< Isaiah 10 >

1 Ègbé ni fún àwọn ti ń ṣe òfin àìṣòdodo,
Wo to them that maken wickid lawis, and thei writynge han wryte vnriytfulnesse, for to oppresse pore men in doom,
2 láti dún àwọn aláìní ní ẹ̀tọ́ wọn àti láti fa ọwọ́ ìdájọ́ sẹ́yìn kúrò níwájú àwọn olùpọ́njú ènìyàn mi, wọ́n sọ àwọn ọ̀pọ̀ di ìjẹ fún wọn, wọ́n sì ń ja àwọn aláìní baba lólè.
and to do violence to the cause of meke men of my puple; that widewis schulen be the prey of them, and that thei schulden rauysche fadirles children.
3 Kí ni ìwọ yóò ṣe ní ọjọ́ ìṣirò nígbà tí ìparun bá ti ọ̀nà jíjìn wá? Ta ni ìwọ yóò sá tọ̀ fún ìrànlọ́wọ́? Níbo ni ìwọ yóò fi ọrọ̀ rẹ sí?
What schulen ye do in the dai of visitacioun, and of wretchidnesse comynge fro fer? To whos help schulen ye fle? and where schulen ye leeue youre glorie,
4 Ohunkóhun kò ní ṣẹ́kù mọ́ bí kò ṣe láti tẹ̀ ba láàrín àwọn ìgbèkùn tàbí kí o ṣubú sáàrín àwọn tí a pa. Pẹ̀lú gbogbo nǹkan wọ̀nyí, ìbínú rẹ̀ kò kúrò, ọwọ́ rẹ̀ sì tún gbé sókè.
that ye be not bowid doun vndur boond, and falle not doun with slayn men? On alle these thingis his strong veniaunce is not turned awei, but yit his hond is stretchid forth.
5 “Ègbé ni fún àwọn ará Asiria, ọ̀gọ ìbínú mi, ní ọwọ́ ẹni tí kùmọ̀ ìbínú mi wà!
Wo to Assur, he is the yerde and staf of my strong veniaunce; myn indignacioun is in the hond of them.
6 Mo rán an sí orílẹ̀-èdè aláìní Ọlọ́run, mo dojú rẹ̀ kọ àwọn ènìyàn tí ó mú mi bínú láti já ẹrù gbà, àti láti kó ìkógun láti tẹ̀ mọ́lẹ̀ bí amọ̀ ní ojú òpópó.
Y schal send hym to a fals folk, and Y schal comaunde to hym ayens the puple of my strong veniaunce; that he take awei the spuylis, and departe prey, and that he sette that puple in to defouling, as the fen of stretis.
7 Ṣùgbọ́n, èyí kì í ṣe ohun tí ó fẹ́ ṣe, èyí kọ́ ni ohun tí ó ní lọ́kàn; èrò rẹ̀ ni láti parun, láti fi òpin sí ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè.
Forsothe he schal not deme so, and his herte schal not gesse so, but his herte schal be for to al to-breke, and to the sleynge of many folkis.
8 ‘Kì í ha ṣe pé ọba ni gbogbo àwọn aláṣẹ mi?’ ni Olúwa wí.
For he schal seie, Whether my princes ben not kyngis to gidere?
9 ‘Kì í ha ṣe pé Kalno dàbí i Karkemiṣi? Hamati kò ha dàbí i Arpadi, àti Samaria bí i Damasku?
Whether not as Carcamys, so Calanno; and as Arphat, so Emath? whether not as Damask, so Samarie?
10 Gẹ́gẹ́ bí ọwọ́ mi ti gbá ìjọba àwọn òrìṣà mú, ìjọba tí ère rẹ̀ pọ̀ ju ti Jerusalẹmu àti Samaria lọ.
As myn hond foond the rewmes of idol, so and the symylacris of hem of Jerusalem and of Samarie.
11 Èmi kì yóò a bá Jerusalẹmu wí àti àwọn ère rẹ̀?’” Gẹ́gẹ́ bí mo ṣe ṣe sí Samaria àti àwọn ère rẹ̀?
Whether not as Y dide to Samarie, and to the idols therof, so Y schal do to Jerusalem, and to the simylacris therof?
12 Nígbà tí Olúwa ti ṣe iṣẹ́ rẹ̀ sí òkè Sioni àti Jerusalẹmu, yóò sọ wí pé, “Èmi yóò fi ìyà jẹ ọba Asiria nítorí gààrù àyà rẹ̀ àti ìgbéraga ojú rẹ̀.
