< Isaiah 1 >

1 Ìran sí Juda àti Jerusalẹmu èyí tí Isaiah ọmọ Amosi rí ní àsìkò ìjọba Ussiah, Jotamu, Ahasi àti Hesekiah àwọn ọba Juda.
[I am] Isaiah, the son of Amoz. [Yahweh showed me] visions about Jerusalem and [all the other places in] Judah. He showed me these visions during the years that Uzziah, Jotham, Ahaz, and Hezekiah were kings of Judah.
2 Gbọ́ ẹ̀yin ọ̀run! Fi etí sílẹ̀, ìwọ ayé! Nítorí Olúwa ti sọ̀rọ̀: “Mo tọ́ àwọn ọmọ dàgbà, ṣùgbọ́n wọ́n ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi.
This is what Yahweh says: “All you [angels in] [APO] heaven and [all you people on] [APO] earth, listen to me! The people that I caused to exist and took care of [DOU] have rebelled against me.
3 Màlúù mọ olówó rẹ̀, kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ sì mọ ibùjẹ olówó rẹ̀, ṣùgbọ́n Israẹli kò mọ̀, òye kò yé àwọn ènìyàn mi.”
Oxen know their owners, and donkeys know who provides food for them, but my Israeli people do not know [me]; they do not realize [that I am the one who takes care of them].”
4 Á à! Orílẹ̀-èdè ẹlẹ́ṣẹ̀, àwọn ènìyàn tí ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ ń pa lẹ́rù, ìran àwọn aṣebi, àwọn ọmọ tó ti di aṣèbàjẹ́! Wọn ti kọ Olúwa sílẹ̀ wọn ti gan Ẹni Mímọ́ Israẹli, wọn sì ti kẹ̀yìn sí i.
Terrible things will happen to that sinful nation, to those people who are guilty of sinning greatly. They are a group of very evil people, who act very unjustly. They have abandoned Yahweh, the holy one of Israel; they have (abandoned/turned away from) him.
5 Èéṣe tí a ó fi tún lù yín mọ́? Èéṣe tí ẹ ò dẹ́kun ọ̀tẹ̀ ṣíṣe? Gbogbo orí yín jẹ́ kìkì ọgbẹ́, gbogbo ọkàn yín sì ti pòruurù.
Why do you [RHQ] continue to [do things for which] you should be punished? Why do you continue to rebel against Yahweh? [You are like] [MET] someone whose head is badly injured and whose mind is sick/corrupt.
6 Láti àtẹ́lẹsẹ̀ yín dé àtàrí yín kò sí àlàáfíà rárá, àyàfi ọgbẹ́ òun ìfarapa àti ojú egbò, tí a kò nù kúrò tàbí kí á dì tàbí kí a kùn ún ní òróró.
[It is as though] [MET] from the soles/bottoms of your feet to the [tops of your] heads nothing is healthy; there are only open wounds and cuts and sores that have not been cleaned or bandaged, and no [olive] oil has been put on them [to heal them].
7 Orílẹ̀-èdè yín dahoro, a dáná sun àwọn ìlú yín, oko yín ni àwọn àjèjì ti jẹ run lójú ara yín náà, ni gbogbo rẹ̀ ṣòfò bí èyí tí àwọn àjèjì borí rẹ̀.
[It is as though] your country is ruined/desolate; your towns have been burned. Foreigners plunder/steal the crops in your fields while you watch; they destroy everything [that they see].
8 Ọmọbìnrin Sioni ni a fi sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àtíbàbà nínú ọgbà àjàrà, gẹ́gẹ́ bí abà nínú oko ẹ̀gúnsí, àti bí ìlú tí a dó tì.
The city of Jerusalem has [already] been abandoned, it is like [SIM] a shelter in a vineyard that has been abandoned by the watchmen; it is like [SIM] a watchman’s hut in a field of melons that has been deserted. It is a city surrounded by its enemies who are waiting to attack it.
9 Àyàfi bí Olúwa àwọn ọmọ-ogun bá ṣẹ́ díẹ̀ kù fún wà, a ò bá ti rí bí Sodomu, a ò bá sì ti dàbí Gomorra.
If the Commander of the armies of angels had not allowed a few of us [his people] to (survive/remain alive), we would have [all] been [destroyed], like [the cities of] Sodom and Gomorrah [were destroyed].
10 Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, ẹ̀yin aláṣẹ Sodomu, tẹ́tí sí òfin Ọlọ́run wa, ẹ̀yin ènìyàn Gomorra!
You [leaders of Judah are as wicked as] the rulers of Sodom were, and you [other people in Jerusalem areas are as wicked as] the people in Gomorrah [were]. Listen to this message from Yahweh, [all of you]!
