< Isaiah 14 >

1 Olúwa yóò fi àánú hàn fún Jakọbu, yóò tún Israẹli yàn lẹ́ẹ̀kan sí i yóò sì fi ìdí wọn kalẹ̀ ní ilẹ̀ àwọn tìkára wọn. Àwọn àjèjì yóò darapọ̀ mọ́ wọn, wọn yóò sì fọwọ́sowọ́pọ̀ pẹ̀lú ilé e Jakọbu.
PAN bowiem zlituje się nad Jakubem i znowu wybierze Izraela, i osadzi ich w ich własnej ziemi. Cudzoziemcy przyłączą się do nich i przystaną do domu Jakuba.
2 Àwọn orílẹ̀-èdè yóò gbà wọ́n wọn yóò sì mú wọn wá sí ààyè e wọn. Ilé Israẹli yóò gba àwọn orílẹ̀-èdè gẹ́gẹ́ bí àwọn ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin ní ilẹ̀ Olúwa. Wọn yóò kó àwọn akónilẹ́rú wọn ní ìgbèkùn wọn yóò sì jẹ ọba lórí àwọn amúnisìn wọn.
Wezmą ich narody i przyprowadzą do ich miejsca. A dom Izraela weźmie ich w posiadanie w ziemi PANA jako sługi i służące. I będą trzymać w niewoli tych, u których byli w niewoli, i będą panować nad swoimi ciemięzcami.
3 Ní ọjọ́ tí Olúwa yóò fi ìtura fún un yín kúrò nínú ìpọ́njú àti ìyà àti ìdè ìkà,
W tym dniu, kiedy PAN da ci odpoczynek po twojej udręce, po twoim strachu i po twojej ciężkiej niewoli, w którą zostałeś podbity;
4 ẹ ó sì fi ọ̀rọ̀ àbùkù yìí kan ọba Babeli pé, báwo ni amúnisìn ṣe wá sí òpin! Báwo ni ìbínú rẹ̀ ṣe parí!
Podejmiesz tę przypowieść przeciw królowi Babilonu i powiesz: O jakże ustał ciemięzca! Jakże ustało złote miasto!
5 Olúwa ti dá ọ̀pá ìkà náà, ọ̀pá àwọn aláṣẹ,
PAN złamał kij niegodziwych i berło panujących;
6 èyí tí ó ti lu àwọn ènìyàn bolẹ̀ pẹ̀lú ti kò dáwọ́ dúró, nínú ìrunú ni ó ṣẹ́gun àwọn orílẹ̀-èdè pẹ̀lú ìgbónára tí kò lópin.
Tego, który smagał ludzi z wściekłością nieustannymi ciosami, który panował w gniewie [nad] narodami i dręczył bez litości.
7 Gbogbo ilẹ̀ ni ó wà ní ìsinmi àti àlàáfíà, wọ́n bú sí orin.
[Teraz] cała ziemia odpoczywa i jest spokojna, [wszyscy] głośno śpiewają;
8 Pẹ̀lúpẹ̀lú àwọn igi junifa àti àwọn igi kedari ti Lebanoni ń yọ̀ lórí rẹ wí pé, “Níwọ́n bí a ti rẹ̀ ọ́ sílẹ̀ báyìí, kò sí agégi tí yóò wá láti gé wa lulẹ̀.”
Nawet cyprysy radują się z powodu ciebie, a także cedry Libanu, [mówiąc]: [Odkąd] ległeś, żaden drwal nie powstał przeciwko nam.
9 Ibojì tí ó wà ní ìsàlẹ̀ ni a ru sókè láti pàdé rẹ ní ìpadàbọ̀ rẹ̀ ó ru ẹ̀mí àwọn tí ó ti lọ sókè láti wá kí ọ gbogbo àwọn tí ó jẹ́ olórí ní ayé ó mú kí wọn dìde lórí ìtẹ́ wọn gbogbo àwọn tí ó jẹ ọba lórí àwọn orílẹ̀-èdè. (Sheol h7585)
Piekło w dole poruszyło się przez ciebie, by wyjść ci na spotkanie; dla ciebie obudziło umarłych, wszystkich książąt ziemi; rozkazało wszystkim królom narodów powstać ze swoich tronów. (Sheol h7585)
10 Gbogbo wọn yóò dáhùn, wọn yóò wí fún ọ wí pé, “Ìwọ pẹ̀lú ti di aláìlera, gẹ́gẹ́ bí àwa pẹ̀lú ìwọ náà ti dàbí wa.”
Ci wszyscy odezwą się i powiedzą ci: Czyż zasłabłeś jak i my? Czy stałeś się podobny do nas?
