< Isaiah 10 >

1 Ègbé ni fún àwọn ti ń ṣe òfin àìṣòdodo,
Ⱪǝbiⱨlik ⱪanunlirini tüzgüqilǝrgǝ, Azabliⱪ pǝrman-ⱨɵkümlǝrni yazƣuqilarƣa way!
2 láti dún àwọn aláìní ní ẹ̀tọ́ wọn àti láti fa ọwọ́ ìdájọ́ sẹ́yìn kúrò níwájú àwọn olùpọ́njú ènìyàn mi, wọ́n sọ àwọn ọ̀pọ̀ di ìjẹ fún wọn, wọ́n sì ń ja àwọn aláìní baba lólè.
Tul hotunlarni oljimiz ⱪilayli, Yetim-yesirlarni bulap-talayli dǝp, Ular miskinlǝrgǝ adalǝtni bǝrmǝy, Hǝlⱪimdiki ajiz-beqarilǝrdin ⱨoⱪuⱪni bulap ketidu.
3 Kí ni ìwọ yóò ṣe ní ọjọ́ ìṣirò nígbà tí ìparun bá ti ọ̀nà jíjìn wá? Ta ni ìwọ yóò sá tọ̀ fún ìrànlọ́wọ́? Níbo ni ìwọ yóò fi ọrọ̀ rẹ sí?
Ⱨesab alidiƣan künidǝ, Yǝni yiraⱪtin kǝlgǝn tuyuⱪsiz balayi’apǝt künidǝ, Nemǝ ⱪilisilǝr? Kimdin baxpanaⱨliⱪ izdǝp yürisilǝr? Bayliⱪ-xɵⱨritinglarni nǝgǝ amanǝt ⱪoyisilǝr?
4 Ohunkóhun kò ní ṣẹ́kù mọ́ bí kò ṣe láti tẹ̀ ba láàrín àwọn ìgbèkùn tàbí kí o ṣubú sáàrín àwọn tí a pa. Pẹ̀lú gbogbo nǹkan wọ̀nyí, ìbínú rẹ̀ kò kúrò, ọwọ́ rẹ̀ sì tún gbé sókè.
Ularƣa ǝsirlǝr arisida zongziyip olturuxtin, Yaki ɵltürülgǝnlǝr arisida yiⱪilixtin baxⱪa ⱨeqnemǝ ⱪalmidi! Ⱨǝmmisi xundaⱪ bolsimu, Uning ƣǝzipi yǝnila yanmaydu, Sozƣan ⱪoli yǝnila ⱪayturulmay turidu.
5 “Ègbé ni fún àwọn ará Asiria, ọ̀gọ ìbínú mi, ní ọwọ́ ẹni tí kùmọ̀ ìbínú mi wà!
Ⱪoliƣa ƣǝzipimning toⱪmiⱪi tutⱪuzulƣan, Ɵzümning dǝrƣǝzipimning tayiⱪi bolƣan Asuriyǝlikkǝ way!
6 Mo rán an sí orílẹ̀-èdè aláìní Ọlọ́run, mo dojú rẹ̀ kọ àwọn ènìyàn tí ó mú mi bínú láti já ẹrù gbà, àti láti kó ìkógun láti tẹ̀ mọ́lẹ̀ bí amọ̀ ní ojú òpópó.
Mǝn uni hudasiz bir «yat ǝl»gǝ, Dǝrƣǝzipim ⱪaritilƣan hǝlⱪimgǝ zǝrbǝ berixkǝ ǝwǝtimǝn; Uningƣa olja tutuwelixⱪa, Ƣǝniymǝtni bulaxⱪa, [Hǝlⱪimni] koqilardiki lay-patⱪaⱪlarni dǝssigǝndǝk dǝssǝxkǝ buyruymǝn.
7 Ṣùgbọ́n, èyí kì í ṣe ohun tí ó fẹ́ ṣe, èyí kọ́ ni ohun tí ó ní lọ́kàn; èrò rẹ̀ ni láti parun, láti fi òpin sí ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè.
