< Hosea 5 >
1 “Ẹ gbọ́ èyí, ẹ̀yìn àlùfáà! Ẹ fetísílẹ̀ ẹ̀yin ọmọ Israẹli! Ẹ gbọ́, ẹ̀yìn ilé ọba! Ìdájọ́ yìí kàn yín. Ẹ ti jẹ́ ẹ̀bìtì ní Mispa àwọ̀n ti a nà sílẹ̀ lórí Tabori.
Ô prêtres, écoutez ce que Je vais vous dire, recueillez-le; maison d'Israël, maison du roi, prêtez-Moi une oreille attentive: le jugement est près de vous; car vous êtes comme un filet vers l'affût, comme un lacs tendu sur le Thabor,
2 Àwọn ọlọ̀tẹ̀ ti gbilẹ̀ nínú ìpànìyàn gbogbo wọn ni èmi ó bá wí,
et que des chasseurs ont attaché; et Moi, je suis Celui qui vous instruit.
3 mo mọ ohun gbogbo nípa Efraimu Israẹli kò sì pamọ́ fún mi Efraimu, ní báyìí ó ti ṣe àgbèrè Israẹli sì ti díbàjẹ́.
Je connais Éphraïm, et Israël ne M'a point échappé; parce que maintenant Éphraïm s'est prostitué, et qu'Israël s'est couvert de souillures,
4 “Ìṣe wọn kò gbà wọ́n láààyè láti padà sí ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wọn. Ẹ̀mí àgbèrè wà ni ọkàn wọn, wọn kò sì mọ Olúwa.
ils n'ont point pensé, en leur conseil, à se convertir à Dieu; car l'esprit de prostitution est en eux, et ils ne connaissent point le Seigneur.
5 Ìgbéraga Israẹli ń jẹ́rìí lé wọn; àwọn ọmọ Israẹli, àti Efraimu pàápàá kọsẹ̀ nínú ẹ̀ṣẹ̀ wọn. Juda náà sì kọsẹ̀ pẹ̀lú wọn.
Et l'orgueil d'Israël sera abaissé en sa face, et Israël et Éphraïm trébucheront en leurs iniquités, et Juda aussi tombera avec eux.
6 Nígbà tí wọ́n bá lọ pẹ̀lú agbo ẹran àti ọ̀wọ́ ẹran wọn láti wá Olúwa, wọn kò ní rí i, ó ti yọ ara rẹ̀ kúrò láàrín wọn.
Ils s'en iront, avec leurs bœufs et leurs brebis, pour chercher le Seigneur, et ils ne Le trouveront pas; car Il S'est éloigné d'eux;
7 Wọ́n jẹ́ aláìṣòótọ́ sí Olúwa wọ́n sì bí àwọn àjèjì ọmọ. Nísinsin yìí, ọdún oṣù tuntun wọn, ni yóò pa wọn run pẹ̀lú ìpín wọn.
parce qu'ils L'ont abandonné et qu'il leur est né des fils d'étrangères, maintenant la nielle les dévorera eux et leurs enfants.
8 “Fọn fèrè ní Gibeah, kí ẹ sì fun ìpè ní Rama. Ẹ pariwo ogun ní Beti-Afeni; máa wárìrì, ìwọ Benjamini.
Trompettes, sonnez sur les collines, retentissez sur les hauts lieux; annoncez comme des hérauts en la maison de On. Benjamin est dans la stupeur;
9 Efraimu yóò di ahoro ní ọjọ́ ìbáwí láàrín àwọn ẹ̀yà Israẹli, Mo sọ ohun tí ó dájú.
Éphraïm a été effacé au jour du châtiment. J'ai montré aux tribus d'Israël des choses dignes de foi.
10 Àwọn olórí Juda dàbí àwọn tí í máa yí òkúta ààlà kúrò. Èmi ó tú ìbínú gbígbóná mi lé wọn lórí bí ìkún omi.
Les chefs de Juda sont devenus comme ceux qui déplacent les bornes des champs, Je répandrai sur eux Ma fureur comme un torrent.
11 A ni Efraimu lára, a sì tẹ̀ ẹ́ mọ́lẹ̀ ní ìdájọ́, nítorí pé, ó pinnu láti tẹ̀lé òrìṣà.
Éphraïm a prévalu sur son adversaire; il a foulé aux pieds le jugement, parce qu'il avait commencé à adorer des choses vaines.
12 Mo dàbí kòkòrò aṣọ sí Efraimu, Mo sì dàbí ìdin ara Juda.
Et Moi Je suis comme une épouvante pour Éphraïm, comme un aiguillon pour la maison de Juda.
13 “Nígbà ti Efraimu ri àìsàn rẹ̀, tí Juda sì rí ojú egbò rẹ̀ ni Efraimu bá tọ ará Asiria lọ, ó sì ránṣẹ́ sí ọba ńlá náà fún ìrànlọ́wọ́. Ṣùgbọ́n kò le è wò ó sàn bẹ́ẹ̀ ni kò le wo ojú egbò rẹ̀ jinná.
Et Éphraïm a subi son infirmité, et Juda sa douleur. Et Éphraïm est allé aux Assyriens, et il a envoyé ses anciens chez le roi Jarim. Mais celui-ci n'a pu vous guérir, et vos douleurs ne se sont point calmées;
14 Nítorí pé, èmi ó dàbí kìnnìún sí Efraimu, bí i kìnnìún ńlá sí ilé Juda. Èmi ó fà wọ́n ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ èmi ó sì lọ; Èmi ó gbé wọn lọ, láìsí ẹni tí yóò gbà wọ́n sílẹ̀.
parce que Je suis comme une panthère pour Éphraïm, et comme un lion pour Juda; et Je M'élancerai, et Je saisirai et ravirai Ma proie, et nul ne pourra Me l'arracher.
15 Nígbà náà ni èmi ó padà lọ sí ààyè mi títí di ìgbà tí wọn ó fi gbà pé àwọn jẹ̀bi wọn yóò sì wá ojú mi nínú ìpọ́njú wọn, wọn ó fi ìtara wá mi.”
Et Je partirai, et Je retournerai en Ma demeure, jusqu'à ce qu'ils soient exténués et qu'ils recherchent Ma présence. Dans leur tribulation, ils se lèveront de grand matin, et viendront à moi, en disant: