< Isaiah 10 >

1 Ègbé ni fún àwọn ti ń ṣe òfin àìṣòdodo,
Malheur à ceux qui décrètent des ordonnances injustes, Et aux rédacteurs qui écrivent des ordonnances oppressives
2 láti dún àwọn aláìní ní ẹ̀tọ́ wọn àti láti fa ọwọ́ ìdájọ́ sẹ́yìn kúrò níwájú àwọn olùpọ́njú ènìyàn mi, wọ́n sọ àwọn ọ̀pọ̀ di ìjẹ fún wọn, wọ́n sì ń ja àwọn aláìní baba lólè.
pour priver de justice les indigents, Et pour dépouiller de leurs droits les pauvres de mon peuple, Afin que les veuves soient leur butin, Et qu'ils fassent de l'orphelin leur proie!
3 Kí ni ìwọ yóò ṣe ní ọjọ́ ìṣirò nígbà tí ìparun bá ti ọ̀nà jíjìn wá? Ta ni ìwọ yóò sá tọ̀ fún ìrànlọ́wọ́? Níbo ni ìwọ yóò fi ọrọ̀ rẹ sí?
Que ferez-vous au jour du châtiment, au jour de la désolation qui viendra de loin? Vers qui fuiras-tu pour demander du secours? Où laisserez-vous vos richesses?
4 Ohunkóhun kò ní ṣẹ́kù mọ́ bí kò ṣe láti tẹ̀ ba láàrín àwọn ìgbèkùn tàbí kí o ṣubú sáàrín àwọn tí a pa. Pẹ̀lú gbogbo nǹkan wọ̀nyí, ìbínú rẹ̀ kò kúrò, ọwọ́ rẹ̀ sì tún gbé sókè.
Ils ne se prosterneront que sous les prisonniers, et tomberont sous les morts. Pour autant, sa colère n'est pas détournée, mais sa main est encore tendue.
5 “Ègbé ni fún àwọn ará Asiria, ọ̀gọ ìbínú mi, ní ọwọ́ ẹni tí kùmọ̀ ìbínú mi wà!
Hélas Assyrien, la verge de ma colère, le bâton dans la main duquel est ma fureur!
6 Mo rán an sí orílẹ̀-èdè aláìní Ọlọ́run, mo dojú rẹ̀ kọ àwọn ènìyàn tí ó mú mi bínú láti já ẹrù gbà, àti láti kó ìkógun láti tẹ̀ mọ́lẹ̀ bí amọ̀ ní ojú òpópó.
Je l'envoie contre une nation profane, et contre le peuple qui m'irrite, je lui donne l'ordre de prendre le pillage et le butin, et de les fouler comme la boue des rues.
7 Ṣùgbọ́n, èyí kì í ṣe ohun tí ó fẹ́ ṣe, èyí kọ́ ni ohun tí ó ní lọ́kàn; èrò rẹ̀ ni láti parun, láti fi òpin sí ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè.
Mais ce n'est pas ce qu'il veut, et ce n'est pas ce que son cœur pense; mais il a dans le cœur de détruire, et d'exterminer non pas quelques nations.
8 ‘Kì í ha ṣe pé ọba ni gbogbo àwọn aláṣẹ mi?’ ni Olúwa wí.
Car il dit: « Tous mes princes ne sont-ils pas des rois?
9 ‘Kì í ha ṣe pé Kalno dàbí i Karkemiṣi? Hamati kò ha dàbí i Arpadi, àti Samaria bí i Damasku?
Calno n'est-elle pas comme Carménich? Hamath n`est-elle pas comme Arpad? Samarie n'est-elle pas comme Damas? »
10 Gẹ́gẹ́ bí ọwọ́ mi ti gbá ìjọba àwọn òrìṣà mú, ìjọba tí ère rẹ̀ pọ̀ ju ti Jerusalẹmu àti Samaria lọ.
Comme ma main a trouvé les royaumes des idoles, dont les images gravées dépassaient celles de Jérusalem et de Samarie,
11 Èmi kì yóò a bá Jerusalẹmu wí àti àwọn ère rẹ̀?’” Gẹ́gẹ́ bí mo ṣe ṣe sí Samaria àti àwọn ère rẹ̀?
ne ferai-je pas, comme j'ai fait à Samarie et à ses idoles, à Jérusalem et à ses idoles?
12 Nígbà tí Olúwa ti ṣe iṣẹ́ rẹ̀ sí òkè Sioni àti Jerusalẹmu, yóò sọ wí pé, “Èmi yóò fi ìyà jẹ ọba Asiria nítorí gààrù àyà rẹ̀ àti ìgbéraga ojú rẹ̀.
