< Isaiah 1 >

1 Ìran sí Juda àti Jerusalẹmu èyí tí Isaiah ọmọ Amosi rí ní àsìkò ìjọba Ussiah, Jotamu, Ahasi àti Hesekiah àwọn ọba Juda.
Viziunea lui Isaia, fiul lui Amoţ, pe care a văzut-o referitor la Iuda şi Ierusalim în zilele lui Ozia, Iotam, Ahaz şi Ezechia, împăraţi ai lui Iuda.
2 Gbọ́ ẹ̀yin ọ̀run! Fi etí sílẹ̀, ìwọ ayé! Nítorí Olúwa ti sọ̀rọ̀: “Mo tọ́ àwọn ọmọ dàgbà, ṣùgbọ́n wọ́n ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi.
Ascultaţi cerurilor, şi deschide urechea pământule, căci DOMNUL a vorbit: Am hrănit şi am crescut copii şi ei s-au răzvrătit împotriva mea.
3 Màlúù mọ olówó rẹ̀, kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ sì mọ ibùjẹ olówó rẹ̀, ṣùgbọ́n Israẹli kò mọ̀, òye kò yé àwọn ènìyàn mi.”
Boul îşi cunoaşte stăpânul şi măgarul ieslea stăpânului, dar Israel nu mă cunoaşte, poporul meu nu ia aminte.
4 Á à! Orílẹ̀-èdè ẹlẹ́ṣẹ̀, àwọn ènìyàn tí ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ ń pa lẹ́rù, ìran àwọn aṣebi, àwọn ọmọ tó ti di aṣèbàjẹ́! Wọn ti kọ Olúwa sílẹ̀ wọn ti gan Ẹni Mímọ́ Israẹli, wọn sì ti kẹ̀yìn sí i.
Ah, naţiune păcătoasă, popor împovărat cu nelegiuire, sămânţă de făcători de rău, copii corupători; ei au părăsit pe DOMNUL, l-au provocat pe Cel Sfânt al lui Israel la mânie, au plecat întorcându-şi spatele.
5 Èéṣe tí a ó fi tún lù yín mọ́? Èéṣe tí ẹ ò dẹ́kun ọ̀tẹ̀ ṣíṣe? Gbogbo orí yín jẹ́ kìkì ọgbẹ́, gbogbo ọkàn yín sì ti pòruurù.
De ce să mai fiţi loviţi? Vă veţi răzvrăti tot mai mult; tot capul este bolnav şi toată inima leşinată.
6 Láti àtẹ́lẹsẹ̀ yín dé àtàrí yín kò sí àlàáfíà rárá, àyàfi ọgbẹ́ òun ìfarapa àti ojú egbò, tí a kò nù kúrò tàbí kí á dì tàbí kí a kùn ún ní òróró.
Din talpa piciorului până la cap nu este sănătate în el; ci răni şi vânătăi şi răni ce putrezesc; ele nu au fost închise, nici legate, nici înmuiate cu untdelemn.
7 Orílẹ̀-èdè yín dahoro, a dáná sun àwọn ìlú yín, oko yín ni àwọn àjèjì ti jẹ run lójú ara yín náà, ni gbogbo rẹ̀ ṣòfò bí èyí tí àwọn àjèjì borí rẹ̀.
Ţara voastră este pustiită, cetăţile voastre arse cu foc; pământul vostru, străini îl mănâncă în prezenţa voastră şi este pustiit, ca doborât de străini.
8 Ọmọbìnrin Sioni ni a fi sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àtíbàbà nínú ọgbà àjàrà, gẹ́gẹ́ bí abà nínú oko ẹ̀gúnsí, àti bí ìlú tí a dó tì.
Şi fiica Sionului este lăsată ca un cort în vie, ca o colibă într-o grădină de castraveţi, ca o cetate asediată.
9 Àyàfi bí Olúwa àwọn ọmọ-ogun bá ṣẹ́ díẹ̀ kù fún wà, a ò bá ti rí bí Sodomu, a ò bá sì ti dàbí Gomorra.
Dacă DOMNUL oştirilor nu ne-ar fi lăsat o rămăşiţă foarte mică, am fi fost ca Sodoma şi am fi fost ca Gomora.
10 Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, ẹ̀yin aláṣẹ Sodomu, tẹ́tí sí òfin Ọlọ́run wa, ẹ̀yin ènìyàn Gomorra!
Ascultaţi cuvântul DOMNULUI, voi conducători ai Sodomei; deschideţi urechea la legea Dumnezeului nostru, voi popor al Gomorei.