11 “Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹbọ yín kín ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹbọ yín jásí fún mi?” ni Olúwa wí. “Mo ti ní ànító àti àníṣẹ́kù ẹbọ sísun ti àgbò àti ọ̀rá ẹran àbọ́pa, Èmi kò ní inú dídùn nínú ẹ̀jẹ̀ akọ màlúù, ti àgùntàn àti ti òbúkọ.
He says, “You continue to bring many sacrifices to me, but I do not [RHQ] want them [because you do not worship me sincerely]! You bring me many offerings to be completely burned [on the altar], [but] I (am tired/do not want any more) of your burning all those offerings, the burning rams and the fat from fat cattle. I am not pleased with the blood of bulls and lambs and goats that [the priest] pours [against the altar].
12 Nígbà tí ẹ wá farahàn níwájú mi, ta ni ó béèrè èyí lọ́wọ́ yín, gìrì gìrì ẹsẹ̀ nínú àgbàlá mi?
When you come to my temple to worship me, no one [RHQ] told you to trample on my courtyard while you perform all those rituals.
13 Ẹ má mú ọrẹ asán wá mọ́! Ìríra ni tùràrí yín jásí fún mi, oṣù tuntun àti ọjọ́ ìsinmi àti àwọn àpéjọ, Èmi kò lè faradà á, ẹ̀ṣẹ̀ ni àpéjọ yín wọ̀nyí.
Stop bringing to me those offerings, because they are useless [to me]; I am disgusted with the incense that [the priests burn]. And [your feasts to celebrate] the new moon [each month] and your (Sabbath [days]/days of rest) and your [other] festivals— I detest them because of the wicked things [that you do].
14 Ayẹyẹ oṣù tuntun yín àti àjọ̀dún tí a yàn, ni ọkàn mi kórìíra. Wọ́n ti di àjàgà sí mi ní ọrùn, Ó sú mi láti fi ara dà wọ́n.
I [SYN] hate [all] your celebrations of each new moon and the [other] festivals that you celebrate each year. They are [like] [MET] a heavy burden that I am tired of carrying.
15 Nígbà tí ẹ bá tẹ́ ọwọ́ yín sókè ni àdúrà, Èmi yóò fi ojú mi pamọ́ fún un yín, kódà bí ẹ bá gba ọ̀pọ̀lọpọ̀ àdúrà, Èmi kò ni tẹ́tí sí i. “Ọwọ́ yín kún fún ẹ̀jẹ̀.
[So], when you lift up your hands when you pray [to me], I will not [even] look at you. Even if you pray [to me very] frequently, I will not listen [to you], [because it is as though] your hands are covered with the blood [of people whom you have killed].
16 “Wẹ̀ kí ẹ sì jẹ́ kí ara yín mọ́. Ẹ mú ìwà ibi yín kúrò níwájú mi! Dáwọ́ àìṣedéédéé dúró,
Cleanse your inner beings, and become [spiritually] clean! Stop your evil behavior! Stop doing things that are wrong!
17 kọ́ láti ṣe rere! Wá ìdájọ́ òtítọ́, tu àwọn tí a ń pọ́n lójú nínú. Ṣàtìlẹyìn fún ẹ̀tọ́ aláìní baba, gbà ẹjọ́ opó rò.
Learn to do [things that are] good! [Try to] cause people to do what is just. Help people who are (oppressed/treated cruelly). Defend orphans and widows [when people take them to court].”
18 “Ẹ wá ní ìsinsin yìí, ẹ jẹ́ kí a jọ ṣàṣàrò,” ni Olúwa wí. “Bí ẹ̀ṣẹ̀ yín bá rí bí osùn, wọn ó sì funfun bí i yìnyín, bí wọn bá sì pọ́n bí ẹ̀jẹ̀, wọn ó sì dàbí ẹ̀gbọ̀n òwú.
Yahweh says, “You need to think about the results of what you do. Even though [the guilt of] your sins be [as evident and as difficult to get rid of] as [SIM] red [stains on a white garment] [DOU], [I will get rid of them completely] [like someone who can make that stained garment] become as white as snow or wool [DOU].
19 Tí ẹ̀yin bá fẹ́, tí ẹ sì gbọ́rọ̀, ẹ̀yin yóò sì jẹ ojúlówó adùn ilẹ̀ náà.
If you are willing to obey [me], [I will enable] you to have plenty to eat.
20 Ṣùgbọ́n tí ẹ bá kọ̀ tí ẹ sì ṣọ̀tẹ̀, idà ni a ó fi pa yín run.” Nítorí ẹnu Olúwa la ti sọ ọ́.
But, if you turn away [from me and] rebel against me, you will be killed [by your enemies’] swords. [That will surely happen, because I, ] Yahweh, have said it.”
