< Isaiah 10 >

1 Ègbé ni fún àwọn ti ń ṣe òfin àìṣòdodo,
Biada tym, którzy wydają niesprawiedliwe ustawy, i tym, którzy wypisują dekrety ucisku;
2 láti dún àwọn aláìní ní ẹ̀tọ́ wọn àti láti fa ọwọ́ ìdájọ́ sẹ́yìn kúrò níwájú àwọn olùpọ́njú ènìyàn mi, wọ́n sọ àwọn ọ̀pọ̀ di ìjẹ fún wọn, wọ́n sì ń ja àwọn aláìní baba lólè.
Aby odepchnąć ubogiego od sądu i pozbawić sprawiedliwości ubogich mego ludu, aby wdowy stały się ich łupem i aby mogli ograbiać sieroty.
3 Kí ni ìwọ yóò ṣe ní ọjọ́ ìṣirò nígbà tí ìparun bá ti ọ̀nà jíjìn wá? Ta ni ìwọ yóò sá tọ̀ fún ìrànlọ́wọ́? Níbo ni ìwọ yóò fi ọrọ̀ rẹ sí?
A co uczynicie w dniu nawiedzenia i spustoszenia, który przyjdzie z daleka? Do kogo będziecie uciekać się o pomoc? I gdzie zostawicie swoją chwałę?
4 Ohunkóhun kò ní ṣẹ́kù mọ́ bí kò ṣe láti tẹ̀ ba láàrín àwọn ìgbèkùn tàbí kí o ṣubú sáàrín àwọn tí a pa. Pẹ̀lú gbogbo nǹkan wọ̀nyí, ìbínú rẹ̀ kò kúrò, ọwọ́ rẹ̀ sì tún gbé sókè.
Beze mnie skulą się wśród więźniów, upadną wśród zabitych. Mimo tego wszystkiego jego gniew nie ustał, ale jego ręka jest jeszcze wyciągnięta.
5 “Ègbé ni fún àwọn ará Asiria, ọ̀gọ ìbínú mi, ní ọwọ́ ẹni tí kùmọ̀ ìbínú mi wà!
Ach, Asyryjczyk, rózga mego gniewu; w jego ręku jest kij mojego oburzenia.
6 Mo rán an sí orílẹ̀-èdè aláìní Ọlọ́run, mo dojú rẹ̀ kọ àwọn ènìyàn tí ó mú mi bínú láti já ẹrù gbà, àti láti kó ìkógun láti tẹ̀ mọ́lẹ̀ bí amọ̀ ní ojú òpópó.
Wyślę go przeciw obłudnemu narodowi, przeciw ludowi mojego gniewu przykażę mu, aby zebrał łup i zdobycz, aby zdeptał go, jak błoto na ulicach.
7 Ṣùgbọ́n, èyí kì í ṣe ohun tí ó fẹ́ ṣe, èyí kọ́ ni ohun tí ó ní lọ́kàn; èrò rẹ̀ ni láti parun, láti fi òpin sí ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè.
Lecz on nie tak będzie mniemał i jego serce nie będzie tak myślało, ponieważ w swoim sercu umyślił wytracić i wytępić niemało narodów.
8 ‘Kì í ha ṣe pé ọba ni gbogbo àwọn aláṣẹ mi?’ ni Olúwa wí.
Mówi bowiem: Czyż moi książęta nie są królami?
9 ‘Kì í ha ṣe pé Kalno dàbí i Karkemiṣi? Hamati kò ha dàbí i Arpadi, àti Samaria bí i Damasku?
Czy Kalno nie jest jak Karkemisz? Czy Chamat nie jest jak Arpad? Czy Samaria nie jest jak Damaszek?
10 Gẹ́gẹ́ bí ọwọ́ mi ti gbá ìjọba àwọn òrìṣà mú, ìjọba tí ère rẹ̀ pọ̀ ju ti Jerusalẹmu àti Samaria lọ.
Jak moja ręka dosięgła królestw bożków, chociaż ich bożki [przewyższały] te w Jerozolimie i Samarii;
11 Èmi kì yóò a bá Jerusalẹmu wí àti àwọn ère rẹ̀?’” Gẹ́gẹ́ bí mo ṣe ṣe sí Samaria àti àwọn ère rẹ̀?
Czyż nie uczynię z Jerozolimą i jej bożkami tak, jak uczyniłem z Samarią i jej bożkami?
12 Nígbà tí Olúwa ti ṣe iṣẹ́ rẹ̀ sí òkè Sioni àti Jerusalẹmu, yóò sọ wí pé, “Èmi yóò fi ìyà jẹ ọba Asiria nítorí gààrù àyà rẹ̀ àti ìgbéraga ojú rẹ̀.
