< Isaiah 10 >

1 Ègbé ni fún àwọn ti ń ṣe òfin àìṣòdodo,
Ak vai, tiem, kas ceļ netaisnus likumus, un tiem rakstītājiem, kas raksta grūtu tiesu,
2 láti dún àwọn aláìní ní ẹ̀tọ́ wọn àti láti fa ọwọ́ ìdájọ́ sẹ́yìn kúrò níwájú àwọn olùpọ́njú ènìyàn mi, wọ́n sọ àwọn ọ̀pọ̀ di ìjẹ fún wọn, wọ́n sì ń ja àwọn aláìní baba lólè.
Ka nabagiem tiesu neizdod un tiesu laupa tiem bēdīgiem starp Maniem ļaudīm, ka atraitnes aplaupa un bāriņus posta!
3 Kí ni ìwọ yóò ṣe ní ọjọ́ ìṣirò nígbà tí ìparun bá ti ọ̀nà jíjìn wá? Ta ni ìwọ yóò sá tọ̀ fún ìrànlọ́wọ́? Níbo ni ìwọ yóò fi ọrọ̀ rẹ sí?
Bet ko jūs darīsiet piemeklēšanas dienā un tai postā, kas nāk no tālienes? Pie kā bēgsiet pēc palīdzības, un kur glabāsiet savu godību?
4 Ohunkóhun kò ní ṣẹ́kù mọ́ bí kò ṣe láti tẹ̀ ba láàrín àwọn ìgbèkùn tàbí kí o ṣubú sáàrín àwọn tí a pa. Pẹ̀lú gbogbo nǹkan wọ̀nyí, ìbínú rẹ̀ kò kúrò, ọwọ́ rẹ̀ sì tún gbé sókè.
Bet jūs locīsities starp gūstītiem un kritīsiet starp nokautiem. Ar visu to Viņa dusmība nenovēršas, un Viņa roka vēl ir izstiepta.
5 “Ègbé ni fún àwọn ará Asiria, ọ̀gọ ìbínú mi, ní ọwọ́ ẹni tí kùmọ̀ ìbínú mi wà!
Ak vai, Asuram! Tas ir Manas dusmības rīkste, un viņa rokā Manas bardzības zizlis.
6 Mo rán an sí orílẹ̀-èdè aláìní Ọlọ́run, mo dojú rẹ̀ kọ àwọn ènìyàn tí ó mú mi bínú láti já ẹrù gbà, àti láti kó ìkógun láti tẹ̀ mọ́lẹ̀ bí amọ̀ ní ojú òpópó.
Es viņu sūtu pret viltīgiem ļaudīm un viņam pavēlu pret ļaudīm, par kuriem Es apskaities, lai viņš tos laupīdams laupa un postīdams posta, un tos samin kā dubļus uz ielām.
7 Ṣùgbọ́n, èyí kì í ṣe ohun tí ó fẹ́ ṣe, èyí kọ́ ni ohun tí ó ní lọ́kàn; èrò rẹ̀ ni láti parun, láti fi òpin sí ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè.
Bet viņam tā nešķiet, un viņa sirds tā nedomā; jo viņš apņēmies izdeldēt un izsakņot daudz tautas.
8 ‘Kì í ha ṣe pé ọba ni gbogbo àwọn aláṣẹ mi?’ ni Olúwa wí.
Jo viņš saka: vai mani virsnieki visi kopā nav ķēniņi?
9 ‘Kì í ha ṣe pé Kalno dàbí i Karkemiṣi? Hamati kò ha dàbí i Arpadi, àti Samaria bí i Damasku?
Vai Kalno nav kā Karķemis? Vai Hamata nav kā Arvada? Vai Samarija nav kā Damaskus?
10 Gẹ́gẹ́ bí ọwọ́ mi ti gbá ìjọba àwọn òrìṣà mú, ìjọba tí ère rẹ̀ pọ̀ ju ti Jerusalẹmu àti Samaria lọ.
Tā kā mana roka dabūjusi tās elku dievu valstis, jebšu viņu dievekļu bija vairāk nekā to, kas Jeruzālemē un Samarijā, -
11 Èmi kì yóò a bá Jerusalẹmu wí àti àwọn ère rẹ̀?’” Gẹ́gẹ́ bí mo ṣe ṣe sí Samaria àti àwọn ère rẹ̀?
Vai es nevarētu darīt pie Jeruzālemes un pie viņas elkiem tāpat, kā esmu darījis pie Samarijas un viņas elkiem?
12 Nígbà tí Olúwa ti ṣe iṣẹ́ rẹ̀ sí òkè Sioni àti Jerusalẹmu, yóò sọ wí pé, “Èmi yóò fi ìyà jẹ ọba Asiria nítorí gààrù àyà rẹ̀ àti ìgbéraga ojú rẹ̀.
