< Isaiah 13 >
1 Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ tí ó kan Babeli èyí tí Isaiah ọmọ Amosi rí.
Jövendölés Babilonia ellen, a melyet látott Ésaiás, Ámós fia.
2 Gbé àsíá sókè ní orí òkè gbẹrẹfu, kígbe sí wọn, pè wọ́n láti wọlé sí ẹnu-ọ̀nà àwọn ọlọ́lá.
Emeljetek zászlót kopasz hegyen, kiáltsatok nékik, kézzel intsetek, hogy bevonuljanak a fejedelmek kapuin!
3 Mo ti pàṣẹ fún àwọn ẹni mímọ́ mi, mo ti pe àwọn jagunjagun mi láti gbé ìbínú mi jáde àwọn tí ń yọ̀ nínú ìṣẹ́gun mi.
Én parancsoltam felszentelt vitézeimnek, és elhívtam erősimet haragomnak véghezvitelére, a kik én bennem büszkén örvendenek.
4 Gbọ́ ohùn kan ní àwọn orí òkè, gẹ́gẹ́ bí i ti ogunlọ́gọ̀ ènìyàn. Gbọ́ ìdàrúdàpọ̀ láàrín àwọn ìjọba, gẹ́gẹ́ bí i ti ìkórajọ àwọn orílẹ̀-èdè! Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti kó ogun rẹ̀ jọ àwọn jagunjagun fún ogun.
Hah! zsibongás a hegyeken, mint nagy néptömegé; hah! összegyűlt népek országainak zúgása; a seregek Ura harczi sereget számlál.
5 Wọ́n wá láti ọ̀nà jíjìn réré, láti ìpẹ̀kun ọ̀run wá Olúwa pẹ̀lú àwọn ohun ìjà ìbínú rẹ̀, láti pa gbogbo orílẹ̀-èdè náà run.
Jőnek messze földről, az égnek végéről, az Úr, és haragjának eszközei, elpusztítani mind az egész földet.
6 Ẹ hu, nítorí ọjọ́ Olúwa súnmọ́ tòsí, yóò sì wá gẹ́gẹ́ bí ìparun láti ọ̀dọ̀ Alágbára jùlọ.
Jajgassatok, mert közel van az Úrnak napja, mint pusztító hatalom jő a Mindenhatótól.
7 Nítorí èyí, gbogbo ọwọ́ ni yóò rọ, ọkàn ẹnìkọ̀ọ̀kan yóò rẹ̀wẹ̀sì.
Ezért megerőtlenülnek minden kezek, és elolvad minden embernek szíve;
8 Ẹ̀rù yóò gbá wọn mú, ìrora àti ìpayínkeke yóò dìwọ́n mú, wọn yóò kérora gẹ́gẹ́ bí obìnrin tí ó ń rọbí. Ẹnìkínní yóò wo ẹnìkejì rẹ̀ pẹ̀lú ìpayà ojú wọn á sì gbinájẹ.
És megrémülnek, kínok és fájdalmak fogják el őket, és szenvednek, mint a szülőasszony; egyik a másikon csodálkozik, és arczuk lángba borul.
9 Kíyèsi i, ọjọ́ Olúwa ń bọ̀ ọjọ́ búburú, pẹ̀lú ìbínú àti ìrunú gbígbóná— láti sọ ilẹ̀ náà dahoro, àti láti pa àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ inú rẹ̀ run.
Ímé az Úrnak napja jő kegyetlen búsulással és felgerjedt haraggal, hogy a földet pusztasággá tegye, és annak bűnöseit elveszesse arról.
10 Àwọn ìràwọ̀ ojú ọ̀run àti ìkójọpọ̀ wọn kò sì ní fi ìmọ́lẹ̀ wọn hàn. Àṣẹ̀ṣẹ̀yọ oòrùn yóò di òkùnkùn àti òṣùpá kò ní fi ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ hàn.
Mert az ég csillagai és csillagzatai nem ragyogtatják fényöket, sötét lesz a nap támadásakor, és a hold fényét nem tündökölteti.
11 Èmi yóò jẹ ayé ní ìyà nítorí ibi rẹ̀, àwọn ìkà nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn. Èmi yóò fi òpin sí gààrù àwọn agbéraga èmi ó sì rẹ ìgbéraga àwọn aláìláàánú sílẹ̀.
És meglátogatom a földön a bűnt, és a gonoszokon vétküket, és megszüntetem az istentelenek kevélységét, és az erőszakoskodóknak gőgjét megalázom.
