< Hosea 7 >

1 nígbà tí èmi ìbá mú Israẹli láradá. Ẹ̀ṣẹ̀ Efraimu ń farahàn ìwà búburú Samaria sì ń hàn síta. Wọ́n ń ṣe ẹ̀tàn, àwọn olè ń fọ́ ilé; àwọn ọlọ́ṣà ń jalè ní òpópónà;
Gdy leczę Izraela, tedy się odkrywa nieprawość Efraimowa i złości Samaryjskie, bo się bawią kłamstwem; w miastach złodziejstwo, a na dworze łupiestwo przewodzą;
2 ṣùgbọ́n wọn kò mọ̀ pé mo rántí gbogbo ìwà búburú wọn. Ẹ̀ṣẹ̀ wọn gbé wọn mì pátápátá; wọ́n wà níwájú mi nígbà gbogbo.
A nie myślą w sercu swojem, że na wszystkie złości ich pamiętam; a teraz ich ogarniają sprawy ich, i są przed obliczem mojem.
3 “Wọ́n ń mú inú ọba dùn pẹ̀lú ìwà búburú wọn, àti inú ọmọ-aládé dùn pẹ̀lú irọ́ wọn.
Króla uweselają złością swoją a książąt kłamstwy swemi.
4 Alágbèrè ni gbogbo wọn wọ́n gbóná bí ààrò àkàrà tí a dáwọ́ kíkoná dúró, lẹ́yìn ìgbà tí o ti pò ìyẹ̀fun tán, títí ìgbà tí yóò wú.
Wszyscy zgoła cudzołożą, są jako piec rozpalony od piekarza, który przestaje czuć, gdy zaczynił ciasto, ażby ukisiało.
5 Ní ọjọ́ àjọ̀dún ọba wa wáìnì mú ara ọmọ-aládé gbóná ó sì darapọ̀ mọ́ àwọn oníyẹ̀yẹ́.
W dzień króla naszego w chorobę go wprawiają książęta łagwiami wina, tak że i on rękę swą z naśmiewcami wyciąga.
6 Ọkàn wọn ń gbóná bí i ààrò wọ́n sì tọ̀ ọ́ lọ pẹ̀lú rìkíṣí, ìbínú wọn pa lọ́lọ́ ní gbogbo òru ó sì bú jáde bí ọ̀wọ́-iná ní òwúrọ̀.
Bo przyłożyli serce swe do zasadzek, jako piec rozpalony; całą noc śpi piekarz ich, a z poranku gore jako płomień ognia.
7 Gbogbo wọn gbóná bí ààrò wọ́n pa gbogbo olórí wọn run, gbogbo ọba wọn si ṣubú kò sì ṣí ẹnìkan nínú wọn tí ó ké pè mí.
Wszyscy zgoła rozpalili się jako piec, a pożerają sędziów swoich; wszyscy królowie ich upadają, niemasz między nimi, ktoby wołał do mnie.
8 “Efraimu ti darapọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn náà; Efraimu jẹ́ àkàrà tí a kò yípadà.
Efraim ten się z narodami zmieszał; Efraim będzie jako podpłomyk nieprzewracany.
9 Àwọn àlejò ti jẹ agbára rẹ̀ run ṣùgbọ́n kò sì mọ̀. Ewú ti wà ní orí rẹ̀ káàkiri bẹ́ẹ̀ ni kò kíyèsi i.
Pożarli obcy siłę jego, a on o tem nie wie; sędziwość też nań występuje, wszakże on tego nie wie.
10 Ìgbéraga Israẹli ń jẹ́rìí sí i ṣùgbọ́n pẹ̀lú gbogbo èyí kò padà sí ọ̀dọ̀ Olúwa Ọlọ́run, tàbí kí ó wá a.
A choć pycha Izraelska świadczy w oczy przeciwko niemu, wszakże się nie nawracają do Pana, Boga swego, ani go w tem wszystkiem szukają.
11 “Efraimu dàbí àdàbà tó rọrùn láti tànjẹ àti aláìgbọ́n tó wá ń pé Ejibiti nísinsin yìí tó sì tún ń padà lọ si Asiria.
I stał się Efraim jako gołębica głupia, nie mająca serca; Egiptu przyzywają a do Assura się uciekają.
12 Nígbà tí wọ́n bá lọ, èmi ó ta àwọ̀n mi sórí wọn, Èmi ó fà wọ́n lulẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹyẹ ojú ọ̀run. Nígbà tí mo bá gbọ́ pé wọ́n rìn pọ̀, Èmi ó nà wọ́n fún iṣẹ́ búburú ọwọ́ wọn.
Ale gdy odejdą, rozciągnę na nich sieć moję, a jako ptastwo niebieskie potargnę ich; skarzę ich, jako im o tem powiadano w zgromadzeniu ich.
13 Ègbé ní fún wọn, nítorí pé wọ́n ti yà kúrò lọ́dọ̀ mi! Ìparun wà lórí wọn, nítorí pé wọ́n ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi! Èmi fẹ́ láti rà wọ́n padà. Ṣùgbọ́n wọ́n ń parọ́ mọ́ mi.
Biada im, że się rozbiegli odemnie! spustoszenie przyjdzie na nich, bo wystąpili przeciwko mnie; choćem Ja ich odkupił, ale oni przeciwko mnie mówili kłamstwa;
14 Wọn kò kégbe pè mí láti ọkàn wọn, ṣùgbọ́n wọ́n ń pohùnréré ẹkún lórí ibùsùn wọn. Wọ́n kó ara wọn jọ, nítorí ọkà àti wáìnì ṣùgbọ́n wọ́n yípadà kúrò ní ọ̀dọ̀ mi.
I nie wołają do mnie z serca swego, gdy wyją na łożach swoich; wprawdźieć dla zboża i moszczu zgromadzają się, ale mię potem odstępują.
15 Mo kọ́ wọn, mo sì fún wọn ní agbára, síbẹ̀ wọ́n tún ń dìtẹ̀ mọ́ mi.
Choćem utwierdzał ramiona ich pokarawszy ich, ale oni złe myślą przeciwko mnie.
16 Wọn kò padà sí ọ̀dọ̀ Ọ̀gá-ògo; wọ́n dàbí ọfà tí ó ti bàjẹ́. Àwọn aṣíwájú wọn yóò ti ipa idà ṣubú nítorí ìrunú ahọ́n wọn. Torí èyí, wọn ó fi wọ́n ṣe ẹlẹ́yà ní ilẹ̀ Ejibiti.
Nawracają się, ale nie do Najwyższego; są jako łuk zdradliwy, polegną od miecza, książęta ich od popędliwości języka ich, co im jest ku pośmiewisku w ziemi Egipskiej.

< Hosea 7 >