< Isaiah 13 >
1 Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ tí ó kan Babeli èyí tí Isaiah ọmọ Amosi rí.
Ĩno nĩyo ndũmĩrĩri nditũ ĩkoniĩ Babuloni, ĩrĩa Isaia mũrũ wa Amozu onire:
2 Gbé àsíá sókè ní orí òkè gbẹrẹfu, kígbe sí wọn, pè wọ́n láti wọlé sí ẹnu-ọ̀nà àwọn ọlọ́lá.
Atĩrĩrĩ, haandai bendera kĩrĩma igũrũ kĩrĩa gĩtarĩ mĩtĩ, anĩrĩrai na mũmahenerie, nĩguo matoonyere ihingo-inĩ cia arĩa marĩ igweta.
3 Mo ti pàṣẹ fún àwọn ẹni mímọ́ mi, mo ti pe àwọn jagunjagun mi láti gbé ìbínú mi jáde àwọn tí ń yọ̀ nínú ìṣẹ́gun mi.
Nĩnjathĩte andũ akwa arĩa atheru, nĩndũmanĩire njamba ciakwa, o icio ikenagĩra ũhootani wakwa, ciũke ikinyanĩrie marakara makwa.
4 Gbọ́ ohùn kan ní àwọn orí òkè, gẹ́gẹ́ bí i ti ogunlọ́gọ̀ ènìyàn. Gbọ́ ìdàrúdàpọ̀ láàrín àwọn ìjọba, gẹ́gẹ́ bí i ti ìkórajọ àwọn orílẹ̀-èdè! Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti kó ogun rẹ̀ jọ àwọn jagunjagun fún ogun.
Ta thikĩrĩriai, mũigue inegene rĩrĩ irĩma-inĩ igũrũ, inegene rĩhaana ta rĩa kĩrĩndĩ kĩingĩ! Ta thikĩrĩriai mũigue ngũĩ gatagatĩ ka mothamaki, taarĩ ndũrĩrĩ irarũrũngana hamwe! Jehova Mwene-Hinya-Wothe nĩwe ũracookanĩrĩria ita rĩa kũrũa mbaara.
5 Wọ́n wá láti ọ̀nà jíjìn réré, láti ìpẹ̀kun ọ̀run wá Olúwa pẹ̀lú àwọn ohun ìjà ìbínú rẹ̀, láti pa gbogbo orílẹ̀-èdè náà run.
Andũ acio marooka moimĩte mabũrũri ma kũraya, makoima ituri-inĩ cia kũũrĩa igũrũ. Ti-itherũ Jehova nĩarooka na indo cia mbaara cia mangʼũrĩ make, nĩguo aanange bũrũri wothe.
6 Ẹ hu, nítorí ọjọ́ Olúwa súnmọ́ tòsí, yóò sì wá gẹ́gẹ́ bí ìparun láti ọ̀dọ̀ Alágbára jùlọ.
Girĩkai, nĩgũkorwo mũthenya wa Jehova nĩũkuhĩrĩirie; ũgooka ũtariĩ ta mwanangĩko uumĩte kũrĩ Mwene-Hinya-Wothe.
7 Nítorí èyí, gbogbo ọwọ́ ni yóò rọ, ọkàn ẹnìkọ̀ọ̀kan yóò rẹ̀wẹ̀sì.
Tondũ ũcio moko mothe nĩmakaregera, na ngoro ya mũndũ o wothe ĩringĩke.
8 Ẹ̀rù yóò gbá wọn mú, ìrora àti ìpayínkeke yóò dìwọ́n mú, wọn yóò kérora gẹ́gẹ́ bí obìnrin tí ó ń rọbí. Ẹnìkínní yóò wo ẹnìkejì rẹ̀ pẹ̀lú ìpayà ojú wọn á sì gbinájẹ.
