< Isaiah 14 >

1 Olúwa yóò fi àánú hàn fún Jakọbu, yóò tún Israẹli yàn lẹ́ẹ̀kan sí i yóò sì fi ìdí wọn kalẹ̀ ní ilẹ̀ àwọn tìkára wọn. Àwọn àjèjì yóò darapọ̀ mọ́ wọn, wọn yóò sì fọwọ́sowọ́pọ̀ pẹ̀lú ilé e Jakọbu.
No rĩrĩ, Jehova nĩakaiguĩra Jakubu tha; nĩegwĩthuurĩra Isiraeli o rĩngĩ, na atũme maikare bũrũri wao ene. Ageni nĩmakegwatania nao, na manyiitane na nyũmba ya Jakubu.
2 Àwọn orílẹ̀-èdè yóò gbà wọ́n wọn yóò sì mú wọn wá sí ààyè e wọn. Ilé Israẹli yóò gba àwọn orílẹ̀-èdè gẹ́gẹ́ bí àwọn ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin ní ilẹ̀ Olúwa. Wọn yóò kó àwọn akónilẹ́rú wọn ní ìgbèkùn wọn yóò sì jẹ ọba lórí àwọn amúnisìn wọn.
Ndũrĩrĩ nĩikamooya, imacookie kũndũ kwao. Nayo nyũmba ya Isiraeli nĩĩkegwatĩra ndũrĩrĩ, ituĩke ndungata ciao cia arũme na cia airĩtu kũu bũrũri wa Jehova. Nĩmagataha andũ arĩa maamatahĩte tene, na macooke gwatha andũ arĩa maamahinyagĩrĩria.
3 Ní ọjọ́ tí Olúwa yóò fi ìtura fún un yín kúrò nínú ìpọ́njú àti ìyà àti ìdè ìkà,
Mũthenya ũrĩa Jehova akaamũhurũkia kuuma mathĩĩna-inĩ na mĩnyamaro-inĩ, na ũkombo-inĩ wa kũhinyĩrĩrio-rĩ,
4 ẹ ó sì fi ọ̀rọ̀ àbùkù yìí kan ọba Babeli pé, báwo ni amúnisìn ṣe wá sí òpin! Báwo ni ìbínú rẹ̀ ṣe parí!
nĩmũgookĩrĩra mũthamaki wa Babuloni na kĩnyũrũri, mũmwĩre atĩrĩ: Kaĩ mũhinyanĩrĩria nĩakinyĩte mũthia-ĩ! Kaĩ marakara make mahiũ nĩmathirĩte-ĩ!
5 Olúwa ti dá ọ̀pá ìkà náà, ọ̀pá àwọn aláṣẹ,
Jehova nĩoinangĩte rũthanju rwa andũ arĩa aaganu, o na akoinanga thimbũ ya ũnene ya arĩa maathanaga,
6 èyí tí ó ti lu àwọn ènìyàn bolẹ̀ pẹ̀lú ti kò dáwọ́ dúró, nínú ìrunú ni ó ṣẹ́gun àwọn orílẹ̀-èdè pẹ̀lú ìgbónára tí kò lópin.
ĩrĩa maahũũraga andũ nayo mategũtigithĩria, marakarĩte, magaatha ndũrĩrĩ marĩ na marakara, na magaciũgitaga matarĩ na tha.
7 Gbogbo ilẹ̀ ni ó wà ní ìsinmi àti àlàáfíà, wọ́n bú sí orin.
Mabũrũri mothe rĩu nĩmahurũkĩte na marĩ na thayũ; nĩmambĩrĩirie kũina.
8 Pẹ̀lúpẹ̀lú àwọn igi junifa àti àwọn igi kedari ti Lebanoni ń yọ̀ lórí rẹ wí pé, “Níwọ́n bí a ti rẹ̀ ọ́ sílẹ̀ báyìí, kò sí agégi tí yóò wá láti gé wa lulẹ̀.”
O nayo mĩtĩ ya mĩkarakaba na mĩtarakwa ya Lebanoni ĩragũkenerera, ĩkoiga atĩrĩ: “Kuuma hĩndĩ ĩrĩa wagũithirio thĩ, gũtirĩ mũtemi mĩtĩ ũrĩ woka gũtũtema.”
