< Isaiah 13 >
1 Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ tí ó kan Babeli èyí tí Isaiah ọmọ Amosi rí.
Brzemię Babilonu, które widział Izajasz, syn Amosa.
2 Gbé àsíá sókè ní orí òkè gbẹrẹfu, kígbe sí wọn, pè wọ́n láti wọlé sí ẹnu-ọ̀nà àwọn ọlọ́lá.
Na wysokiej górze wznieście sztandar, podnieście na nich głos, machajcie ręką, aby weszli w bramy książąt.
3 Mo ti pàṣẹ fún àwọn ẹni mímọ́ mi, mo ti pe àwọn jagunjagun mi láti gbé ìbínú mi jáde àwọn tí ń yọ̀ nínú ìṣẹ́gun mi.
Ja nakazałem swoim poświęconym, wezwałem też swoich mocarzy [do okazywania] mojego gniewu, tych, którzy radują się z mojego majestatu.
4 Gbọ́ ohùn kan ní àwọn orí òkè, gẹ́gẹ́ bí i ti ogunlọ́gọ̀ ènìyàn. Gbọ́ ìdàrúdàpọ̀ láàrín àwọn ìjọba, gẹ́gẹ́ bí i ti ìkórajọ àwọn orílẹ̀-èdè! Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti kó ogun rẹ̀ jọ àwọn jagunjagun fún ogun.
Odgłosy zgrai na górach jakby licznego ludu, odgłosy zgiełku królestw, zgromadzonych narodów. PAN zastępów gromadzi wojsko na wojnę.
5 Wọ́n wá láti ọ̀nà jíjìn réré, láti ìpẹ̀kun ọ̀run wá Olúwa pẹ̀lú àwọn ohun ìjà ìbínú rẹ̀, láti pa gbogbo orílẹ̀-èdè náà run.
Przybywają z dalekiej ziemi, z krańców nieba, PAN i narzędzia jego zapalczywości, aby spustoszyć całą ziemię.
6 Ẹ hu, nítorí ọjọ́ Olúwa súnmọ́ tòsí, yóò sì wá gẹ́gẹ́ bí ìparun láti ọ̀dọ̀ Alágbára jùlọ.
Zawódźcie, bo bliski jest dzień PANA; przyjdzie jak spustoszenie od Wszechmocnego.
7 Nítorí èyí, gbogbo ọwọ́ ni yóò rọ, ọkàn ẹnìkọ̀ọ̀kan yóò rẹ̀wẹ̀sì.
Dlatego wszelkie ręce opadną, a każde serce człowieka struchleje.
8 Ẹ̀rù yóò gbá wọn mú, ìrora àti ìpayínkeke yóò dìwọ́n mú, wọn yóò kérora gẹ́gẹ́ bí obìnrin tí ó ń rọbí. Ẹnìkínní yóò wo ẹnìkejì rẹ̀ pẹ̀lú ìpayà ojú wọn á sì gbinájẹ.
I będą przerażeni: ogarną ich skurcze i boleści, będą wić się z bólu jak rodząca kobieta. Jeden na drugiego spojrzy z osłupieniem, ich twarze będą podobne do płomieni.
9 Kíyèsi i, ọjọ́ Olúwa ń bọ̀ ọjọ́ búburú, pẹ̀lú ìbínú àti ìrunú gbígbóná— láti sọ ilẹ̀ náà dahoro, àti láti pa àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ inú rẹ̀ run.
Oto dzień PANA nadchodzi, okrutny, w zapalczywości i srogim gniewie, aby zamienić tę ziemię w pustynię i wytępić z niej grzeszników.
10 Àwọn ìràwọ̀ ojú ọ̀run àti ìkójọpọ̀ wọn kò sì ní fi ìmọ́lẹ̀ wọn hàn. Àṣẹ̀ṣẹ̀yọ oòrùn yóò di òkùnkùn àti òṣùpá kò ní fi ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ hàn.
Gwiazdy nieba bowiem i ich konstelacje nie będą jaśniały swoim światłem. Słońce się zaćmi, gdy tylko wzejdzie, a księżyc nie zabłyśnie swoim światłem.
11 Èmi yóò jẹ ayé ní ìyà nítorí ibi rẹ̀, àwọn ìkà nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn. Èmi yóò fi òpin sí gààrù àwọn agbéraga èmi ó sì rẹ ìgbéraga àwọn aláìláàánú sílẹ̀.
I ukarzę świat za jego zło i niegodziwych za ich nieprawość; położę kres pysze zuchwałych i poniżę wyniosłość okrutników.
