< Hosea 9 >

1 Má ṣe yọ̀, ìwọ Israẹli; má ṣe hó ìhó ayọ̀ bí àwọn orílẹ̀-èdè yòókù. Nítorí ẹ ti jẹ́ aláìṣòótọ́ si Ọlọ́run yín. Ẹ fẹ́ràn láti gba owó iṣẹ́ àgbèrè ní gbogbo ilẹ̀ ìpakà.
Nu te bucura, Israele, veselindu-te ca alte popoare, pentru că ai plecat curvind de la Dumnezeul tău, ai iubit o răsplată în fiecare arie de grâu.
2 Àwọn ilẹ̀ ìpakà àti ilé ìfun wáìnì kò ní fún àwọn ènìyàn lóúnjẹ wáìnì tuntun yóò tàn láìròtẹ́lẹ̀.
Aria şi teascul nu îi vor hrăni şi vinul nou îi va lipsi.
3 Wọn kò ní ṣẹ́kù sí ilé Olúwa Efraimu yóò padà sí Ejibiti, yóò sì jẹ oúnjẹ àìmọ́ ní Asiria.
Ei nu vor locui în ţara DOMNULUI; ci Efraim se va întoarce în Egipt şi vor mânca lucruri necurate în Asiria.
4 Wọn kò ní fi ọrẹ ohun mímu fún Olúwa. Bẹ́ẹ̀ ni ìrúbọ wọn kò ní mú, inú rẹ̀ dùn. Ìrú ẹbọ bẹ́ẹ̀ yóò dàbí oúnjẹ àwọn tí ń ṣọ̀fọ̀. Gbogbo àwọn tó bá sì jẹ ẹ́ yóò di aláìmọ́. Oúnjẹ yìí yóò wà fún wọn fúnra wọn kò ní wá sí orí tẹmpili Olúwa.
Nu vor aduce DOMNULUI ofrande de vin, nici nu îi vor fi acestea plăcute; sacrificiile lor le vor fi ca pâinea jelitorilor; toţi care mănâncă din ea se vor pângări, pentru că pâinea lor, pentru sufletul lor, nu va intra în casa DOMNULUI.
5 Kí ni ẹ̀yin ó ṣe ní ọjọ́ àjọ̀dún tí a yàn ní àwọn ọjọ́ àjọ̀dún Olúwa?
Ce veţi face în ziua solemnă şi în ziua sărbătorii DOMNULUI?
6 Bí wọ́n tilẹ̀ yọ́ kúrò lọ́wọ́ ìparun Ejibiti yóò kó wọn jọ, Memfisi yóò sì sin wọ́n. Ibi ìsọjọ̀ fàdákà wọn ni ẹ̀gún yóò jogún, Ẹ̀gún yóò bo àpótí ìṣúra fàdákà wọn. Ẹ̀gún yóò sì bo gbogbo àgọ́ wọn.
Fiindcă, iată, ei au plecat din cauza nimicirii; Egiptul îi va aduna, Memfis îi va îngropa; urzicile vor stăpâni locurile plăcute pentru argintul lor; spini vor fi în corturile lor.
7 Àwọn ọjọ́ ìjìyà ń bọ̀; àwọn ọjọ́ ìṣirò iṣẹ́ ti dé. Jẹ́ kí Israẹli mọ èyí. Nítorí pé ẹ̀ṣẹ̀ yín pọ̀ ìkórìíra yín sì pọ̀ gan an ni. A ka àwọn wòlíì sí òmùgọ̀, a ka ẹni ìmísí sí asínwín.
Zilele cercetării au venit, zilele răsplătirii au venit; Israel va cunoaşte aceasta; profetul este un prost, omul spiritual este nebun, din cauza mulţimii nelegiuirilor tale şi a urii tale mari.
8 Wòlíì, papọ̀ pẹ̀lú Ọlọ́run, ni olùṣọ́ ọ Efraimu. Síbẹ̀ ìdẹ̀kùn dúró dè é ní gbogbo ọ̀nà rẹ̀ àti ìkórìíra ní ilé Ọlọ́run rẹ̀.
Paznicul lui Efraim era cu Dumnezeul meu; dar profetul este o capcană a unui păsărar în toate căile sale şi ură în casa Dumnezeului său.