21 Wo bí ìlú òtítọ́ ṣe di àgbèrè! Ó ti kún fún ìdájọ́ òtítọ́ nígbà kan rí, òdodo ń gbé ibẹ̀ tẹ́lẹ̀ rí, ṣùgbọ́n báyìí àwọn apànìyàn!
“[You people of Jerusalem previously] faithfully [worshiped only] me, but now you have become like [MET] prostitutes [who are not faithful to any husband]. Previously, people there always acted justly/fairly and righteously, but now your city [is full of] murderers.
22 Fàdákà rẹ ti di ìpẹ́pẹ́, ààyò wáìnì rẹ la ti bu omi là.
Previously, you were [like] [MET] pure silver, but now you have become [like] [MET] the scum that is left [when silver is purified]. Previously you were [like pure] wine, but you have become [like] [MET] wine that has [a lot of] water mixed with it.
23 Ọlọ̀tẹ̀ ni àwọn aláṣẹ yín, akẹgbẹ́ àwọn olè, gbogbo wọn ló fẹ́ràn àbẹ̀tẹ́lẹ̀ wọ́n sì ń wá ẹ̀bùn kiri. Wọ́n kì í ṣàtìlẹyìn fún ẹ̀tọ́ aláìní baba, ẹjọ́ opó kì í sì í dé iwájú wọn.
Your leaders are rebels; they spend time with thieves. They all want to get bribes and force others to give them gifts [in order that they do good things for them]. They do not defend orphans [in court], and they do not do all they can to enable widows to get what they should receive.
24 Nítorí náà ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, alágbára kan ṣoṣo tí Israẹli sọ wí pé: “Á à! Èmi yóò ní ìfọ̀kànbalẹ̀ lórí àwọn ọ̀tá mi n ó sì gbẹ̀san lára àwọn ọ̀tá mi.
Therefore [I, ] the Commander of the armies of angels, the mighty God of Israel, say to my enemies, ‘will get revenge on you; you will not cause me any more trouble. And I will pay you back for the evil things that you did.
25 Èmi yóò pa ọwọ́ mi dà sí ọ, èmi ó sì ku ìpẹ́pẹ́ rẹ dànù, n ó sì mú gbogbo ìdọ̀tí rẹ kúrò.
I will raise my fist to strike you. I will [punish you severely] [MET], as though [MET] you were silver [and I needed to heat you very greatly to] melt you and get rid of the impurities.
26 Èmi yóò mú àwọn adájọ́ rẹ bọ̀ sí ipò gẹ́gẹ́ bí i ti àtijọ́, àti àwọn olùdámọ̀ràn rẹ̀ bí i ti ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀. Lẹ́yìn náà ni a ó pè ọ ní ìlú òdodo, ìlú òtítọ́.”
[After that happens, ] I will give you good judges like you had previously; you will have [wise] counselors like you had long ago. Then people will call your city “a city where people [act] righteously, a city where people are loyal to me.”'”
27 A ó fi ìdájọ́ òtítọ́ ra Sioni padà, àti àwọn tí ó ronúpìwàdà pẹ̀lú òdodo.
Because the people of Jerusalem will do what is fair/just, their city will be restored; those who repent [will be saved] because of [their acting] righteously.
28 Ṣùgbọ́n àwọn ọlọ̀tẹ̀ àti àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ ni a ó parun. Àwọn tí ó bá sì kọ Olúwa sílẹ̀ ni yóò ṣègbé.
But rebels and sinners will be crushed by Yahweh, and those who forsake him will disappear.
29 “Ojú yóò tì yín nítorí igi óákù mímọ́ èyí tí ẹ ní inú dídùn sí, a ó kàn yín lábùkù nítorí àwọn ọgbà yìí tí ẹ ti yàn fúnra yín.
You will be ashamed because [you worshiped] idols under the oak trees [that you considered to be] sacred; you will be disgraced because [you worshiped idols] in the gardens where you chose [to worship them].
30 Ẹ ó sì dàbí igi óákù tí ewé rẹ̀ ti rọ, bí ọgbà tí kò ní omi.
You will be like [SIM] a very large tree which has withered leaves, like [SIM] a garden that [is dried up because] it has no water.
31 Alágbára ọkùnrin náà yóò sì dàbí ohun ìdáná, iṣẹ́ rẹ̀ bí ẹ̀ṣẹ́-iná, àwọn méjèèjì ni yóò jóná papọ̀, láìsí ẹni tí yóò lè pa iná yìí.”
Those among you who are [very] strong will become [like] [MET] dry wood, and the work they do will be [like] [MET] a spark; both they and the evil things that they do will burn up completely, and no one will be able to put out the fire.

< Isaiah 1 >