< Isaiah 14 >
1 Olúwa yóò fi àánú hàn fún Jakọbu, yóò tún Israẹli yàn lẹ́ẹ̀kan sí i yóò sì fi ìdí wọn kalẹ̀ ní ilẹ̀ àwọn tìkára wọn. Àwọn àjèjì yóò darapọ̀ mọ́ wọn, wọn yóò sì fọwọ́sowọ́pọ̀ pẹ̀lú ilé e Jakọbu.
Certes, l’Eternel aura pitié de Jacob, et il fera encore d’Israël son élu; il les rétablira sur leur sol. L’Étranger, alors, se ralliera à eux et s’annexera à la maison de Jacob.
2 Àwọn orílẹ̀-èdè yóò gbà wọ́n wọn yóò sì mú wọn wá sí ààyè e wọn. Ilé Israẹli yóò gba àwọn orílẹ̀-èdè gẹ́gẹ́ bí àwọn ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin ní ilẹ̀ Olúwa. Wọn yóò kó àwọn akónilẹ́rú wọn ní ìgbèkùn wọn yóò sì jẹ ọba lórí àwọn amúnisìn wọn.
Les peuples viendront les prendre pour les ramener en leur pays, et la maison d’Israël les possédera comme esclaves et comme servantes sur la terre du Seigneur. Ainsi ils retiendront captifs ceux qui les avaient faits captifs et auront la haute main sur leurs oppresseurs.
3 Ní ọjọ́ tí Olúwa yóò fi ìtura fún un yín kúrò nínú ìpọ́njú àti ìyà àti ìdè ìkà,
Le jour où l’Eternel aura assuré ton repos, après tes épreuves, tes tourments et la dure servitude qui te fut imposée,
4 ẹ ó sì fi ọ̀rọ̀ àbùkù yìí kan ọba Babeli pé, báwo ni amúnisìn ṣe wá sí òpin! Báwo ni ìbínú rẹ̀ ṣe parí!
tu entonneras le chant que voici sur le roi de Babylone: "Comment a disparu l’oppresseur, cessé la tyrannie!
5 Olúwa ti dá ọ̀pá ìkà náà, ọ̀pá àwọn aláṣẹ,
L’Eternel a brisé le bâton des méchants, le sceptre des despotes,
6 èyí tí ó ti lu àwọn ènìyàn bolẹ̀ pẹ̀lú ti kò dáwọ́ dúró, nínú ìrunú ni ó ṣẹ́gun àwọn orílẹ̀-èdè pẹ̀lú ìgbónára tí kò lópin.
qui frappait avec fureur les peuples de coups sans trêve, accablait avec rage les nations de persécutions sans merci.
7 Gbogbo ilẹ̀ ni ó wà ní ìsinmi àti àlàáfíà, wọ́n bú sí orin.
La terre entière a maintenant retrouvé le calme et la paix: on éclate en cris d’allégresse.
8 Pẹ̀lúpẹ̀lú àwọn igi junifa àti àwọn igi kedari ti Lebanoni ń yọ̀ lórí rẹ wí pé, “Níwọ́n bí a ti rẹ̀ ọ́ sílẹ̀ báyìí, kò sí agégi tí yóò wá láti gé wa lulẹ̀.”
Même les cyprès et les cèdres du Liban se réjouissent de ta chute: "Depuis que tu es à terre, le bûcheron ne monte plus contre nous."
9 Ibojì tí ó wà ní ìsàlẹ̀ ni a ru sókè láti pàdé rẹ ní ìpadàbọ̀ rẹ̀ ó ru ẹ̀mí àwọn tí ó ti lọ sókè láti wá kí ọ gbogbo àwọn tí ó jẹ́ olórí ní ayé ó mú kí wọn dìde lórí ìtẹ́ wọn gbogbo àwọn tí ó jẹ ọba lórí àwọn orílẹ̀-èdè. (Sheol )
Le Cheol, dans ses profondeurs, s’est ému à ton approche, il a réveillé pour toi les ombres, ceux qui furent jadis les puissants de la terre, il a fait lever de leurs trônes les rois des nations. (Sheol )
10 Gbogbo wọn yóò dáhùn, wọn yóò wí fún ọ wí pé, “Ìwọ pẹ̀lú ti di aláìlera, gẹ́gẹ́ bí àwa pẹ̀lú ìwọ náà ti dàbí wa.”
Tous ensemble prennent la parole et te disent: "Te voilà donc aussi frappé comme nous! Te voilà donc pareil à nous!"
