< Hosea 9 >

1 Má ṣe yọ̀, ìwọ Israẹli; má ṣe hó ìhó ayọ̀ bí àwọn orílẹ̀-èdè yòókù. Nítorí ẹ ti jẹ́ aláìṣòótọ́ si Ọlọ́run yín. Ẹ fẹ́ràn láti gba owó iṣẹ́ àgbèrè ní gbogbo ilẹ̀ ìpakà.
Não te alegres, ó Israel, até saltar, como os povos; porque pela fornicação abandonaste o teu Deus: amaste a paga de meretriz sobre todas as eiras de trigo.
2 Àwọn ilẹ̀ ìpakà àti ilé ìfun wáìnì kò ní fún àwọn ènìyàn lóúnjẹ wáìnì tuntun yóò tàn láìròtẹ́lẹ̀.
A eira e o lagar não os manterão; e o mosto lhe faltará.
3 Wọn kò ní ṣẹ́kù sí ilé Olúwa Efraimu yóò padà sí Ejibiti, yóò sì jẹ oúnjẹ àìmọ́ ní Asiria.
Na terra do Senhor não permanecerão; mas Ephraim tornará ao Egito, e na Assyria comerão o imundo.
4 Wọn kò ní fi ọrẹ ohun mímu fún Olúwa. Bẹ́ẹ̀ ni ìrúbọ wọn kò ní mú, inú rẹ̀ dùn. Ìrú ẹbọ bẹ́ẹ̀ yóò dàbí oúnjẹ àwọn tí ń ṣọ̀fọ̀. Gbogbo àwọn tó bá sì jẹ ẹ́ yóò di aláìmọ́. Oúnjẹ yìí yóò wà fún wọn fúnra wọn kò ní wá sí orí tẹmpili Olúwa.
Não derramarão vinho ao Senhor, nem lhe serão suaves: os seus sacrifícios lhes serão como pão de pranto; todos os que dele comerem serão imundos, porque o seu pão é por sua alma; não entrará na casa do Senhor
5 Kí ni ẹ̀yin ó ṣe ní ọjọ́ àjọ̀dún tí a yàn ní àwọn ọjọ́ àjọ̀dún Olúwa?
Que fareis vós no dia da solenidade, e no dia da festa do Senhor?
6 Bí wọ́n tilẹ̀ yọ́ kúrò lọ́wọ́ ìparun Ejibiti yóò kó wọn jọ, Memfisi yóò sì sin wọ́n. Ibi ìsọjọ̀ fàdákà wọn ni ẹ̀gún yóò jogún, Ẹ̀gún yóò bo àpótí ìṣúra fàdákà wọn. Ẹ̀gún yóò sì bo gbogbo àgọ́ wọn.
Porque, eis que eles se foram por causa da destruição: o Egito os recolherá, Memphis os sepultará: o desejável da sua prata as ortigas o possuirão por herança, espinhos haverá nas suas moradas.
7 Àwọn ọjọ́ ìjìyà ń bọ̀; àwọn ọjọ́ ìṣirò iṣẹ́ ti dé. Jẹ́ kí Israẹli mọ èyí. Nítorí pé ẹ̀ṣẹ̀ yín pọ̀ ìkórìíra yín sì pọ̀ gan an ni. A ka àwọn wòlíì sí òmùgọ̀, a ka ẹni ìmísí sí asínwín.
Já chegaram os dias da visitação, já chegaram os dias da retribuição; os de Israel o saberão: o profeta é louco, o homem de espírito é furioso; por causa da abundância da tua iniquidade também abundará o ódio.
8 Wòlíì, papọ̀ pẹ̀lú Ọlọ́run, ni olùṣọ́ ọ Efraimu. Síbẹ̀ ìdẹ̀kùn dúró dè é ní gbogbo ọ̀nà rẹ̀ àti ìkórìíra ní ilé Ọlọ́run rẹ̀.
