< Hosea 8 >

1 “Fi ìpè sí ẹnu rẹ! Ẹyẹ idì wà lórí ilé Olúwa nítorí pé àwọn ènìyàn ti dalẹ̀ májẹ̀mú, wọ́n sì ti ṣọ̀tẹ̀ sí òfin mi.
Przyłóż trąbę do ust twoich, a rzecz: Oto leci na dom Pański jako orzeł, przeto, że przestąpili przymierze moje, a przeciwko zakonowi mojemu wykroczyli.
2 Israẹli kígbe pè mí, ‘Ọlọ́run wa, àwa mọ̀ ọ́n!’
Będąć do mnie wołać: Boże mój! My, lud twój Izrael, znamy cię;
3 Ṣùgbọ́n Israẹli ti kọ ohun tí ó dára sílẹ̀ ọ̀tá yóò sì máa lépa rẹ̀.
Ale Izrael opuścił dobro; przetoż go nieprzyjaciel gonić będzie.
4 Wọ́n fi àwọn ọba jẹ ṣùgbọ́n, kì í ṣe nípasẹ̀ mi wọ́n yan ọmọ-aládé láì si ìmọ̀ mi níbẹ̀. Wọ́n fi fàdákà àti wúrà ṣe ère fún ara wọn, si ìparun ara wọn.
Oni stanowią królów, ale bezemnie: książąt obierają, do których się Ja nie znam; ze srebra swego i ze złota swego czynią sobie bałwany na swoje zginienie.
5 Ju ère ẹgbọrọ màlúù rẹ, ìwọ Samaria! Ìbínú mi ń ru sí wọn: yóò ti pẹ́ tó kí wọ́n tó dé ipò àìmọ̀kan?
Opuści ich cielec twój, o Samaryja! gdy się zapali na nich gniew mój; dokądże nie będą mogli przestrzegać niewinności?
6 Israẹli ni wọ́n ti wá! Ère yìí agbẹ́gilére ló ṣe é, àní ère ẹgbọrọ màlúù Samaria, ni a ó fọ́ túútúú.
Wszak i on jest z Izraela; rzemieślnik go urobił, a nie jest Bogiem; bo się w proch obróci cielec Samaryjski.
7 “Wọ́n gbin afẹ́fẹ́ wọ́n sì ká ìjì. Igi ọkà kò lórí, kò sì ní mú oúnjẹ wá. Bí ó bá tilẹ̀ ní ọkà àwọn àjèjì ni yóò jẹ.
Bo iż wiatr siali, wicher też żąć będą, a żadnego źdźbła mieć nie będą; urodzaj nie wyda mąki, a choćby wydał, cudzoziemcy to zjedzą.
8 A ti gbé Israẹli mì, báyìí, ó sì ti wà láàrín àwọn orílẹ̀-èdè bí ohun èlò tí kò wúlò.
Izrael pożarty będzie, wnetże będzie między poganami jako naczynie, z którego niemasz żadnej uciechy.
9 Nítorí pé wọ́n ti gòkè lọ sí Asiria gẹ́gẹ́ bí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó tó ń rìn kiri. Efraimu ti ta ara rẹ̀ fún àwọn olólùfẹ́ rẹ̀.
Przeto, że się oni do Assyryjczyka, osła leśnego, uciekają, który się samotnie chowa, a że Efraim sobie miłośników najmuje,
10 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n ti ta ara wọn sí àárín Orílẹ̀-èdè, Èmi ó ṣà wọ́n jọ nísinsin yìí. Wọn ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í ṣòfò dànù lọ́wọ́ ìnilára ọba alágbára.
A iż dary posyłali między pogan: przetoż i Ja ich wnetże zbiorę, owszem, już cośkolwiek ucierpieli dla brzemienia króla książąt.
11 “Nítorí Efraimu ti kọ́ pẹpẹ púpọ̀ fún ìrúbọ ẹ̀ṣẹ̀ gbogbo rẹ̀ ti di pẹpẹ ìdẹ́ṣẹ̀ fún un
Bo iż rozmnożył Efraim ołtarze ku grzeszeniu, stały mu się one ołtarze ku grzeszeniu.
12 Mo kọ ọ̀pọ̀lọpọ̀ ohun tí ó jẹ́ òfin mi fún wọn, ṣùgbọ́n wọn kà á sí ohun àjèjì.
Spisałem mu wielkie rzeczy w zakonie moim; ale tak je sobie waży jako co obcego.
13 Wọ́n ń rú ẹbọ tí wọ́n yàn fún mi, wọ́n sì ń jẹ ẹran ibẹ̀, ṣùgbọ́n inú Olúwa kò dùn sí wọn. Báyìí yóò rántí ìwà búburú wọn yóò sì jẹ wọ́n ní yà fún ẹ̀ṣẹ̀ wọn. Wọn yóò padà sí Ejibiti.
Z ofiar darów moich ofiarują mięso i jedzą, ale ich Pan nie przyjmuje; już wspomnę nieprawości ich, i nawiedzę grzechy ich, że się oni do Egiptu nawracają;
14 Nítorí Israẹli ti gbàgbé ẹlẹ́dàá rẹ̀ Ó sì ń kọ́ ààfin púpọ̀ Juda ti kọ́ ìlú olódi púpọ̀ ṣùgbọ́n èmi ó rán iná kan sí orí àwọn ìlú rẹ̀ èyí tí yóò jẹ ibi agbára rẹ̀ run.”
A że zapomniał Izrael stworzyciela swego, i nabudował kościołów, a Juda rozmnożył miasta obronne, przetoż poślę ogień na miasta jego, który pożre pałace jego.

< Hosea 8 >