< Hosea 1 >
1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Hosea ọmọ Beeri wá ní àkókò ìjọba Ussiah, Jotamu, Ahasi àti Hesekiah; àwọn ọba Juda àti ní àkókò ọba Jeroboamu ọmọ Jehoaṣi ní Israẹli.
Gospodova beseda, ki je prišla Beeríjevemu sinu Ozeju v dneh Uzíjaha, Jotáma, Aháza in Ezekíja, Judovih kraljev in v dneh Joáševega sina Jerobeáma, Izraelovega kralja.
2 Nígbà tí Olúwa bẹ̀rẹ̀ sí ní sọ̀rọ̀ láti ẹnu Hosea, Olúwa wí fún un pé, “Lọ, fẹ́ àgbèrè obìnrin kan fún ara rẹ, kí ó sì bí ọmọ àgbèrè fún ọ nípasẹ̀ àwọn ọkùnrin mìíràn, nítorí ilẹ̀ ti ṣẹ ẹ̀ṣẹ̀ àgbèrè púpọ̀ nípa yíyapa kúrò lọ́dọ̀ Olúwa.”
Začetek Gospodove besede po Ozeju. Gospod je Ozeju rekel: »Pojdi, vzemi si ženo vlačugarstev in otroke vlačugarstev, kajti dežela je zagrešila veliko vlačugarstvo, odhajajoč od Gospoda.«
3 Nígbà náà ni ó sì lọ, ó sì fẹ́ Gomeri ọmọbìnrin Diblaimu, ọmọbìnrin náà sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan fún un.
Torej je odšel in vzel Diblájimovo hčer Gómero, ki je spočela in mu rodila sina.
4 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Hosea pé, “Pe orúkọ ọmọ náà ní Jesreeli, nítorí pé láìpẹ́ ni èmi yóò jẹ ìdílé Jehu ní ìyà fún ẹ̀jẹ̀ àwọn ènìyàn tó pa ní ìpakúpa ní Jesreeli, Èmi yóò sì mú ìjọba Israẹli wá sí òpin.
Gospod mu je rekel: »Njegovo ime kliči Jezreél, kajti le še malo in jaz bom maščeval kri Jezreéla na Jehújevi hiši in povzročil bom, da bo prenehalo kraljestvo Izraelove hiše.
5 Ní ọjọ́ náà ni Èmi yóò ṣẹ́ ọrun Israẹli ní àfonífojì Jesreeli.”
Na ta dan se bo zgodilo, da bom Izraelov lok zlomil v dolini Jezreél.«
6 Gomeri sì tún lóyún, ó sì bí ọmọbìnrin kan. Olúwa sọ fún un pé, “Pe orúkọ rẹ̀ ní Lo-ruhama, nítorí pé, Èmi kò ní ṣàánú fún ilé Israẹli mọ́, Èmi kò sì ní dáríjì wọ́n.
Ponovno je spočela in rodila hčer. Bog mu je rekel: »Njeno ime kliči Nepomiloščena, kajti ne bom več imel milosti nad Izraelovo hišo, temveč jih bom popolnoma odvedel stran.
7 Síbẹ̀, èmi yóò ṣàánú fún ilé Juda, èmi ó gbà wọ́n—kì í ṣe nípa ọfà, idà tàbí ogun, ẹṣin tàbí kẹ̀kẹ́ ẹlẹ́ṣin bí kò ṣe nípa Olúwa Ọlọ́run wọn.”
Toda imel bom usmiljenje nad Judovo hišo in rešil jih bom po Gospodu, njihovem Bogu in ne bom jih rešil z lokom, niti z mečem, niti z bitko, [niti] s konji, niti s konjeniki.«
8 Lẹ́yìn ìgbà tí ó gba ọmú lẹ́nu Lo-ruhama, ó sì lóyún ó sì bí ọmọkùnrin mìíràn. Nígbà náà ni
Torej, ko je odstavila Nepomiloščeno, je spočela in rodila sina.
9 Olúwa sì sọ fún un pé, “Pe orúkọ rẹ̀ ní Lo-Ammi, nítorí pé ẹ kì í ṣe ènìyàn mi, èmi náà kì í sì í ṣe Ọlọ́run yín.
Potem je Bog rekel: »Njegovo ime kliči Ne-moje-ljudstvo, kajti vi niste moje ljudstvo in jaz ne bom vaš Bog.«
10 “Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Israẹli yóò pọ̀ bí i iyanrìn etí Òkun tí a kò le wọ́n, tí a kò sì le è kà, yóò sì ṣe. Ní ibi tí wọ́n ti sọ fún wọn pé. ‘Ẹ̀yin kì í ṣe ènìyàn mi,’ níbẹ̀ ni a ó ti máa pè wọ́n ní ‘Ọmọ Ọlọ́run alààyè.’
Vendar bo število Izraelovih otrok kakor morskega peska, ki ne more biti izmerjen niti preštet in zgodilo se bo, da jim bo na kraju, kjer jim je bilo rečeno: ›Vi niste moje ljudstvo, ‹ tam jim bo rečeno: › Vi ste sinovi živega Boga.‹
11 Àwọn ènìyàn Juda àti àwọn ènìyàn Israẹli yóò parapọ̀, wọn yóò sì yan olórí kan tí yóò jáde láti ilẹ̀ náà, nítorí pé ọjọ́ ńlá ni ọjọ́ Jesreeli yóò jẹ́.
Potem bodo Judovi otroci in Izraelovi otroci zbrani skupaj in določili si bodo eno glavo in prišli bodo gor iz dežele, kajti velik bo Jezreélov dan.‹