C'est pourquoi, lorsque l'Éternel aura accompli toute son œuvre sur la montagne de Sion et sur Jérusalem, je punirai le fruit du cœur orgueilleux et volontaire du roi d'Assyrie, et l'insolence de ses regards arrogants.
13 Nítorí ó sọ pé: “‘Pẹ̀lú agbára ọwọ́ mi ni mo fi ṣe èyí àti pẹ̀lú ọgbọ́n ọ̀n mi, nítorí mo ní òye. Mo mú ààlà àwọn orílẹ̀-èdè kúrò, mo sì ti kó ìṣúra wọn. Gẹ́gẹ́ bí alágbára kan, mo borí àwọn ọba wọn.
Car il a dit: « C'est par la force de ma main que j'ai agi, et par ma sagesse, car j'ai de l'intelligence. J'ai fait disparaître les limites des peuples, et j'ai dérobé leurs trésors. Comme un vaillant homme, j'ai abattu leurs chefs.
14 Bí ènìyàn ti í tọwọ́ bọ ìtẹ́ ẹyẹ, bẹ́ẹ̀ ni ọwọ́ mi tẹ ọrọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè. Bí ènìyàn ti í kó ẹyin tí a kọ̀sílẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni mo kó àwọn orílẹ̀-èdè kò sí èyí tí ó fi apá lu apá, tàbí kí ó ya ẹnu láti dún.’”
Ma main a trouvé les richesses des peuples comme un nid, et comme on recueille des œufs abandonnés, j'ai recueilli toute la terre. Il n'y en a pas un qui ait remué l'aile, qui ait ouvert la bouche, ou qui ait gazouillé. »
15 Ǹjẹ́ àáké le gbé ara rẹ̀ sókè kọjá ẹni tí ó ń fì í, tàbí kí ayùn fọ́nnu sí ẹni tí ó ń lò ó? Àfi bí ẹni pé ọ̀pá ó na ẹni tí ó gbé e sókè, tàbí kí kùmọ̀ lu èyí tí kì í ṣe igi.
La hache se vante-t-elle de celui qui coupe? La scie doit-elle s'élever au-dessus de celui qui la scie? Comme si une verge devait élever ceux qui la soulèvent, ou comme si un bâton devait élever quelqu'un qui n'est pas du bois.
16 Nítorí náà, ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, yóò rán ààrùn ìrẹ̀dànù sórí àwọn akíkanjú jagunjagun, lábẹ́ ògo rẹ̀ ni iná kan yóò ti sọ gẹ́gẹ́ bí iná ajónirun.
C'est pourquoi l'Éternel, l'Éternel des armées, enverra parmi ses gros la maigreur, et sous sa gloire s'allumera une ardeur comme celle d'un feu.
17 Ìmọ́lẹ̀ Israẹli yóò di iná, Ẹni Mímọ́ rẹ̀ yóò jẹ́ ọ̀wọ́-iná, ní ọjọ́ kan ṣoṣo yóò jó yóò sì run àti ẹ̀gún àti ẹ̀wọ̀n.
La lumière d'Israël sera comme un feu, et son Saint comme une flamme; et il brûlera et dévorera ses épines et ses ronces en un seul jour.
18 Gbogbo ẹwà igbó o rẹ̀, àti àwọn pápá ọlọ́ràá gbogbo rẹ̀ ni yóò run pátápátá, gẹ́gẹ́ bí ẹni tí ó ṣàìsàn ti í ṣòfò dànù.
Il consumera la gloire de sa forêt et de son champ fertile, l'âme et le corps. Ce sera comme lorsqu'un porte-étendard s'évanouit.
19 Àwọn igi tí yóò kù nínú igbó o rẹ̀ yóò kéré níye, tí ọ̀dọ́mọdé yóò fi le kọ̀ wọ́n sílẹ̀.
Le reste des arbres de sa forêt sera peu nombreux, au point qu'un enfant pourrait écrire leur nombre.
20 Ní ọjọ́ náà, àwọn tí ó ṣẹ́kù ní Israẹli, àwọn tí ó yè ní ilé e Jakọbu, kò ní gbẹ́kẹ̀lé ẹni náà tí ó lù wọ́n bolẹ̀, ṣùgbọ́n ní òtítọ́ yóò gbẹ́kẹ̀lé Olúwa, Ẹni Mímọ́ Israẹli.
En ce jour-là, le reste d'Israël et les réchappés de la maison de Jacob ne s'appuieront plus sur celui qui les frappait, mais ils s'appuieront sur Yahvé, le Saint d'Israël, dans la vérité.
21 Àwọn ìyókù yóò padà, àwọn ìyókù ti Jakọbu yóò padà sí ọ̀dọ̀ Ọlọ́run Alágbára.
