< Isaiah 10 >

1 Ègbé ni fún àwọn ti ń ṣe òfin àìṣòdodo,
Warra seera jalʼaa baasan, kanneen labsii cunqursaa labsaniif wayyoo;
2 láti dún àwọn aláìní ní ẹ̀tọ́ wọn àti láti fa ọwọ́ ìdájọ́ sẹ́yìn kúrò níwájú àwọn olùpọ́njú ènìyàn mi, wọ́n sọ àwọn ọ̀pọ̀ di ìjẹ fún wọn, wọ́n sì ń ja àwọn aláìní baba lólè.
isaan murtii rakkattootaa jalʼisu; mirga hiyyeeyyii saba koos ni dhiibu; haadhota hiyyeessaa boojuu godhatu; ijoollee abbaa hin qabnes ni saamu.
3 Kí ni ìwọ yóò ṣe ní ọjọ́ ìṣirò nígbà tí ìparun bá ti ọ̀nà jíjìn wá? Ta ni ìwọ yóò sá tọ̀ fún ìrànlọ́wọ́? Níbo ni ìwọ yóò fi ọrọ̀ rẹ sí?
Isin yeroo badiisni fagoodhaa dhufu guyyaa adabbiitti maal gootu? Gargaarsa argachuuf eenyutti baqattu? Qabeenya keessan eessatti dhiiftu?
4 Ohunkóhun kò ní ṣẹ́kù mọ́ bí kò ṣe láti tẹ̀ ba láàrín àwọn ìgbèkùn tàbí kí o ṣubú sáàrín àwọn tí a pa. Pẹ̀lú gbogbo nǹkan wọ̀nyí, ìbínú rẹ̀ kò kúrò, ọwọ́ rẹ̀ sì tún gbé sókè.
Warra boojiʼaman jala gugguufuu yookaan warra ajjeefaman jalatti kufuu malee homtuu hin hafu. Kana hundaan illee dheekkamsi isaa hin qabbanoofne; harki isaas amma iyyuu akkuma ol kaafametti jira.
5 “Ègbé ni fún àwọn ará Asiria, ọ̀gọ ìbínú mi, ní ọwọ́ ẹni tí kùmọ̀ ìbínú mi wà!
“Asooricha isa ulee aarii kootii taʼeef, isa bokkuun dheekkamsa kootii harka isaa jiruuf wayyoo!
6 Mo rán an sí orílẹ̀-èdè aláìní Ọlọ́run, mo dojú rẹ̀ kọ àwọn ènìyàn tí ó mú mi bínú láti já ẹrù gbà, àti láti kó ìkógun láti tẹ̀ mọ́lẹ̀ bí amọ̀ ní ojú òpópó.
Ani akka inni isaan saamuu fi boojiʼuuf akka inni akkuma dhoqqee karaa irraa lafatti isaan dhidhiituuf saba Waaqatti hin bulletti isa nan erga; uummata na aarsuttis isa nan ajaja.
7 Ṣùgbọ́n, èyí kì í ṣe ohun tí ó fẹ́ ṣe, èyí kọ́ ni ohun tí ó ní lọ́kàn; èrò rẹ̀ ni láti parun, láti fi òpin sí ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè.
Garuu kun waan inni yaadu miti; yaadni akkasiis garaa isaa keessa hin jiru; kaayyoon isaa barbadeessuu dha; saba baayʼees fixuu dha.
8 ‘Kì í ha ṣe pé ọba ni gbogbo àwọn aláṣẹ mi?’ ni Olúwa wí.
Innis akkana jedha; ‘Ajajjoonni koo hundinuu mootota mitii?
9 ‘Kì í ha ṣe pé Kalno dàbí i Karkemiṣi? Hamati kò ha dàbí i Arpadi, àti Samaria bí i Damasku?
Kaalnoon akkuma Karkemiish mitii? Hamaati akkuma Arfaad mitii? Samaariyaanis akkuma Damaasqoo mitii?