11 Gbogbo rẹ̀ ni ó di ìrẹ̀sílẹ̀ lọ sí ibojì, pẹ̀lú ariwo àwọn dùùrù rẹ, àwọn ìdin ni wọ́n fọ́nkálẹ̀ lábẹ́ rẹ àwọn ekòló sì ti bò ọ́ mọ́lẹ̀. (Sheol h7585)
Strącono do piekła twój przepych i dźwięk twojej lutni. Twoim posłaniem jest robactwo, robactwo też jest twoim przykryciem. (Sheol h7585)
12 Báwo ni ìwọ ṣe ṣubú lulẹ̀ láti ọ̀run wá, ìwọ ìràwọ̀ òwúrọ̀, ọmọ òwúrọ̀ náà! A ti sọ ọ́ sílẹ̀ sínú ayé, ìwọ tí o ti tẹ orí àwọn orílẹ̀-èdè ba rí!
O jakże spadłeś z nieba, Lucyferze, synu jutrzenki! Powalony jesteś aż na ziemię, ty, który osłabiałeś narody!
13 Ìwọ sọ nínú ọkàn rẹ pé, “Èmi yóò gòkè lọ sí ọ̀run; èmi yóò gbé ìtẹ́ mi sókè ga ju àwọn ìràwọ̀ Ọlọ́run, Èmi yóò gúnwà ní orí òkè àpéjọ ní ṣóńṣó orí òkè mímọ́.
Ty bowiem mówiłeś w swoim sercu: Wstąpię do nieba, ponad gwiazdy Boga wywyższę swój tron. Zasiądę na górze zgromadzenia, na krańcach północy;
14 Èmi yóò gòkè lọ rékọjá àwọn àwọsánmọ̀; èmi yóò ṣe ara mi gẹ́gẹ́ bí Ọ̀gá-ògo.”
Wzniosę się nad szczyty obłoków, będę równy Najwyższemu.
15 Ṣùgbọ́n a ti rẹ̀ ọ́ sílẹ̀ wọ inú ibojì lọ lọ sí ìsàlẹ̀ ọ̀gbun. (Sheol h7585)
Lecz zostaniesz strącony aż do piekła, do krańców dołu. (Sheol h7585)
16 Àwọn tí ó rí ọ yóò tẹjúmọ́ ọ, wọ́n ronú nípa àtubọ̀tán rẹ: “Ǹjẹ́ èyí ni ẹni tí ó mi ayé tìtì tí ó sì jẹ́ kí àwọn ilẹ̀ ọba wárìrì.
Ci, którzy cię ujrzą, będą patrzeć na ciebie i zastanawiać się nad tobą, [mówiąc]: Czy to ten, który wprawił w drżenie ziemię i trząsł królestwami?
17 Ẹni tí ó sọ ayé di aginjù, tí ó sì pa ìlú ńlá ńlá rẹ̀ run tí kò dá àwọn òǹdè rẹ̀ sílẹ̀ láti padà sílé?”
Ten, który świat zamienił w pustynię i zniszczył jego miasta, a swoich więźniów nie wypuścił z ciemnicy?
18 Gbogbo àwọn ọba orílẹ̀-èdè ni a tẹ́ sílẹ̀ ọ̀kọ̀ọ̀kan nínú ibojì tirẹ̀.
Wszyscy królowie narodów, wszyscy oni spoczywają w chwale, każdy w swoim domu.
19 Ṣùgbọ́n a jù ọ́ síta kúrò nínú ibojì gẹ́gẹ́ bí ẹ̀ka igi tí a kọ̀sílẹ̀, àwọn tí a pa ni ó bò ọ́ mọ́lẹ̀, àwọn tí idà ti gún, àwọn tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ sínú òkúta inú ọ̀gbun. Gẹ́gẹ́ bí òkú ó di ìtẹ̀mọ́lẹ̀ ní abẹ́ àtẹ́lẹsẹ̀,
Ale ty zostałeś wyrzucony ze swego grobu jak obrzydła latorośl, [jak] szata zabitych, których przeszyto mieczem, którzy zstępują do kamiennego dołu, zdeptani jak padlina.
20 a kò ní sin ọ́ pẹ̀lú wọn, nítorí pé o ti ba ilẹ̀ rẹ jẹ́ o sì ti pa àwọn ènìyàn rẹ. Ìran àwọn ìkà ni a kì yóò dárúkọ wọn mọ́.
Nie będziesz uczestniczył wraz z nimi w pogrzebie, bo zniszczyłeś swoją ziemię i wymordowałeś swój lud. Potomstwo złoczyńców nie będzie wspominane na wieki.
21 Tọ́jú ibìkan tí a ó ti pa àwọn ọmọkùnrin rẹ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba ńlá wọn, wọn kò gbọdọ̀ dìde láti jogún ilẹ̀ kí wọ́n sì bo orí ilẹ̀ pẹ̀lú àwọn ìlú u wọn.