Un reste reviendra, le reste de Jacob, vers le Dieu puissant.
22 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn ènìyàn rẹ, ìwọ Israẹli dàbí yanrìn ní Òkun, ẹni díẹ̀ ni yóò padà. A ti pàṣẹ ìparun, àkúnwọ́sílẹ̀ àti òdodo.
Car si ton peuple, Israël, est comme le sable de la mer, un reste seulement reviendra. Une destruction est prévue, débordante de justice.
23 Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni yóò mú un ṣẹ, ìparun tí a ti pàṣẹ rẹ̀ lórí gbogbo ilẹ̀ náà.
Car l'Éternel, le Yahvé des armées, fera une destruction complète, et déterminée, sur toute la terre.
24 Nítorí náà, báyìí ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “Ẹ̀yin ènìyàn mi tí ó ń gbé Sioni, ẹ má ṣe bẹ̀rù àwọn Asiria, tí ó ń fi ọ̀pá lù yín, tí wọ́n sì ń gbé ọ̀gọ tì yín bí Ejibiti ti ṣe.
C'est pourquoi l'Éternel, le Yahvé des armées, dit: « Mon peuple qui habite Sion, ne craignez pas l'Assyrien, même s'il vous frappe de sa verge et qu'il lève son bâton contre vous, comme l'Égypte.
25 Láìpẹ́, ìbínú mi sí i yín yóò wá sí òpin n ó sì dojú ìrunú mi kọ wọ́n, fún ìparun wọn.”
Car encore un tout petit moment, et l'indignation contre vous s'accomplira, et ma colère se portera sur sa destruction. »
26 Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò nà wọ́n ní ẹgba. Gẹ́gẹ́ bí ó ṣe lu Midiani ní òkè Orebu, yóò sì gbé ọ̀pá rẹ̀ lé orí omi gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe ní Ejibiti.
Yahvé des armées suscitera contre lui un fléau, comme lors du massacre de Madian au rocher d'Oreb. Sa verge sera au-dessus de la mer, et il la lèvera comme il l'a fait contre l'Égypte.
27 Ní ọjọ́ náà, a ó gbé ẹrù wọn kúrò ní èjìká a yín, àti àjàgà a wọn kúrò ní ọrùn un yín a ó fọ́ àjàgà náà, nítorí pé ẹ̀yin ó ti sanra.
En ce jour-là, son fardeau disparaîtra de ton épaule, et son joug de ton cou, et le joug sera détruit à cause de l'huile d'onction.
28 Wọ́n wọ Aiati, wọ́n gba Migroni kọjá, wọ́n kó nǹkan pamọ́ sí Mikmasi.
Il est arrivé à Aiath. Il passe par Migron. A Michmash, il range ses bagages.
29 Wọ́n ti rékọjá ọ̀nà, wọ́n wí pé, “Àwa ó tẹ̀dó sí Geba lóru yìí.” Rama mì tìtì Gibeah ti Saulu sálọ.
Ils ont franchi le col. Ils se logent à Guéba. Rama tremble. Gibéa de Saül s'est enfuie.
30 Gbé ohùn rẹ sókè, ìwọ ọmọbìnrin Galimu! Dẹ etí sílẹ̀, ìwọ Laiṣa! Ìwọ òtòṣì Anatoti!
Crie de ta voix, fille de Gallim! Écoute, Laisha! Pauvre Anathoth!
31 Madmena ti fẹsẹ̀ fẹ́ ẹ, àwọn ènìyàn Gebimu ti fi ara pamọ́.
Madmena est une fugitive. Les habitants de Guébim fuient pour se mettre en sûreté.
32 Ní ọjọ́ yìí, wọn yóò dúró ní Nobu wọn yóò kan sáárá, ní òkè ọmọbìnrin Sioni ní òkè Jerusalẹmu.
Aujourd'hui même, il s'arrête à Nob. Il serre la main à la montagne de la fille de Sion, à la colline de Jérusalem.
33 Wò ó, Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, yóò kán ẹ̀ka náà sọnù pẹ̀lú agbára. Àwọn igi ọlọ́lá ni a ó gé lulẹ̀ àwọn tí ó ga gogoro ni a ó rẹ̀ sílẹ̀.
Voici que le Seigneur, l'Éternel des armées, fauche les rameaux avec terreur. Les grands seront abattus, et les grands seront abaissés.
34 Òun yóò gé igbó dídí pẹ̀lú àáké, Lebanoni yóò ṣubú níwájú Alágbára náà.
Ilabattra avec le fer les fourrés de la forêt, et le Liban tombera sous les coups du Puissant.

< Isaiah 10 >