10 Gẹ́gẹ́ bí ọwọ́ mi ti gbá ìjọba àwọn òrìṣà mú, ìjọba tí ère rẹ̀ pọ̀ ju ti Jerusalẹmu àti Samaria lọ.
Akkuma harki koo mootummoota waaqota tolfamoo kanneen fakkiiwwan soofamoo kan Yerusaalemii fi Samaariyaa caalan qabe sana,
11 Èmi kì yóò a bá Jerusalẹmu wí àti àwọn ère rẹ̀?’” Gẹ́gẹ́ bí mo ṣe ṣe sí Samaria àti àwọn ère rẹ̀?
ani waanan Samaariyaa fi fakkiiwwan ishee godhe sana Yerusaalemii fi waaqota ishee tolfamoo hin godhuu?’”
12 Nígbà tí Olúwa ti ṣe iṣẹ́ rẹ̀ sí òkè Sioni àti Jerusalẹmu, yóò sọ wí pé, “Èmi yóò fi ìyà jẹ ọba Asiria nítorí gààrù àyà rẹ̀ àti ìgbéraga ojú rẹ̀.
Gooftaan yeroo Tulluu Xiyoon irrattii fi Yerusaalem keessatti hojii isaa hunda fixatutti akkana jedha; “Ani sababii of jajuu garaa isaatii fi ilaalcha isaa kan of tuulummaan guutame sanaatiif jedhee mooticha Asoor nan adaba.
13 Nítorí ó sọ pé: “‘Pẹ̀lú agbára ọwọ́ mi ni mo fi ṣe èyí àti pẹ̀lú ọgbọ́n ọ̀n mi, nítorí mo ní òye. Mo mú ààlà àwọn orílẹ̀-èdè kúrò, mo sì ti kó ìṣúra wọn. Gẹ́gẹ́ bí alágbára kan, mo borí àwọn ọba wọn.
Inni akkana jedhaatii: “‘Ani jabina harka kootiin waan kana hojjedheera; ani sababiin hubannaa qabuuf, ogummaa kootiin hojjedheera. Ani daangaa sabootaa iddoodhaa buqqiseera; qabeenya isaanii illee saameera. Akkuma nama jabaa tokkoo ani mootota isaanii of jala galfadheera.
14 Bí ènìyàn ti í tọwọ́ bọ ìtẹ́ ẹyẹ, bẹ́ẹ̀ ni ọwọ́ mi tẹ ọrọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè. Bí ènìyàn ti í kó ẹyin tí a kọ̀sílẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni mo kó àwọn orílẹ̀-èdè kò sí èyí tí ó fi apá lu apá, tàbí kí ó ya ẹnu láti dún.’”
Akkuma namni tokko manʼee simbiraa keessa harka kaaʼu sana anis harka koo qabeenya sabootaa keessa nan kaaʼa; akkuma namoonni hanqaaquu dagatame walitti qaban sana, anis biyya hunda walitti nan qabe; kan qoochoo hurgufate, yookaan wacuuf afaan banate tokko iyyuu hin turre.’”
15 Ǹjẹ́ àáké le gbé ara rẹ̀ sókè kọjá ẹni tí ó ń fì í, tàbí kí ayùn fọ́nnu sí ẹni tí ó ń lò ó? Àfi bí ẹni pé ọ̀pá ó na ẹni tí ó gbé e sókè, tàbí kí kùmọ̀ lu èyí tí kì í ṣe igi.
Qottoon nama ittiin waa murutti ni kooraa? Yookaan wanni ittiin waa muran nama itti fayyadamutti of jajaa? Kunis akka waan uleen tokko nama isa qabatutti of mirmirsuu ti; yookaan akkuma bokkuun tokko akka waan muka hin taʼiniitti ol of guddisuu ti!
16 Nítorí náà, ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, yóò rán ààrùn ìrẹ̀dànù sórí àwọn akíkanjú jagunjagun, lábẹ́ ògo rẹ̀ ni iná kan yóò ti sọ gẹ́gẹ́ bí iná ajónirun.
