< Hosea 7 >
1 nígbà tí èmi ìbá mú Israẹli láradá. Ẹ̀ṣẹ̀ Efraimu ń farahàn ìwà búburú Samaria sì ń hàn síta. Wọ́n ń ṣe ẹ̀tàn, àwọn olè ń fọ́ ilé; àwọn ọlọ́ṣà ń jalè ní òpópónà;
Quand je veux opérer la guérison d’Israël, il arrive que se dévoilent l’iniquité d’Ephraïm et les méfaits de Samarie, car ils pratiquent le mensonge, des voleurs font irruption, des bandes de pillards se répandent au dehors.
2 ṣùgbọ́n wọn kò mọ̀ pé mo rántí gbogbo ìwà búburú wọn. Ẹ̀ṣẹ̀ wọn gbé wọn mì pátápátá; wọ́n wà níwájú mi nígbà gbogbo.
Ils ne se disent pas dans le secret de leur cœur que je garde le souvenir de toute leur perversité; or, leurs actions les enserrent, elles sont là devant ma face.
3 “Wọ́n ń mú inú ọba dùn pẹ̀lú ìwà búburú wọn, àti inú ọmọ-aládé dùn pẹ̀lú irọ́ wọn.
Par leur perversité, ils font plaisir au roi, par leurs tromperies aux princes.
4 Alágbèrè ni gbogbo wọn wọ́n gbóná bí ààrò àkàrà tí a dáwọ́ kíkoná dúró, lẹ́yìn ìgbà tí o ti pò ìyẹ̀fun tán, títí ìgbà tí yóò wú.
Ils sont tous débauchés, ardents comme un four allumé par le boulanger, qui s’abstient d’attiser le feu depuis le moment où la pâte est pétrie jusqu’à ce qu’elle soit levée.
5 Ní ọjọ́ àjọ̀dún ọba wa wáìnì mú ara ọmọ-aládé gbóná ó sì darapọ̀ mọ́ àwọn oníyẹ̀yẹ́.
"C’Est le jour de fête de notre roi!" Les princes s’y rendent malades par la chaleur du vin: on tend la main aux railleurs.
6 Ọkàn wọn ń gbóná bí i ààrò wọ́n sì tọ̀ ọ́ lọ pẹ̀lú rìkíṣí, ìbínú wọn pa lọ́lọ́ ní gbogbo òru ó sì bú jáde bí ọ̀wọ́-iná ní òwúrọ̀.
Oui, dans leurs machinations, ils rendent leur cœur semblable à un four qui, même si le boulanger dort toute la nuit, est brûlant au matin comme un feu qui flambe.
7 Gbogbo wọn gbóná bí ààrò wọ́n pa gbogbo olórí wọn run, gbogbo ọba wọn si ṣubú kò sì ṣí ẹnìkan nínú wọn tí ó ké pè mí.
Tous ils sont échauffés comme le four, et ils consument leurs juges; tous leurs rois sont renversés, sans que personne parmi eux s’adresse à moi.
8 “Efraimu ti darapọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn náà; Efraimu jẹ́ àkàrà tí a kò yípadà.
Ephraïm se confond parmi les nations, Ephraïm est un gâteau qui n’a pas été retourné.
9 Àwọn àlejò ti jẹ agbára rẹ̀ run ṣùgbọ́n kò sì mọ̀. Ewú ti wà ní orí rẹ̀ káàkiri bẹ́ẹ̀ ni kò kíyèsi i.
Des étrangers dévorent sa force, sans qu’il s’en aperçoive, la décrépitude l’a atteint sans qu’il s’en doute.
10 Ìgbéraga Israẹli ń jẹ́rìí sí i ṣùgbọ́n pẹ̀lú gbogbo èyí kò padà sí ọ̀dọ̀ Olúwa Ọlọ́run, tàbí kí ó wá a.
L’Orgueil d’Israël est humilié en sa présence; cependant ils ne sont pas revenus à l’Eternel, leur Dieu, et, en dépit de tout, ils ne l’ont pas recherché.
11 “Efraimu dàbí àdàbà tó rọrùn láti tànjẹ àti aláìgbọ́n tó wá ń pé Ejibiti nísinsin yìí tó sì tún ń padà lọ si Asiria.
Ephraïm est devenu comme un pigeon étourdi, sans intelligence; ils en appellent à l’Egypte, ils se rendent en Assyrie.
12 Nígbà tí wọ́n bá lọ, èmi ó ta àwọ̀n mi sórí wọn, Èmi ó fà wọ́n lulẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹyẹ ojú ọ̀run. Nígbà tí mo bá gbọ́ pé wọ́n rìn pọ̀, Èmi ó nà wọ́n fún iṣẹ́ búburú ọwọ́ wọn.
Tandis qu’ils prennent ce chemin, je tendrai mon filet sur eux et les y ferai tomber comme des oiseaux du ciel, je les châtierai à l’annonce de leur rassemblement.
13 Ègbé ní fún wọn, nítorí pé wọ́n ti yà kúrò lọ́dọ̀ mi! Ìparun wà lórí wọn, nítorí pé wọ́n ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi! Èmi fẹ́ láti rà wọ́n padà. Ṣùgbọ́n wọ́n ń parọ́ mọ́ mi.
Malheur à eux, car ils ont erré loin de moi! Ruine sur eux, car ils me sont devenus infidèles! Est-ce à moi de les délivrer, alors qu’ils profèrent des mensonges contre moi?
14 Wọn kò kégbe pè mí láti ọkàn wọn, ṣùgbọ́n wọ́n ń pohùnréré ẹkún lórí ibùsùn wọn. Wọ́n kó ara wọn jọ, nítorí ọkà àti wáìnì ṣùgbọ́n wọ́n yípadà kúrò ní ọ̀dọ̀ mi.
Ils ne m’invoquent pas de tout cœur quand ils se lamentent sur leur couche: sont-ils alarmés au sujet du froment et du vin, alors ils s’approchent de moi?
15 Mo kọ́ wọn, mo sì fún wọn ní agbára, síbẹ̀ wọ́n tún ń dìtẹ̀ mọ́ mi.
Cependant moi, en les redressant, je fortifiais leurs bras, mais ils ont conçu de mauvaises pensées à mon égard.
16 Wọn kò padà sí ọ̀dọ̀ Ọ̀gá-ògo; wọ́n dàbí ọfà tí ó ti bàjẹ́. Àwọn aṣíwájú wọn yóò ti ipa idà ṣubú nítorí ìrunú ahọ́n wọn. Torí èyí, wọn ó fi wọ́n ṣe ẹlẹ́yà ní ilẹ̀ Ejibiti.
S’Ils retournent, ce n’est pas pour s’élever vers Dieu, ils sont tels qu’un arc trompeur. Leurs princes tomberont sous le glaive à cause de leur langue virulente. Voilà ce qui fait d’eux une risée dans le pays d’Egypte.