< Hosea 5 >

1 “Ẹ gbọ́ èyí, ẹ̀yìn àlùfáà! Ẹ fetísílẹ̀ ẹ̀yin ọmọ Israẹli! Ẹ gbọ́, ẹ̀yìn ilé ọba! Ìdájọ́ yìí kàn yín. Ẹ ti jẹ́ ẹ̀bìtì ní Mispa àwọ̀n ti a nà sílẹ̀ lórí Tabori.
« Écoutez ceci, vous, les prêtres! Écoutez, maison d'Israël, et écoutez, maison du roi! Car le jugement est contre vous; car tu as été un piège à Mitspa, et un écart net sur Tabor.
2 Àwọn ọlọ̀tẹ̀ ti gbilẹ̀ nínú ìpànìyàn gbogbo wọn ni èmi ó bá wí,
Les rebelles sont en plein massacre, mais je les discipline tous.
3 mo mọ ohun gbogbo nípa Efraimu Israẹli kò sì pamọ́ fún mi Efraimu, ní báyìí ó ti ṣe àgbèrè Israẹli sì ti díbàjẹ́.
Je connais Ephraïm, et Israël ne m'est pas caché; pour l'instant, Ephraim, tu as joué la prostituée. Israël est souillé.
4 “Ìṣe wọn kò gbà wọ́n láààyè láti padà sí ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wọn. Ẹ̀mí àgbèrè wà ni ọkàn wọn, wọn kò sì mọ Olúwa.
Leurs actes ne leur permettent pas de se tourner vers leur Dieu, car l'esprit de prostitution est en eux, et ils ne connaissent pas Yahvé.
5 Ìgbéraga Israẹli ń jẹ́rìí lé wọn; àwọn ọmọ Israẹli, àti Efraimu pàápàá kọsẹ̀ nínú ẹ̀ṣẹ̀ wọn. Juda náà sì kọsẹ̀ pẹ̀lú wọn.
L'orgueil d'Israël témoigne de sa face. C'est pourquoi Israël et Ephraïm trébucheront dans leur iniquité. Juda aussi trébuchera avec eux.
6 Nígbà tí wọ́n bá lọ pẹ̀lú agbo ẹran àti ọ̀wọ́ ẹran wọn láti wá Olúwa, wọn kò ní rí i, ó ti yọ ara rẹ̀ kúrò láàrín wọn.
Ils iront avec leurs troupeaux et leurs bêtes pour chercher Yahvé, mais ils ne le trouveront pas. Il s'est retiré d'eux.
7 Wọ́n jẹ́ aláìṣòótọ́ sí Olúwa wọ́n sì bí àwọn àjèjì ọmọ. Nísinsin yìí, ọdún oṣù tuntun wọn, ni yóò pa wọn run pẹ̀lú ìpín wọn.
Ils sont infidèles à Yahvé; car elles ont porté des enfants illégitimes. Maintenant, la nouvelle lune va les dévorer avec leurs champs.
8 “Fọn fèrè ní Gibeah, kí ẹ sì fun ìpè ní Rama. Ẹ pariwo ogun ní Beti-Afeni; máa wárìrì, ìwọ Benjamini.
« Sonnez de la trompette à Gibéa, et la trompette à Rama! Sonnez un cri de guerre à Beth Aven, derrière vous, Benjamin!
9 Efraimu yóò di ahoro ní ọjọ́ ìbáwí láàrín àwọn ẹ̀yà Israẹli, Mo sọ ohun tí ó dájú.
Ephraïm deviendra une désolation au jour du châtiment. Parmi les tribus d'Israël, j'ai fait connaître ce qui sera sûrement.
10 Àwọn olórí Juda dàbí àwọn tí í máa yí òkúta ààlà kúrò. Èmi ó tú ìbínú gbígbóná mi lé wọn lórí bí ìkún omi.
Les princes de Juda sont comme ceux qui enlèvent un repère. Je déverserai ma colère sur eux comme de l'eau.
11 A ni Efraimu lára, a sì tẹ̀ ẹ́ mọ́lẹ̀ ní ìdájọ́, nítorí pé, ó pinnu láti tẹ̀lé òrìṣà.
Ephraïm est opprimé, il est écrasé par le jugement, parce qu'il est déterminé dans sa poursuite des idoles.
12 Mo dàbí kòkòrò aṣọ sí Efraimu, Mo sì dàbí ìdin ara Juda.
C'est pourquoi je suis pour Éphraïm comme un papillon de nuit, et à la maison de Juda comme une pourriture.
13 “Nígbà ti Efraimu ri àìsàn rẹ̀, tí Juda sì rí ojú egbò rẹ̀ ni Efraimu bá tọ ará Asiria lọ, ó sì ránṣẹ́ sí ọba ńlá náà fún ìrànlọ́wọ́. Ṣùgbọ́n kò le è wò ó sàn bẹ́ẹ̀ ni kò le wo ojú egbò rẹ̀ jinná.
« Quand Ephraïm vit sa maladie, et Juda sa blessure, puis Ephraïm est allé en Assyrie, et envoyé au roi Jareb: mais il n'est pas capable de vous guérir, il ne vous guérira pas non plus de votre blessure.
14 Nítorí pé, èmi ó dàbí kìnnìún sí Efraimu, bí i kìnnìún ńlá sí ilé Juda. Èmi ó fà wọ́n ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ èmi ó sì lọ; Èmi ó gbé wọn lọ, láìsí ẹni tí yóò gbà wọ́n sílẹ̀.
Car je serai pour Ephraïm comme un lion, et comme un jeune lion à la maison de Juda. Je vais moi-même me déchirer en morceaux et m'en aller. J'emporterai, et il n'y aura personne pour délivrer.
15 Nígbà náà ni èmi ó padà lọ sí ààyè mi títí di ìgbà tí wọn ó fi gbà pé àwọn jẹ̀bi wọn yóò sì wá ojú mi nínú ìpọ́njú wọn, wọn ó fi ìtara wá mi.”
Je vais m'en aller et retourner à ma place, jusqu'à ce qu'ils reconnaissent leur offense, et cherchez ma face. Dans leur détresse, ils me chercheront avec ardeur. »

< Hosea 5 >