< Isaiah 10 >

1 Ègbé ni fún àwọn ti ń ṣe òfin àìṣòdodo,
Anunae boethae oltlueh a tarhit tih, a daek khaw thakthaenah ni a daek uh.
2 láti dún àwọn aláìní ní ẹ̀tọ́ wọn àti láti fa ọwọ́ ìdájọ́ sẹ́yìn kúrò níwájú àwọn olùpọ́njú ènìyàn mi, wọ́n sọ àwọn ọ̀pọ̀ di ìjẹ fún wọn, wọ́n sì ń ja àwọn aláìní baba lólè.
tattloel kah dumlai te aka phaelh sak ham neh ka pilnam mangdaeng kah laitloeknah aka rhawth la om. Te dongah nuhmai te a kutbuem la a poeh sak tih cadah te a poelyoe uh.
3 Kí ni ìwọ yóò ṣe ní ọjọ́ ìṣirò nígbà tí ìparun bá ti ọ̀nà jíjìn wá? Ta ni ìwọ yóò sá tọ̀ fún ìrànlọ́wọ́? Níbo ni ìwọ yóò fi ọrọ̀ rẹ sí?
Cawhnah tue vaengah balae na saii vetih khohla bangsang lamkah khohli rhamrhael ha pawk vaengah u taengah lae na rhaelrham eh? Bomnah ham neh na thangpomnah te melam na hnoo eh?
4 Ohunkóhun kò ní ṣẹ́kù mọ́ bí kò ṣe láti tẹ̀ ba láàrín àwọn ìgbèkùn tàbí kí o ṣubú sáàrín àwọn tí a pa. Pẹ̀lú gbogbo nǹkan wọ̀nyí, ìbínú rẹ̀ kò kúrò, ọwọ́ rẹ̀ sì tún gbé sókè.
Hlongkhoh lakli ah a koisu vetih a ngawn yueng la a cungku sak ham phoeiah a tloe om pawh. Te boeih nen khaw a thintoek mael pawt tih a kut a thueng pueng.
5 “Ègbé ni fún àwọn ará Asiria, ọ̀gọ ìbínú mi, ní ọwọ́ ẹni tí kùmọ̀ ìbínú mi wà!
Anunae Assyria aih, ka thintoek caitueng neh a kut dongkah a conghol khaw kai kah kosi lamni a om.
6 Mo rán an sí orílẹ̀-èdè aláìní Ọlọ́run, mo dojú rẹ̀ kọ àwọn ènìyàn tí ó mú mi bínú láti já ẹrù gbà, àti láti kó ìkógun láti tẹ̀ mọ́lẹ̀ bí amọ̀ ní ojú òpópó.
Anih te namtom lailak taengah, ka thinpom te pilnam taengah ka tueih. Kutbuem buem ham neh maeh poelyoe ham khaw anih tih ka uen coeng. Te dongah anih te a dueh a dueh tih vongvoel kah dikpo bangla cawtkoi la om ni.
7 Ṣùgbọ́n, èyí kì í ṣe ohun tí ó fẹ́ ṣe, èyí kọ́ ni ohun tí ó ní lọ́kàn; èrò rẹ̀ ni láti parun, láti fi òpin sí ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè.
Tedae a lutlat toengloeng moenih a he, a thinko loh a moeh te khaw a thinko neh mitmoeng sak ham moenih a? Te dongah namtom a phit ham te a yolkai mai moenih.
8 ‘Kì í ha ṣe pé ọba ni gbogbo àwọn aláṣẹ mi?’ ni Olúwa wí.
Ka mangpa ke manghai boeiloeih moenih a?
9 ‘Kì í ha ṣe pé Kalno dàbí i Karkemiṣi? Hamati kò ha dàbí i Arpadi, àti Samaria bí i Damasku?
Kalneh Karkhemish bang moenih a? Khamath Arpad bang moenih a? Samaria Damasku bang moenih a?
10 Gẹ́gẹ́ bí ọwọ́ mi ti gbá ìjọba àwọn òrìṣà mú, ìjọba tí ère rẹ̀ pọ̀ ju ti Jerusalẹmu àti Samaria lọ.
Jerusalem lakah khaw, Samaria lakah ah khaw ka kut loh amih kah mueirhol neh mueidaep ram te a puei vanbangla,
11 Èmi kì yóò a bá Jerusalẹmu wí àti àwọn ère rẹ̀?’” Gẹ́gẹ́ bí mo ṣe ṣe sí Samaria àti àwọn ère rẹ̀?
Samaria neh anih kah mueirhol taengah khaw ka saii van mahpawt a? Te dongah Jerusalem neh anih kah mueirhol taengah khaw ka saii van ni.
12 Nígbà tí Olúwa ti ṣe iṣẹ́ rẹ̀ sí òkè Sioni àti Jerusalẹmu, yóò sọ wí pé, “Èmi yóò fi ìyà jẹ ọba Asiria nítorí gààrù àyà rẹ̀ àti ìgbéraga ojú rẹ̀.