And it schal be, whanne the Lord hath fillid alle hise werkis in the hil of Syon and in Jerusalem, Y schal visite on the fruit of the greet doynge herte of the kyng of Assur, and on the glorie of the hiynesse of hise iyen.
13 Nítorí ó sọ pé: “‘Pẹ̀lú agbára ọwọ́ mi ni mo fi ṣe èyí àti pẹ̀lú ọgbọ́n ọ̀n mi, nítorí mo ní òye. Mo mú ààlà àwọn orílẹ̀-èdè kúrò, mo sì ti kó ìṣúra wọn. Gẹ́gẹ́ bí alágbára kan, mo borí àwọn ọba wọn.
For he seide, Y haue do in the strengthe of myn honde, and Y haue understonde in my wisdom; and Y haue take awei the endis of peplis, and Y haue robbid the princes of them, and Y as a myyti man haue drawun doun them that saten an hiy.
14 Bí ènìyàn ti í tọwọ́ bọ ìtẹ́ ẹyẹ, bẹ́ẹ̀ ni ọwọ́ mi tẹ ọrọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè. Bí ènìyàn ti í kó ẹyin tí a kọ̀sílẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni mo kó àwọn orílẹ̀-èdè kò sí èyí tí ó fi apá lu apá, tàbí kí ó ya ẹnu láti dún.’”
And myn hond foond the strengthe of puplis as a nest, and as eirun ben gaderid togidere that ben forsakun, so Y gaderid togidere al erthe; and noon was that mouyde a fethere, and openyde the mouth, and grutchide.
15 Ǹjẹ́ àáké le gbé ara rẹ̀ sókè kọjá ẹni tí ó ń fì í, tàbí kí ayùn fọ́nnu sí ẹni tí ó ń lò ó? Àfi bí ẹni pé ọ̀pá ó na ẹni tí ó gbé e sókè, tàbí kí kùmọ̀ lu èyí tí kì í ṣe igi.
Whether an ax schal haue glorie ayens hym that kittith with it? ether a sawe schal be enhaunsid ayens hym of whom it is drawun? as if a yerde is reisid ayens hym that reisith it, and a staf is enhaunsid, which sotheli is a tre.
16 Nítorí náà, ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, yóò rán ààrùn ìrẹ̀dànù sórí àwọn akíkanjú jagunjagun, lábẹ́ ògo rẹ̀ ni iná kan yóò ti sọ gẹ́gẹ́ bí iná ajónirun.
For this thing the lordli gouernour, Lord of oostis, schal sende thinnesse in the fatte men of hym, and his glorie kyndlid vndur schal brenne as `the brenning of fier.
17 Ìmọ́lẹ̀ Israẹli yóò di iná, Ẹni Mímọ́ rẹ̀ yóò jẹ́ ọ̀wọ́-iná, ní ọjọ́ kan ṣoṣo yóò jó yóò sì run àti ẹ̀gún àti ẹ̀wọ̀n.
And the liyt of Israel schal be in fier, and the hooli of it in flawme; and the thorn of him and brere schal be kyndlid and deuourid in o dai.
18 Gbogbo ẹwà igbó o rẹ̀, àti àwọn pápá ọlọ́ràá gbogbo rẹ̀ ni yóò run pátápátá, gẹ́gẹ́ bí ẹni tí ó ṣàìsàn ti í ṣòfò dànù.
And the glorie of his forest and of his Carmele schal be wastid, fro the soule `til to fleisch; and he schal be fleynge awei for drede.
19 Àwọn igi tí yóò kù nínú igbó o rẹ̀ yóò kéré níye, tí ọ̀dọ́mọdé yóò fi le kọ̀ wọ́n sílẹ̀.
And the relifs of the tree of his forest schulen be noumbrid for fewnesse, and a child schal write hem.
20 Ní ọjọ́ náà, àwọn tí ó ṣẹ́kù ní Israẹli, àwọn tí ó yè ní ilé e Jakọbu, kò ní gbẹ́kẹ̀lé ẹni náà tí ó lù wọ́n bolẹ̀, ṣùgbọ́n ní òtítọ́ yóò gbẹ́kẹ̀lé Olúwa, Ẹni Mímọ́ Israẹli.
And it schal be in that dai, the remenaunt of Israel, and thei that fledden of the house of Jacob, schal not adde for to triste on hym that smytith hem; but it schal triste on the hooli Lord of Israel, in treuthe.
21 Àwọn ìyókù yóò padà, àwọn ìyókù ti Jakọbu yóò padà sí ọ̀dọ̀ Ọlọ́run Alágbára.
The relifs, Y seie, the relifs of Jacob, schulen be conuertid to the stronge Lord.
