< Hosea 1 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Hosea ọmọ Beeri wá ní àkókò ìjọba Ussiah, Jotamu, Ahasi àti Hesekiah; àwọn ọba Juda àti ní àkókò ọba Jeroboamu ọmọ Jehoaṣi ní Israẹli.
The word of the Lord that was maad to Osee, the sone of Bery, in the daies of Osie, Joathan, Achas, Ezechie, kingis of Juda, and in the daies of Jeroboam, sone of Joas, the kyng of Israel.
2 Nígbà tí Olúwa bẹ̀rẹ̀ sí ní sọ̀rọ̀ láti ẹnu Hosea, Olúwa wí fún un pé, “Lọ, fẹ́ àgbèrè obìnrin kan fún ara rẹ, kí ó sì bí ọmọ àgbèrè fún ọ nípasẹ̀ àwọn ọkùnrin mìíràn, nítorí ilẹ̀ ti ṣẹ ẹ̀ṣẹ̀ àgbèrè púpọ̀ nípa yíyapa kúrò lọ́dọ̀ Olúwa.”
The bigynnyng of the spekyng to the Lord in Osee. And the Lord seide to Osee, Go thou, take to thee a wijf of fornycaciouns, and make to thee sones of fornycaciouns, for the lond doynge fornicacioun schal do fornicacioun fro the Lord.
3 Nígbà náà ni ó sì lọ, ó sì fẹ́ Gomeri ọmọbìnrin Diblaimu, ọmọbìnrin náà sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan fún un.
And he yede, and took Gomer, the douyter of Debelaym; and sche conseyuede, and childide a sone to hym.
4 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Hosea pé, “Pe orúkọ ọmọ náà ní Jesreeli, nítorí pé láìpẹ́ ni èmi yóò jẹ ìdílé Jehu ní ìyà fún ẹ̀jẹ̀ àwọn ènìyàn tó pa ní ìpakúpa ní Jesreeli, Èmi yóò sì mú ìjọba Israẹli wá sí òpin.
And the Lord seide to hym, Clepe thou the name of hym Jesrael; for yit a litil and Y schal visite the blood of Jesrael on the hous of Hieu, and Y schal make to reste the rewme of the hous of Israel.
5 Ní ọjọ́ náà ni Èmi yóò ṣẹ́ ọrun Israẹli ní àfonífojì Jesreeli.”
And in that dai Y schal al to-breke the bowe of Israel in the valei of Jesrael.
6 Gomeri sì tún lóyún, ó sì bí ọmọbìnrin kan. Olúwa sọ fún un pé, “Pe orúkọ rẹ̀ ní Lo-ruhama, nítorí pé, Èmi kò ní ṣàánú fún ilé Israẹli mọ́, Èmi kò sì ní dáríjì wọ́n.
And sche conseyuede yit, and childide a douyter. And the Lord seide to hym, Clepe thou the name of hir With out merci, for Y schal no more leye to, for to haue merci on the hous of Israel, but bi foryetyng Y schal foryete hem.
7 Síbẹ̀, èmi yóò ṣàánú fún ilé Juda, èmi ó gbà wọ́n—kì í ṣe nípa ọfà, idà tàbí ogun, ẹṣin tàbí kẹ̀kẹ́ ẹlẹ́ṣin bí kò ṣe nípa Olúwa Ọlọ́run wọn.”
And Y schal haue merci on the hous of Juda, and Y schal saue hem in her Lord God; and Y schal not saue hem in bowe, and swerd, and batel, and in horsis, and in horse men, ether kniytis.
8 Lẹ́yìn ìgbà tí ó gba ọmú lẹ́nu Lo-ruhama, ó sì lóyún ó sì bí ọmọkùnrin mìíràn. Nígbà náà ni
And he wenyde hir that was With out merci. And sche conseyuede, and childide a sone to hym.
9 Olúwa sì sọ fún un pé, “Pe orúkọ rẹ̀ ní Lo-Ammi, nítorí pé ẹ kì í ṣe ènìyàn mi, èmi náà kì í sì í ṣe Ọlọ́run yín.
And he seide, Clepe thou his name Not my puple, for ye schulen not be my puple, and Y schal not be youre God.
10 “Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Israẹli yóò pọ̀ bí i iyanrìn etí Òkun tí a kò le wọ́n, tí a kò sì le è kà, yóò sì ṣe. Ní ibi tí wọ́n ti sọ fún wọn pé. ‘Ẹ̀yin kì í ṣe ènìyàn mi,’ níbẹ̀ ni a ó ti máa pè wọ́n ní ‘Ọmọ Ọlọ́run alààyè.’
And the noumbre of the sones of Israel schal be as grauel of the see, which grauel is with out mesure, and it schal not be noumbrid; and it schal be in the place, where it schal be seid to hem, Ye ben not my puple; it schal be seid to hem, Ye ben the sones of God lyuynge.
11 Àwọn ènìyàn Juda àti àwọn ènìyàn Israẹli yóò parapọ̀, wọn yóò sì yan olórí kan tí yóò jáde láti ilẹ̀ náà, nítorí pé ọjọ́ ńlá ni ọjọ́ Jesreeli yóò jẹ́.
And the sones of Juda and the sones of Israel schulen be gaderid togidere, and thei schulen sette oon heed to hem silf, and thei schulen stie fro erthe, for the dai of Jesrael is greet.

< Hosea 1 >