< Hosea 5 >

1 “Ẹ gbọ́ èyí, ẹ̀yìn àlùfáà! Ẹ fetísílẹ̀ ẹ̀yin ọmọ Israẹli! Ẹ gbọ́, ẹ̀yìn ilé ọba! Ìdájọ́ yìí kàn yín. Ẹ ti jẹ́ ẹ̀bìtì ní Mispa àwọ̀n ti a nà sílẹ̀ lórí Tabori.
Hear this, O ye priests; and listen well, O ye house of Israel; and give ye ear, O house of the king; for the punishment threateneth you; because ye have been a snare on Mizpah, and a net spread out upon Thabor.
2 Àwọn ọlọ̀tẹ̀ ti gbilẹ̀ nínú ìpànìyàn gbogbo wọn ni èmi ó bá wí,
And for murdering they who had rebelled [against God] concealed themselves in deep places; but I will inflict correction on them all.
3 mo mọ ohun gbogbo nípa Efraimu Israẹli kò sì pamọ́ fún mi Efraimu, ní báyìí ó ti ṣe àgbèrè Israẹli sì ti díbàjẹ́.
I well know Ephraim, and Israel is not hidden from me; for now, O Ephraim, hast thou played the harlot, [and] Israel is defiled.
4 “Ìṣe wọn kò gbà wọ́n láààyè láti padà sí ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wọn. Ẹ̀mí àgbèrè wà ni ọkàn wọn, wọn kò sì mọ Olúwa.
Their doings will not permit them to return unto their God; for the spirit of lewdness is in their bosom, and the Lord they have not known.
5 Ìgbéraga Israẹli ń jẹ́rìí lé wọn; àwọn ọmọ Israẹli, àti Efraimu pàápàá kọsẹ̀ nínú ẹ̀ṣẹ̀ wọn. Juda náà sì kọsẹ̀ pẹ̀lú wọn.
Therefore shall the pride of Israel be humbled before his face: and Israel and Ephraim shall stumble in their iniquity; Judah also shall stumble with them.
6 Nígbà tí wọ́n bá lọ pẹ̀lú agbo ẹran àti ọ̀wọ́ ẹran wọn láti wá Olúwa, wọn kò ní rí i, ó ti yọ ara rẹ̀ kúrò láàrín wọn.
With their flocks and with their herds will they go to seek the Lord; but they shall not find him: he hath withdrawn himself from them.
7 Wọ́n jẹ́ aláìṣòótọ́ sí Olúwa wọ́n sì bí àwọn àjèjì ọmọ. Nísinsin yìí, ọdún oṣù tuntun wọn, ni yóò pa wọn run pẹ̀lú ìpín wọn.
Against the Lord have they dealt treacherously; for strange children have they begotten: now shall one month devour them together with their possessions.
8 “Fọn fèrè ní Gibeah, kí ẹ sì fun ìpè ní Rama. Ẹ pariwo ogun ní Beti-Afeni; máa wárìrì, ìwọ Benjamini.
Blow ye the cornet in Gib'ah, the trumpet in Ramah: blow the alarm at Beth-aven, [The enemy is] after thee, O Benjamin.
9 Efraimu yóò di ahoro ní ọjọ́ ìbáwí láàrín àwọn ẹ̀yà Israẹli, Mo sọ ohun tí ó dájú.
Ephraim shall be made desolate on the day of chastisement: among the tribes of Israel had I made known that which is true.
10 Àwọn olórí Juda dàbí àwọn tí í máa yí òkúta ààlà kúrò. Èmi ó tú ìbínú gbígbóná mi lé wọn lórí bí ìkún omi.
The princes of Judah were like those that remove the landmark: my wrath, therefore, will I pour out upon them like water.
11 A ni Efraimu lára, a sì tẹ̀ ẹ́ mọ́lẹ̀ ní ìdájọ́, nítorí pé, ó pinnu láti tẹ̀lé òrìṣà.
Oppressed is Ephraim, broken through punishment; because he willingly walked after the commandment [of false prophets].
12 Mo dàbí kòkòrò aṣọ sí Efraimu, Mo sì dàbí ìdin ara Juda.
But like the moth became I unto Ephraim, and like rottenness to the house of Judah.
13 “Nígbà ti Efraimu ri àìsàn rẹ̀, tí Juda sì rí ojú egbò rẹ̀ ni Efraimu bá tọ ará Asiria lọ, ó sì ránṣẹ́ sí ọba ńlá náà fún ìrànlọ́wọ́. Ṣùgbọ́n kò le è wò ó sàn bẹ́ẹ̀ ni kò le wo ojú egbò rẹ̀ jinná.
Then saw Ephraim his sickness, and Judah his wound, and Ephraim went to Asshur, and [the other] sent to the king that should contend [[Jareb]]; but he will never be able to heal you, nor remove from you your wound.
14 Nítorí pé, èmi ó dàbí kìnnìún sí Efraimu, bí i kìnnìún ńlá sí ilé Juda. Èmi ó fà wọ́n ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ èmi ó sì lọ; Èmi ó gbé wọn lọ, láìsí ẹni tí yóò gbà wọ́n sílẹ̀.
For I am as a lion unto Ephraim, and as a young lion to the house of Judah: I, even I myself will tear in pieces and go away; I will bear away, and none shall deliver.
15 Nígbà náà ni èmi ó padà lọ sí ààyè mi títí di ìgbà tí wọn ó fi gbà pé àwọn jẹ̀bi wọn yóò sì wá ojú mi nínú ìpọ́njú wọn, wọn ó fi ìtara wá mi.”
I will go [from here, and] return to my place, till they acknowledge their guilt, and seek my presence: in their affliction will they seek for me.

< Hosea 5 >