22 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn ènìyàn rẹ, ìwọ Israẹli dàbí yanrìn ní Òkun, ẹni díẹ̀ ni yóò padà. A ti pàṣẹ ìparun, àkúnwọ́sílẹ̀ àti òdodo.
Forwhi, Israel, if thi puple is as the grauel of the see, the relifs schulen be turned therof; an endyng maad schort schal make riytfulnesse to be plenteuouse.
23 Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni yóò mú un ṣẹ, ìparun tí a ti pàṣẹ rẹ̀ lórí gbogbo ilẹ̀ náà.
For whi the Lord God of oostis schal make an endyng and a breggyng in the myddis of al erthe.
24 Nítorí náà, báyìí ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “Ẹ̀yin ènìyàn mi tí ó ń gbé Sioni, ẹ má ṣe bẹ̀rù àwọn Asiria, tí ó ń fi ọ̀pá lù yín, tí wọ́n sì ń gbé ọ̀gọ tì yín bí Ejibiti ti ṣe.
For this thing the Lord God of oostis seith these thingis, My puple, the dwellere of Sion, nyle thou drede of Assur, for he schal smite thee in a yerde, and he schal reise his staf on thee in the weie of Egipt.
25 Láìpẹ́, ìbínú mi sí i yín yóò wá sí òpin n ó sì dojú ìrunú mi kọ wọ́n, fún ìparun wọn.”
Forwhi yit a litil, and a litil, and myn indignacioun and my strong veniaunce schal be endid on the greet trespas of hem.
26 Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò nà wọ́n ní ẹgba. Gẹ́gẹ́ bí ó ṣe lu Midiani ní òkè Orebu, yóò sì gbé ọ̀pá rẹ̀ lé orí omi gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe ní Ejibiti.
And the Lord of oostis schal reise a scourge on hym bi the veniaunce of Madian in the stoon of Oreb, and bi his yerde on the see; and he schal reise that yerde in the wei of Egipt.
27 Ní ọjọ́ náà, a ó gbé ẹrù wọn kúrò ní èjìká a yín, àti àjàgà a wọn kúrò ní ọrùn un yín a ó fọ́ àjàgà náà, nítorí pé ẹ̀yin ó ti sanra.
And it schal be in that dai, his birthun schal be takun awei fro thi schuldre, and his yok fro thi necke; and the yok schal wexe rotun fro the face of oile.
28 Wọ́n wọ Aiati, wọ́n gba Migroni kọjá, wọ́n kó nǹkan pamọ́ sí Mikmasi.
He schal come in to Aioth, he schal passe in to Magron, at Magynas he schal bitake his vessels to kepyng.
29 Wọ́n ti rékọjá ọ̀nà, wọ́n wí pé, “Àwa ó tẹ̀dó sí Geba lóru yìí.” Rama mì tìtì Gibeah ti Saulu sálọ.
Thei passiden swiftli, Gabaa is oure seete, Rama was astonyed, Gabaa of Saul fled.
30 Gbé ohùn rẹ sókè, ìwọ ọmọbìnrin Galimu! Dẹ etí sílẹ̀, ìwọ Laiṣa! Ìwọ òtòṣì Anatoti!
Thou douytir of Gallym, weile with thi vois; thou Laisa, perseyue, thou pore Anatot.
31 Madmena ti fẹsẹ̀ fẹ́ ẹ, àwọn ènìyàn Gebimu ti fi ara pamọ́.
Medemena passide; the dwelleris of Gabyn fledden; be ye coumfortid.
32 Ní ọjọ́ yìí, wọn yóò dúró ní Nobu wọn yóò kan sáárá, ní òkè ọmọbìnrin Sioni ní òkè Jerusalẹmu.
Yit it is dai, that me stonde in Nobe; he schal dryue his hond on the hil of the douyter of Syon, on the litil hil of Jerusalem.
33 Wò ó, Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, yóò kán ẹ̀ka náà sọnù pẹ̀lú agbára. Àwọn igi ọlọ́lá ni a ó gé lulẹ̀ àwọn tí ó ga gogoro ni a ó rẹ̀ sílẹ̀.
Lo! the lordli gouernour, the Lord of oostis, schal breke a potel in drede, and hiy men of stature schulen be kit doun.
34 Òun yóò gé igbó dídí pẹ̀lú àáké, Lebanoni yóò ṣubú níwájú Alágbára náà.
And proude men schulen be maade low, and the thicke thingis of the forest schulen be distried bi irun; and the Liban with hiy thingis schal falle doun.

< Isaiah 10 >