Andũ makaanyiitwo nĩ kĩmako kĩnene, na magwatwo nĩ ruo na kĩeha, na manyiitwo nĩ ruo o ta rwa mũndũ-wa-nja akĩrũmwo. O mũndũ akaagegio nĩ ũrĩa ũngĩ, na mothiũ mao mahaane ta nĩnĩmbĩ cia mwaki.
9 Kíyèsi i, ọjọ́ Olúwa ń bọ̀ ọjọ́ búburú, pẹ̀lú ìbínú àti ìrunú gbígbóná— láti sọ ilẹ̀ náà dahoro, àti láti pa àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ inú rẹ̀ run.
Atĩrĩrĩ, mũthenya ũcio wa Jehova nĩũrooka, na gũtikaiguanĩrwo tha; ũgaakorwo ũrĩ mũthenya wa mangʼũrĩ na marakara mahiũ, ma gũtũma thĩ ĩkire ihooru, na ũniine ehia arĩa magaakorwo kuo.
10 Àwọn ìràwọ̀ ojú ọ̀run àti ìkójọpọ̀ wọn kò sì ní fi ìmọ́lẹ̀ wọn hàn. Àṣẹ̀ṣẹ̀yọ oòrùn yóò di òkùnkùn àti òṣùpá kò ní fi ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ hàn.
Nĩgũkorwo njata cia igũrũ na iria cionekaga irĩ gĩtutu itigacooka kwara na ũtheri wacio. Narĩo riũa rĩkĩratha rĩgaatuĩka nduma, naguo mweri ũtige gũcooka kwara.
11 Èmi yóò jẹ ayé ní ìyà nítorí ibi rẹ̀, àwọn ìkà nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn. Èmi yóò fi òpin sí gààrù àwọn agbéraga èmi ó sì rẹ ìgbéraga àwọn aláìláàánú sílẹ̀.
Nĩngaherithia thĩ nĩ ũndũ wa ũũru wayo, na herithie andũ arĩa aaganu nĩ ũndũ wa mehia mao. Nĩnganiina mwĩĩkĩrĩro wa andũ arĩa etĩĩi, na nyiihie mwĩtĩĩo wa arĩa matarĩ tha.
12 Èmi yóò jẹ́ kí ọkùnrin kí ó wọn ju ojúlówó wúrà lọ, yóò sì ṣọ̀wọ́n ju wúrà Ofiri lọ.
Ũgaakorwo ũrĩ ũndũ mũritũ mũno kuona mũndũ, gũkĩra kuona thahabu therie, kana kuona thahabu ya ofiri.
13 Nítorí náà èmi yóò jẹ́ kí àwọn ọ̀run kí ó wárìrì; ayé yóò sì mì tìtì ní ibùjókòó rẹ̀ láti ọwọ́ ìbínú Olúwa àwọn ọmọ-ogun, ní ọjọ́ ìbínú gbígbóná rẹ.
Nĩ ũndũ ũcio nĩngatũma igũrũ rĩinaine; nayo thĩ nĩĩgaathingitha, yehere gĩikaro kĩayo, nĩ ũndũ wa mangʼũrĩ ma Jehova Mwene-Hinya-Wothe, mũthenya ũrĩa marakara make makarĩrĩmbũka.
14 Gẹ́gẹ́ bí egbin tí à ń dọdẹ rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí àgùntàn tí kò ní olùṣọ́, ọ̀kọ̀ọ̀kan yóò padà tọ àwọn ènìyàn rẹ̀ lọ, ọ̀kọ̀ọ̀kan yóò sá padà sí ilẹ̀ abínibí i rẹ̀.
O ta thwariga ĩrĩa ĩkũguĩmwo, na o ta ũrĩa ngʼondu itarĩ na mũrĩithi ciũraga, ũguo no taguo mũndũ o mũndũ agaacookerera andũ ao kĩũmbe, na o mũndũ oore acooke bũrũri wao kĩũmbe.
