< Isaiah 12 >
1 Ní ọjọ́ náà ni ìwọ ó wí pé, “Èmi ó yìn ọ́, Olúwa. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé ò ti bínú sí mi ìbínú rẹ ti yí kúrò níbẹ̀ ìwọ sì ti tù mí nínú.
At that time, you [people of Jerusalem] will sing [this song]: “Yahweh, we praise you! [Previously], you were angry with us, but you are not angry now and you have comforted us.
2 Nítòótọ́ Ọlọ́run ni ìgbàlà mi, èmi yóò gbẹ́kẹ̀lé e èmi kì yóò bẹ̀rù. Olúwa, Olúwa náà ni agbára à mi àti orin ìn mi, òun ti di ìgbàlà mi.”
Amazingly, you [have come to] save us, [so] we will trust [in you] and not be afraid. Yahweh our God, you enable us to be strong; you are [the one about whom] we sing; you have rescued us [from our enemies].”
3 Pẹ̀lú ayọ̀ ni ìwọ yóò máa pọn omi láti inú kànga ìgbàlà.
You(pl), [his people], will greatly enjoy being saved like [MET] you enjoy drinking water from a fountain.
4 Ní ọjọ́ náà, ìwọ yóò wí pé, “Fi ọpẹ́ fún Olúwa, ké pe orúkọ rẹ̀, jẹ́ kí ó di mí mọ̀ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, ohun tí ó ti ṣe kí o sì kéde pé a ti gbé orúkọ rẹ̀ ga.
At that time you [all] will say, “We should thank Yahweh! We should praise him [MTY]! We should tell [the people of all] the people-groups what he has done; we should enable them to know that he [MTY] is very great!
5 Kọ orin sí Olúwa, nítorí ó ti ṣe ohun tí ó lógo, jẹ́ kí èyí di mí mọ̀ fún gbogbo ayé.
We should sing to Yahweh, because he has done wonderful things. We should enable everyone in the world to know it!
6 Kígbe sókè kí o sì kọrin fún ayọ̀, ẹ̀yin ènìyàn Sioni, nítorí títóbi ni ẹni mímọ́ kan ṣoṣo ti Israẹli láàrín yín.”
You people of Jerusalem, shout joyfully to praise Yahweh, because he is the great Holy One whom we Israeli [people worship], and he lives among us!”