< Isaiah 13 >
1 Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ tí ó kan Babeli èyí tí Isaiah ọmọ Amosi rí.
Povara Babilonului, pe care Isaia, fiul lui Amoţ, a văzut-o.
2 Gbé àsíá sókè ní orí òkè gbẹrẹfu, kígbe sí wọn, pè wọ́n láti wọlé sí ẹnu-ọ̀nà àwọn ọlọ́lá.
Ridicaţi un steag pe muntele înalt, înălţaţi vocea către ei, scuturaţi mâna, ca ei să intre pe porţile nobililor.
3 Mo ti pàṣẹ fún àwọn ẹni mímọ́ mi, mo ti pe àwọn jagunjagun mi láti gbé ìbínú mi jáde àwọn tí ń yọ̀ nínú ìṣẹ́gun mi.
Am poruncit celor sfinţiţi ai mei, am chemat de asemenea pe cei tari ai mei pentru furia mea, [adică] pe cei ce se bucură în înălţimea mea.
4 Gbọ́ ohùn kan ní àwọn orí òkè, gẹ́gẹ́ bí i ti ogunlọ́gọ̀ ènìyàn. Gbọ́ ìdàrúdàpọ̀ láàrín àwọn ìjọba, gẹ́gẹ́ bí i ti ìkórajọ àwọn orílẹ̀-èdè! Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti kó ogun rẹ̀ jọ àwọn jagunjagun fún ogun.
Zgomotul unei mulţimi în munţi, ca al unui popor mare; un zgomot tumultuos al împărăţiilor naţiunilor adunate împreună: DOMNUL oştirilor adună armata pentru bătălie.
5 Wọ́n wá láti ọ̀nà jíjìn réré, láti ìpẹ̀kun ọ̀run wá Olúwa pẹ̀lú àwọn ohun ìjà ìbínú rẹ̀, láti pa gbogbo orílẹ̀-èdè náà run.
Ei vin dintr-o ţară îndepărtată, de la marginea cerului, DOMNUL şi armele indignării lui, pentru a nimici toată ţara.
6 Ẹ hu, nítorí ọjọ́ Olúwa súnmọ́ tòsí, yóò sì wá gẹ́gẹ́ bí ìparun láti ọ̀dọ̀ Alágbára jùlọ.
Urlaţi, căci ziua DOMNULUI este aproape; va veni ca o nimicire de la cel Atotputernic.
7 Nítorí èyí, gbogbo ọwọ́ ni yóò rọ, ọkàn ẹnìkọ̀ọ̀kan yóò rẹ̀wẹ̀sì.
De aceea toate mâinile vor slăbi şi inima fiecărui om se va topi;
8 Ẹ̀rù yóò gbá wọn mú, ìrora àti ìpayínkeke yóò dìwọ́n mú, wọn yóò kérora gẹ́gẹ́ bí obìnrin tí ó ń rọbí. Ẹnìkínní yóò wo ẹnìkejì rẹ̀ pẹ̀lú ìpayà ojú wọn á sì gbinájẹ.
Şi vor fi înspăimântaţi; junghiuri şi întristări îi vor apuca; vor fi în durere ca o femeie în travaliu; se vor uimi unul pe altul; feţele lor vor fi ca flăcările.
9 Kíyèsi i, ọjọ́ Olúwa ń bọ̀ ọjọ́ búburú, pẹ̀lú ìbínú àti ìrunú gbígbóná— láti sọ ilẹ̀ náà dahoro, àti láti pa àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ inú rẹ̀ run.
Iată, ziua DOMNULUI vine, crudă, deopotrivă cu furie şi mânie înverşunată, pentru a lăsa ţara pustiită, iar el îi va nimici pe păcătoşii din ea.
10 Àwọn ìràwọ̀ ojú ọ̀run àti ìkójọpọ̀ wọn kò sì ní fi ìmọ́lẹ̀ wọn hàn. Àṣẹ̀ṣẹ̀yọ oòrùn yóò di òkùnkùn àti òṣùpá kò ní fi ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ hàn.
Fiindcă stelele cerului şi constelaţiile acestuia nu îşi vor da lumina, soarele va fi întunecat în mersul lui şi luna nu va face ca lumina ei să strălucească.
11 Èmi yóò jẹ ayé ní ìyà nítorí ibi rẹ̀, àwọn ìkà nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn. Èmi yóò fi òpin sí gààrù àwọn agbéraga èmi ó sì rẹ ìgbéraga àwọn aláìláàánú sílẹ̀.
Şi voi pedepsi lumea pentru răul oamenilor şi pe cei stricaţi pentru nelegiuirea lor; şi voi face ca aroganţa celor mândri să înceteze şi voi doborî trufia tiranilor.