11 Gbogbo rẹ̀ ni ó di ìrẹ̀sílẹ̀ lọ sí ibojì, pẹ̀lú ariwo àwọn dùùrù rẹ, àwọn ìdin ni wọ́n fọ́nkálẹ̀ lábẹ́ rẹ àwọn ekòló sì ti bò ọ́ mọ́lẹ̀. (Sheol )
Ton faste est descendu dans le Cheol, avec tes harpes retentissantes; sous toi la vermine forme ta couche et les vers te servent de couverture. (Sheol )
12 Báwo ni ìwọ ṣe ṣubú lulẹ̀ láti ọ̀run wá, ìwọ ìràwọ̀ òwúrọ̀, ọmọ òwúrọ̀ náà! A ti sọ ọ́ sílẹ̀ sínú ayé, ìwọ tí o ti tẹ orí àwọn orílẹ̀-èdè ba rí!
Comme tu es tombé du ciel, astre brillant, fils de l’aurore! Comme tu as été renversé jusqu’à terre, dompteur des nations!
13 Ìwọ sọ nínú ọkàn rẹ pé, “Èmi yóò gòkè lọ sí ọ̀run; èmi yóò gbé ìtẹ́ mi sókè ga ju àwọn ìràwọ̀ Ọlọ́run, Èmi yóò gúnwà ní orí òkè àpéjọ ní ṣóńṣó orí òkè mímọ́.
Tu disais en ton cœur: "Je monterai au ciel; au-dessus des étoiles de Dieu, j’érigerai mon trône; je m’assiérai sur la montagne du rendez-vous (des dieux), dans les profondeurs du Nord.
14 Èmi yóò gòkè lọ rékọjá àwọn àwọsánmọ̀; èmi yóò ṣe ara mi gẹ́gẹ́ bí Ọ̀gá-ògo.”
Je monterai sur les hauteurs des nuées, je serai l’égal du Très-Haut."
15 Ṣùgbọ́n a ti rẹ̀ ọ́ sílẹ̀ wọ inú ibojì lọ lọ sí ìsàlẹ̀ ọ̀gbun. (Sheol )
Mais non, c’est dans le Cheol que tu es précipité, dans les profondeurs du gouffre. (Sheol )
16 Àwọn tí ó rí ọ yóò tẹjúmọ́ ọ, wọ́n ronú nípa àtubọ̀tán rẹ: “Ǹjẹ́ èyí ni ẹni tí ó mi ayé tìtì tí ó sì jẹ́ kí àwọn ilẹ̀ ọba wárìrì.
Ceux qui te voient te fixent de leur regard et, pensifs, se disent: "Est-ce là cet homme qui faisait trembler la terre, chanceler les empires,
17 Ẹni tí ó sọ ayé di aginjù, tí ó sì pa ìlú ńlá ńlá rẹ̀ run tí kò dá àwọn òǹdè rẹ̀ sílẹ̀ láti padà sílé?”
qui changeait le monde en désert, renversait les villes et jamais n’ouvrait à ses captifs la porte des cachots?"
18 Gbogbo àwọn ọba orílẹ̀-èdè ni a tẹ́ sílẹ̀ ọ̀kọ̀ọ̀kan nínú ibojì tirẹ̀.
Tous les rois des nations sont couchés avec honneur, chacun dans son mausolée;
19 Ṣùgbọ́n a jù ọ́ síta kúrò nínú ibojì gẹ́gẹ́ bí ẹ̀ka igi tí a kọ̀sílẹ̀, àwọn tí a pa ni ó bò ọ́ mọ́lẹ̀, àwọn tí idà ti gún, àwọn tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ sínú òkúta inú ọ̀gbun. Gẹ́gẹ́ bí òkú ó di ìtẹ̀mọ́lẹ̀ ní abẹ́ àtẹ́lẹsẹ̀,
mais toi, tu as été expulsé de ta tombe tel qu’un rejeton maudit; sous un linceul de morts, percés par le glaive et descendus dans les pierres du sépulcre, tu es pareil, toi, à une charogne piétinée.
20 a kò ní sin ọ́ pẹ̀lú wọn, nítorí pé o ti ba ilẹ̀ rẹ jẹ́ o sì ti pa àwọn ènìyàn rẹ. Ìran àwọn ìkà ni a kì yóò dárúkọ wọn mọ́.
Tu ne partageras pas avec eux les honneurs de la sépulture, car tu as perdu ton pays, assassiné ton peuple. La race des méchants ne doit pas avoir de nom dans l’éternité.
21 Tọ́jú ibìkan tí a ó ti pa àwọn ọmọkùnrin rẹ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba ńlá wọn, wọn kò gbọdọ̀ dìde láti jogún ilẹ̀ kí wọ́n sì bo orí ilẹ̀ pẹ̀lú àwọn ìlú u wọn.