Biraⱪ [Asuriyǝlikning] kɵzdǝ tutⱪini muxu ǝmǝs, U xundaⱪ ⱨeq oyliƣan ǝmǝs. Uning oyliƣini wǝyran ⱪilix, Kɵp dɵlǝtlǝrni yoⱪitixtin ibarǝttur.
8 ‘Kì í ha ṣe pé ọba ni gbogbo àwọn aláṣẹ mi?’ ni Olúwa wí.
U: — «Mening sǝrdarlirimningmu ⱨǝmmisi padixaⱨlarƣa barawǝr ǝmǝsmu?
9 ‘Kì í ha ṣe pé Kalno dàbí i Karkemiṣi? Hamati kò ha dàbí i Arpadi, àti Samaria bí i Damasku?
Kalno xǝⱨiri Karkemix xǝⱨirigǝ, Hamat xǝⱨiri Arpad xǝⱨirigǝ, Samariyǝ xǝⱨiri Dǝmǝxⱪ xǝⱨirigǝ ohxax ǝmǝsmu?
10 Gẹ́gẹ́ bí ọwọ́ mi ti gbá ìjọba àwọn òrìṣà mú, ìjọba tí ère rẹ̀ pọ̀ ju ti Jerusalẹmu àti Samaria lọ.
Mǝbudliri Samariyǝning wǝ Yerusalemningkidin uluƣ bolƣini bilǝn, Mening ⱪolum muxu mǝbudⱪa tǝwǝ bolƣan padixaⱨliⱪlarƣa igǝ boluxⱪa yǝtküdǝk tursa,
11 Èmi kì yóò a bá Jerusalẹmu wí àti àwọn ère rẹ̀?’” Gẹ́gẹ́ bí mo ṣe ṣe sí Samaria àti àwọn ère rẹ̀?
Samariyǝ wǝ uning mǝbudlirini ⱪandaⱪ ⱪilƣan bolsam, Yerusalem wǝ uning mǝbudlirini ohxaxla xundaⱪ ⱪilmamdimǝn?» — dǝydu.
12 Nígbà tí Olúwa ti ṣe iṣẹ́ rẹ̀ sí òkè Sioni àti Jerusalẹmu, yóò sọ wí pé, “Èmi yóò fi ìyà jẹ ọba Asiria nítorí gààrù àyà rẹ̀ àti ìgbéraga ojú rẹ̀.
Biraⱪ Rǝb Zion teƣi wǝ Yerusalemda pütkül jaza ixini pütküzüp bolƣandin keyin, U: — «Mǝn Asuriyǝ padixaⱨining kɵnglidiki baxbaxtaⱪliⱪning aⱪiwitini [uningƣa qüxürimǝn], Uning kɵzliridiki kibirlik nǝzǝrlirini jazalaymǝn» dǝydu.
13 Nítorí ó sọ pé: “‘Pẹ̀lú agbára ọwọ́ mi ni mo fi ṣe èyí àti pẹ̀lú ọgbọ́n ọ̀n mi, nítorí mo ní òye. Mo mú ààlà àwọn orílẹ̀-èdè kúrò, mo sì ti kó ìṣúra wọn. Gẹ́gẹ́ bí alágbára kan, mo borí àwọn ọba wọn.
Qünki u: — «Bu ixlarni ɵz ⱪolumning küqi bilǝn, Ɵz danaliⱪim bilǝn mǝn ⱪilƣanmǝn; Qünki mǝn ǝⱪilliⱪturmǝn; Mǝn ǝllǝrning pasillirini yoⱪattim, Ularning hǝzinilirini buliwaldim, Tǝhtkǝ olturƣanlarni batur kǝbi qüxürüp taxlidimmǝn;
14 Bí ènìyàn ti í tọwọ́ bọ ìtẹ́ ẹyẹ, bẹ́ẹ̀ ni ọwọ́ mi tẹ ọrọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè. Bí ènìyàn ti í kó ẹyin tí a kọ̀sílẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni mo kó àwọn orílẹ̀-èdè kò sí èyí tí ó fi apá lu apá, tàbí kí ó ya ẹnu láti dún.’”