Bet kad Tas Kungs visu Savu darbu būs pabeidzis Ciānas kalnā un Jeruzālemē, tad (sacīs): Es piemeklēšu to sirds lepnības augli pie Asīrijas ķēniņa un viņa acu augsto greznību.
13 Nítorí ó sọ pé: “‘Pẹ̀lú agbára ọwọ́ mi ni mo fi ṣe èyí àti pẹ̀lú ọgbọ́n ọ̀n mi, nítorí mo ní òye. Mo mú ààlà àwọn orílẹ̀-èdè kúrò, mo sì ti kó ìṣúra wọn. Gẹ́gẹ́ bí alágbára kan, mo borí àwọn ọba wọn.
Jo tas saka: caur savas rokas spēku es to esmu darījis un caur savu gudrību, jo es esmu prātīgs. Es esmu atņēmis tautu robežas un laupījis viņu mantas un kā varonis zemē gāzis valdniekus.
14 Bí ènìyàn ti í tọwọ́ bọ ìtẹ́ ẹyẹ, bẹ́ẹ̀ ni ọwọ́ mi tẹ ọrọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè. Bí ènìyàn ti í kó ẹyin tí a kọ̀sílẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni mo kó àwọn orílẹ̀-èdè kò sí èyí tí ó fi apá lu apá, tàbí kí ó ya ẹnu láti dún.’”
Un mana roka atradusi tautu bagātību kā ligzdu, un es esmu sagrābis visu pasauli, kā sagrābj atstātas olas, un neviens nav bijis, kas spārnu būtu kustinājis vai muti atdarījis vai pīkstējis.
15 Ǹjẹ́ àáké le gbé ara rẹ̀ sókè kọjá ẹni tí ó ń fì í, tàbí kí ayùn fọ́nnu sí ẹni tí ó ń lò ó? Àfi bí ẹni pé ọ̀pá ó na ẹni tí ó gbé e sókè, tàbí kí kùmọ̀ lu èyí tí kì í ṣe igi.
Vai tad cirvis lai lielās pret to, kas ar to cērt? Jeb vai zāģis lai turas pretī tam, kas to velk! tā kā zizlis to turētu, kas viņu paceļ, tā kā rīkste to cilātu, kas nav koks!
16 Nítorí náà, ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, yóò rán ààrùn ìrẹ̀dànù sórí àwọn akíkanjú jagunjagun, lábẹ́ ògo rẹ̀ ni iná kan yóò ti sọ gẹ́gẹ́ bí iná ajónirun.
Tādēļ Tas Kungs Dievs Cebaot sūtīs diloni starp viņa (Asura) trekniem, un apakš viņa godības dedzin degs, kā uguns deg.
17 Ìmọ́lẹ̀ Israẹli yóò di iná, Ẹni Mímọ́ rẹ̀ yóò jẹ́ ọ̀wọ́-iná, ní ọjọ́ kan ṣoṣo yóò jó yóò sì run àti ẹ̀gún àti ẹ̀wọ̀n.
Un Israēla gaišums būs uguns, un viņa Svētais būs liesma, kas sadedzinās un norīs viņa ērkšķus un dadžus vienā dienā.
18 Gbogbo ẹwà igbó o rẹ̀, àti àwọn pápá ọlọ́ràá gbogbo rẹ̀ ni yóò run pátápátá, gẹ́gẹ́ bí ẹni tí ó ṣàìsàn ti í ṣòfò dànù.
Un viņš aprīs viņa meža un viņa dārza godību, līdz ar dvēseli un miesu, un tas novārgs kā vārgulis.
19 Àwọn igi tí yóò kù nínú igbó o rẹ̀ yóò kéré níye, tí ọ̀dọ́mọdé yóò fi le kọ̀ wọ́n sílẹ̀.
Un viņa meža atlikušie koki būs mazs pulciņš, ka zēns tos varētu sarakstīt.
20 Ní ọjọ́ náà, àwọn tí ó ṣẹ́kù ní Israẹli, àwọn tí ó yè ní ilé e Jakọbu, kò ní gbẹ́kẹ̀lé ẹni náà tí ó lù wọ́n bolẹ̀, ṣùgbọ́n ní òtítọ́ yóò gbẹ́kẹ̀lé Olúwa, Ẹni Mímọ́ Israẹli.
Tanī dienā Israēla atlikušie, un Jēkaba nama izglābtie nepaļausies vairs uz to, kas viņu sitis, bet uzticībā paļausies uz To Kungu, to Svēto iekš Israēla.
21 Àwọn ìyókù yóò padà, àwọn ìyókù ti Jakọbu yóò padà sí ọ̀dọ̀ Ọlọ́run Alágbára.
