< Hosea 8 >

1 “Fi ìpè sí ẹnu rẹ! Ẹyẹ idì wà lórí ilé Olúwa nítorí pé àwọn ènìyàn ti dalẹ̀ májẹ̀mú, wọ́n sì ti ṣọ̀tẹ̀ sí òfin mi.
To thy mouth, with a horn! Like an eagle, on the house of Yahweh, —because they have violated my covenant, and, against my law, have they transgressed.
2 Israẹli kígbe pè mí, ‘Ọlọ́run wa, àwa mọ̀ ọ́n!’
Unto me, shall they make outcry, My God! we acknowledge thee—[we], Israel!
3 Ṣùgbọ́n Israẹli ti kọ ohun tí ó dára sílẹ̀ ọ̀tá yóò sì máa lépa rẹ̀.
Israel hath cast away what is good, —an enemy, shall pursue him.
4 Wọ́n fi àwọn ọba jẹ ṣùgbọ́n, kì í ṣe nípasẹ̀ mi wọ́n yan ọmọ-aládé láì si ìmọ̀ mi níbẹ̀. Wọ́n fi fàdákà àti wúrà ṣe ère fún ara wọn, si ìparun ara wọn.
They, have appointed kings, but not from me, have made rulers, but I have not acknowledged them: of their silver and their gold, they made themselves idols, to the end they might be cut off.
5 Ju ère ẹgbọrọ màlúù rẹ, ìwọ Samaria! Ìbínú mi ń ru sí wọn: yóò ti pẹ́ tó kí wọ́n tó dé ipò àìmọ̀kan?
He hath cast away thy calf, O Samaria, kindled is mine anger upon them, —How long shall they not endure to be innocent?
6 Israẹli ni wọ́n ti wá! Ère yìí agbẹ́gilére ló ṣe é, àní ère ẹgbọrọ màlúù Samaria, ni a ó fọ́ túútúú.
For, of Israel, is even that thing! A craftsman, made it, and, a No-god, it is! For, into fragments, shall the Calf of Samaria be broken.
7 “Wọ́n gbin afẹ́fẹ́ wọ́n sì ká ìjì. Igi ọkà kò lórí, kò sì ní mú oúnjẹ wá. Bí ó bá tilẹ̀ ní ọkà àwọn àjèjì ni yóò jẹ.
For, to the wind, they sow, and, to the whirlwind, they reap: stalk, hath it none, That which shooteth forth, shall yield no meal, If so be it yield, foreigners, swallow it lip,
8 A ti gbé Israẹli mì, báyìí, ó sì ti wà láàrín àwọn orílẹ̀-èdè bí ohun èlò tí kò wúlò.
Swallowed up, is Israel; Now, have they gone among the nations, like a vessel in which no man taketh, delight.
9 Nítorí pé wọ́n ti gòkè lọ sí Asiria gẹ́gẹ́ bí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó tó ń rìn kiri. Efraimu ti ta ara rẹ̀ fún àwọn olólùfẹ́ rẹ̀.
For, they, have gone up to Assyria, A wild ass going alone for himself, is Ephraim! They have hired lovers!
10 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n ti ta ara wọn sí àárín Orílẹ̀-èdè, Èmi ó ṣà wọ́n jọ nísinsin yìí. Wọn ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í ṣòfò dànù lọ́wọ́ ìnilára ọba alágbára.
Even though they hire them among the nations, at once, will I gather them, when they have begun to be diminished by reason of the burden of the king of rulers.
11 “Nítorí Efraimu ti kọ́ pẹpẹ púpọ̀ fún ìrúbọ ẹ̀ṣẹ̀ gbogbo rẹ̀ ti di pẹpẹ ìdẹ́ṣẹ̀ fún un
Because Ephraim hath multiplied altars sinfully, they have become to him the altars of sin.
12 Mo kọ ọ̀pọ̀lọpọ̀ ohun tí ó jẹ́ òfin mi fún wọn, ṣùgbọ́n wọn kà á sí ohun àjèjì.
I have been wont to write for him the myriad things of my law, —Like something alien, have they been accounted.
13 Wọ́n ń rú ẹbọ tí wọ́n yàn fún mi, wọ́n sì ń jẹ ẹran ibẹ̀, ṣùgbọ́n inú Olúwa kò dùn sí wọn. Báyìí yóò rántí ìwà búburú wọn yóò sì jẹ wọ́n ní yà fún ẹ̀ṣẹ̀ wọn. Wọn yóò padà sí Ejibiti.
My sacrificial gifts, have they been sacrificing as [common] flesh, and have eaten, Yahweh, hath not accepted them, —Now, will he call to mind their iniquity, that he may punish their sin, they, to Egypt, will return.
14 Nítorí Israẹli ti gbàgbé ẹlẹ́dàá rẹ̀ Ó sì ń kọ́ ààfin púpọ̀ Juda ti kọ́ ìlú olódi púpọ̀ ṣùgbọ́n èmi ó rán iná kan sí orí àwọn ìlú rẹ̀ èyí tí yóò jẹ ibi agbára rẹ̀ run.”
And so Israel hath forgotten his Maker, and hath built temples, and, Judah, hath multiplied fortified cities, —Therefore will I send a fire upon his cities, and it shall consume the palaces thereof.

< Hosea 8 >