Mǝn ⱪolumni bir ⱪux uwisiƣa uzatⱪandǝk ǝllǝrning bayliⱪliriƣa uzattim, Birsi taxliwetilgǝn tuhumlarni tǝrgǝndǝk mǝn pütkül dunyani yiƣⱪanmǝn; Ulardin ⱨeqbirimu ⱪanatlirini palaⱪlatmidi, Tumxuⱪini aqmidi, Yaki quk-quk ⱪilip awaz qiⱪarmidi» — dǝydu.
15 Ǹjẹ́ àáké le gbé ara rẹ̀ sókè kọjá ẹni tí ó ń fì í, tàbí kí ayùn fọ́nnu sí ẹni tí ó ń lò ó? Àfi bí ẹni pé ọ̀pá ó na ẹni tí ó gbé e sókè, tàbí kí kùmọ̀ lu èyí tí kì í ṣe igi.
Palta ɵzini ixlǝtküqisigǝ lap atsa bolamdu? Ⱨǝrǝ ⱨǝridigüqigǝ poqiliⱪ ⱪilsa bolamdu? Xundaⱪ ix ikǝn, huddi tayaⱪ ɵzini kɵtürgüqisini oynitalisa bolidiƣandǝk, Huddi ⱨasa yaƣaq ǝmǝs bolƣuqini kɵtürgǝndǝk bolatti ǝmǝsmu?!
16 Nítorí náà, ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, yóò rán ààrùn ìrẹ̀dànù sórí àwọn akíkanjú jagunjagun, lábẹ́ ògo rẹ̀ ni iná kan yóò ti sọ gẹ́gẹ́ bí iná ajónirun.
Xunga samawi ⱪoxunlarning Sǝrdari bolƣan Rǝb Pǝrwǝrdigar xu [Asuriyǝlkning] palwanliri arisiƣa oruⱪlitix kesilini ǝwǝtidu, Uning xan-xǝripining astida lawuldap yalⱪunlaydiƣan bir otni yaⱪidu.
17 Ìmọ́lẹ̀ Israẹli yóò di iná, Ẹni Mímọ́ rẹ̀ yóò jẹ́ ọ̀wọ́-iná, ní ọjọ́ kan ṣoṣo yóò jó yóò sì run àti ẹ̀gún àti ẹ̀wọ̀n.
«Israilning Nuri»ning Ɵzi ot, Uningdiki Muⱪǝddǝs Bolƣuqi yalⱪun bolidu, U bir kün iqidǝ uning jiƣanliri wǝ tikǝnlirini kɵydürüp, yutuwalidu.
18 Gbogbo ẹwà igbó o rẹ̀, àti àwọn pápá ọlọ́ràá gbogbo rẹ̀ ni yóò run pátápátá, gẹ́gẹ́ bí ẹni tí ó ṣàìsàn ti í ṣòfò dànù.
Ⱨǝm uning ormanzarliⱪ wǝ baƣ-etizlirining xan-xǝripini, jan wǝ tenini kɵydürüp kül ⱪiliwetidu; Ular bǝǝyni jüdǝp ketiwatⱪan kesǝl adǝmdǝk bolup ⱪalidu.
19 Àwọn igi tí yóò kù nínú igbó o rẹ̀ yóò kéré níye, tí ọ̀dọ́mọdé yóò fi le kọ̀ wọ́n sílẹ̀.
Buning bilǝn ormanzarliⱪtiki dǝrǝhlǝrning ⱪep ⱪalƣini xunqǝ az boliduki, Kiqik bala ularni sanap hatiriliyǝlǝydu.