9 Wọ́n ti gbilẹ̀ nínú ìwà ìbàjẹ́ gẹ́gẹ́ bí i ọjọ́ Gibeah Ọlọ́run yóò rántí ìwà búburú wọn yóò sì jẹ wọ́n ní yà fún ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
S-au corupt profund pe ei înşişi, ca în zilele din Ghibea; de aceea el îşi va aminti de nelegiuirile lor, va cerceta păcatele lor.
10 “Mo rí Israẹli bí èso àjàrà ní aginjù. Mo rí àwọn baba yín, bí àkọ́pọ́n nínú igi ọ̀pọ̀tọ́ ní àkọ́so rẹ̀. Ṣùgbọ́n wọ́n tọ Baali-Peori lọ, wọ́n yà wọn sọ́tọ̀ fún òrìṣà tó ń mú ìtìjú bá ni, ohun ìríra wọn sì rí gẹ́gẹ́ bí wọn ti fẹ́.
Am găsit pe Israel ca struguri în pustie; am văzut pe părinții voştri ca pe întâiul rod al smochinului la prima recoltă; dar ei au mers la Baal-Peor şi s-au consacrat acestei ruşini şi urâciunile [lor] au devenit asemenea iubirii lor.
11 Ògo Efraimu yóò fò lọ bí ẹyẹ kò ní sí ìfẹ́rakù, ìlóyún àti ìbímọ.
Cât despre Efraim, gloria lor va zbura ca o pasăre, de la naştere şi din pântece şi de la concepere.
12 Bí wọ́n tilẹ̀ tọ́ ọmọ dàgbà. Èmi yóò mú wọn ṣọ̀fọ̀ lórí gbogbo wọn. Ègbé ni fún wọn, nígbà tí mo yípadà kúrò lọ́dọ̀ wọn!
Deşi îşi cresc copiii, totuşi eu îi voi văduvi de ei, ca să nu rămână niciun bărbat; da, vai de asemenea lor, când mă voi depărta de ei!
13 Mo rí Efraimu bí ìlú Tire tí a tẹ̀dó sí ibi dáradára ṣùgbọ́n Efraimu yóò kó àwọn ọmọ rẹ̀ jáde fún àwọn apànìyàn.”
Efraimul, precum am văzut Tirul, este sădit într-un loc plăcut; dar Efraim îşi va aduce copiii înaintea ucigaşului.
14 Fún wọn, Olúwa! Kí ni ìwọ yóò fún wọn? Fún wọn ní inú tí ń ba oyún jẹ́ àti ọyàn gbígbẹ.
Dă-le, DOAMNE! Ce le vei da? Dă-le un pântece sterp şi sâni seci.
15 “Nítorí gbogbo ìwà búburú tí wọ́n hù ní Gilgali, Mo kórìíra wọn níbẹ̀, nítorí ìwà ẹ̀ṣẹ̀ wọn. Èmi yóò lé wọn jáde ní ilé mi, Èmi kò ní ní ìfẹ́ wọn mọ́ ọlọ̀tẹ̀ ni gbogbo olórí wọn.
Toată stricăciunea lor este în Ghilgal; fiindcă acolo i-am urât; pentru stricăciunea faptelor lor îi vor alunga din casa mea, nu îi voi mai iubi; toţi prinţii lor sunt răzvrătiţi.
16 Efraimu ti rẹ̀ dànù gbogbo rẹ̀ sì ti rọ, kò sì so èso. Bí wọ́n tilẹ̀ bímọ. Èmi ó pa àwọn ọmọ wọn tí wọ́n fẹ́ràn jùlọ.”
Efraim este lovit, rădăcina lor este uscată, rod nu vor aduce; da, chiar dacă ar naşte, totuşi voi ucide rodul iubit al pântecului lor.
17 Ọlọ́run mi yóò kọ̀ wọ́n sílẹ̀ nítorí pé wọn kò gbọ́rọ̀ sí i; wọn yóò sì di alárìnkiri láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.
Dumnezeul meu îi va lepăda, pentru că nu i-au dat ascultare; şi ei vor fi rătăcitori printre naţiuni.

< Hosea 9 >