Przygotujcie rzeź dla jego synów z powodu nieprawości ich ojców, aby nie powstali ani nie odziedziczyli ziemi, ani nie pokryli powierzchni ziemi miastami.
22 “Èmi yóò dìde sókè sí wọn,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. “Èmi yóò ké orúkọ rẹ̀ kúrò ní Babeli àti àwọn tí ó sálà, àwọn ọmọ àti ìran rẹ̀,” ni Olúwa wí.
Powstanę bowiem przeciwko nim, mówi PAN zastępów, a zniszczę z Babilonu imię, resztkę, syna i wnuka, mówi PAN;
23 Èmi yóò yí i padà sí ibùgbé àwọn òwìwí àti sí irà; Èmi yóò fi ọwọ́ ìparun gbá a, ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
I uczynię go siedliskiem bąków i stawami wodnymi. I wymiotę go miotłą spustoszenia, mówi PAN zastępów.
24 Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti búra, “Gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣètò, bẹ́ẹ̀ ni yóò rí, àti bí mo ti pinnu, bẹ́ẹ̀ ni yóò sì dúró.
Przysiągł PAN zastępów, mówiąc: Zaprawdę, jak obmyśliłem, tak będzie, a jak postanowiłem, tak się stanie;
25 Èmi yóò run Asiria ní ilẹ̀ mi, ní àwọn orí òkè mi ni èmi yóò ti rún un mọ́lẹ̀. Àjàgà rẹ̀ ni a ó mú kúrò lọ́rùn àwọn ènìyàn mi, ẹrù u rẹ̀ ni ó mú kúrò ní èjìká wọn.”
Złamię Asyryjczyka w mojej ziemi i na moich górach zdepczę go. Wtedy spadnie z nich jego jarzmo i jego brzemię spadnie z ich ramion.
26 Èyí ni ètò tí a pinnu rẹ̀ fún gbogbo ayé, èyí ni ọwọ́ tí a nà jáde káàkiri gbogbo orílẹ̀-èdè.
To jest powzięty zamiar co do całej ziemi i to jest ręka wyciągnięta nad wszystkie narody.
27 Nítorí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti pète, ta ni yóò sì ká a lọ́wọ́ kò? Ọwọ́ọ rẹ ti nà jáde, ta ni ó sì le è fà á padà?
Skoro PAN zastępów postanowił, któż to udaremni? Jego ręka jest wyciągnięta, któż ją odwróci?
28 Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ yí wá ní ọdún tí ọba Ahasi kú.
W roku, w którym umarł król Achaz, stało się takie [oto] proroctwo:
29 Má ṣe yọ̀, gbogbo ẹ̀yin Filistia, pé ọ̀pá tí ó lù ọ́ ti dá; láti ibi gbòǹgbò ejò náà ni paramọ́lẹ̀ yóò ti hù jáde, èso rẹ̀ yóò sì jẹ́ oró ejò tí í jóni.
Nie raduj się, cała ziemio Filisteo, z tego, że został złamany kij tego, który cię bił, bo z korzenia węża wyjdzie żmija, jego płodem [będzie] ognisty smok latający.
30 Ẹni tí ó kúṣẹ̀ẹ́ jù yóò ní pápá oko, àwọn aláìní yóò sì dùbúlẹ̀ láìléwu. Ṣùgbọ́n gbòǹgbò o rẹ̀ ni èmi ó fi ìyàn parun, yóò sì ké àwọn ẹni rẹ tí ó sálà kúrò.
Pierworodni nędzarzy będą się paść, a ubodzy odpoczną bezpiecznie. Lecz twój korzeń wytępię głodem, a zabiję twoją resztkę.
31 Hu, ìwọ ẹnu-ọ̀nà! Kígbe, ìwọ ìlú! Yọ́ kúrò, gbogbo ẹ̀yin Filistia! Èéfín kurukuru kan ti àríwá wá, kò sì ṣí amóríbọ́ kan nínú ẹgbẹ́ wọn.
Zawódź, bramo! Krzycz, miasto! Ty, cała Filisteo, już się rozpłynęłaś. Od północy bowiem nadciąga dym i nikt nie będzie stronił od jego szeregów.
32 Kí ni ìdáhùn tí a ó fún agbẹnusọ orílẹ̀-èdè náà? “Olúwa ti fi ìdí Sioni kalẹ̀, àti nínú rẹ̀ ni àwọn ènìyàn rẹ̀ tí a ti pọ́n ọn lójú yóò ti rí ààbò o wọn.”
I cóż odpowiedzieć posłom narodu? [To], że PAN ugruntował Syjon i w nim będą się chronić ubodzy jego ludu.

< Isaiah 14 >