< Hosea 7 >

1 nígbà tí èmi ìbá mú Israẹli láradá. Ẹ̀ṣẹ̀ Efraimu ń farahàn ìwà búburú Samaria sì ń hàn síta. Wọ́n ń ṣe ẹ̀tàn, àwọn olè ń fọ́ ilé; àwọn ọlọ́ṣà ń jalè ní òpópónà;
Pendant que Je guérissais Israël, l'iniquité d'Éphraïm et la méchanceté de Samarie ont été révélées; car ils étaient ouvriers de mensonges. Et le larron entrera chez Éphraïm, et le brigand le pillera dans ses chemins,
2 ṣùgbọ́n wọn kò mọ̀ pé mo rántí gbogbo ìwà búburú wọn. Ẹ̀ṣẹ̀ wọn gbé wọn mì pátápátá; wọ́n wà níwájú mi nígbà gbogbo.
comme des chanteurs qui s'accordent entre eux. Je Me suis souvenu de toute leur malice; et maintenant leurs pensées les ont enveloppés, et elles sont venues devant Ma face.
3 “Wọ́n ń mú inú ọba dùn pẹ̀lú ìwà búburú wọn, àti inú ọmọ-aládé dùn pẹ̀lú irọ́ wọn.
Ils ont réjoui les rois par leur perversité, et les princes par leurs mensonges.
4 Alágbèrè ni gbogbo wọn wọ́n gbóná bí ààrò àkàrà tí a dáwọ́ kíkoná dúró, lẹ́yìn ìgbà tí o ti pò ìyẹ̀fun tán, títí ìgbà tí yóò wú.
Ils sont tous adultères; ils sont comme un feu brûlant pour la cuisson, tout échauffé par la flamme, lorsque l'on a pétri la pâte, jusqu'à ce qu'elle ait fermenté.
5 Ní ọjọ́ àjọ̀dún ọba wa wáìnì mú ara ọmọ-aládé gbóná ó sì darapọ̀ mọ́ àwọn oníyẹ̀yẹ́.
Du temps de vos rois, vos princes commençaient la journée par s'enflammer avec le vin; le roi lui-même étendait la main avec des hommes de pestilence.
6 Ọkàn wọn ń gbóná bí i ààrò wọ́n sì tọ̀ ọ́ lọ pẹ̀lú rìkíṣí, ìbínú wọn pa lọ́lọ́ ní gbogbo òru ó sì bú jáde bí ọ̀wọ́-iná ní òwúrọ̀.
Parce que leurs cœurs étaient brûlants comme un four pendant qu'ils s'exaltaient, Éphraïm se rassasiait de sommeil toute la nuit; et quand venait l'aurore il brûlait encore comme la flamme du feu.
7 Gbogbo wọn gbóná bí ààrò wọ́n pa gbogbo olórí wọn run, gbogbo ọba wọn si ṣubú kò sì ṣí ẹnìkan nínú wọn tí ó ké pè mí.
Ils étaient tous échauffés comme un four, et ils dévorèrent leurs juges; tous leurs rois tombèrent, et nul ne fut parmi eux pour M'invoquer.
8 “Efraimu ti darapọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn náà; Efraimu jẹ́ àkàrà tí a kò yípadà.
Éphraïm se mêla à leurs peuples; Éphraïm devint comme un gâteau cuit sous la cendre et qu'on n'a pas retourné.
9 Àwọn àlejò ti jẹ agbára rẹ̀ run ṣùgbọ́n kò sì mọ̀. Ewú ti wà ní orí rẹ̀ káàkiri bẹ́ẹ̀ ni kò kíyèsi i.
Les étrangers dévorèrent sa force, et il n'en sut rien; ses cheveux blanchirent, et il ne le sut pas.
10 Ìgbéraga Israẹli ń jẹ́rìí sí i ṣùgbọ́n pẹ̀lú gbogbo èyí kò padà sí ọ̀dọ̀ Olúwa Ọlọ́run, tàbí kí ó wá a.
Et l'orgueil d'Israël sera humilié en sa face; et ils ne sont point revenus au Seigneur leur Dieu, et ils ne l'ont point cherché dans tous leurs malheurs.
11 “Efraimu dàbí àdàbà tó rọrùn láti tànjẹ àti aláìgbọ́n tó wá ń pé Ejibiti nísinsin yìí tó sì tún ń padà lọ si Asiria.
Et Éphraïm demeura comme une colombe insensée et sans cœur. Il invoqua l'Égypte, et alla aux Assyriens.
12 Nígbà tí wọ́n bá lọ, èmi ó ta àwọ̀n mi sórí wọn, Èmi ó fà wọ́n lulẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹyẹ ojú ọ̀run. Nígbà tí mo bá gbọ́ pé wọ́n rìn pọ̀, Èmi ó nà wọ́n fún iṣẹ́ búburú ọwọ́ wọn.
Tandis qu'ils chemineront, Je jetterai sur eux Mon filet, Je les ramènerai comme des oiseaux du ciel; Je les punirai avec la rumeur même de leurs afflictions.
13 Ègbé ní fún wọn, nítorí pé wọ́n ti yà kúrò lọ́dọ̀ mi! Ìparun wà lórí wọn, nítorí pé wọ́n ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi! Èmi fẹ́ láti rà wọ́n padà. Ṣùgbọ́n wọ́n ń parọ́ mọ́ mi.
Malheur à eux parce qu'ils se sont retirés de Moi! Les voilà tous craintifs parce qu'ils ont péché contre Moi. Je les avais rachetés, et ils ont dit des mensonges contre Moi.
14 Wọn kò kégbe pè mí láti ọkàn wọn, ṣùgbọ́n wọ́n ń pohùnréré ẹkún lórí ibùsùn wọn. Wọ́n kó ara wọn jọ, nítorí ọkà àti wáìnì ṣùgbọ́n wọ́n yípadà kúrò ní ọ̀dọ̀ mi.
Et leurs cœurs n'ont point crié vers Moi; et ils ont hurlé sur leurs couches; ils ont séché faute de pain et de vin.
15 Mo kọ́ wọn, mo sì fún wọn ní agbára, síbẹ̀ wọ́n tún ń dìtẹ̀ mọ́ mi.
Et ils ont été instruits par Moi, et J'ai fortifié leurs mains; et ils ont eu contre Moi des pensées de malice.
16 Wọn kò padà sí ọ̀dọ̀ Ọ̀gá-ògo; wọ́n dàbí ọfà tí ó ti bàjẹ́. Àwọn aṣíwájú wọn yóò ti ipa idà ṣubú nítorí ìrunú ahọ́n wọn. Torí èyí, wọn ó fi wọ́n ṣe ẹlẹ́yà ní ilẹ̀ Ejibiti.
Ils sont devenus à rien; les voilà comme un arc détendu; leurs princes tomberont sous le glaive à cause de l'intempérance de leur langue; tel est leur avilissement dans la terre d'Égypte.

< Hosea 7 >