< Hosea 8 >

1 “Fi ìpè sí ẹnu rẹ! Ẹyẹ idì wà lórí ilé Olúwa nítorí pé àwọn ènìyàn ti dalẹ̀ májẹ̀mú, wọ́n sì ti ṣọ̀tẹ̀ sí òfin mi.
« Mettez la trompette à vos lèvres! Quelque chose comme un aigle est au-dessus de la maison de Yahvé, parce qu'ils ont rompu mon alliance et se sont rebellés contre ma loi.
2 Israẹli kígbe pè mí, ‘Ọlọ́run wa, àwa mọ̀ ọ́n!’
Ils s'écrient: « Mon Dieu, nous, Israël, nous te reconnaissons.
3 Ṣùgbọ́n Israẹli ti kọ ohun tí ó dára sílẹ̀ ọ̀tá yóò sì máa lépa rẹ̀.
Israël a rejeté ce qui est bon. L'ennemi le poursuivra.
4 Wọ́n fi àwọn ọba jẹ ṣùgbọ́n, kì í ṣe nípasẹ̀ mi wọ́n yan ọmọ-aládé láì si ìmọ̀ mi níbẹ̀. Wọ́n fi fàdákà àti wúrà ṣe ère fún ara wọn, si ìparun ara wọn.
Ils ont établi des rois, mais pas par moi. Ils ont fait des princes, et je n'ai pas approuvé. De leur argent et de leur or, ils se sont fait des idoles, pour qu'ils soient exterminés.
5 Ju ère ẹgbọrọ màlúù rẹ, ìwọ Samaria! Ìbínú mi ń ru sí wọn: yóò ti pẹ́ tó kí wọ́n tó dé ipò àìmọ̀kan?
Que Samarie jette son idole de veau! Ma colère brûle contre eux! Combien de temps faudra-t-il avant qu'ils soient capables de pureté?
6 Israẹli ni wọ́n ti wá! Ère yìí agbẹ́gilére ló ṣe é, àní ère ẹgbọrọ màlúù Samaria, ni a ó fọ́ túútúú.
Car cela vient même d'Israël! L'ouvrier l'a fait, et ce n'est pas Dieu; en effet, le veau de Samarie sera brisé en morceaux.
7 “Wọ́n gbin afẹ́fẹ́ wọ́n sì ká ìjì. Igi ọkà kò lórí, kò sì ní mú oúnjẹ wá. Bí ó bá tilẹ̀ ní ọkà àwọn àjèjì ni yóò jẹ.
Car ils sèment le vent, et ils récolteront la tempête. Il n'a pas de grain sur pied. La tige ne donnera pas de tête. S'il cède, les étrangers l'avaleront.
8 A ti gbé Israẹli mì, báyìí, ó sì ti wà láàrín àwọn orílẹ̀-èdè bí ohun èlò tí kò wúlò.
Israël est englouti. Maintenant, ils sont parmi les nations comme une chose sans valeur.
9 Nítorí pé wọ́n ti gòkè lọ sí Asiria gẹ́gẹ́ bí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó tó ń rìn kiri. Efraimu ti ta ara rẹ̀ fún àwọn olólùfẹ́ rẹ̀.
Car ils sont montés en Assyrie, comme un âne sauvage errant seul. Ephraim a engagé des amants pour lui-même.
10 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n ti ta ara wọn sí àárín Orílẹ̀-èdè, Èmi ó ṣà wọ́n jọ nísinsin yìí. Wọn ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í ṣòfò dànù lọ́wọ́ ìnilára ọba alágbára.
Mais bien qu'ils se soient vendus parmi les nations, Je vais maintenant les rassembler; et ils commencent à dépérir à cause de l'oppression du roi des puissants.
11 “Nítorí Efraimu ti kọ́ pẹpẹ púpọ̀ fún ìrúbọ ẹ̀ṣẹ̀ gbogbo rẹ̀ ti di pẹpẹ ìdẹ́ṣẹ̀ fún un
Car Ephraïm a multiplié les autels pour pécher, ils sont devenus pour lui des autels pour le péché.
12 Mo kọ ọ̀pọ̀lọpọ̀ ohun tí ó jẹ́ òfin mi fún wọn, ṣùgbọ́n wọn kà á sí ohun àjèjì.
J'ai écrit pour lui les nombreuses choses de ma loi, mais ils étaient considérés comme une chose étrange.
13 Wọ́n ń rú ẹbọ tí wọ́n yàn fún mi, wọ́n sì ń jẹ ẹran ibẹ̀, ṣùgbọ́n inú Olúwa kò dùn sí wọn. Báyìí yóò rántí ìwà búburú wọn yóò sì jẹ wọ́n ní yà fún ẹ̀ṣẹ̀ wọn. Wọn yóò padà sí Ejibiti.
Quant aux sacrifices de mes offrandes, ils sacrifient de la viande et la mangent, mais Yahvé ne les accepte pas. Maintenant, il se souviendra de leur iniquité, et punir leurs péchés. Ils retourneront en Égypte.
14 Nítorí Israẹli ti gbàgbé ẹlẹ́dàá rẹ̀ Ó sì ń kọ́ ààfin púpọ̀ Juda ti kọ́ ìlú olódi púpọ̀ ṣùgbọ́n èmi ó rán iná kan sí orí àwọn ìlú rẹ̀ èyí tí yóò jẹ ibi agbára rẹ̀ run.”
Car Israël a oublié son créateur et a construit des palais; et Juda a multiplié les villes fortifiées; mais j'enverrai un feu sur ses villes, et il dévorera ses forteresses. »

< Hosea 8 >