9 Ibojì tí ó wà ní ìsàlẹ̀ ni a ru sókè láti pàdé rẹ ní ìpadàbọ̀ rẹ̀ ó ru ẹ̀mí àwọn tí ó ti lọ sókè láti wá kí ọ gbogbo àwọn tí ó jẹ́ olórí ní ayé ó mú kí wọn dìde lórí ìtẹ́ wọn gbogbo àwọn tí ó jẹ ọba lórí àwọn orílẹ̀-èdè. (Sheol h7585)
Mbĩrĩra kũu mũhuro wa thĩ nĩyarahũkĩte, ĩgũtũnge ũgĩkinya kuo; nĩyarahũrĩte maroho ma arĩa maanakua makũgeithie: arĩa othe maarĩ atongoria gũkũ thĩ; ĩtũmaga mookĩrĩrie itĩ ciao cia ũnene, o arĩa othe maarĩ athamaki a ndũrĩrĩ. (Sheol h7585)
10 Gbogbo wọn yóò dáhùn, wọn yóò wí fún ọ wí pé, “Ìwọ pẹ̀lú ti di aláìlera, gẹ́gẹ́ bí àwa pẹ̀lú ìwọ náà ti dàbí wa.”
Nao othe magaacookia, makwĩre atĩrĩ, “O nawe nĩwagĩte hinya o ta ithuĩ; ũhaanĩte o ta ithuĩ.”
11 Gbogbo rẹ̀ ni ó di ìrẹ̀sílẹ̀ lọ sí ibojì, pẹ̀lú ariwo àwọn dùùrù rẹ, àwọn ìdin ni wọ́n fọ́nkálẹ̀ lábẹ́ rẹ àwọn ekòló sì ti bò ọ́ mọ́lẹ̀. (Sheol h7585)
Riiri wothe wa ũnene waku ũikũrũkĩtio o nginya mbĩrĩra-inĩ, hamwe na mĩgambo ya inanda ciaku cia mũgeeto; igunyũ nĩcio ũkomeire, na igunyũ nocio ikũhumbĩire. (Sheol h7585)
12 Báwo ni ìwọ ṣe ṣubú lulẹ̀ láti ọ̀run wá, ìwọ ìràwọ̀ òwúrọ̀, ọmọ òwúrọ̀ náà! A ti sọ ọ́ sílẹ̀ sínú ayé, ìwọ tí o ti tẹ orí àwọn orílẹ̀-èdè ba rí!
Hĩ! Kaĩ wee njata ya kĩwariĩ nĩũgwĩte ũkoima igũrũ-ĩ, o wee mũrũ wa rũciinĩ kĩroko gwakĩa! Ũharũrũkĩtio ũgaikio gũkũ thĩ, o wee ũrĩa hĩndĩ ĩmwe wahinyagĩrĩria ndũrĩrĩ!
13 Ìwọ sọ nínú ọkàn rẹ pé, “Èmi yóò gòkè lọ sí ọ̀run; èmi yóò gbé ìtẹ́ mi sókè ga ju àwọn ìràwọ̀ Ọlọ́run, Èmi yóò gúnwà ní orí òkè àpéjọ ní ṣóńṣó orí òkè mímọ́.
Wee weĩraga atĩrĩ na ngoro yaku, “Ngũhaica nginye igũrũ; na gĩtĩ gĩakwa kĩa ũnene ndĩkĩambararie gĩkĩre njata cia Mũrungu; na njikarĩre kĩrĩma-inĩ gĩa gũtũnganwo, o gacũmbĩrĩ ga kĩrĩma kĩrĩa kĩamũre.
14 Èmi yóò gòkè lọ rékọjá àwọn àwọsánmọ̀; èmi yóò ṣe ara mi gẹ́gẹ́ bí Ọ̀gá-ògo.”
Nĩngahaica nginya kũndũ kũraihu igũrũ rĩa matu, ndĩĩhaananie na Ũrĩa-ũrĩ-Igũrũ-Mũno.”
15 Ṣùgbọ́n a ti rẹ̀ ọ́ sílẹ̀ wọ inú ibojì lọ lọ sí ìsàlẹ̀ ọ̀gbun. (Sheol h7585)
No rĩrĩ, wee ũharũrũkĩtio thĩ nginya mbĩrĩra-inĩ, ũgakinya irima kũrĩa kũriku. (Sheol h7585)
16 Àwọn tí ó rí ọ yóò tẹjúmọ́ ọ, wọ́n ronú nípa àtubọ̀tán rẹ: “Ǹjẹ́ èyí ni ẹni tí ó mi ayé tìtì tí ó sì jẹ́ kí àwọn ilẹ̀ ọba wárìrì.