Tie atlikušie atgriezīsies, Jēkaba atlikušie, pie tā visuvarenā Dieva.
22 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn ènìyàn rẹ, ìwọ Israẹli dàbí yanrìn ní Òkun, ẹni díẹ̀ ni yóò padà. A ti pàṣẹ ìparun, àkúnwọ́sílẹ̀ àti òdodo.
Jo jebšu tavi ļaudis, Israēl, ir kā jūras smiltis, tomēr (tikai) viņu atlikums atgriezīsies. Jo gals ir nospriests pilnīgā taisnībā.
23 Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni yóò mú un ṣẹ, ìparun tí a ti pàṣẹ rẹ̀ lórí gbogbo ilẹ̀ náà.
Jo Tas Kungs Dievs Cebaot nolikto gala spriedumu izdarīs pa visu zemes virsu.
24 Nítorí náà, báyìí ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “Ẹ̀yin ènìyàn mi tí ó ń gbé Sioni, ẹ má ṣe bẹ̀rù àwọn Asiria, tí ó ń fi ọ̀pá lù yín, tí wọ́n sì ń gbé ọ̀gọ tì yín bí Ejibiti ti ṣe.
Tāpēc Tas Kungs Dievs Cebaot saka tā: Mani ļaudis, kas dzīvojat Ciānā, nebīstaties no Asura, kad tas jūs sit ar rīksti, un savu zizli paceļ pret jums, kā notika Ēģiptē.
25 Láìpẹ́, ìbínú mi sí i yín yóò wá sí òpin n ó sì dojú ìrunú mi kọ wọ́n, fún ìparun wọn.”
Jo vēl mazs brīdis, tad dusmība būs pagalam, un Mana bardzība tos izdeldēs.
26 Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò nà wọ́n ní ẹgba. Gẹ́gẹ́ bí ó ṣe lu Midiani ní òkè Orebu, yóò sì gbé ọ̀pá rẹ̀ lé orí omi gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe ní Ejibiti.
Jo Tas Kungs Cebaot pacels pātagu pret to, kā Viņš sita Midijanu pie Horeba kalna, un Ciņa zizlis ir pār jūru un viņš to paceļ kā Ēģiptes zemē.
27 Ní ọjọ́ náà, a ó gbé ẹrù wọn kúrò ní èjìká a yín, àti àjàgà a wọn kúrò ní ọrùn un yín a ó fọ́ àjàgà náà, nítorí pé ẹ̀yin ó ti sanra.
Un tai dienā viņa nasta atstāsies no tava kamieša un viņa jūgs no tava kakla, un tas jūgs šķīdīs no treknuma.
28 Wọ́n wọ Aiati, wọ́n gba Migroni kọjá, wọ́n kó nǹkan pamọ́ sí Mikmasi.
Tas nāk uz Ajatu, tas iet caur Migronu, Mikmasā tas atstāj savas lietas.
29 Wọ́n ti rékọjá ọ̀nà, wọ́n wí pé, “Àwa ó tẹ̀dó sí Geba lóru yìí.” Rama mì tìtì Gibeah ti Saulu sálọ.
Tie iet caur šaurumu, Ģebā tie paliek par nakti, Rāma dreb, Saula Ģibeja bēg.
30 Gbé ohùn rẹ sókè, ìwọ ọmọbìnrin Galimu! Dẹ etí sílẹ̀, ìwọ Laiṣa! Ìwọ òtòṣì Anatoti!
Kliedz stiprā balsī, Galima meita! Klausies, Laīša! nabaga Anatota!
31 Madmena ti fẹsẹ̀ fẹ́ ẹ, àwọn ènìyàn Gebimu ti fi ara pamọ́.
Madmena bēg, Ģebimas iedzīvotāji glābjās.
32 Ní ọjọ́ yìí, wọn yóò dúró ní Nobu wọn yóò kan sáárá, ní òkè ọmọbìnrin Sioni ní òkè Jerusalẹmu.
Vēl šodien tas apmetīsies Nobā, pacels roku pret Ciānas meitas kalnu, pret Jeruzālemes pakalnu.
33 Wò ó, Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, yóò kán ẹ̀ka náà sọnù pẹ̀lú agbára. Àwọn igi ọlọ́lá ni a ó gé lulẹ̀ àwọn tí ó ga gogoro ni a ó rẹ̀ sílẹ̀.
Redzi, Tas Kungs Dievs Cebaot nokapā tos zarus ar briesmīgu varu, un tie, kas ir augsti augumā, top nocirsti, un tie lielie pazemoti.
34 Òun yóò gé igbó dídí pẹ̀lú àáké, Lebanoni yóò ṣubú níwájú Alágbára náà.
Un Viņš nocērt ar dzelzi biezos meža krūmus, un Lībanus krīt caur vareno.

< Isaiah 10 >