< Hosea 1 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Hosea ọmọ Beeri wá ní àkókò ìjọba Ussiah, Jotamu, Ahasi àti Hesekiah; àwọn ọba Juda àti ní àkókò ọba Jeroboamu ọmọ Jehoaṣi ní Israẹli.
Ilizwi likaThixo lafika kuHosiya indodana kaBheri ngezinsuku zemibuso yabo-Uziya, loJothamu, lo-Ahazi loHezekhiya amakhosi akoJuda, kanye lasezinsukwini zokubusa kukaJerobhowamu indodana kaJowashi inkosi yako-Israyeli.
2 Nígbà tí Olúwa bẹ̀rẹ̀ sí ní sọ̀rọ̀ láti ẹnu Hosea, Olúwa wí fún un pé, “Lọ, fẹ́ àgbèrè obìnrin kan fún ara rẹ, kí ó sì bí ọmọ àgbèrè fún ọ nípasẹ̀ àwọn ọkùnrin mìíràn, nítorí ilẹ̀ ti ṣẹ ẹ̀ṣẹ̀ àgbèrè púpọ̀ nípa yíyapa kúrò lọ́dọ̀ Olúwa.”
Kwathi uThixo eseqalise ukukhuluma ngoHosiya, uThixo wathi kuye, “Hamba uyethatha umfazi oyisifebe ubelabantwana bobufebe, ngoba ilizwe lilecala lobufebe obubi kakhulu ngokweduka kuThixo.”
3 Nígbà náà ni ó sì lọ, ó sì fẹ́ Gomeri ọmọbìnrin Diblaimu, ọmọbìnrin náà sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan fún un.
Ngakho wathatha uGomeri indodakazi kaDibilayimi, njalo wathatha isisu wamzalela indodana.
4 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Hosea pé, “Pe orúkọ ọmọ náà ní Jesreeli, nítorí pé láìpẹ́ ni èmi yóò jẹ ìdílé Jehu ní ìyà fún ẹ̀jẹ̀ àwọn ènìyàn tó pa ní ìpakúpa ní Jesreeli, Èmi yóò sì mú ìjọba Israẹli wá sí òpin.
UThixo wasesithi kuHoseya, “Methe ibizo uthi nguJezerili, ngoba masinyane nje ngizayijezisa indlu kaJehu ngenxa yesihluku sokubulala abantu abanengi eJezerili, njalo ngizawuqeda umbuso wako-Israyeli.
5 Ní ọjọ́ náà ni Èmi yóò ṣẹ́ ọrun Israẹli ní àfonífojì Jesreeli.”
Ngalolosuku ngizakwephula idandili lika-Israyeli eSigodini saseJezerili.”
6 Gomeri sì tún lóyún, ó sì bí ọmọbìnrin kan. Olúwa sọ fún un pé, “Pe orúkọ rẹ̀ ní Lo-ruhama, nítorí pé, Èmi kò ní ṣàánú fún ilé Israẹli mọ́, Èmi kò sì ní dáríjì wọ́n.
UGomeri wathatha isisu futhi, wazala indodakazi. UThixo wasesithi, “Muphe ibizo uthi nguLo-Ruhama, ngoba kangisoze ngibe lothando futhi endlini ka-Israyeli, ukuba ngibathethelele.
7 Síbẹ̀, èmi yóò ṣàánú fún ilé Juda, èmi ó gbà wọ́n—kì í ṣe nípa ọfà, idà tàbí ogun, ẹṣin tàbí kẹ̀kẹ́ ẹlẹ́ṣin bí kò ṣe nípa Olúwa Ọlọ́run wọn.”
Kodwa ngizakuba lothando endlini kaJuda, njalo ngizabakhulula, kungayisikho ngedandili, inkemba kumbe impi, loba ngamabhiza langabagadi bamabhiza, kodwa ngoThixo uNkulunkulu wabo.”
8 Lẹ́yìn ìgbà tí ó gba ọmú lẹ́nu Lo-ruhama, ó sì lóyún ó sì bí ọmọkùnrin mìíràn. Nígbà náà ni
UGomeri eselumule uLo-Ruhama ebeleni, waba lenye indodana.
9 Olúwa sì sọ fún un pé, “Pe orúkọ rẹ̀ ní Lo-Ammi, nítorí pé ẹ kì í ṣe ènìyàn mi, èmi náà kì í sì í ṣe Ọlọ́run yín.
UThixo wasesithi, “Muphe ibizo lokuthi nguLo-Ami, ngoba lina kalisibo bantu bami, lami kangisuye uNkulunkulu wenu.
10 “Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Israẹli yóò pọ̀ bí i iyanrìn etí Òkun tí a kò le wọ́n, tí a kò sì le è kà, yóò sì ṣe. Ní ibi tí wọ́n ti sọ fún wọn pé. ‘Ẹ̀yin kì í ṣe ènìyàn mi,’ níbẹ̀ ni a ó ti máa pè wọ́n ní ‘Ọmọ Ọlọ́run alààyè.’
Kodwa abako-Israyeli bazakuba njengetshebetshebe ekhunjini lolwandle elingeke lilinganiswe kumbe libalwe. Endaweni lapho okwakuthiwe khona kubo, ‘Kalisibo bantu bami,’ bazabizwa ngokuthi, ‘bantwana bakaNkulunkulu ophilayo.’
11 Àwọn ènìyàn Juda àti àwọn ènìyàn Israẹli yóò parapọ̀, wọn yóò sì yan olórí kan tí yóò jáde láti ilẹ̀ náà, nítorí pé ọjọ́ ńlá ni ọjọ́ Jesreeli yóò jẹ́.
Abantu bakoJuda labantu bako-Israyeli bazamanyana, njalo bazakhetha umkhokheli oyedwa baphume elizweni, ngoba luzakuba lukhulu usuku lukaJezerili.”

< Hosea 1 >