< Hosea 8 >

1 “Fi ìpè sí ẹnu rẹ! Ẹyẹ idì wà lórí ilé Olúwa nítorí pé àwọn ènìyàn ti dalẹ̀ májẹ̀mú, wọ́n sì ti ṣọ̀tẹ̀ sí òfin mi.
Pune trâmbiţa la gură. El va veni ca o acvilă împotriva casei DOMNULUI, pentru că au încălcat legământul meu şi s-au răzvrătit împotriva legii mele.
2 Israẹli kígbe pè mí, ‘Ọlọ́run wa, àwa mọ̀ ọ́n!’
Israel va striga către mine: Dumnezeul meu, noi te cunoaştem.
3 Ṣùgbọ́n Israẹli ti kọ ohun tí ó dára sílẹ̀ ọ̀tá yóò sì máa lépa rẹ̀.
Israel a lepădat ceea ce este bun; duşmanul îl va urmări.
4 Wọ́n fi àwọn ọba jẹ ṣùgbọ́n, kì í ṣe nípasẹ̀ mi wọ́n yan ọmọ-aládé láì si ìmọ̀ mi níbẹ̀. Wọ́n fi fàdákà àti wúrà ṣe ère fún ara wọn, si ìparun ara wọn.
Ei şi-au pus împăraţi, dar nu prin mine; au făcut prinţi fără ca eu să ştiu; din argintul lor şi din aurul lor şi-au făcut idoli ca să fie stârpiţi.
5 Ju ère ẹgbọrọ màlúù rẹ, ìwọ Samaria! Ìbínú mi ń ru sí wọn: yóò ti pẹ́ tó kí wọ́n tó dé ipò àìmọ̀kan?
Viţelul tău, Samaria, te-a lepădat; mânia mea este aprinsă împotriva lor; cât timp va fi până când vor ajunge la nevinovăţie?
6 Israẹli ni wọ́n ti wá! Ère yìí agbẹ́gilére ló ṣe é, àní ère ẹgbọrọ màlúù Samaria, ni a ó fọ́ túútúú.
Fiindcă din Israel a fost şi aceasta; lucrătorul l-a făcut, de aceea nu este Dumnezeu; dar viţelul Samariei va fi spart în bucăţi.
7 “Wọ́n gbin afẹ́fẹ́ wọ́n sì ká ìjì. Igi ọkà kò lórí, kò sì ní mú oúnjẹ wá. Bí ó bá tilẹ̀ ní ọkà àwọn àjèjì ni yóò jẹ.
Căci au semănat vânt şi vor secera vârtejul de vânt; nu are spic; mugurele nu va da făină; şi dacă totuşi dă roadă, străinii îl vor înghiţi.
8 A ti gbé Israẹli mì, báyìí, ó sì ti wà láàrín àwọn orílẹ̀-èdè bí ohun èlò tí kò wúlò.
Israel este înghiţit; acum, printre neamuri, ei vor fi ca un vas în care nu este plăcere.
9 Nítorí pé wọ́n ti gòkè lọ sí Asiria gẹ́gẹ́ bí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó tó ń rìn kiri. Efraimu ti ta ara rẹ̀ fún àwọn olólùfẹ́ rẹ̀.
Fiindcă au urcat în Asiria, un măgar sălbatic, singur; Efraim a angajat iubiţi.
10 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n ti ta ara wọn sí àárín Orílẹ̀-èdè, Èmi ó ṣà wọ́n jọ nísinsin yìí. Wọn ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í ṣòfò dànù lọ́wọ́ ìnilára ọba alágbára.
Da, deşi au angajat printre naţiuni, acum îi voi aduna, şi se vor întrista puţin timp din cauza poverii împăratului prinţilor.
11 “Nítorí Efraimu ti kọ́ pẹpẹ púpọ̀ fún ìrúbọ ẹ̀ṣẹ̀ gbogbo rẹ̀ ti di pẹpẹ ìdẹ́ṣẹ̀ fún un
Pentru că Efraim a făcut multe altare pentru a păcătui, altarele îi vor fi pentru a păcătui.
12 Mo kọ ọ̀pọ̀lọpọ̀ ohun tí ó jẹ́ òfin mi fún wọn, ṣùgbọ́n wọn kà á sí ohun àjèjì.
I-am scris lucrurile măreţe ale legii mele, dar erau socotite ca un lucru străin.
13 Wọ́n ń rú ẹbọ tí wọ́n yàn fún mi, wọ́n sì ń jẹ ẹran ibẹ̀, ṣùgbọ́n inú Olúwa kò dùn sí wọn. Báyìí yóò rántí ìwà búburú wọn yóò sì jẹ wọ́n ní yà fún ẹ̀ṣẹ̀ wọn. Wọn yóò padà sí Ejibiti.
Carne sacrifică ei pentru sacrificiile ofrandelor mele, şi o mănâncă; dar DOMNUL nu le primeşte; acum îşi va aminti nelegiuirea lor şi va cerceta păcatele lor; ei se vor întoarce în Egipt.
14 Nítorí Israẹli ti gbàgbé ẹlẹ́dàá rẹ̀ Ó sì ń kọ́ ààfin púpọ̀ Juda ti kọ́ ìlú olódi púpọ̀ ṣùgbọ́n èmi ó rán iná kan sí orí àwọn ìlú rẹ̀ èyí tí yóò jẹ ibi agbára rẹ̀ run.”
Fiindcă Israel a uitat pe Făcătorul lui şi construieşte temple; şi Iuda a înmulţit cetăţile întărite; dar eu voi trimite un foc asupra cetăţilor lui şi acesta le va mistui palatele.

< Hosea 8 >