn yóò sì síjú wo Ẹni Mímọ́ Israẹli.
Ce jour-là, l'homme mettra sa confiance en son Créateur; il tournera ses yeux vers le Saint d'Israël.
8 Wọn kò ní wo àwọn pẹpẹ mọ́, èyí tí í ṣe iṣẹ́ ọwọ́ wọn, wọn kò sì ní kọbi ara sí ère Aṣerah mọ́ tàbí pẹpẹ tùràrí tí ìka ọwọ́ wọn ti ṣe.
Et ils ne croiront plus à leurs autels, ni aux ouvrages de leurs mains que leurs doigts ont façonnés; ils ne regarderont plus leurs bois sacrés ni leurs abominations.
9 Ní ọjọ́ náà àwọn ìlú alágbára rẹ̀, yóò dàbí ẹ̀ka ìkọ̀sílẹ̀, àti ẹ̀ka téńté òkè tí wọ́n fi sílẹ̀ nítorí àwọn ọmọ Israẹli. Gbogbo wọn yóò sì di ahoro.
En ce jour tes villes seront abandonnées, comme le furent celles des Amorrhéens et des Hévéens, en présence des fils d'Israël; et elles seront désertes,
10 Nítorí ìwọ ti gbàgbé Ọlọ́run ìgbàlà rẹ; tí ìwọ kò sì náání àpáta ìgbàlà rẹ̀, nítorí náà ni ìwọ ti gbin ọ̀gbìn dáradára ìwọ sì tọ́ àjèjì ẹ̀ka sínú rẹ̀.
Parce que tu as délaissé Dieu ton Sauveur, et que tu ne t'es plus souvenu du Seigneur qui t'avait secouru; et, à cause de cela, tu planteras des arbres trompeurs et des graines infidèles.
11 Nítorí náà, bí ẹ tilẹ̀ mú àṣàyàn igi tí ẹ sì gbin àjàrà tí ó ti òkèrè wá, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ọjọ́ tí ẹ kó wọn jáde ẹ mú wọn hù jáde, àti ní òwúrọ̀ tí ẹ gbìn wọ́n ẹ mú kí wọ́n rúdí, síbẹ̀síbẹ̀ ìkórè kò ní mú nǹkan wá ní ọjọ́ ààrùn àti ìrora tí kò gbóògùn.
Le jour où tu planteras, tu seras déçu. Si tu sèmes le matin, ta semence fleurira pour être moissonnée le jour où tu laisseras ton héritage, et où, comme le père de l'homme, tu distribueras ton patrimoine à tes fils.
12 Kíyèsi i, ìrunú àwọn orílẹ̀-èdè— wọ́n ń runú bí ìgbì Òkun! Kíyèsi i, rògbòdìyàn tí ogunlọ́gọ̀ ènìyàn wọ́n bú ramúramù gẹ́gẹ́ bí ariwo odò ńlá!
Malheur à la multitude des nations! Comme une mer agitée, ainsi vous serez bouleversées; et leurs armes retentiront sur leur dos, comme des vagues.
13 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn ènìyàn ń bú ramúramù gẹ́gẹ́ bí ìrúmi odò, nígbà tí ó bá wọn wí wọ́n sálọ jìnnà réré, a tì wọ́n lọ gẹ́gẹ́ bí ìyàngbò ní orí òkè, àti gẹ́gẹ́ bí ewéko níwájú ìjì líle.
Cette multitude ressemblera à des flots tumultueux, à des ondes emportées par le vent. Le Seigneur exterminera le peuple assyrien, et il le rejettera au loin, comme au moindre souffle vole la paille légère des vanneurs, ou le tourbillon de poussière que soulève un ouragan.
14 Ní aginjù, ìpayà òjijì! Kí ó tó di òwúrọ̀, a ò rí wọn mọ́! Èyí ni ìpín àwọn tí ó jí wa lẹ́rù, àti ìpín àwọn tí ó fi ogun kó wa.
Sa douleur durera jusqu'au soir, et avant l'aurore il ne sera plus. Tel sera le partage de ceux qui ont fait de vous leur proie; tel sera l'héritage de ceux qui ont pris possession de vous.