I stanie się, że gdy Pan dokona całego swojego dzieła nad górą Syjonu i nad Jerozolimą, ukarzę owoc wyniosłego serca króla Asyrii i pychę jego zuchwałych oczu.
13 Nítorí ó sọ pé: “‘Pẹ̀lú agbára ọwọ́ mi ni mo fi ṣe èyí àti pẹ̀lú ọgbọ́n ọ̀n mi, nítorí mo ní òye. Mo mú ààlà àwọn orílẹ̀-èdè kúrò, mo sì ti kó ìṣúra wọn. Gẹ́gẹ́ bí alágbára kan, mo borí àwọn ọba wọn.
Mówi bowiem: Dokonałem [tego] mocą swojej ręki i własną mądrością, bo jestem mądry. Zniosłem granice narodów, zabrałem ich skarby i powaliłem mieszkańców jak mocarz.
14 Bí ènìyàn ti í tọwọ́ bọ ìtẹ́ ẹyẹ, bẹ́ẹ̀ ni ọwọ́ mi tẹ ọrọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè. Bí ènìyàn ti í kó ẹyin tí a kọ̀sílẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni mo kó àwọn orílẹ̀-èdè kò sí èyí tí ó fi apá lu apá, tàbí kí ó ya ẹnu láti dún.’”
Moja ręka sięgnęła po bogactwo narodów jak do gniazda. A jak się zbiera porzucone jajka, tak ja zgarnąłem całą ziemię; i nikt nawet skrzydłem nie poruszył, nie otworzył dzioba ani nie pisnął.
15 Ǹjẹ́ àáké le gbé ara rẹ̀ sókè kọjá ẹni tí ó ń fì í, tàbí kí ayùn fọ́nnu sí ẹni tí ó ń lò ó? Àfi bí ẹni pé ọ̀pá ó na ẹni tí ó gbé e sókè, tàbí kí kùmọ̀ lu èyí tí kì í ṣe igi.
Czy chełpi się siekiera wobec tego, który nią rąbie? Czy wynosi się piła nad tego, który nią piłuje? Jak gdyby rózga wywijała tym, który ją podnosi, jak gdyby kij podnosił się, jakby nie był drewnem.
16 Nítorí náà, ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, yóò rán ààrùn ìrẹ̀dànù sórí àwọn akíkanjú jagunjagun, lábẹ́ ògo rẹ̀ ni iná kan yóò ti sọ gẹ́gẹ́ bí iná ajónirun.
Dlatego Pan, PAN zastępów, ześle wycieńczenie na jego opasłych, a pod jego chwałą rozpali ogień, jakby płonący ogień.
17 Ìmọ́lẹ̀ Israẹli yóò di iná, Ẹni Mímọ́ rẹ̀ yóò jẹ́ ọ̀wọ́-iná, ní ọjọ́ kan ṣoṣo yóò jó yóò sì run àti ẹ̀gún àti ẹ̀wọ̀n.
A Światłość Izraela będzie ogniem, a jego Święty – płomieniem, który spali i strawi jego ciernie i osty w jednym dniu.
18 Gbogbo ẹwà igbó o rẹ̀, àti àwọn pápá ọlọ́ràá gbogbo rẹ̀ ni yóò run pátápátá, gẹ́gẹ́ bí ẹni tí ó ṣàìsàn ti í ṣòfò dànù.
Strawi także wspaniałość jego lasu i urodzajnych pól, od duszy aż do ciała, i stanie się tak jak [wtedy], gdy chorąży ucieka ze strachu.
19 Àwọn igi tí yóò kù nínú igbó o rẹ̀ yóò kéré níye, tí ọ̀dọ́mọdé yóò fi le kọ̀ wọ́n sílẹ̀.
A pozostałych drzew jego lasu będzie tak niewiele, że nawet dziecko będzie mogło je spisać.
20 Ní ọjọ́ náà, àwọn tí ó ṣẹ́kù ní Israẹli, àwọn tí ó yè ní ilé e Jakọbu, kò ní gbẹ́kẹ̀lé ẹni náà tí ó lù wọ́n bolẹ̀, ṣùgbọ́n ní òtítọ́ yóò gbẹ́kẹ̀lé Olúwa, Ẹni Mímọ́ Israẹli.
I w tym dniu stanie się, że resztka Izraela i ci, którzy ocaleli z domu Jakuba, nie będą już polegać na tym, który ich bije, lecz będą prawdziwie polegać na PANU, Świętym Izraela.
21 Àwọn ìyókù yóò padà, àwọn ìyókù ti Jakọbu yóò padà sí ọ̀dọ̀ Ọlọ́run Alágbára.
