< Isaiah 1 >

1 Ìran sí Juda àti Jerusalẹmu èyí tí Isaiah ọmọ Amosi rí ní àsìkò ìjọba Ussiah, Jotamu, Ahasi àti Hesekiah àwọn ọba Juda.
Judah siangpahrang Uziah, Jotham, Ahaz, Hezekiah tinaw a bawi awh navah, Amos capa Isaiah ni Judahnaw hoi Jerusalem kho hoi kâkuen lah a hmu e vision,
2 Gbọ́ ẹ̀yin ọ̀run! Fi etí sílẹ̀, ìwọ ayé! Nítorí Olúwa ti sọ̀rọ̀: “Mo tọ́ àwọn ọmọ dàgbà, ṣùgbọ́n wọ́n ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi.
Cathut ni lawk a dei dawkvah, Oe kalvannaw, thai awh haw. Oe talai, hnâpakeng haw. Ka kawk e catounnaw ni Kai na taran awh toe.
3 Màlúù mọ olówó rẹ̀, kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ sì mọ ibùjẹ olówó rẹ̀, ṣùgbọ́n Israẹli kò mọ̀, òye kò yé àwọn ènìyàn mi.”
Maito ni kakhoumkung a panue. La ni hai kakawkkung e dokko a panue. Isarelnaw ni Kai na panuek awh hoeh toe. Ka taminaw ni pouk panuek awh hoeh toe a ti.
4 Á à! Orílẹ̀-èdè ẹlẹ́ṣẹ̀, àwọn ènìyàn tí ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ ń pa lẹ́rù, ìran àwọn aṣebi, àwọn ọmọ tó ti di aṣèbàjẹ́! Wọn ti kọ Olúwa sílẹ̀ wọn ti gan Ẹni Mímọ́ Israẹli, wọn sì ti kẹ̀yìn sí i.
Miphun kathout, sak payonnae ka phawt e tamihu, kahawihoehe hno ka sak e catoun, rawknae canaw lah bo na o awh toung aw. BAWIPA hah na ceitakhai awh toe. Isarelnaw e kathounge Cathut hah na bari awh laipalah, hnamthun sin awh teh, na kamlang takhai awh toe.
5 Èéṣe tí a ó fi tún lù yín mọ́? Èéṣe tí ẹ ò dẹ́kun ọ̀tẹ̀ ṣíṣe? Gbogbo orí yín jẹ́ kìkì ọgbẹ́, gbogbo ọkàn yín sì ti pòruurù.
Ahnimanaw hah bangtelamaw bout ka hem han vai. Bangtelamaw bout ka yue han vai. A lû teh hmâtan hoi king akawi, na lung hai tha khoeroe awm hoeh toe.
6 Láti àtẹ́lẹsẹ̀ yín dé àtàrí yín kò sí àlàáfíà rárá, àyàfi ọgbẹ́ òun ìfarapa àti ojú egbò, tí a kò nù kúrò tàbí kí á dì tàbí kí a kùn ún ní òróró.
Khoktabei koehoi lû koe totouh, damnae awmhoeh. Hmâtan hoi, a phing teh, a hnai ka lawi e seng lah ao. Hote hmânaw hah pâsu hoeh, kawm hoeh, satui hai hluk pouh hoeh rah.
7 Orílẹ̀-èdè yín dahoro, a dáná sun àwọn ìlú yín, oko yín ni àwọn àjèjì ti jẹ run lójú ara yín náà, ni gbogbo rẹ̀ ṣòfò bí èyí tí àwọn àjèjì borí rẹ̀.
Nangmae ram teh tami kingkadi lah ao. Khonaw hai hmai a kak toe. Na talainaw hai ramlouknaw ni na hmaitung vah a ca awh vaiteh, taran ni a raphoe tangcoung e patetlah tami kingdi han.
8 Ọmọbìnrin Sioni ni a fi sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àtíbàbà nínú ọgbà àjàrà, gẹ́gẹ́ bí abà nínú oko ẹ̀gúnsí, àti bí ìlú tí a dó tì.
Zion canu hai misur takha ringnae patetlah payin takha dawk e rim patetlah taran ni a kalup e kho patetlah ceitakhai lah ao.
9 Àyàfi bí Olúwa àwọn ọmọ-ogun bá ṣẹ́ díẹ̀ kù fún wà, a ò bá ti rí bí Sodomu, a ò bá sì ti dàbí Gomorra.
Rasahu BAWIPA ni mamouh hanelah younca hai cawi sak hoehpawiteh, maimouh teh Sodom kho patetlah o awh teh, Gomorrah kho hoi kâvan awh.
10 Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, ẹ̀yin aláṣẹ Sodomu, tẹ́tí sí òfin Ọlọ́run wa, ẹ̀yin ènìyàn Gomorra!
Sodom kho ka uk e bawinaw, Cathut e lawk hah thai awh haw. Gomorrah khocanaw kaimae Cathut lawk hah hnâpakeng awh haw.