12 Èmi yóò jẹ́ kí ọkùnrin kí ó wọn ju ojúlówó wúrà lọ, yóò sì ṣọ̀wọ́n ju wúrà Ofiri lọ.
Uczynię człowieka droższym niż czyste złoto, a nawet droższym niż złoto z Ofiru.
13 Nítorí náà èmi yóò jẹ́ kí àwọn ọ̀run kí ó wárìrì; ayé yóò sì mì tìtì ní ibùjókòó rẹ̀ láti ọwọ́ ìbínú Olúwa àwọn ọmọ-ogun, ní ọjọ́ ìbínú gbígbóná rẹ.
Dlatego zatrząsnę niebem, a ziemia ruszy się ze swego miejsca pod zapalczywością PANA zastępów i w dniu jego srogiego gniewu.
14 Gẹ́gẹ́ bí egbin tí à ń dọdẹ rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí àgùntàn tí kò ní olùṣọ́, ọ̀kọ̀ọ̀kan yóò padà tọ àwọn ènìyàn rẹ̀ lọ, ọ̀kọ̀ọ̀kan yóò sá padà sí ilẹ̀ abínibí i rẹ̀.
I będzie jak spłoszona sarna i jak trzoda, której nikt nie gromadzi: każdy powróci do swego ludu i każdy ucieknie do swojej ziemi.
15 Ẹnikẹ́ni tí a bá gbámú ni a ó wọ́ nílẹ̀ tuurutu, gbogbo àwọn tí ọwọ́ bá tẹ̀ ni yóò ti ipa idà kú.
Każdy, kogo znajdą, zostanie przebity; a każdy, kto się do nich przyłączy, polegnie od miecza.
16 Àwọn ọ̀dọ́mọdé wọn ni a ó fọ́ sí wẹ́wẹ́ níṣojú wọn, gbogbo ilẹ̀ wọn ni a ó kó àwọn aya wọn ni a ó sì bá dàpọ̀.
Ich dzieci będą roztrzaskane na ich oczach, ich domy będą splądrowane, a ich żony – zgwałcone.
17 Kíyèsi i, èmi yóò ru àwọn Media sókè sí wọn, àwọn tí kò bìkítà fún fàdákà tí kò sì ní inú dídùn sí wúrà.
Oto pobudzę przeciwko nim Medów, którzy o srebro nie będą dbać, a w złocie nie będą się lubować.
18 Ọrùn wọn yóò ré àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin lulẹ̀; wọn kò ní ṣàánú àwọn ọ̀dọ́mọdé tàbí kí wọn síjú àánú wo àwọn ọmọdé.
Ich łuki roztrzaskają młodzieńców, nie zlitują się nad płodem łona, ich oko nie przepuści dzieciom.
19 Babeli, ohun ọ̀ṣọ́ àwọn ìjọba ògo ìgbéraga àwọn ará Babeli ni Ọlọ́run yóò da ojú rẹ̀ bolẹ̀ gẹ́gẹ́ bí Sodomu àti Gomorra.
I Babilon, ozdoba królestw i chluba majestatu Chaldejczyków, stanie się jak Sodoma i Gomora, kiedy Bóg je zniszczył.
20 A kì yóò tẹ̀ ibẹ̀ dó mọ́ tàbí kí á gbé inú rẹ̀ láti ìrandíran; ará Arabia kì yóò pa àgọ́ níbẹ̀ mọ́, olùṣọ́-àgùntàn kan kì yóò kó ẹran rẹ̀ sinmi níbẹ̀.
Nie będzie nigdy więcej zamieszkany ani zasiedlony z pokolenia na pokolenie; Arab nie rozbije tam namiotu ani pasterze nie odpoczną tam [z trzodami].
21 Ṣùgbọ́n àwọn ẹranko igbó ni yóò dùbúlẹ̀ níbẹ̀, àwọn ajáko yóò kún inú ilé wọn, níbẹ̀ ni àwọn òwìwí yóò máa gbé níbẹ̀ ni àwọn ewúrẹ́ igbó yóò ti máa bẹ́ kiri.
Ale dziki zwierz pustyni będzie tam odpoczywać, a ich domy będą pełne wyjących bestii; zamieszkają tam sowy, a kozice będą tam podskakiwać.
22 Ìkookò yóò máa gbó ní ibùba wọn, àwọn ajáko nínú arẹwà ààfin wọn.
Straszne bestie wysp będą wyć w ich opuszczonych domach, a smoki w ich wspaniałych pałacach. Jego czas jest bliski, jego dni nie będą przedłużone.