Préparez le champ de carnage pour ses fils, à cause des iniquités de leurs pères, de peur qu’ils ne se lèvent pour reconquérir le monde, et que la terre ne soit de nouveau remplie de violences,
22 “Èmi yóò dìde sókè sí wọn,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. “Èmi yóò ké orúkọ rẹ̀ kúrò ní Babeli àti àwọn tí ó sálà, àwọn ọmọ àti ìran rẹ̀,” ni Olúwa wí.
"Oui, je me lèverai contre eux, dit l’Eternel-Cebaot et, de Babylone je détruirai le nom et la trace, tout descendant, toute postérité, dit le Seigneur;
23 Èmi yóò yí i padà sí ibùgbé àwọn òwìwí àti sí irà; Èmi yóò fi ọwọ́ ìparun gbá a, ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
j’en ferai le domaine du hérisson, le réceptacle des eaux, je le balaierai du balai de la destruction," dit l’Eternel-Cebaot.
24 Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti búra, “Gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣètò, bẹ́ẹ̀ ni yóò rí, àti bí mo ti pinnu, bẹ́ẹ̀ ni yóò sì dúró.
L’Eternel-Cebaot a prononcé ce serment: "Certes, ce que j’ai résolu arrivera, ce que j’ai décrété s’accomplira.
25 Èmi yóò run Asiria ní ilẹ̀ mi, ní àwọn orí òkè mi ni èmi yóò ti rún un mọ́lẹ̀. Àjàgà rẹ̀ ni a ó mú kúrò lọ́rùn àwọn ènìyàn mi, ẹrù u rẹ̀ ni ó mú kúrò ní èjìká wọn.”
Je briserai Achour en ma terre, je le broierai sur mes montagnes; son joug disparaîtra de dessus les hommes, et son fardeau cessera de peser sur leurs épaules.
26 Èyí ni ètò tí a pinnu rẹ̀ fún gbogbo ayé, èyí ni ọwọ́ tí a nà jáde káàkiri gbogbo orílẹ̀-èdè.
Voilà le décret préparé contre toute la terre, voilà la main étendue sur toutes les nations.
27 Nítorí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti pète, ta ni yóò sì ká a lọ́wọ́ kò? Ọwọ́ọ rẹ ti nà jáde, ta ni ó sì le è fà á padà?
Oui, quand l’Eternel-Cebaot a décrété, qui peut faire obstacle? Sa main étendue, qui peut la ramener?"
28 Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ yí wá ní ọdún tí ọba Ahasi kú.
L’Année de la mort du roi Achaz fut prononcé cet oracle:
29 Má ṣe yọ̀, gbogbo ẹ̀yin Filistia, pé ọ̀pá tí ó lù ọ́ ti dá; láti ibi gbòǹgbò ejò náà ni paramọ́lẹ̀ yóò ti hù jáde, èso rẹ̀ yóò sì jẹ́ oró ejò tí í jóni.
"Terre des Philistins, ne te réjouis pas sans mesure de ce qu’elle soit brisée, la verge qui te frappait; car de la racine d’un serpent sortira un basilic, et son fruit sera un dragon volant.
30 Ẹni tí ó kúṣẹ̀ẹ́ jù yóò ní pápá oko, àwọn aláìní yóò sì dùbúlẹ̀ láìléwu. Ṣùgbọ́n gbòǹgbò o rẹ̀ ni èmi ó fi ìyàn parun, yóò sì ké àwọn ẹni rẹ tí ó sálà kúrò.
Tandis que les élus des malheureux se nourriront et les humbles gîteront en sécurité, je ferai mourir de faim ta race; et ceux des tiens qui survivront, on les égorgera.
31 Hu, ìwọ ẹnu-ọ̀nà! Kígbe, ìwọ ìlú! Yọ́ kúrò, gbogbo ẹ̀yin Filistia! Èéfín kurukuru kan ti àríwá wá, kò sì ṣí amóríbọ́ kan nínú ẹgbẹ́ wọn.
Lamente-toi, porte, crie ta plainte, cité! Tu es toute défaillante, terre des Philistins: c’est qu’une fumée s’avance du Nord. Personne ne reste en arrière dans ses légions assemblées.
32 Kí ni ìdáhùn tí a ó fún agbẹnusọ orílẹ̀-èdè náà? “Olúwa ti fi ìdí Sioni kalẹ̀, àti nínú rẹ̀ ni àwọn ènìyàn rẹ̀ tí a ti pọ́n ọn lójú yóò ti rí ààbò o wọn.”
Et quelle réponse sera faite aux députés des nations? C’Est que l’Eternel a fondé Sion et que les humbles de son peuple y trouvent un abri!"