11 “Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹbọ yín kín ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹbọ yín jásí fún mi?” ni Olúwa wí. “Mo ti ní ànító àti àníṣẹ́kù ẹbọ sísun ti àgbò àti ọ̀rá ẹran àbọ́pa, Èmi kò ní inú dídùn nínú ẹ̀jẹ̀ akọ màlúù, ti àgùntàn àti ti òbúkọ.
Cathut ni a dei e teh, nangmouh ni na thueng awh e satheinaw teh kai hoi bangtelamaw a kâkuet vaw. Thuengnae tu, ka phuekuek lah na paca e saring thawnaw hoi ka boum toe. Maito, tuca hoi hmaenaw e thi hah ka ngai hoeh.
12 Nígbà tí ẹ wá farahàn níwájú mi, ta ni ó béèrè èyí lọ́wọ́ yín, gìrì gìrì ẹsẹ̀ nínú àgbàlá mi?
Ka hmalah minhmai patue han na tho awh navah, Kaie thongma coungroe hanlah apinimaw na patoun awh.
13 Ẹ má mú ọrẹ asán wá mọ́! Ìríra ni tùràrí yín jásí fún mi, oṣù tuntun àti ọjọ́ ìsinmi àti àwọn àpéjọ, Èmi kò lè faradà á, ẹ̀ṣẹ̀ ni àpéjọ yín wọ̀nyí.
Ayawmyin e pasoum hno hah bout thokhai awh hanh lawih. Hmai na sawi awh e hmuitui hah ka panuet. Thapa rei hnin, kamhluem hnin, kamkhueng hnin naw hai ka panuet. Hawihoehnae hoi kâkalawt e kathoung kamkhuengnae hah ka panguep thai hoeh.
14 Ayẹyẹ oṣù tuntun yín àti àjọ̀dún tí a yàn, ni ọkàn mi kórìíra. Wọ́n ti di àjàgà sí mi ní ọrùn, Ó sú mi láti fi ara dà wọ́n.
Ka muitha ni nangmae thapa rei hnin hoi nangmae pawinaw hah ka hmuhma. Kai katarawk e lah ao teh ka panguep lawi ngawt ka tawn toe.
15 Nígbà tí ẹ bá tẹ́ ọwọ́ yín sókè ni àdúrà, Èmi yóò fi ojú mi pamọ́ fún un yín, kódà bí ẹ bá gba ọ̀pọ̀lọpọ̀ àdúrà, Èmi kò ni tẹ́tí sí i. “Ọwọ́ yín kún fún ẹ̀jẹ̀.
Nangmouh ni, na kut na kadai awh toteh, alouklah na kangvawi takhai awh han. Avai moikapap na ratoum awh nakunghai, ka thai mahoeh. Na kutnaw teh thi hoi akawi.
16 “Wẹ̀ kí ẹ sì jẹ́ kí ara yín mọ́. Ẹ mú ìwà ibi yín kúrò níwájú mi! Dáwọ́ àìṣedéédéé dúró,
Kâpasu awh, kamthoung awh. Na payonnae hah ka hmaitung hoi takhoe awh. Kahawihoehe nuencang hah kâhat awh leih.
17 kọ́ láti ṣe rere! Wá ìdájọ́ òtítọ́, tu àwọn tí a ń pọ́n lójú nínú. Ṣàtìlẹyìn fún ẹ̀tọ́ aláìní baba, gbà ẹjọ́ opó rò.
Kahawi hno sak hanelah kamtu awh. Lannae hah tawng awh. Ka lawngkoi e hah palan awh. Naranaw hanelah kalan lah sak awh. Lahmainunaw hanelah kalan lah sak awh. Lahmainunaw hah pahren awh.
18 “Ẹ wá ní ìsinsin yìí, ẹ jẹ́ kí a jọ ṣàṣàrò,” ni Olúwa wí. “Bí ẹ̀ṣẹ̀ yín bá rí bí osùn, wọn ó sì funfun bí i yìnyín, bí wọn bá sì pọ́n bí ẹ̀jẹ̀, wọn ó sì dàbí ẹ̀gbọ̀n òwú.
BAWIPA ni a dei e teh, tho awh. Cungtalah pouk awh haw sei. Nangmae yonnae teh ka paling nakunghai tadamtui patetlah a pangaw han. Âthi patetlah ka paling nakunghai tumuen patetlah ao han.
19 Tí ẹ̀yin bá fẹ́, tí ẹ sì gbọ́rọ̀, ẹ̀yin yóò sì jẹ ojúlówó adùn ilẹ̀ náà.
Nangmouh ni ngainae lahoi lawk na ngâi awh pawiteh, ram thung e hnokahawi e a pawnaw hah na ca awh han.
20 Ṣùgbọ́n tí ẹ bá kọ̀ tí ẹ sì ṣọ̀tẹ̀, idà ni a ó fi pa yín run.” Nítorí ẹnu Olúwa la ti sọ ọ́.
Hatei na taran awh pawiteh, tahloi hoi na due awh han telah BAWIPA e pahni ni a dei toe a ti.