Tedae Zion tlang neh Jerusalem taengkah a bibi boeih te Boeipa loh mueluem a khueh vaengah tah Assyria manghai kah thinko mamlal thaih te khaw, a mik dongkah buhuengpomnah boeimang te khaw ka cawh ni.
13 Nítorí ó sọ pé: “‘Pẹ̀lú agbára ọwọ́ mi ni mo fi ṣe èyí àti pẹ̀lú ọgbọ́n ọ̀n mi, nítorí mo ní òye. Mo mú ààlà àwọn orílẹ̀-èdè kúrò, mo sì ti kó ìṣúra wọn. Gẹ́gẹ́ bí alágbára kan, mo borí àwọn ọba wọn.
Ka kut dongkah thadueng neh ka saii coeng tih ka cueihnah neh ka yakming dongah pilnam kah rhilung khaw ka thoeih coeng. A coekcoe la khohrhang rheth pah tih a lueng la kho aka sa te ka suntlak sak coeng.
14 Bí ènìyàn ti í tọwọ́ bọ ìtẹ́ ẹyẹ, bẹ́ẹ̀ ni ọwọ́ mi tẹ ọrọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè. Bí ènìyàn ti í kó ẹyin tí a kọ̀sílẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni mo kó àwọn orílẹ̀-èdè kò sí èyí tí ó fi apá lu apá, tàbí kí ó ya ẹnu láti dún.’”
Pilnam kah thadueng te ka kut dongkah vaa bu bangla a hmuh tih, diklai pum kah a hnoo vaa duei a coi bangla kamah loh ka coi. Te vaengah a phae aka khong neh a ka aka ang tih aka cip om pawh,” a ti.
15 Ǹjẹ́ àáké le gbé ara rẹ̀ sókè kọjá ẹni tí ó ń fì í, tàbí kí ayùn fọ́nnu sí ẹni tí ó ń lò ó? Àfi bí ẹni pé ọ̀pá ó na ẹni tí ó gbé e sókè, tàbí kí kùmọ̀ lu èyí tí kì í ṣe igi.
Hai loh amah neh aka daeh soah kohang uh vetih, hlawh loh amah aka pom te thangpom thil saeh a? Conghol loh amah aka thueng te thing pawt mai akhaw conghol bangla thueng saeh a?
16 Nítorí náà, ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, yóò rán ààrùn ìrẹ̀dànù sórí àwọn akíkanjú jagunjagun, lábẹ́ ògo rẹ̀ ni iná kan yóò ti sọ gẹ́gẹ́ bí iná ajónirun.
Te dongah caempuei Boeipa Yahovah loh a putsut te pawtrhawt la, a thangpomnah khaw hmaisai bangla a rhong pah ni.
17 Ìmọ́lẹ̀ Israẹli yóò di iná, Ẹni Mímọ́ rẹ̀ yóò jẹ́ ọ̀wọ́-iná, ní ọjọ́ kan ṣoṣo yóò jó yóò sì run àti ẹ̀gún àti ẹ̀wọ̀n.
Israel kah vangnah te hmai la, amah kah a cimcaih te hmaisai la poeh ni. Te vaengah a hling neh a lota te a dom vetih hnin at dongah a tlum sak ni.
18 Gbogbo ẹwà igbó o rẹ̀, àti àwọn pápá ọlọ́ràá gbogbo rẹ̀ ni yóò run pátápátá, gẹ́gẹ́ bí ẹni tí ó ṣàìsàn ti í ṣòfò dànù.
A duup kah a thangpomnah khaw, a hinglu lamkah a cangthai khaw pumsa duela a thok sak ni. Te vaengah aka ngoi loh a paci bangla anih te om ni.
19 Àwọn igi tí yóò kù nínú igbó o rẹ̀ yóò kéré níye, tí ọ̀dọ́mọdé yóò fi le kọ̀ wọ́n sílẹ̀.
A duup kah thing aka sueng te a yol tah camoe kah a tae la om rhung ni.
20 Ní ọjọ́ náà, àwọn tí ó ṣẹ́kù ní Israẹli, àwọn tí ó yè ní ilé e Jakọbu, kò ní gbẹ́kẹ̀lé ẹni náà tí ó lù wọ́n bolẹ̀, ṣùgbọ́n ní òtítọ́ yóò gbẹ́kẹ̀lé Olúwa, Ẹni Mímọ́ Israẹli.
Te khohnin a pha vaengah Israel aka sueng khaw thap voel pawt vetih Jakob imkhui kah aka rhalyong long khaw amah aka ngawn soah hangdang voel mahpawh. Tedae Israel kah BOEIPA cim dongah ni oltak la a hangdang eh.
21 Àwọn ìyókù yóò padà, àwọn ìyókù ti Jakọbu yóò padà sí ọ̀dọ̀ Ọlọ́run Alágbára.
