< Hosea 6 >

1 “Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a padà sọ́dọ̀ Olúwa ó ti fà wá ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ ṣùgbọ́n yóò mú wa láradá Ó ti pa wá lára ṣùgbọ́n yóò dí ojú ọgbẹ́ wa.
“Gelin, RAB'be dönelim. Bizi O parçaladı, O iyileştirecek. Bizi O yaraladı, Yaramızı O saracak.
2 Lẹ́yìn ọjọ́ méjì, yóò sọ wá jí ní ọjọ́ kẹta yóò mú wa padà bọ̀ sípò kí a ba à le wá gbé níwájú rẹ̀.
İki gün sonra bizi diriltecek, Üçüncü gün ayağa kaldıracak, Huzurunda yaşayalım diye.
3 Ẹ jẹ́ kí a mọ Olúwa; ẹ jẹ́ kí a tẹ̀síwájú láti mọ̀ ọ́n. Gẹ́gẹ́ bí oòrùn ṣe ń yọ, yóò jáde; yóò tọ̀ wá wá bí òjò, bí òjò àkọ́rọ̀ ti ń bomirin ilẹ̀.”
RAB'bi tanıyalım, RAB'bi tanımaya gayret edelim. O tan gibi şaşmadan doğacak, Yağmur gibi, toprağı sulayan Son yağmur gibi bize gelecektir.”
4 “Kí ni èmi ó ṣe pẹ̀lú rẹ, Efraimu? Kí ni èmi ó ṣe pẹ̀lú rẹ, Juda? Ìfẹ́ rẹ dàbí ìkùùkuu òwúrọ̀ bí ìrì ìdájí tí ó kọjá lọ kíákíá.
Tanrı şöyle diyor: “Ey Efrayim, ne yapayım sana? Ey Yahuda, sana ne yapayım? Sevginiz sabah sisine benziyor, Erkenden uçup giden çiy gibi.
5 Nítorí náà ni mo ṣe gé e yín sí wẹ́wẹ́ láti ọwọ́ àwọn wòlíì, Mo pa yín pẹ̀lú ọ̀rọ̀ ẹnu mi, ìdájọ́ mi tàn bí i mọ̀nàmọ́ná lórí yín.
Bu yüzden sizi peygamberler aracılığıyla lime lime doğradım, Ağzımdan çıkan sözlerle öldürdüm; Yargılarım şimşek gibi ışıldıyor.
6 Nítorí àánú ni mo fẹ́, kì í ṣe ẹbọ; àti ìmọ̀ Ọlọ́run ju ọrẹ ẹbọ sísun lọ.
Çünkü ben kurbandan değil, bağlılıktan hoşlanırım, Yakmalık sunulardan çok beni tanımanızı isterim.
7 Bí i Adamu, wọ́n da májẹ̀mú wọ́n jẹ́ aláìṣòótọ́ sí mi níbẹ̀.
Oysa onlar Adam Kenti'nde Antlaşmaya uymadılar, Orada bana ihanet ettiler.
8 Gileadi jẹ́ ìlú àwọn ènìyàn búburú tí ń ṣiṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀, a sí ti fi ẹ̀ṣẹ̀ bà á jẹ́.
Gilat kötülük yapanların kentidir, Kan izleriyle doludur.
9 Bí adigunjalè ṣe ń ba ní bùba de àwọn ènìyàn bẹ́ẹ̀ ni àwọn àlùfáà, ń parapọ̀; tí wọ́n sì ń pànìyàn lójú ọ̀nà tó lọ sí Ṣekemu, tí wọ́n sì ń dá ẹ̀ṣẹ̀ tí ó ti ni lójú.
Haydut çeteleri nasıl pusuya yatarsa, Kâhinler takımı da öyle; Şekem yolunda adam öldürüyor, Rezillik yapıyorlar.
10 Mo ti rí ohun tó ba ni lẹ́rù ní ilé Israẹli. Níbẹ̀ Efraimu, fi ara rẹ̀ fún àgbèrè Israẹli sì di aláìmọ́.
İsrail halkında korkunç bir şey gördüm. Efrayim zinaya kapılmış, Kirlenmiş İsrail.
11 “Àti fún ìwọ, Juda, a ti yan ọjọ́ ìkórè rẹ. “Nígbà tí mo bá fẹ́ dá ohun ìní àwọn ènìyàn mi padà,
“Ey Yahuda, senin için de bir hasat günü saptandı. “Ne zaman halkımın durumunu düzeltmek,

< Hosea 6 >