11 “Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹbọ yín kín ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹbọ yín jásí fún mi?” ni Olúwa wí. “Mo ti ní ànító àti àníṣẹ́kù ẹbọ sísun ti àgbò àti ọ̀rá ẹran àbọ́pa, Èmi kò ní inú dídùn nínú ẹ̀jẹ̀ akọ màlúù, ti àgùntàn àti ti òbúkọ.
Ce îmi este mulţimea sacrificiilor voastre? spune DOMNUL; Sunt sătul de ofrandele arse din berbeci şi de grăsimea vitelor îngrăşate; şi nu mă desfăt în sângele taurilor sau al mieilor sau al ţapilor.
12 Nígbà tí ẹ wá farahàn níwájú mi, ta ni ó béèrè èyí lọ́wọ́ yín, gìrì gìrì ẹsẹ̀ nínú àgbàlá mi?
Când veniţi să vă arătaţi înaintea mea, cine a cerut aceasta din mâna voastră, ca să îmi călcaţi curţile?
13 Ẹ má mú ọrẹ asán wá mọ́! Ìríra ni tùràrí yín jásí fún mi, oṣù tuntun àti ọjọ́ ìsinmi àti àwọn àpéjọ, Èmi kò lè faradà á, ẹ̀ṣẹ̀ ni àpéjọ yín wọ̀nyí.
Nu mai aduceţi daruri deşarte; tămâia este o urâciune pentru mine; lunile noi şi sabatele, chemarea adunărilor, nu le pot suporta; este nelegiuire, chiar adunarea solemnă.
14 Ayẹyẹ oṣù tuntun yín àti àjọ̀dún tí a yàn, ni ọkàn mi kórìíra. Wọ́n ti di àjàgà sí mi ní ọrùn, Ó sú mi láti fi ara dà wọ́n.
Sufletul meu urăşte lunile voastre noi şi sărbătorile voastre rânduite; ele sunt tulburare pentru mine; am obosit a le purta.
15 Nígbà tí ẹ bá tẹ́ ọwọ́ yín sókè ni àdúrà, Èmi yóò fi ojú mi pamọ́ fún un yín, kódà bí ẹ bá gba ọ̀pọ̀lọpọ̀ àdúrà, Èmi kò ni tẹ́tí sí i. “Ọwọ́ yín kún fún ẹ̀jẹ̀.
Şi când vă întindeţi mâinile, îmi voi ascunde ochii de voi, da, când faceţi multe rugăciuni, nu voi asculta; mâinile vă sunt pline de sânge.
16 “Wẹ̀ kí ẹ sì jẹ́ kí ara yín mọ́. Ẹ mú ìwà ibi yín kúrò níwájú mi! Dáwọ́ àìṣedéédéé dúró,
Spălaţi-vă, curăţiţi-vă; puneţi deoparte facerile voastre de rău din faţa ochilor mei; încetaţi să faceţi răul;
17 kọ́ láti ṣe rere! Wá ìdájọ́ òtítọ́, tu àwọn tí a ń pọ́n lójú nínú. Ṣàtìlẹyìn fún ẹ̀tọ́ aláìní baba, gbà ẹjọ́ opó rò.
Învăţaţi să faceţi binele; căutaţi judecata, uşuraţi pe oprimat, judecaţi pe cel fără tată, pledaţi pentru văduvă.
18 “Ẹ wá ní ìsinsin yìí, ẹ jẹ́ kí a jọ ṣàṣàrò,” ni Olúwa wí. “Bí ẹ̀ṣẹ̀ yín bá rí bí osùn, wọn ó sì funfun bí i yìnyín, bí wọn bá sì pọ́n bí ẹ̀jẹ̀, wọn ó sì dàbí ẹ̀gbọ̀n òwú.
Veniţi acum să ne judecăm, spune DOMNUL, de sunt păcatele voastre ca stacojiul, vor fi albe ca zăpada; de sunt roşii precum carminul, vor fi ca lâna.
19 Tí ẹ̀yin bá fẹ́, tí ẹ sì gbọ́rọ̀, ẹ̀yin yóò sì jẹ ojúlówó adùn ilẹ̀ náà.
Dacă veţi fi voitori şi ascultători, veţi mânca bunătatea pământului,
20 Ṣùgbọ́n tí ẹ bá kọ̀ tí ẹ sì ṣọ̀tẹ̀, idà ni a ó fi pa yín run.” Nítorí ẹnu Olúwa la ti sọ ọ́.
Dar dacă veţi refuza şi vă veţi răzvrăti, veţi fi mâncaţi de sabie; căci gura DOMNULUI a vorbit.