20 Ní ọjọ́ náà, àwọn tí ó ṣẹ́kù ní Israẹli, àwọn tí ó yè ní ilé e Jakọbu, kò ní gbẹ́kẹ̀lé ẹni náà tí ó lù wọ́n bolẹ̀, ṣùgbọ́n ní òtítọ́ yóò gbẹ́kẹ̀lé Olúwa, Ẹni Mímọ́ Israẹli.
Xu küni xundaⱪ boliduki, Israilning ⱪaldi hǝlⱪi, yǝni Yaⱪupning jǝmǝtidin ⱪeqip ⱪaytⱪanlar ɵzlirini urƣuqiƣa ikkinqi tayanmaydu; bǝlki ular ⱨǝⱪiⱪǝtǝn Pǝrwǝrdigar, yǝni «Israildiki Muⱪǝddǝs Bolƣuqi»ƣa tayinidu.
21 Àwọn ìyókù yóò padà, àwọn ìyókù ti Jakọbu yóò padà sí ọ̀dọ̀ Ọlọ́run Alágbára.
Bǝrⱨǝⱪ, bir «ⱪaldi» ⱪaytip kelidu, Yǝni Yaⱪupning «ⱪaldisi» ⱪudrǝtlik Tǝngrining yeniƣa ⱪaytip kelidu.
22 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn ènìyàn rẹ, ìwọ Israẹli dàbí yanrìn ní Òkun, ẹni díẹ̀ ni yóò padà. A ti pàṣẹ ìparun, àkúnwọ́sílẹ̀ àti òdodo.
I Israil, hǝlⱪing dengizdiki ⱪumdǝk kɵp bolƣini bilǝn, Pǝⱪǝt bir ⱪaldisi ⱪaytidu; [Qünki] ⱨǝⱪⱪaniyliⱪ bilǝn yürgüzülgǝn, bir ⱨalakǝtning texip üstünglarƣa qüxüxi bekitilgǝndur;
23 Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni yóò mú un ṣẹ, ìparun tí a ti pàṣẹ rẹ̀ lórí gbogbo ilẹ̀ náà.
Qünki bir ⱨalakǝtni — bekitilgǝn bir ⱨalakǝtni samawi ⱪoxunlarning Sǝrdari bolƣan Pǝrwǝrdigar pütkül yǝr yüzidǝ ǝmǝlgǝ axuridu.
24 Nítorí náà, báyìí ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “Ẹ̀yin ènìyàn mi tí ó ń gbé Sioni, ẹ má ṣe bẹ̀rù àwọn Asiria, tí ó ń fi ọ̀pá lù yín, tí wọ́n sì ń gbé ọ̀gọ tì yín bí Ejibiti ti ṣe.
Xunga samawi ⱪoxunlarning Sǝrdari bolƣan Rǝb Pǝrwǝrdigar mundaⱪ dǝydu: — « — I Zion teƣida turƣan hǝlⱪim, Asuriyǝdin ⱪorⱪma! U seni tayaⱪ bilǝn uridiƣan, Wǝ Misirliⱪlardǝk sanga ⱪarap ⱨasisini kɵtüridiƣan bolsimu,
25 Láìpẹ́, ìbínú mi sí i yín yóò wá sí òpin n ó sì dojú ìrunú mi kọ wọ́n, fún ìparun wọn.”
Pǝⱪǝt azƣinǝ waⱪit ɵtüxi bilǝnla, Silǝrgǝ ⱪaratⱪan muxu dǝrƣǝzipim tügǝp, Ƣǝzipimni ularƣa ⱨalakǝt qüxsun dǝp ⱪaritimǝn.
26 Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò nà wọ́n ní ẹgba. Gẹ́gẹ́ bí ó ṣe lu Midiani ní òkè Orebu, yóò sì gbé ọ̀pá rẹ̀ lé orí omi gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe ní Ejibiti.