12 Èmi yóò jẹ́ kí ọkùnrin kí ó wọn ju ojúlówó wúrà lọ, yóò sì ṣọ̀wọ́n ju wúrà Ofiri lọ.
Drágábbá teszem az embert a színaranynál, és a férfit Ofir kincsaranyánál.
13 Nítorí náà èmi yóò jẹ́ kí àwọn ọ̀run kí ó wárìrì; ayé yóò sì mì tìtì ní ibùjókòó rẹ̀ láti ọwọ́ ìbínú Olúwa àwọn ọmọ-ogun, ní ọjọ́ ìbínú gbígbóná rẹ.
Ezért az egeket megrendítem, és megindul helyéről a föld is, a seregek Urának búsulása miatt, és felgerjedett haragjának napján,
14 Gẹ́gẹ́ bí egbin tí à ń dọdẹ rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí àgùntàn tí kò ní olùṣọ́, ọ̀kọ̀ọ̀kan yóò padà tọ àwọn ènìyàn rẹ̀ lọ, ọ̀kọ̀ọ̀kan yóò sá padà sí ilẹ̀ abínibí i rẹ̀.
És mint az űzött zerge, és mint a pásztor nélkül való nyáj, kiki népéhez tér meg, és kiki az ő földére fut;
15 Ẹnikẹ́ni tí a bá gbámú ni a ó wọ́ nílẹ̀ tuurutu, gbogbo àwọn tí ọwọ́ bá tẹ̀ ni yóò ti ipa idà kú.
Valaki ott találtatik, átveretik, és valaki megfogatik, fegyver miatt hull el,
16 Àwọn ọ̀dọ́mọdé wọn ni a ó fọ́ sí wẹ́wẹ́ níṣojú wọn, gbogbo ilẹ̀ wọn ni a ó kó àwọn aya wọn ni a ó sì bá dàpọ̀.
Kisdedeiket szemök előtt zúzzák szét, házaikat elzsákmányolják, és feleségeiket megszeplősítik.
17 Kíyèsi i, èmi yóò ru àwọn Media sókè sí wọn, àwọn tí kò bìkítà fún fàdákà tí kò sì ní inú dídùn sí wúrà.
Ímé, én feltámasztom ellenök a Médiabelieket, a kik ezüsttel nem gondolnak, és aranyban nem gyönyörködnek;
18 Ọrùn wọn yóò ré àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin lulẹ̀; wọn kò ní ṣàánú àwọn ọ̀dọ́mọdé tàbí kí wọn síjú àánú wo àwọn ọmọdé.
Kézíveik szétzúznak ifjakat, és nem könyörülnek a méh gyümölcsén, a fiaknak nem irgalmaz szemök:
19 Babeli, ohun ọ̀ṣọ́ àwọn ìjọba ògo ìgbéraga àwọn ará Babeli ni Ọlọ́run yóò da ojú rẹ̀ bolẹ̀ gẹ́gẹ́ bí Sodomu àti Gomorra.
És olyan lesz Babilon, a királyságok ékessége, a Khaldeusok dicsekvésének dísze, mint a hogyan elpusztítá Isten Sodomát és Gomorát;
20 A kì yóò tẹ̀ ibẹ̀ dó mọ́ tàbí kí á gbé inú rẹ̀ láti ìrandíran; ará Arabia kì yóò pa àgọ́ níbẹ̀ mọ́, olùṣọ́-àgùntàn kan kì yóò kó ẹran rẹ̀ sinmi níbẹ̀.
Nem ülik meg soha, és nem lakják nemzetségről nemzetségre, nem von sátort ott az arábiai, és pásztorok sem tanyáznak ott;
21 Ṣùgbọ́n àwọn ẹranko igbó ni yóò dùbúlẹ̀ níbẹ̀, àwọn ajáko yóò kún inú ilé wọn, níbẹ̀ ni àwọn òwìwí yóò máa gbé níbẹ̀ ni àwọn ewúrẹ́ igbó yóò ti máa bẹ́ kiri.
Hanem vadak tanyáznak ott, és baglyok töltik be házaikat, és struczok laknak ott, és bakok szökdelnek ott;
22 Ìkookò yóò máa gbó ní ibùba wọn, àwọn ajáko nínú arẹwà ààfin wọn.
És vad ebek üvöltenek palotáikban, és mulató házaikban sakálok; és ideje nem sokára eljő, és napjai nem késnek.