< Hosea 8 >

1 “Fi ìpè sí ẹnu rẹ! Ẹyẹ idì wà lórí ilé Olúwa nítorí pé àwọn ènìyàn ti dalẹ̀ májẹ̀mú, wọ́n sì ti ṣọ̀tẹ̀ sí òfin mi.
A ta bouche la trompette! Comme un aigle sur la maison de Yahweh!... Parce qu'ils ont transgressé mon alliance, et péché contre ma loi.
2 Israẹli kígbe pè mí, ‘Ọlọ́run wa, àwa mọ̀ ọ́n!’
Ils crient vers moi: " Mon Dieu! nous t'avons connu, nous, Israël! "
3 Ṣùgbọ́n Israẹli ti kọ ohun tí ó dára sílẹ̀ ọ̀tá yóò sì máa lépa rẹ̀.
Israël s'est dégoûté du bien; que l'ennemi le poursuive!
4 Wọ́n fi àwọn ọba jẹ ṣùgbọ́n, kì í ṣe nípasẹ̀ mi wọ́n yan ọmọ-aládé láì si ìmọ̀ mi níbẹ̀. Wọ́n fi fàdákà àti wúrà ṣe ère fún ara wọn, si ìparun ara wọn.
Ils ont fait des rois, mais non de ma part; ils ont établi des chefs, mais que je n'ai pas connus; de leur argent et de leur or ils ont fait des idoles, pour que l'argent et l'or leur fussent ôtés.
5 Ju ère ẹgbọrọ màlúù rẹ, ìwọ Samaria! Ìbínú mi ń ru sí wọn: yóò ti pẹ́ tó kí wọ́n tó dé ipò àìmọ̀kan?
Ton veau m'a dégoûté, Samarie; ma colère s'est enflammée contre eux; jusques à quand ne pourront-ils être purifiés?
6 Israẹli ni wọ́n ti wá! Ère yìí agbẹ́gilére ló ṣe é, àní ère ẹgbọrọ màlúù Samaria, ni a ó fọ́ túútúú.
Car il vient d'Israël, lui aussi; un ouvrier l'a fabriqué, et ce n'est pas un Dieu; car il sera mis en pièces, le veau de Samarie!
7 “Wọ́n gbin afẹ́fẹ́ wọ́n sì ká ìjì. Igi ọkà kò lórí, kò sì ní mú oúnjẹ wá. Bí ó bá tilẹ̀ ní ọkà àwọn àjèjì ni yóò jẹ.
Parce qu'ils ont semé le vent, ils moissonneront la tempête. Il n'y aura pas pour lui d'épi, mais du blé qui ne donnera pas de farine; et, s'il en donne, les étrangers le dévoreront.
8 A ti gbé Israẹli mì, báyìí, ó sì ti wà láàrín àwọn orílẹ̀-èdè bí ohun èlò tí kò wúlò.
Israël est dévoré; maintenant ils sont devenus parmi les nations comme un objet sans valeur.
9 Nítorí pé wọ́n ti gòkè lọ sí Asiria gẹ́gẹ́ bí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó tó ń rìn kiri. Efraimu ti ta ara rẹ̀ fún àwọn olólùfẹ́ rẹ̀.
Car eux-mêmes sont montés vers Assur; L'onagre vit à l'écart; Ephraïm s'est acheté des amants.
10 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n ti ta ara wọn sí àárín Orílẹ̀-èdè, Èmi ó ṣà wọ́n jọ nísinsin yìí. Wọn ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í ṣòfò dànù lọ́wọ́ ìnilára ọba alágbára.
Même s'ils font des présents aux nations, je les rassemblerai contre eux, et ils trembleront pour un peu de temps, sous le fardeau du roi des princes.
11 “Nítorí Efraimu ti kọ́ pẹpẹ púpọ̀ fún ìrúbọ ẹ̀ṣẹ̀ gbogbo rẹ̀ ti di pẹpẹ ìdẹ́ṣẹ̀ fún un
Ephraïm a multiplié les autels en péchant, et ces autels l'ont fait tomber dans le péché.
12 Mo kọ ọ̀pọ̀lọpọ̀ ohun tí ó jẹ́ òfin mi fún wọn, ṣùgbọ́n wọn kà á sí ohun àjèjì.
Que j'écrive pour lui mille articles de ma loi, ils sont regardés comme une chose étrangère.
13 Wọ́n ń rú ẹbọ tí wọ́n yàn fún mi, wọ́n sì ń jẹ ẹran ibẹ̀, ṣùgbọ́n inú Olúwa kò dùn sí wọn. Báyìí yóò rántí ìwà búburú wọn yóò sì jẹ wọ́n ní yà fún ẹ̀ṣẹ̀ wọn. Wọn yóò padà sí Ejibiti.
Les sacrifices qu'ils m'offrent, c'est de la viande qu'ils immolent, et ils la mangent; Yahweh n'y prend point de plaisir. Maintenant il se souviendra de leur iniquité, et il punira leurs péchés; ils retourneront, eux, en Egypte.
14 Nítorí Israẹli ti gbàgbé ẹlẹ́dàá rẹ̀ Ó sì ń kọ́ ààfin púpọ̀ Juda ti kọ́ ìlú olódi púpọ̀ ṣùgbọ́n èmi ó rán iná kan sí orí àwọn ìlú rẹ̀ èyí tí yóò jẹ ibi agbára rẹ̀ run.”
Israël a oublié son auteur, et il a bâti des palais; et Juda a multiplié ses villes fortes. J'enverrai le feu dans ses villes, et il dévorera ses châteaux.

< Hosea 8 >