< Hosea 8 >
1 “Fi ìpè sí ẹnu rẹ! Ẹyẹ idì wà lórí ilé Olúwa nítorí pé àwọn ènìyàn ti dalẹ̀ májẹ̀mú, wọ́n sì ti ṣọ̀tẹ̀ sí òfin mi.
Kanayni aghzinggha salghin! Perwerdigarning öyi üstide bir qorultaz aylinip yüridu! Chünki ular Méning ehdemni buzghan, Tewrat-qanunumgha itaetsizlik qilghan.
2 Israẹli kígbe pè mí, ‘Ọlọ́run wa, àwa mọ̀ ọ́n!’
Ular Manga: «I Xudayim, biz Israil xelqi Séni tonuymiz!» dep warqiraydu.
3 Ṣùgbọ́n Israẹli ti kọ ohun tí ó dára sílẹ̀ ọ̀tá yóò sì máa lépa rẹ̀.
Israil yaxshiliq-méhribanliqni tashliwetken; Shunga düshmen uni qoghlaydu.
4 Wọ́n fi àwọn ọba jẹ ṣùgbọ́n, kì í ṣe nípasẹ̀ mi wọ́n yan ọmọ-aládé láì si ìmọ̀ mi níbẹ̀. Wọ́n fi fàdákà àti wúrà ṣe ère fún ara wọn, si ìparun ara wọn.
Ular özliri padishahlarni tikligen, biraq Men arqiliq emes; Ular bezilerni emir qilghan, biraq uningdin xewirim yoq; Ular öz jénigha zamin bolush üchün, Özlirige butlarni kümüsh-altunliridin yasighan.
5 Ju ère ẹgbọrọ màlúù rẹ, ìwọ Samaria! Ìbínú mi ń ru sí wọn: yóò ti pẹ́ tó kí wọ́n tó dé ipò àìmọ̀kan?
I Samariye, séning moziying séni tashliwetti! Méning ghezipim ulargha qozghaldi; Ular qachan’ghiche pakliqtin yiraq turidu?
6 Israẹli ni wọ́n ti wá! Ère yìí agbẹ́gilére ló ṣe é, àní ère ẹgbọrọ màlúù Samaria, ni a ó fọ́ túútúú.
Shu nerse Israildin chiqqan’ghu — Uni bir hünerwen yasighan, xalas; u Xuda emes; Samariyening moziyi derweqe pare-pare chéqiwétilidu!
7 “Wọ́n gbin afẹ́fẹ́ wọ́n sì ká ìjì. Igi ọkà kò lórí, kò sì ní mú oúnjẹ wá. Bí ó bá tilẹ̀ ní ọkà àwọn àjèjì ni yóò jẹ.
Chünki ular shamal téridi, shunga qara quyunni oridu! Ularning shadisida héch bashaqlar yoq, u héch ash bermeydu; Hetta ash bergen bolsimu, yat ademler uni yutuwalghan bolatti.
8 A ti gbé Israẹli mì, báyìí, ó sì ti wà láàrín àwọn orílẹ̀-èdè bí ohun èlò tí kò wúlò.
Israil yutuwélindi; Ular yat eller arisida yarimas bir qacha bolup qaldi;
9 Nítorí pé wọ́n ti gòkè lọ sí Asiria gẹ́gẹ́ bí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó tó ń rìn kiri. Efraimu ti ta ara rẹ̀ fún àwọn olólùfẹ́ rẹ̀.
Chünki ular yalghuz yürgen yawayi éshektek Asuriyeni izdep chiqti; Efraim «ashna»larni yalliwaldi.
10 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n ti ta ara wọn sí àárín Orílẹ̀-èdè, Èmi ó ṣà wọ́n jọ nísinsin yìí. Wọn ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í ṣòfò dànù lọ́wọ́ ìnilára ọba alágbára.
Gerche ular eller arisidin «yalliwalghan» bolsimu, Emdi Men ularni yighip bir terep qilimen; Ular tézla «Emirlerning shahi»ning bésimi astida tolghinip kétidu.
11 “Nítorí Efraimu ti kọ́ pẹpẹ púpọ̀ fún ìrúbọ ẹ̀ṣẹ̀ gbogbo rẹ̀ ti di pẹpẹ ìdẹ́ṣẹ̀ fún un
Efraim «gunah qurbanliq»liri üchün qurban’gahlarni köpeytkini bilen, Bular gunah qozghaydighan qurban’gahlar bolup qaldi.
12 Mo kọ ọ̀pọ̀lọpọ̀ ohun tí ó jẹ́ òfin mi fún wọn, ṣùgbọ́n wọn kà á sí ohun àjèjì.
Men uning üchün Tewrat-qanunumda köp tereplime nersilerni yazghan bolsammu, Ular yat bir nerse dep hésablanmaqta.
13 Wọ́n ń rú ẹbọ tí wọ́n yàn fún mi, wọ́n sì ń jẹ ẹran ibẹ̀, ṣùgbọ́n inú Olúwa kò dùn sí wọn. Báyìí yóò rántí ìwà búburú wọn yóò sì jẹ wọ́n ní yà fún ẹ̀ṣẹ̀ wọn. Wọn yóò padà sí Ejibiti.
Ular qurbanliqlargha amraq! Ular Manga qurbanliqlarni qilip, göshidin yeydu, Biraq Perwerdigar bulardin héch xursenlik almaydu; U ularning qebihlikini hazir ésige keltürüp, Gunahlirini öz béshigha chüshüridu; Ular Misirgha qaytidu!
14 Nítorí Israẹli ti gbàgbé ẹlẹ́dàá rẹ̀ Ó sì ń kọ́ ààfin púpọ̀ Juda ti kọ́ ìlú olódi púpọ̀ ṣùgbọ́n èmi ó rán iná kan sí orí àwọn ìlú rẹ̀ èyí tí yóò jẹ ibi agbára rẹ̀ run.”
Chünki Israil öz Yasighuchisini untup, «ibadetxana»larni quridu; Yehuda bolsa istihkamlashturulghan sheherlerni köpeytken; Biraq Men ularning sheherliri üstige ot ewetimen, Ot bularning qel’e-ordilirini yep kétidu.