Arĩa marĩkuonaga, marĩgũkũũragĩra maitho, magecũũrania ũhoro waku, makoorania atĩrĩ, “Ũyũ nĩwe mũndũ ũrĩa wenyenyagia thĩ na agatũma mothamaki mainaine,
17 Ẹni tí ó sọ ayé di aginjù, tí ó sì pa ìlú ńlá ńlá rẹ̀ run tí kò dá àwọn òǹdè rẹ̀ sílẹ̀ láti padà sílé?”
mũndũ ũrĩa watũmire thĩ ĩtuĩke ta werũ, na akangʼaũrania matũũra mayo marĩa manene? Nĩwe ũrĩa ũtetĩkagĩria andũ arĩa oohe mainũke kwao mĩciĩ?”
18 Gbogbo àwọn ọba orílẹ̀-èdè ni a tẹ́ sílẹ̀ ọ̀kọ̀ọ̀kan nínú ibojì tirẹ̀.
Athamaki othe a ndũrĩrĩ makuĩte magakomio, o mũndũ mbĩrĩra-inĩ yake.
19 Ṣùgbọ́n a jù ọ́ síta kúrò nínú ibojì gẹ́gẹ́ bí ẹ̀ka igi tí a kọ̀sílẹ̀, àwọn tí a pa ni ó bò ọ́ mọ́lẹ̀, àwọn tí idà ti gún, àwọn tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ sínú òkúta inú ọ̀gbun. Gẹ́gẹ́ bí òkú ó di ìtẹ̀mọ́lẹ̀ ní abẹ́ àtẹ́lẹsẹ̀,
No wee-rĩ, nĩgũteo ũtetwo kuuma mbĩrĩra-inĩ yaku, o ta rũhonge rũrĩ magigi; ũkahumbĩrwo nĩ ciimba cia arĩa moragĩtwo, arĩa matheecangĩtwo na hiũ cia njora, o acio maikĩtio irima rĩrĩ mahiga. Ũikarĩte ta kĩimba kĩrangĩrĩrie thĩ na magũrũ,
20 a kò ní sin ọ́ pẹ̀lú wọn, nítorí pé o ti ba ilẹ̀ rẹ jẹ́ o sì ti pa àwọn ènìyàn rẹ. Ìran àwọn ìkà ni a kì yóò dárúkọ wọn mọ́.
no wee-rĩ, ndũgaathikwo tao, tondũ nĩwaanangire bũrũri waku, na ũkĩũraga andũ aku. Rũciaro rwa andũ arĩa aaganu rũtikaagwetwo rĩngĩ.
21 Tọ́jú ibìkan tí a ó ti pa àwọn ọmọkùnrin rẹ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba ńlá wọn, wọn kò gbọdọ̀ dìde láti jogún ilẹ̀ kí wọ́n sì bo orí ilẹ̀ pẹ̀lú àwọn ìlú u wọn.
Haarĩriai handũ ha kũũragĩra ciana ciake, nĩ ũndũ wa mehia ma maithe mao ma tene; nĩguo itikanarahũke ciĩgaĩre bũrũri, na ciĩyakĩre matũũra maiyũre thĩ.
22 “Èmi yóò dìde sókè sí wọn,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. “Èmi yóò ké orúkọ rẹ̀ kúrò ní Babeli àti àwọn tí ó sálà, àwọn ọmọ àti ìran rẹ̀,” ni Olúwa wí.
Jehova Mwene-Hinya-Wothe ekuuga atĩrĩ, “Niĩ nĩngarahũka ndĩciũkĩrĩre, nĩngeheria rĩĩtwa rĩacio kũu Babuloni, o na rĩa matigari ma cio, o na njeherie ciana ciao na rũciaro rwao,” nĩguo Jehova ekuuga.
23 Èmi yóò yí i padà sí ibùgbé àwọn òwìwí àti sí irà; Èmi yóò fi ọwọ́ ìparun gbá a, ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
“Nĩngatua kũndũ kũu gĩikaro kĩa ndundu, na ndĩgũtue bũrũri wa maria ma maaĩ; ngaakũhaata na kĩhato kĩa mwanangĩko,”
24 Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti búra, “Gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣètò, bẹ́ẹ̀ ni yóò rí, àti bí mo ti pinnu, bẹ́ẹ̀ ni yóò sì dúró.
Jehova Mwene-Hinya-Wothe nĩehĩtĩte, akoiga atĩrĩ, “Ti-itherũ, o ũrĩa thugundĩte, ũguo noguo gũgaatuĩka, na ũrĩa nduĩte, ũguo noguo gũgaikara.
