< Hosea 9 >

1 Má ṣe yọ̀, ìwọ Israẹli; má ṣe hó ìhó ayọ̀ bí àwọn orílẹ̀-èdè yòókù. Nítorí ẹ ti jẹ́ aláìṣòótọ́ si Ọlọ́run yín. Ẹ fẹ́ràn láti gba owó iṣẹ́ àgbèrè ní gbogbo ilẹ̀ ìpakà.
Tosanyuka ggwe Isirayiri; tojaguza ng’amawanga amalala, kubanga tobadde mwesigwa eri Katonda wo, weegomba empeera eya malaaya ku buli gguuliro.
2 Àwọn ilẹ̀ ìpakà àti ilé ìfun wáìnì kò ní fún àwọn ènìyàn lóúnjẹ wáìnì tuntun yóò tàn láìròtẹ́lẹ̀.
Egguuliro n’essogolero tebiribaliisa, ne wayini omusu alibaggwaako.
3 Wọn kò ní ṣẹ́kù sí ilé Olúwa Efraimu yóò padà sí Ejibiti, yóò sì jẹ oúnjẹ àìmọ́ ní Asiria.
Tebalisigala mu nsi ya Mukama; Efulayimu aliddayo e Misiri n’alya emmere etali nnongoofu mu Bwasuli.
4 Wọn kò ní fi ọrẹ ohun mímu fún Olúwa. Bẹ́ẹ̀ ni ìrúbọ wọn kò ní mú, inú rẹ̀ dùn. Ìrú ẹbọ bẹ́ẹ̀ yóò dàbí oúnjẹ àwọn tí ń ṣọ̀fọ̀. Gbogbo àwọn tó bá sì jẹ ẹ́ yóò di aláìmọ́. Oúnjẹ yìí yóò wà fún wọn fúnra wọn kò ní wá sí orí tẹmpili Olúwa.
Tebaliwaayo biweebwayo ebya wayini eri Mukama, so ne ssaddaaka zaabwe tezirimusanyusa. Ssaddaaka zaabwe ziriba ng’emmere ey’abakungubazi, ne bonna abaliziryako balifuuka abatali balongoofu. Emmere eyo eriba yaabwe bo, so teriyingizibwa mu yeekaalu ya Mukama.
5 Kí ni ẹ̀yin ó ṣe ní ọjọ́ àjọ̀dún tí a yàn ní àwọn ọjọ́ àjọ̀dún Olúwa?
Kiki ky’olikola ku lunaku olw’embaga ezaalondebwa, ku lunaku olw’embaga ya Mukama?
6 Bí wọ́n tilẹ̀ yọ́ kúrò lọ́wọ́ ìparun Ejibiti yóò kó wọn jọ, Memfisi yóò sì sin wọ́n. Ibi ìsọjọ̀ fàdákà wọn ni ẹ̀gún yóò jogún, Ẹ̀gún yóò bo àpótí ìṣúra fàdákà wọn. Ẹ̀gún yóò sì bo gbogbo àgọ́ wọn.
Ne bwe baliwona okuzikirira, Misiri alibakuŋŋaanya, ne Menfisi alibaziika. Eby’obugagga byabwe ebya ffeeza birizika, n’eweema zaabwe zirimeramu amaggwa.
7 Àwọn ọjọ́ ìjìyà ń bọ̀; àwọn ọjọ́ ìṣirò iṣẹ́ ti dé. Jẹ́ kí Israẹli mọ èyí. Nítorí pé ẹ̀ṣẹ̀ yín pọ̀ ìkórìíra yín sì pọ̀ gan an ni. A ka àwọn wòlíì sí òmùgọ̀, a ka ẹni ìmísí sí asínwín.
Ennaku ez’okubonerezebwa zijja, ennaku ez’okusasulirwamu ziri kumpi. Ekyo Isirayiri akimanye. Olw’ebibi byammwe okuba ebingi ennyo, n’obukambwe bwammwe obungi, nnabbi ayitibwa musirusiru, n’oyo eyabikkulirwa mumuyita mugu wa ddalu.
8 Wòlíì, papọ̀ pẹ̀lú Ọlọ́run, ni olùṣọ́ ọ Efraimu. Síbẹ̀ ìdẹ̀kùn dúró dè é ní gbogbo ọ̀nà rẹ̀ àti ìkórìíra ní ilé Ọlọ́run rẹ̀.