15 Ẹnikẹ́ni tí a bá gbámú ni a ó wọ́ nílẹ̀ tuurutu, gbogbo àwọn tí ọwọ́ bá tẹ̀ ni yóò ti ipa idà kú.
Mũndũ ũrĩa wothe ũkaanyiitwo mũgwate agaathecwo atũrĩkanio; nao arĩa othe makaanyiitwo makooragwo na rũhiũ rwa njora.
16 Àwọn ọ̀dọ́mọdé wọn ni a ó fọ́ sí wẹ́wẹ́ níṣojú wọn, gbogbo ilẹ̀ wọn ni a ó kó àwọn aya wọn ni a ó sì bá dàpọ̀.
Twana twao tũkaabacanio thĩ tũtuĩke icunjĩ makĩĩonagĩra na maitho; indo ciao cia nyũmba igaatahwo, na atumia ao manyiitwo na hinya.
17 Kíyèsi i, èmi yóò ru àwọn Media sókè sí wọn, àwọn tí kò bìkítà fún fàdákà tí kò sì ní inú dídùn sí wúrà.
Atĩrĩrĩ, nĩngarahũra andũ a Amedi mamookĩrĩre, arĩa matarĩ bata wa betha, na matakenagio nĩ thahabu.
18 Ọrùn wọn yóò ré àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin lulẹ̀; wọn kò ní ṣàánú àwọn ọ̀dọ́mọdé tàbí kí wọn síjú àánú wo àwọn ọmọdé.
Nĩmakooraga aanake na mĩguĩ yao; o na matikaiguĩra twana tha, kana macaĩre ciana.
19 Babeli, ohun ọ̀ṣọ́ àwọn ìjọba ògo ìgbéraga àwọn ará Babeli ni Ọlọ́run yóò da ojú rẹ̀ bolẹ̀ gẹ́gẹ́ bí Sodomu àti Gomorra.
Itũũra rĩa Babuloni, o rĩo inagĩ rĩa mothamaki, na nĩrĩo rĩtũmaga andũ a Babuloni metĩĩe nĩ ũndũ wa riiri warĩo, nĩrĩkangʼaũranio nĩ Ngai, o ta ũrĩa Sodomu na Gomora kwangʼaũranirio.
20 A kì yóò tẹ̀ ibẹ̀ dó mọ́ tàbí kí á gbé inú rẹ̀ láti ìrandíran; ará Arabia kì yóò pa àgọ́ níbẹ̀ mọ́, olùṣọ́-àgùntàn kan kì yóò kó ẹran rẹ̀ sinmi níbẹ̀.
Gũtirĩ hĩndĩ rĩgaacooka gũtũũrwo o na rĩ, kana rĩikarwo nĩ andũ njiarwa na njiarwa; gũtirĩ Mũarabu ũkaamba hema yake kuo, na gũtirĩ mũrĩithi ũkaarahia mahiũ make kuo.
21 Ṣùgbọ́n àwọn ẹranko igbó ni yóò dùbúlẹ̀ níbẹ̀, àwọn ajáko yóò kún inú ilé wọn, níbẹ̀ ni àwọn òwìwí yóò máa gbé níbẹ̀ ni àwọn ewúrẹ́ igbó yóò ti máa bẹ́ kiri.
No rĩrĩ, gũgaakomagwo nĩ nyamũ cia werũ, nacio nyũmba ciarĩo igaikaragwo nĩ mbwe; kũu nĩkuo ndundu igaatũũraga, na nokuo mbũri cia gĩthaka-inĩ igaatũũhagĩra.
22 Ìkookò yóò máa gbó ní ibùba wọn, àwọn ajáko nínú arẹwà ààfin wọn.
Hiti ikaagambagĩra ciĩgitĩro-inĩ ciakuo, na mbwe ciikarage nyũmba iria njega cia ũthamaki. Na rĩrĩ, ihinda rĩa ituĩro rĩu nĩikinyu, na matukũ marĩo matikongererwo.