Aka sueng la, Jakob ko kah aka sueng te tah hlangrhalh Pathen taengla mael ni.
22 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn ènìyàn rẹ, ìwọ Israẹli dàbí yanrìn ní Òkun, ẹni díẹ̀ ni yóò padà. A ti pàṣẹ ìparun, àkúnwọ́sílẹ̀ àti òdodo.
Na pilnam Israel he tuipuei laivin bangla aka sueng om cakhaw khahoeinah a hlavawt tih duengnah loh a yo hlang tah mael ni.
23 Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni yóò mú un ṣẹ, ìparun tí a ti pàṣẹ rẹ̀ lórí gbogbo ilẹ̀ náà.
A boeihnah dongah caempuei, ka Boeipa Yahovah aka hlavawt tah diklai pum kah a laklung ah a saii van ni.
24 Nítorí náà, báyìí ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “Ẹ̀yin ènìyàn mi tí ó ń gbé Sioni, ẹ má ṣe bẹ̀rù àwọn Asiria, tí ó ń fi ọ̀pá lù yín, tí wọ́n sì ń gbé ọ̀gọ tì yín bí Ejibiti ti ṣe.
Te dongah Boeipa caempuei Yahovah loh, “Zion kah khosa ka pilnam loh Egypt khoboe bangla cungcik neh nang aka taam tih a conghol neh nang aka vuek Assyria te rhih boeh.
25 Láìpẹ́, ìbínú mi sí i yín yóò wá sí òpin n ó sì dojú ìrunú mi kọ wọ́n, fún ìparun wọn.”
Tedae kolkalh rhuet ah ka kosi neh ka thintoek loh a khah vetih amamih kah tlumhmawnnah la om bitni.
26 Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò nà wọ́n ní ẹgba. Gẹ́gẹ́ bí ó ṣe lu Midiani ní òkè Orebu, yóò sì gbé ọ̀pá rẹ̀ lé orí omi gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe ní Ejibiti.
Oreb lungpang kah Midian te rhuihet neh a hmasoe sak bangla, caempuei BOEIPA loh anih te a haenghang thil ni. Te vaengah Egypt khoboe bangla a conghol te tuipuei soah a thueng bal ni.
27 Ní ọjọ́ náà, a ó gbé ẹrù wọn kúrò ní èjìká a yín, àti àjàgà a wọn kúrò ní ọrùn un yín a ó fọ́ àjàgà náà, nítorí pé ẹ̀yin ó ti sanra.
Te khohnin a pha vaengah na laengpang dongkah a hnorhih neh na rhawn dongkah a hnamkun han sawn vetih hnamkun te situi loh a pat sak ni.
28 Wọ́n wọ Aiati, wọ́n gba Migroni kọjá, wọ́n kó nǹkan pamọ́ sí Mikmasi.
Anih Ai la pawk tih Migron te a poeng tih Mikmash ah amah kah hnopai te a hal.
29 Wọ́n ti rékọjá ọ̀nà, wọ́n wí pé, “Àwa ó tẹ̀dó sí Geba lóru yìí.” Rama mì tìtì Gibeah ti Saulu sálọ.
Lamkai a paan uh vaengah mamih kah rhaehim Geba tah lakueng coeng. Saul kah Gibeah Ramah khaw rhaelrham coeng.
30 Gbé ohùn rẹ sókè, ìwọ ọmọbìnrin Galimu! Dẹ etí sílẹ̀, ìwọ Laiṣa! Ìwọ òtòṣì Anatoti!
Gallim nu loh na ol hlampan saeh, Anathoth mangdaeng te Laish loh hnatung saeh.
31 Madmena ti fẹsẹ̀ fẹ́ ẹ, àwọn ènìyàn Gebimu ti fi ara pamọ́.
Madmenah khaw yong coeng, Gebim khosa rhoek khaw bakuep coeng.
32 Ní ọjọ́ yìí, wọn yóò dúró ní Nobu wọn yóò kan sáárá, ní òkè ọmọbìnrin Sioni ní òkè Jerusalẹmu.
Nob ah hnin at duem hamla Zion nu kah tlang neh Jerusalem som ah a kut a thueng ni.
33 Wò ó, Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, yóò kán ẹ̀ka náà sọnù pẹ̀lú agbára. Àwọn igi ọlọ́lá ni a ó gé lulẹ̀ àwọn tí ó ga gogoro ni a ó rẹ̀ sílẹ̀.
Caempuei Boeipa Yahovah loh a rhimom neh thingsam te a doi tih a sang la aka pomsang te khaw a vung coeng dongah aka sang rhoek tah kunyun uh ni.
34 Òun yóò gé igbó dídí pẹ̀lú àáké, Lebanoni yóò ṣubú níwájú Alágbára náà.
Duup khocak te thi neh a hum vetih Lebanon kah aka khuet te khaw cungku ni.

< Isaiah 10 >