Resztka zawróci, resztka Jakuba, do Boga mocnego.
22 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn ènìyàn rẹ, ìwọ Israẹli dàbí yanrìn ní Òkun, ẹni díẹ̀ ni yóò padà. A ti pàṣẹ ìparun, àkúnwọ́sílẹ̀ àti òdodo.
Bo choćby twój lud, Izraelu, był jak piasek morski, [tylko] resztka z niego powróci. Postanowione wytracenie będzie opływało w sprawiedliwość.
23 Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni yóò mú un ṣẹ, ìparun tí a ti pàṣẹ rẹ̀ lórí gbogbo ilẹ̀ náà.
Pan BÓG zastępów dokona bowiem postanowionego wytracenia pośród całej tej ziemi.
24 Nítorí náà, báyìí ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “Ẹ̀yin ènìyàn mi tí ó ń gbé Sioni, ẹ má ṣe bẹ̀rù àwọn Asiria, tí ó ń fi ọ̀pá lù yín, tí wọ́n sì ń gbé ọ̀gọ tì yín bí Ejibiti ti ṣe.
Dlatego tak mówi Pan BÓG zastępów: Mój ludu, który mieszkasz na Syjonie, nie bój się Asyryjczyka. Uderzy cię rózgą i swą laskę podniesie na ciebie, [tak jak] Egipt.
25 Láìpẹ́, ìbínú mi sí i yín yóò wá sí òpin n ó sì dojú ìrunú mi kọ wọ́n, fún ìparun wọn.”
Jeszcze chwila bowiem, a skończy się mój gniew i moja zapalczywość – ku ich zniszczeniu.
26 Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò nà wọ́n ní ẹgba. Gẹ́gẹ́ bí ó ṣe lu Midiani ní òkè Orebu, yóò sì gbé ọ̀pá rẹ̀ lé orí omi gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe ní Ejibiti.
I PAN zastępów wzbudzi bicz na niego, jak podczas porażki Midianitów przy skale Oreba, i podniesie swą laskę tak, jak ją [podniósł] nad morzem, w Egipcie.
27 Ní ọjọ́ náà, a ó gbé ẹrù wọn kúrò ní èjìká a yín, àti àjàgà a wọn kúrò ní ọrùn un yín a ó fọ́ àjàgà náà, nítorí pé ẹ̀yin ó ti sanra.
I stanie się w tym dniu, że jego brzemię zostanie zdjęte z twoich ramion i jego jarzmo z twojej szyi, a to jarzmo zostanie zniszczone z powodu namaszczenia.
28 Wọ́n wọ Aiati, wọ́n gba Migroni kọjá, wọ́n kó nǹkan pamọ́ sí Mikmasi.
Przybył do Ajjat, przeszedł przez Migron, w Mikmas zostawił swój oręż.
29 Wọ́n ti rékọjá ọ̀nà, wọ́n wí pé, “Àwa ó tẹ̀dó sí Geba lóru yìí.” Rama mì tìtì Gibeah ti Saulu sálọ.
Przeszyli przełęcz, w Geba zanocowali; zlękła się Rama, uciekła Gibea Saula.
30 Gbé ohùn rẹ sókè, ìwọ ọmọbìnrin Galimu! Dẹ etí sílẹ̀, ìwọ Laiṣa! Ìwọ òtòṣì Anatoti!
Podnieś swój głos, córko Gallim! Niech słyszą w Laisz, biedny Anatot!
31 Madmena ti fẹsẹ̀ fẹ́ ẹ, àwọn ènìyàn Gebimu ti fi ara pamọ́.
Madmena ustąpiła, mieszkańcy Gabim szykują się [do ucieczki].
32 Ní ọjọ́ yìí, wọn yóò dúró ní Nobu wọn yóò kan sáárá, ní òkè ọmọbìnrin Sioni ní òkè Jerusalẹmu.
Jeszcze przez dzień zostanie w Nob, potrząśnie swoją ręką przeciwko córce Syjonu, wzgórzu Jerozolimy.
33 Wò ó, Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, yóò kán ẹ̀ka náà sọnù pẹ̀lú agbára. Àwọn igi ọlọ́lá ni a ó gé lulẹ̀ àwọn tí ó ga gogoro ni a ó rẹ̀ sílẹ̀.
Oto Pan, PAN zastępów odetnie latorośle gwałtownie. Wznoszące się wysoko zostaną ścięte, a wyniosłe będą poniżone.
34 Òun yóò gé igbó dídí pẹ̀lú àáké, Lebanoni yóò ṣubú níwájú Alágbára náà.
Wytnie także gęstwiny lasu siekierą, a Liban upadnie od wielmożnego.

< Isaiah 10 >