< Hosea 6 >

1 “Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a padà sọ́dọ̀ Olúwa ó ti fà wá ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ ṣùgbọ́n yóò mú wa láradá Ó ti pa wá lára ṣùgbọ́n yóò dí ojú ọgbẹ́ wa.
W utrapieniu swojem rano mię szukać będą, mówiąc: Pójdźcie, a nawróćmy się do Pana; bo on porwał, a uzdrowi nas; uderzył, i zawiąże rany nasze;
2 Lẹ́yìn ọjọ́ méjì, yóò sọ wá jí ní ọjọ́ kẹta yóò mú wa padà bọ̀ sípò kí a ba à le wá gbé níwájú rẹ̀.
Ożywi nas po dwóch dniach, a dnia trzeciego wzbudzi nas, i żyć będziemy przed obliczem jego.
3 Ẹ jẹ́ kí a mọ Olúwa; ẹ jẹ́ kí a tẹ̀síwájú láti mọ̀ ọ́n. Gẹ́gẹ́ bí oòrùn ṣe ń yọ, yóò jáde; yóò tọ̀ wá wá bí òjò, bí òjò àkọ́rọ̀ ti ń bomirin ilẹ̀.”
Tedy poznawszy Pana starać się będziemy, abyśmy go więcej poznali; bo wyjście jego jako ranna zorza zgotowane jest, a przyjdzie nam jako deszcz na wiosnę i w jesieni na zimę.
4 “Kí ni èmi ó ṣe pẹ̀lú rẹ, Efraimu? Kí ni èmi ó ṣe pẹ̀lú rẹ, Juda? Ìfẹ́ rẹ dàbí ìkùùkuu òwúrọ̀ bí ìrì ìdájí tí ó kọjá lọ kíákíá.
Cóż mam czynić z tobą, o Efraimie? cóż mam czynić z tobą, o Judo? gdyż miłosierdzie wasze jest jako obłok poranny a jako rosa rano przemijająca.
5 Nítorí náà ni mo ṣe gé e yín sí wẹ́wẹ́ láti ọwọ́ àwọn wòlíì, Mo pa yín pẹ̀lú ọ̀rọ̀ ẹnu mi, ìdájọ́ mi tàn bí i mọ̀nàmọ́ná lórí yín.
Dlatego ociosywałem ich przez proroków, zabijałem ich słowy ust moich, aby światłość sądów twoich weszła.
6 Nítorí àánú ni mo fẹ́, kì í ṣe ẹbọ; àti ìmọ̀ Ọlọ́run ju ọrẹ ẹbọ sísun lọ.
Bo miłosierdzia chcę, a nie ofiary, a znajomości Bożej więcej, niż całopalenia.
7 Bí i Adamu, wọ́n da májẹ̀mú wọ́n jẹ́ aláìṣòótọ́ sí mi níbẹ̀.
Ale oni przestąpili przymierze moje, jako ludzkie, a temci wystąpili przeciwko mnie.
8 Gileadi jẹ́ ìlú àwọn ènìyàn búburú tí ń ṣiṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀, a sí ti fi ẹ̀ṣẹ̀ bà á jẹ́.
Galaad jest miastem czyniących nieprawość, pełne stóp krwawych.
9 Bí adigunjalè ṣe ń ba ní bùba de àwọn ènìyàn bẹ́ẹ̀ ni àwọn àlùfáà, ń parapọ̀; tí wọ́n sì ń pànìyàn lójú ọ̀nà tó lọ sí Ṣekemu, tí wọ́n sì ń dá ẹ̀ṣẹ̀ tí ó ti ni lójú.
A jako zbójcy czynią, którzy na kogo czyhają na drodze, kędy chodzą do Sychem, tak czyni rota kapłanów; bo umyślnie niecnotę płodzą.
10 Mo ti rí ohun tó ba ni lẹ́rù ní ilé Israẹli. Níbẹ̀ Efraimu, fi ara rẹ̀ fún àgbèrè Israẹli sì di aláìmọ́.
W domu Izraelskim widzę sprosność; tam się wszeteczeństwem Efraimowem splugawił Izrael;
11 “Àti fún ìwọ, Juda, a ti yan ọjọ́ ìkórè rẹ. “Nígbà tí mo bá fẹ́ dá ohun ìní àwọn ènìyàn mi padà,
I w tobie, o Judo! Efraim żniwo położył, gdym Ja zaś przywrócił pojmany lud mój.

< Hosea 6 >