Ephraim era o vigia com o meu Deus, mas o profeta é como um laço de caçador de aves em todos os seus caminhos, ódio na casa do seu Deus.
9 Wọ́n ti gbilẹ̀ nínú ìwà ìbàjẹ́ gẹ́gẹ́ bí i ọjọ́ Gibeah Ọlọ́run yóò rántí ìwà búburú wọn yóò sì jẹ wọ́n ní yà fún ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
Mui profundamente se corromperam, como nos dias de Gibeah: lembrar-se-á das suas injustiças, visitará os pecados deles.
10 “Mo rí Israẹli bí èso àjàrà ní aginjù. Mo rí àwọn baba yín, bí àkọ́pọ́n nínú igi ọ̀pọ̀tọ́ ní àkọ́so rẹ̀. Ṣùgbọ́n wọ́n tọ Baali-Peori lọ, wọ́n yà wọn sọ́tọ̀ fún òrìṣà tó ń mú ìtìjú bá ni, ohun ìríra wọn sì rí gẹ́gẹ́ bí wọn ti fẹ́.
Achei a Israel como uvas no deserto, vi a vossos pais como a fruta temporã da figueira no seu princípio; porém entraram a Baalpeor, e se apartaram para essa vergonha, e se tornaram abomináveis como aquilo que amaram.
11 Ògo Efraimu yóò fò lọ bí ẹyẹ kò ní sí ìfẹ́rakù, ìlóyún àti ìbímọ.
Quanto a Ephraim, a sua glória como ave voará desde o nascimento, e desde o ventre, e desde o concebimento.
12 Bí wọ́n tilẹ̀ tọ́ ọmọ dàgbà. Èmi yóò mú wọn ṣọ̀fọ̀ lórí gbogbo wọn. Ègbé ni fún wọn, nígbà tí mo yípadà kúrò lọ́dọ̀ wọn!
Ainda que venham a criar seus filhos, contudo os privarei deles dentre os homens, porque também, ai deles! quando me apartar deles.
13 Mo rí Efraimu bí ìlú Tire tí a tẹ̀dó sí ibi dáradára ṣùgbọ́n Efraimu yóò kó àwọn ọmọ rẹ̀ jáde fún àwọn apànìyàn.”
Ephraim, assim como vi a Tiro, plantada está num lugar deleitoso; mas Ephraim tirará para fora seus filhos para o matador.
14 Fún wọn, Olúwa! Kí ni ìwọ yóò fún wọn? Fún wọn ní inú tí ń ba oyún jẹ́ àti ọyàn gbígbẹ.
Dá-lhes, ó Senhor; que pois lhes darás? dá-lhes uma madre que aborte e seios secos.
15 “Nítorí gbogbo ìwà búburú tí wọ́n hù ní Gilgali, Mo kórìíra wọn níbẹ̀, nítorí ìwà ẹ̀ṣẹ̀ wọn. Èmi yóò lé wọn jáde ní ilé mi, Èmi kò ní ní ìfẹ́ wọn mọ́ ọlọ̀tẹ̀ ni gbogbo olórí wọn.
Toda a sua malícia se acha em Gilgal, porque ali os aborreci pela malícia das suas obras: lança-los-ei para fora de minha casa; não os amarei mais: todos os seus príncipes são rebeldes.
16 Efraimu ti rẹ̀ dànù gbogbo rẹ̀ sì ti rọ, kò sì so èso. Bí wọ́n tilẹ̀ bímọ. Èmi ó pa àwọn ọmọ wọn tí wọ́n fẹ́ràn jùlọ.”
Ephraim foi ferido, secou-se a sua raiz; não darão fruto: e, ainda que gerem, todavia matarei os desejáveis do seu ventre.
17 Ọlọ́run mi yóò kọ̀ wọ́n sílẹ̀ nítorí pé wọn kò gbọ́rọ̀ sí i; wọn yóò sì di alárìnkiri láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.
O meu Deus os rejeitará, porque não o ouvem, e vagabundos andarão entre as nações.

< Hosea 9 >