< Hosea 1 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Hosea ọmọ Beeri wá ní àkókò ìjọba Ussiah, Jotamu, Ahasi àti Hesekiah; àwọn ọba Juda àti ní àkókò ọba Jeroboamu ọmọ Jehoaṣi ní Israẹli.
Paroles du Seigneur qui vinrent à Osée, fils de Béeri, durant les jours d'Ozias, et de Joathan, et d'Achaz, et d'Ézéchias, rois de Juda, et durant les jours de Jéroboam, fils de Joas, roi d'Israël.
2 Nígbà tí Olúwa bẹ̀rẹ̀ sí ní sọ̀rọ̀ láti ẹnu Hosea, Olúwa wí fún un pé, “Lọ, fẹ́ àgbèrè obìnrin kan fún ara rẹ, kí ó sì bí ọmọ àgbèrè fún ọ nípasẹ̀ àwọn ọkùnrin mìíràn, nítorí ilẹ̀ ti ṣẹ ẹ̀ṣẹ̀ àgbèrè púpọ̀ nípa yíyapa kúrò lọ́dọ̀ Olúwa.”
Commencement des paroles du Seigneur à Osée. Et le Seigneur dit à Osée: Va et prends pour toi une femme de prostitution; aie des enfants de la prostitution, parce que la terre se prostitue, et se prostituera en se retirant du Seigneur.
3 Nígbà náà ni ó sì lọ, ó sì fẹ́ Gomeri ọmọbìnrin Diblaimu, ọmọbìnrin náà sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan fún un.
Et il alla, et il prit Gomer, fille de Debélaïm, et elle conçut, et elle lui enfanta un fils.
4 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Hosea pé, “Pe orúkọ ọmọ náà ní Jesreeli, nítorí pé láìpẹ́ ni èmi yóò jẹ ìdílé Jehu ní ìyà fún ẹ̀jẹ̀ àwọn ènìyàn tó pa ní ìpakúpa ní Jesreeli, Èmi yóò sì mú ìjọba Israẹli wá sí òpin.
Et le Seigneur lui dit: Donne-lui le nom de Jezraël, parce que, encore un peu de temps, et Je vengerai le sang de Jezraël sur la maison de Juda, et Je ferai cesser la royauté de la maison d'Israël.
5 Ní ọjọ́ náà ni Èmi yóò ṣẹ́ ọrun Israẹli ní àfonífojì Jesreeli.”
Et il arrivera, en ce jour-là, que Je briserai l'arc d'Israël dans la vallée de Jezraël.
6 Gomeri sì tún lóyún, ó sì bí ọmọbìnrin kan. Olúwa sọ fún un pé, “Pe orúkọ rẹ̀ ní Lo-ruhama, nítorí pé, Èmi kò ní ṣàánú fún ilé Israẹli mọ́, Èmi kò sì ní dáríjì wọ́n.
Et elle conçut encore, et elle enfanté une fille. Et le Seigneur dit à Osée: Donne-lui le nom de Sans-Pitié, parce que Je ne continuerai plus d'avoir pitié de la maison d'Israël, mais Je lui résisterai et lui résisterai.
7 Síbẹ̀, èmi yóò ṣàánú fún ilé Juda, èmi ó gbà wọ́n—kì í ṣe nípa ọfà, idà tàbí ogun, ẹṣin tàbí kẹ̀kẹ́ ẹlẹ́ṣin bí kò ṣe nípa Olúwa Ọlọ́run wọn.”
Envers les fils de Juda Je serai miséricordieux, et Je les sauverai par le Seigneur leur Dieu; mais Je ne les sauverai pas par l'arc, ni par le glaive, ni par la guerre, ni par les chevaux, ni par les cavaliers.
8 Lẹ́yìn ìgbà tí ó gba ọmú lẹ́nu Lo-ruhama, ó sì lóyún ó sì bí ọmọkùnrin mìíràn. Nígbà náà ni
Et elle sevra cette fille Sans-Pitié; et elle conçut encore, et elle enfanta un fils.
9 Olúwa sì sọ fún un pé, “Pe orúkọ rẹ̀ ní Lo-Ammi, nítorí pé ẹ kì í ṣe ènìyàn mi, èmi náà kì í sì í ṣe Ọlọ́run yín.
Le Seigneur dit à Osée: Appelle-le Non-Mon-Peuple; parce que vous n'êtes plus Mon peuple, et Je ne suis plus votre Dieu.
10 “Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Israẹli yóò pọ̀ bí i iyanrìn etí Òkun tí a kò le wọ́n, tí a kò sì le è kà, yóò sì ṣe. Ní ibi tí wọ́n ti sọ fún wọn pé. ‘Ẹ̀yin kì í ṣe ènìyàn mi,’ níbẹ̀ ni a ó ti máa pè wọ́n ní ‘Ọmọ Ọlọ́run alààyè.’
Et le nombre des fils d'Israël a été comme le sable de la mer, que l'on ne peut ni mesurer ni compter; et ceci arrivera dans le lieu même où il leur a été dit: Vous n'êtes plus Mon peuple; et ils seront appelés fils du Dieu vivant.
11 Àwọn ènìyàn Juda àti àwọn ènìyàn Israẹli yóò parapọ̀, wọn yóò sì yan olórí kan tí yóò jáde láti ilẹ̀ náà, nítorí pé ọjọ́ ńlá ni ọjọ́ Jesreeli yóò jẹ́.
Et les fils de Juda se réuniront, et en même temps ceux d'Israël, et ils institueront pour eux une seule principauté, et ils se répandront sur la terre, parce que le jour de Jezraël est grand.

< Hosea 1 >