Kanaafuu Gooftaan, Waaqayyoon Waan Hunda Dandaʼu, loltoota gagabbatan kanatti dhukkuba nama huqqisu ni erga; ulfina isaa jalaanis ibiddi tokko akkuma arraba ibiddaa ni qabsiifama.
17 Ìmọ́lẹ̀ Israẹli yóò di iná, Ẹni Mímọ́ rẹ̀ yóò jẹ́ ọ̀wọ́-iná, ní ọjọ́ kan ṣoṣo yóò jó yóò sì run àti ẹ̀gún àti ẹ̀wọ̀n.
Ifni Israaʼel ibidda, Qulqullichi isaanii sunis arraba ibiddaa taʼa; ibiddi sun guyyuma tokkoon qoraattii isaatii fi sokorruu isaa gubee balleessa.
18 Gbogbo ẹwà igbó o rẹ̀, àti àwọn pápá ọlọ́ràá gbogbo rẹ̀ ni yóò run pátápátá, gẹ́gẹ́ bí ẹni tí ó ṣàìsàn ti í ṣòfò dànù.
Akkuma namni tokko yeroo dhukkubsatu huqqatu sana, ibiddi sun ulfina bosonaa isaatii fi lafa qotiisaa gabbataa, lubbuu fi foonis ni barbadeessa.
19 Àwọn igi tí yóò kù nínú igbó o rẹ̀ yóò kéré níye, tí ọ̀dọ́mọdé yóò fi le kọ̀ wọ́n sílẹ̀.
Mukkeen bosona isaa keessatti hafan waan akka malee muraasa taʼaniif mucaan tokko galmeessuu ni dandaʼa.
20 Ní ọjọ́ náà, àwọn tí ó ṣẹ́kù ní Israẹli, àwọn tí ó yè ní ilé e Jakọbu, kò ní gbẹ́kẹ̀lé ẹni náà tí ó lù wọ́n bolẹ̀, ṣùgbọ́n ní òtítọ́ yóò gbẹ́kẹ̀lé Olúwa, Ẹni Mímọ́ Israẹli.
Bara sana keessa hambaan Israaʼel, mana Yaaqoob keessaa warri hafan, dhugumaan Waaqayyo Qulqullicha Israaʼel abdatu malee lammata isa isaan dhaʼe sana hin abdatan.
21 Àwọn ìyókù yóò padà, àwọn ìyókù ti Jakọbu yóò padà sí ọ̀dọ̀ Ọlọ́run Alágbára.
Hambaan tokko, hambaan Yaaqoob gara Waaqa Jabaa sanaatti ni deebiʼa.
22 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn ènìyàn rẹ, ìwọ Israẹli dàbí yanrìn ní Òkun, ẹni díẹ̀ ni yóò padà. A ti pàṣẹ ìparun, àkúnwọ́sílẹ̀ àti òdodo.
Yaa Israaʼel, yoo sabni kee akkuma cirracha qarqara galaanaa taʼe iyyuu, hambaa qofatu deebiʼa. Badiisni qajeelummaadhaan guutame labsameera.
23 Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni yóò mú un ṣẹ, ìparun tí a ti pàṣẹ rẹ̀ lórí gbogbo ilẹ̀ náà.
Gooftaan, Waaqayyoon Waan Hunda Dandaʼu badiisa lafa hundatti labsame ni raawwata.
24 Nítorí náà, báyìí ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “Ẹ̀yin ènìyàn mi tí ó ń gbé Sioni, ẹ má ṣe bẹ̀rù àwọn Asiria, tí ó ń fi ọ̀pá lù yín, tí wọ́n sì ń gbé ọ̀gọ tì yín bí Ejibiti ti ṣe.