Samawi ⱪoxunlarning Sǝrdari bolƣan Pǝrwǝrdigar bolsa, ularƣa ⱪamqa bilǝn ⱨujum ⱪozƣaydu; Ularning ⱨali «Orǝbning ⱪoram texi»da bolƣan Midiyan ⱪirƣinqiliⱪidǝk ⱨalǝttǝ bolidu; U ⱨasisini dengizƣa ⱪaritip, Uni Misirliⱪlarning üstigǝ kɵtürgǝndǝk kɵtüridu;
27 Ní ọjọ́ náà, a ó gbé ẹrù wọn kúrò ní èjìká a yín, àti àjàgà a wọn kúrò ní ọrùn un yín a ó fọ́ àjàgà náà, nítorí pé ẹ̀yin ó ti sanra.
Andin xu künidǝ xundaⱪ boliduki, Uning yüki mürǝngdin, Boyunturuⱪi boynungdin elip taxlinidu; Mayliring sǝwǝbidin, Boyunturuⱪ sundurup yoⱪitilidu.
28 Wọ́n wọ Aiati, wọ́n gba Migroni kọjá, wọ́n kó nǹkan pamọ́ sí Mikmasi.
Mana, ular Ayatⱪa yetip, Migrondin ɵtkǝn, Mihmaxta yük-taⱪlirini ⱪoyup ⱪoyidu;
29 Wọ́n ti rékọjá ọ̀nà, wọ́n wí pé, “Àwa ó tẹ̀dó sí Geba lóru yìí.” Rama mì tìtì Gibeah ti Saulu sálọ.
Ular bosuƣa-dawandin ɵtkǝn, Gebada ⱪonup ⱪalidu; Ramaⱨ titrǝp ketidu; Saulning yurti Gibeaⱨdikilǝr bolsa ⱪeqip kǝtkǝn;
30 Gbé ohùn rẹ sókè, ìwọ ọmọbìnrin Galimu! Dẹ etí sílẹ̀, ìwọ Laiṣa! Ìwọ òtòṣì Anatoti!
I Gallimning ⱪizi, pǝryadingni kɵtür! Ⱨǝy Laix, anglap ⱪoy! I biqarǝ Anatot!
31 Madmena ti fẹsẹ̀ fẹ́ ẹ, àwọn ènìyàn Gebimu ti fi ara pamọ́.
Madmǝnaⱨ bolsa ⱪaqti; Gebimdikilǝr bǝdǝr ⱪaqti;
32 Ní ọjọ́ yìí, wọn yóò dúró ní Nobu wọn yóò kan sáárá, ní òkè ọmọbìnrin Sioni ní òkè Jerusalẹmu.
Xu kün ɵtmigüqǝ ular Nob dɵngidǝ tohtap ⱪalidu; Axu yǝrdǝ u Zion ⱪizining teƣiƣa, Yǝni Yerusalemdiki dɵnggǝ ⱪarap muxtini oynitidu.
33 Wò ó, Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, yóò kán ẹ̀ka náà sọnù pẹ̀lú agbára. Àwọn igi ọlọ́lá ni a ó gé lulẹ̀ àwọn tí ó ga gogoro ni a ó rẹ̀ sílẹ̀.
Mana, samawi ⱪoxunlarning Sǝrdari bolƣan Rǝb Pǝrwǝrdigar qong xahlarni xiddǝt bilǝn kesiwetidu; Xuning bilǝn egiz ɵskǝnlǝr kesip yiⱪitilidu; Ⱨali üstünlǝr pǝslǝxtürülidu.
34 Òun yóò gé igbó dídí pẹ̀lú àáké, Lebanoni yóò ṣubú níwájú Alágbára náà.
U tɵmür [ⱪorallar] bilǝn ormanliⱪning Baraⱪsan yǝrlirini kesip ⱪaⱪasliⱪ ⱪiliwetidu; Liwan bolsa uluƣ birsi tǝripidin yiⱪitilidu.

< Isaiah 10 >