Nnabbi awamu ne Katonda wange ye mukuumi wa Efulayimu, newaakubadde nga waliwo emitego mu kkubo lye, n’obukambwe mu nnyumba ya Katonda we.
9 Wọ́n ti gbilẹ̀ nínú ìwà ìbàjẹ́ gẹ́gẹ́ bí i ọjọ́ Gibeah Ọlọ́run yóò rántí ìwà búburú wọn yóò sì jẹ wọ́n ní yà fún ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
Boonoonye nnyo nnyini nga mu nnaku ez’e Gibea. Katonda alijjukira obutali butuukirivu bwabwe, n’ababonereza olw’ebibi byabwe.
10 “Mo rí Israẹli bí èso àjàrà ní aginjù. Mo rí àwọn baba yín, bí àkọ́pọ́n nínú igi ọ̀pọ̀tọ́ ní àkọ́so rẹ̀. Ṣùgbọ́n wọ́n tọ Baali-Peori lọ, wọ́n yà wọn sọ́tọ̀ fún òrìṣà tó ń mú ìtìjú bá ni, ohun ìríra wọn sì rí gẹ́gẹ́ bí wọn ti fẹ́.
We nasangira Isirayiri, kyali nga kulaba zabbibu mu ddungu. Bwe nalaba bajjajjammwe, kyali nga kulaba ebibala ebisooka ku mutiini. Naye bwe bajja e Baalipyoli, beewonga eri ekifaananyi eky’ensonyi, ne bafuuka ekyenyinnyalwa ng’ekifaananyi kye baayagala.
11 Ògo Efraimu yóò fò lọ bí ẹyẹ kò ní sí ìfẹ́rakù, ìlóyún àti ìbímọ.
Ekitiibwa kya Efulayimu kiribuuka ne kigenda ng’ekinyonyi nga tewali kuzaala, newaakubadde okuba olubuto newaakubadde okufuna olubuto.
12 Bí wọ́n tilẹ̀ tọ́ ọmọ dàgbà. Èmi yóò mú wọn ṣọ̀fọ̀ lórí gbogbo wọn. Ègbé ni fún wọn, nígbà tí mo yípadà kúrò lọ́dọ̀ wọn!
Ne bwe balikuza abaana baabwe, ndibabaggyako bonna. Ziribasanga bwe ndibavaako.
13 Mo rí Efraimu bí ìlú Tire tí a tẹ̀dó sí ibi dáradára ṣùgbọ́n Efraimu yóò kó àwọn ọmọ rẹ̀ jáde fún àwọn apànìyàn.”
Nalaba Efulayimu ng’asimbiddwa mu kifo ekirungi, nga Ttuulo bw’ali. Naye Efulayimu alifulumya abaana be ne battibwa.
14 Fún wọn, Olúwa! Kí ni ìwọ yóò fún wọn? Fún wọn ní inú tí ń ba oyún jẹ́ àti ọyàn gbígbẹ.
Bawe Ayi Mukama Katonda. Olibawa ki? Leetera embuto zaabwe okuvaamu obawe n’amabeere amakalu.
15 “Nítorí gbogbo ìwà búburú tí wọ́n hù ní Gilgali, Mo kórìíra wọn níbẹ̀, nítorí ìwà ẹ̀ṣẹ̀ wọn. Èmi yóò lé wọn jáde ní ilé mi, Èmi kò ní ní ìfẹ́ wọn mọ́ ọlọ̀tẹ̀ ni gbogbo olórí wọn.
Olw’ebibi byabwe byonna mu Girugaali, kyennava mbakyayira eyo. Olw’ebikolwa byabwe ebitali bya butuukirivu, kyendiva mbagoba mu nnyumba yange. Siribaagala nate; abakulembeze baabwe bonna bajeemu.
16 Efraimu ti rẹ̀ dànù gbogbo rẹ̀ sì ti rọ, kò sì so èso. Bí wọ́n tilẹ̀ bímọ. Èmi ó pa àwọn ọmọ wọn tí wọ́n fẹ́ràn jùlọ.”
Efulayimu balwadde, emirandira gyabwe gikaze, tebakyabala bibala. Ne bwe balizaala abaana baabwe, nditta ezzadde lyabwe lye baagala ennyo.
17 Ọlọ́run mi yóò kọ̀ wọ́n sílẹ̀ nítorí pé wọn kò gbọ́rọ̀ sí i; wọn yóò sì di alárìnkiri láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.
Katonda wange alibavaako kubanga tebamugondedde; baliba momboze mu mawanga.

< Hosea 9 >