12 Èmi yóò jẹ́ kí ọkùnrin kí ó wọn ju ojúlówó wúrà lọ, yóò sì ṣọ̀wọ́n ju wúrà Ofiri lọ.
Voi face pe om mai preţios decât aurul fin, pe om mai preţios decât lingoul de aur din Ofir.
13 Nítorí náà èmi yóò jẹ́ kí àwọn ọ̀run kí ó wárìrì; ayé yóò sì mì tìtì ní ibùjókòó rẹ̀ láti ọwọ́ ìbínú Olúwa àwọn ọmọ-ogun, ní ọjọ́ ìbínú gbígbóná rẹ.
De aceea voi scutura cerurile şi pământul se va clinti din locul său, în furia DOMNULUI oştirilor şi în ziua mâniei lui înverşunate.
14 Gẹ́gẹ́ bí egbin tí à ń dọdẹ rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí àgùntàn tí kò ní olùṣọ́, ọ̀kọ̀ọ̀kan yóò padà tọ àwọn ènìyàn rẹ̀ lọ, ọ̀kọ̀ọ̀kan yóò sá padà sí ilẹ̀ abínibí i rẹ̀.
Şi va fi ca o căprioară urmărită şi ca o oaie pe care nimeni nu o ia; fiecare se va întoarce la poporul său şi va fugi fiecare în propria ţară.
15 Ẹnikẹ́ni tí a bá gbámú ni a ó wọ́ nílẹ̀ tuurutu, gbogbo àwọn tí ọwọ́ bá tẹ̀ ni yóò ti ipa idà kú.
Fiecare ce este găsit va fi străpuns; şi fiecare ce li se alătură va cădea prin sabie.
16 Àwọn ọ̀dọ́mọdé wọn ni a ó fọ́ sí wẹ́wẹ́ níṣojú wọn, gbogbo ilẹ̀ wọn ni a ó kó àwọn aya wọn ni a ó sì bá dàpọ̀.
Copiii lor de asemenea vor fi zdrobiţi în bucăţi înaintea ochilor lor; casele lor vor fi prădate şi soţiile lor violate.
17 Kíyèsi i, èmi yóò ru àwọn Media sókè sí wọn, àwọn tí kò bìkítà fún fàdákà tí kò sì ní inú dídùn sí wúrà.
Iată, voi stârni împotriva lor pe mezi, care nu vor lua aminte la argint; şi cât despre aur, nu se vor desfăta în el.
18 Ọrùn wọn yóò ré àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin lulẹ̀; wọn kò ní ṣàánú àwọn ọ̀dọ́mọdé tàbí kí wọn síjú àánú wo àwọn ọmọdé.
Arcurile lor de asemenea vor zdrobi pe tineri în bucăţi; şi nu vor avea milă de rodul pântecelui; ochiul lor nu va cruţa copiii.
19 Babeli, ohun ọ̀ṣọ́ àwọn ìjọba ògo ìgbéraga àwọn ará Babeli ni Ọlọ́run yóò da ojú rẹ̀ bolẹ̀ gẹ́gẹ́ bí Sodomu àti Gomorra.
Şi Babilonul, gloria împărăţiilor, frumuseţea maiestăţii caldeilor, va fi ca atunci când Dumnezeu a dărâmat Sodoma şi Gomora.
20 A kì yóò tẹ̀ ibẹ̀ dó mọ́ tàbí kí á gbé inú rẹ̀ láti ìrandíran; ará Arabia kì yóò pa àgọ́ níbẹ̀ mọ́, olùṣọ́-àgùntàn kan kì yóò kó ẹran rẹ̀ sinmi níbẹ̀.
Acesta nu va fi locuit niciodată, nici nu va fi locuit din generaţie în generaţie, nici arabul nu îşi va înălţa cortul acolo; nici păstorii nu îşi vor face staul acolo.
21 Ṣùgbọ́n àwọn ẹranko igbó ni yóò dùbúlẹ̀ níbẹ̀, àwọn ajáko yóò kún inú ilé wọn, níbẹ̀ ni àwọn òwìwí yóò máa gbé níbẹ̀ ni àwọn ewúrẹ́ igbó yóò ti máa bẹ́ kiri.
Ci fiare sălbatice ale deşertului se vor culca acolo; şi casele lor vor fi pline de creaturi jalnice; şi bufniţe vor locui acolo şi satiri vor dansa acolo.
22 Ìkookò yóò máa gbó ní ibùba wọn, àwọn ajáko nínú arẹwà ààfin wọn.
Şi fiarele sălbatice ale insulelor vor ţipa în casele lor pustii şi dragoni în palatele lor plăcute şi timpul lui este aproape să vină şi zilele lui nu vor fi prelungite.