25 Èmi yóò run Asiria ní ilẹ̀ mi, ní àwọn orí òkè mi ni èmi yóò ti rún un mọ́lẹ̀. Àjàgà rẹ̀ ni a ó mú kúrò lọ́rùn àwọn ènìyàn mi, ẹrù u rẹ̀ ni ó mú kúrò ní èjìká wọn.”
Nĩngahehenja Mũashuri ũcio ũrĩ bũrũri-inĩ wakwa; ngaamũrangĩrĩria thĩ irĩma-inĩ ciakwa. Nĩngehereria andũ akwa icooki rĩake, na mũrigo wake ũmoime ciande-inĩ ciao.”
26 Èyí ni ètò tí a pinnu rẹ̀ fún gbogbo ayé, èyí ni ọwọ́ tí a nà jáde káàkiri gbogbo orílẹ̀-èdè.
Ũũ nĩguo thugundĩte gwĩka thĩ yothe; nakuo guoko kũrĩa gũtambũrũkĩirio ndũrĩrĩ ciothe nĩkuo gũkũ.
27 Nítorí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti pète, ta ni yóò sì ká a lọ́wọ́ kò? Ọwọ́ọ rẹ ti nà jáde, ta ni ó sì le è fà á padà?
Nĩgũkorwo Jehova Mwene-Hinya-Wothe nĩguo atuĩte gwĩka, nũũ ũngĩhota kũmũgirĩrĩria? Guoko gwake nĩgũtambũrũkĩtio, nũũ ũngĩhota gũgũthuna?
28 Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ yí wá ní ọdún tí ọba Ahasi kú.
Atĩrĩrĩ, mwaka ũrĩa Mũthamaki Ahazu aakuire-rĩ, nĩguo ndũmĩrĩri ĩno yaguũranĩirio:
29 Má ṣe yọ̀, gbogbo ẹ̀yin Filistia, pé ọ̀pá tí ó lù ọ́ ti dá; láti ibi gbòǹgbò ejò náà ni paramọ́lẹ̀ yóò ti hù jáde, èso rẹ̀ yóò sì jẹ́ oró ejò tí í jóni.
Inyuĩ Afilisti inyuothe tigai gũkena, nĩ atĩ rũthanju rũrĩa rwamũhũũraga nĩrunĩkĩte; nĩgũkorwo kuuma mũri-inĩ wa nyoka ĩyo nĩgũkoima nduĩra, namo maciaro mayo magaatuĩka mũthemba wa nyoka ĩrĩ thumu ĩrĩa ĩticũkaga.
30 Ẹni tí ó kúṣẹ̀ẹ́ jù yóò ní pápá oko, àwọn aláìní yóò sì dùbúlẹ̀ láìléwu. Ṣùgbọ́n gbòǹgbò o rẹ̀ ni èmi ó fi ìyàn parun, yóò sì ké àwọn ẹni rẹ tí ó sálà kúrò.
Nao andũ arĩa athĩĩni biũ nĩmakona gĩa kũrĩa, na mũbatari akomage atarĩ na ũgwati. No rũciaro rwaku nĩngarũũraga na ngʼaragu; nayo ĩkooraga matigari maku.
31 Hu, ìwọ ẹnu-ọ̀nà! Kígbe, ìwọ ìlú! Yọ́ kúrò, gbogbo ẹ̀yin Filistia! Èéfín kurukuru kan ti àríwá wá, kò sì ṣí amóríbọ́ kan nínú ẹgbẹ́ wọn.
Wee kĩhingo-rĩ, girĩka! Na wee itũũra inene-rĩ, ugĩrĩria! Na inyuĩ Afilisti inyuothe mũniinwo nĩ guoya, mũthire biũ! Itu rĩa ndogo rĩrooka riumĩte mwena wa gathigathini, na gũtigakorwo na mũndũ ũgaatigwo na thuutha mbũtũ-inĩ ciake nĩ ũndũ wa kwaga hinya.
32 Kí ni ìdáhùn tí a ó fún agbẹnusọ orílẹ̀-èdè náà? “Olúwa ti fi ìdí Sioni kalẹ̀, àti nínú rẹ̀ ni àwọn ènìyàn rẹ̀ tí a ti pọ́n ọn lójú yóò ti rí ààbò o wọn.”
Nĩ icookio rĩrĩkũ rĩkaaheanwo kũrĩ andũ arĩa matũmĩtwo a rũrĩrĩ rũu? Magaacookerio atĩrĩ, “Jehova nĩahaandĩte Zayuni, na thĩinĩ wakuo andũ ake arĩa anyamaarĩku nĩmakona rĩũrĩro.”

< Isaiah 14 >