21 Wo bí ìlú òtítọ́ ṣe di àgbèrè! Ó ti kún fún ìdájọ́ òtítọ́ nígbà kan rí, òdodo ń gbé ibẹ̀ tẹ́lẹ̀ rí, ṣùgbọ́n báyìí àwọn apànìyàn!
Cum a devenit cetatea credincioasă o curvă! Era plină de judecată; găzduia dreptatea în ea, dar acum găzduiesc ucigaşi.
22 Fàdákà rẹ ti di ìpẹ́pẹ́, ààyò wáìnì rẹ la ti bu omi là.
Argintul tău a devenit zgură, vinul tău amestecat cu apă;
23 Ọlọ̀tẹ̀ ni àwọn aláṣẹ yín, akẹgbẹ́ àwọn olè, gbogbo wọn ló fẹ́ràn àbẹ̀tẹ́lẹ̀ wọ́n sì ń wá ẹ̀bùn kiri. Wọ́n kì í ṣàtìlẹyìn fún ẹ̀tọ́ aláìní baba, ẹjọ́ opó kì í sì í dé iwájú wọn.
Prinţii tăi sunt răzvrătiţi şi însoţitori ai hoţilor; fiecare iubeşte daruri şi urmăreşte răsplăţi; ei nu judecă pe cel fără tată, nici cauza văduvei nu ajunge la ei.
24 Nítorí náà ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, alágbára kan ṣoṣo tí Israẹli sọ wí pé: “Á à! Èmi yóò ní ìfọ̀kànbalẹ̀ lórí àwọn ọ̀tá mi n ó sì gbẹ̀san lára àwọn ọ̀tá mi.
De aceea spune Domnul, DOMNUL oştirilor, Cel puternic al lui Israel: Ah, mă voi uşura de potrivnicii mei şi mă voi răzbuna pe duşmanii mei;
25 Èmi yóò pa ọwọ́ mi dà sí ọ, èmi ó sì ku ìpẹ́pẹ́ rẹ dànù, n ó sì mú gbogbo ìdọ̀tí rẹ kúrò.
Şi îmi voi întoarce mâna asupra ta şi îţi voi îndepărta zgura cu puritate şi îţi voi lua tot cositorul;
26 Èmi yóò mú àwọn adájọ́ rẹ bọ̀ sí ipò gẹ́gẹ́ bí i ti àtijọ́, àti àwọn olùdámọ̀ràn rẹ̀ bí i ti ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀. Lẹ́yìn náà ni a ó pè ọ ní ìlú òdodo, ìlú òtítọ́.”
Şi îţi voi restaura judecătorii ca prima dată şi sfătuitorii tăi ca la început; după aceasta vei fi numită Cetatea dreptăţii, cetatea credincioasă.
27 A ó fi ìdájọ́ òtítọ́ ra Sioni padà, àti àwọn tí ó ronúpìwàdà pẹ̀lú òdodo.
Sionul va fi răscumpărat cu judecată şi convertiţii lui cu dreptate.
28 Ṣùgbọ́n àwọn ọlọ̀tẹ̀ àti àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ ni a ó parun. Àwọn tí ó bá sì kọ Olúwa sílẹ̀ ni yóò ṣègbé.
Şi nimicirea călcătorilor de lege şi a păcătoşilor va fi împreună şi cei ce părăsesc pe DOMNUL vor fi mistuiţi.
29 “Ojú yóò tì yín nítorí igi óákù mímọ́ èyí tí ẹ ní inú dídùn sí, a ó kàn yín lábùkù nítorí àwọn ọgbà yìí tí ẹ ti yàn fúnra yín.
Fiindcă vor fi ruşinaţi de stejarii pe care i-aţi dorit şi veţi fi încurcaţi de grădinile pe care le-aţi ales.
30 Ẹ ó sì dàbí igi óákù tí ewé rẹ̀ ti rọ, bí ọgbà tí kò ní omi.
Fiindcă veţi fi ca un stejar a cărui frunză se ofileşte şi ca o grădină ce nu are apă.
31 Alágbára ọkùnrin náà yóò sì dàbí ohun ìdáná, iṣẹ́ rẹ̀ bí ẹ̀ṣẹ́-iná, àwọn méjèèjì ni yóò jóná papọ̀, láìsí ẹni tí yóò lè pa iná yìí.”
Şi cel tare va fi ca un câlţ şi făcătorul lui ca o scânteie şi vor arde amândoi împreună şi nimeni nu îi va stinge.

< Isaiah 1 >