Kanaafuu Gooftaan, Waaqayyoon Waan Hunda Dandaʼu akkana jedha: “Yaa saba koo warri Xiyoon keessa jiraattan, warra Asoor kanneen uleedhaan isin rukutan, kanneen akkuma warra Gibxi bokkuu ol isinitti fudhatan hin sodaatinaa.
25 Láìpẹ́, ìbínú mi sí i yín yóò wá sí òpin n ó sì dojú ìrunú mi kọ wọ́n, fún ìparun wọn.”
Aariin ani isinitti aare dafee qabbanaaʼa; dheekkamsi koos isaan balleessuuf itti garagala.”
26 Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò nà wọ́n ní ẹgba. Gẹ́gẹ́ bí ó ṣe lu Midiani ní òkè Orebu, yóò sì gbé ọ̀pá rẹ̀ lé orí omi gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe ní Ejibiti.
Waaqayyon Waan Hunda Dandaʼu sun, akkuma kattaa Hereeb biratti Midiyaanin qacceen garafe sana, akkuma biyya Gibxi keessatti godhe sana, ulee isaa bishaan irratti ol fudhata.
27 Ní ọjọ́ náà, a ó gbé ẹrù wọn kúrò ní èjìká a yín, àti àjàgà a wọn kúrò ní ọrùn un yín a ó fọ́ àjàgà náà, nítorí pé ẹ̀yin ó ti sanra.
Gaafas baʼaan isaanii gatiittii keessan irraa, waanjoon isaaniis morma keessan irraa fuudhama; waan isin akka malee gabbattaniif waanjoon ni caccaba.
28 Wọ́n wọ Aiati, wọ́n gba Migroni kọjá, wọ́n kó nǹkan pamọ́ sí Mikmasi.
Isaan gara Ayyati seenan; Migroon keessa baʼan; nyaataa fi hidhata isaaniis Mikmaas keessatti kuuftan.
29 Wọ́n ti rékọjá ọ̀nà, wọ́n wí pé, “Àwa ó tẹ̀dó sí Geba lóru yìí.” Rama mì tìtì Gibeah ti Saulu sálọ.
Isaan karaa qalʼaa irra baʼanii, “Nu Gebaa qubannee bulla” jedhan. Raamaan ni sodaatti; Gibeʼaan Saaʼolis ni baqatti.
30 Gbé ohùn rẹ sókè, ìwọ ọmọbìnrin Galimu! Dẹ etí sílẹ̀, ìwọ Laiṣa! Ìwọ òtòṣì Anatoti!
Yaa intala Galiim, iyyi! Yaa Laayishaa dhaggeeffadhu! Yaa Anaatoot deebii isheef kenni!
31 Madmena ti fẹsẹ̀ fẹ́ ẹ, àwọn ènìyàn Gebimu ti fi ara pamọ́.
Maadmenaan baqataa jirti; uummanni Geebiimis baqachuuf walitti qabama.
32 Ní ọjọ́ yìí, wọn yóò dúró ní Nobu wọn yóò kan sáárá, ní òkè ọmọbìnrin Sioni ní òkè Jerusalẹmu.
Isaan harʼa Noob gaʼu; isaan tulluu Intala Xiyoonitti, gaara Yerusaalemitti harka isaanii raasu.
33 Wò ó, Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, yóò kán ẹ̀ka náà sọnù pẹ̀lú agbára. Àwọn igi ọlọ́lá ni a ó gé lulẹ̀ àwọn tí ó ga gogoro ni a ó rẹ̀ sílẹ̀.
Kunoo Gooftaan, Waaqayyoon Waan Hunda Dandaʼu, humna guddaadhaan dameewwan murmura; mukkeen gurguddaan ni cicciramu; mukkeen dhedheeroonis gad qabamu.
34 Òun yóò gé igbó dídí pẹ̀lú àáké, Lebanoni yóò ṣubú níwájú Alágbára náà.
Inni bosona gobbuu qottoodhaan cira; Libaanoonis fuula Waaqa Jabaa duratti kufa.

< Isaiah 10 >