21 Wo bí ìlú òtítọ́ ṣe di àgbèrè! Ó ti kún fún ìdájọ́ òtítọ́ nígbà kan rí, òdodo ń gbé ibẹ̀ tẹ́lẹ̀ rí, ṣùgbọ́n báyìí àwọn apànìyàn!
Yuemkamcu e kho teh bangtelamaw ka kâyawt e kho lah a kangcoung vaw. Ahmaloe teh, kângingnae hoi ka kawi e, a thung lannae ni hmuen a la e lah ao ei, atuteh tamikathetnaw ni hmuen lanae lah ao toe.
22 Fàdákà rẹ ti di ìpẹ́pẹ́, ààyò wáìnì rẹ la ti bu omi là.
Na tangka hai a ei lah ao toe. Na misurtui hai tui hoi a kâkalawt toe.
23 Ọlọ̀tẹ̀ ni àwọn aláṣẹ yín, akẹgbẹ́ àwọn olè, gbogbo wọn ló fẹ́ràn àbẹ̀tẹ́lẹ̀ wọ́n sì ń wá ẹ̀bùn kiri. Wọ́n kì í ṣàtìlẹyìn fún ẹ̀tọ́ aláìní baba, ẹjọ́ opó kì í sì í dé iwájú wọn.
Na khobawinaw teh, taran lah a thaw toe. Tamrunaw e hui lah ao awh toe. Hote bawinaw pueng ni tadawnghno a ngai awh teh, tawknae phu dueng a pâlei awh. Naranaw hah khenyawn awh hoeh. Lahmainunaw teh banglahai ngâi awh hoeh.
24 Nítorí náà ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, alágbára kan ṣoṣo tí Israẹli sọ wí pé: “Á à! Èmi yóò ní ìfọ̀kànbalẹ̀ lórí àwọn ọ̀tá mi n ó sì gbẹ̀san lára àwọn ọ̀tá mi.
Hatdawkvah, Isarelnaw e Athakaawme, ransahu Bawipa Jehovah ni a dei e teh, Aya! Kai na ka taran e naw hah bat ka takhoe vaiteh, ka tarannaw koe moi ka pathung han.
25 Èmi yóò pa ọwọ́ mi dà sí ọ, èmi ó sì ku ìpẹ́pẹ́ rẹ dànù, n ó sì mú gbogbo ìdọ̀tí rẹ kúrò.
Nang hah na kuet vaiteh, a ei hoi khoeroe na thoungsak vaiteh, thounghoehnae pueng ka takhoe han.
26 Èmi yóò mú àwọn adájọ́ rẹ bọ̀ sí ipò gẹ́gẹ́ bí i ti àtijọ́, àti àwọn olùdámọ̀ràn rẹ̀ bí i ti ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀. Lẹ́yìn náà ni a ó pè ọ ní ìlú òdodo, ìlú òtítọ́.”
Lawkcengkungnaw hoi pouknae kapoekung naw hah, ahmaloe ka ta e patetlah bout ka ta han. Hathnukkhu lannae khopui, yuemkamcu e khopui ati awh han.
27 A ó fi ìdájọ́ òtítọ́ ra Sioni padà, àti àwọn tí ó ronúpìwàdà pẹ̀lú òdodo.
Zion teh kângingnae hoi thoseh, lannae hoi thoseh ratang lah ao han.
28 Ṣùgbọ́n àwọn ọlọ̀tẹ̀ àti àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ ni a ó parun. Àwọn tí ó bá sì kọ Olúwa sílẹ̀ ni yóò ṣègbé.
Kâtapoe e hoi ka yon e tami teh reirei raphoe lah ao han. Cathut ka cettakhai e teh hraba mueng ka yawng lah hmaisawi han.
29 “Ojú yóò tì yín nítorí igi óákù mímọ́ èyí tí ẹ ní inú dídùn sí, a ó kàn yín lábùkù nítorí àwọn ọgbà yìí tí ẹ ti yàn fúnra yín.
Na doun e kathenkungnaw hah na kayakkhai awh toung vaiteh, na kârawi e takha ni kângai lah a ru sak awh han. Minhmai mathoe na poe awh han.
30 Ẹ ó sì dàbí igi óákù tí ewé rẹ̀ ti rọ, bí ọgbà tí kò ní omi.
Bangkongtetpawiteh, a hna kamyai e kathen kung hoi tui kahak e takha patetlah lah na o awh han.
31 Alágbára ọkùnrin náà yóò sì dàbí ohun ìdáná, iṣẹ́ rẹ̀ bí ẹ̀ṣẹ́-iná, àwọn méjèèjì ni yóò jóná papọ̀, láìsí ẹni tí yóò lè pa iná yìí.”
Athakaawme taminaw teh ngun ei patetlah awm vaiteh, a tawksak e teh hmaitali patetlah ao han. Hottaroi teh reirei kang vaiteh, hote hmai hah apinihai padout mahoeh.

< Isaiah 1 >