< Hosea 5 >

1 “Ẹ gbọ́ èyí, ẹ̀yìn àlùfáà! Ẹ fetísílẹ̀ ẹ̀yin ọmọ Israẹli! Ẹ gbọ́, ẹ̀yìn ilé ọba! Ìdájọ́ yìí kàn yín. Ẹ ti jẹ́ ẹ̀bìtì ní Mispa àwọ̀n ti a nà sílẹ̀ lórí Tabori.
Hear this, O ye priests, and hearken, O house of Israel, and give ear, O house of the king, for to you pertains the judgment. For ye have been a snare at Mizpah, and a net spread upon Tabor.
2 Àwọn ọlọ̀tẹ̀ ti gbilẹ̀ nínú ìpànìyàn gbogbo wọn ni èmi ó bá wí,
And the revolters have gone deep in making slaughter, but I am a rebuker of them all.
3 mo mọ ohun gbogbo nípa Efraimu Israẹli kò sì pamọ́ fún mi Efraimu, ní báyìí ó ti ṣe àgbèrè Israẹli sì ti díbàjẹ́.
I know Ephraim, and Israel is not hid from me. For now, O Ephraim, thou have played the harlot; Israel is defiled.
4 “Ìṣe wọn kò gbà wọ́n láààyè láti padà sí ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wọn. Ẹ̀mí àgbèrè wà ni ọkàn wọn, wọn kò sì mọ Olúwa.
Their doings will not allow them to turn to their God, for the spirit of whoredom is within them, and they do not know Jehovah.
5 Ìgbéraga Israẹli ń jẹ́rìí lé wọn; àwọn ọmọ Israẹli, àti Efraimu pàápàá kọsẹ̀ nínú ẹ̀ṣẹ̀ wọn. Juda náà sì kọsẹ̀ pẹ̀lú wọn.
And the pride of Israel testifies to his face. Therefore Israel and Ephraim shall stumble in their iniquity. Judah also shall stumble with them.
6 Nígbà tí wọ́n bá lọ pẹ̀lú agbo ẹran àti ọ̀wọ́ ẹran wọn láti wá Olúwa, wọn kò ní rí i, ó ti yọ ara rẹ̀ kúrò láàrín wọn.
They shall go with their flocks and with their herds to seek Jehovah, but they shall not find him. He has withdrawn himself from them.
7 Wọ́n jẹ́ aláìṣòótọ́ sí Olúwa wọ́n sì bí àwọn àjèjì ọmọ. Nísinsin yìí, ọdún oṣù tuntun wọn, ni yóò pa wọn run pẹ̀lú ìpín wọn.
They have dealt treacherously against Jehovah, for they have borne strange sons. Now the new moon shall devour them with their fields.
8 “Fọn fèrè ní Gibeah, kí ẹ sì fun ìpè ní Rama. Ẹ pariwo ogun ní Beti-Afeni; máa wárìrì, ìwọ Benjamini.
Blow ye the cornet in Gibeah, and the trumpet in Ramah. Sound an alarm at Beth-aven, behind thee, O Benjamin.
9 Efraimu yóò di ahoro ní ọjọ́ ìbáwí láàrín àwọn ẹ̀yà Israẹli, Mo sọ ohun tí ó dájú.
Ephraim shall become a desolation in the day of rebuke. I have made known that which shall surely be among the tribes of Israel.
10 Àwọn olórí Juda dàbí àwọn tí í máa yí òkúta ààlà kúrò. Èmi ó tú ìbínú gbígbóná mi lé wọn lórí bí ìkún omi.
The rulers of Judah are like those who remove the landmark. I will pour out my wrath upon them like water.
11 A ni Efraimu lára, a sì tẹ̀ ẹ́ mọ́lẹ̀ ní ìdájọ́, nítorí pé, ó pinnu láti tẹ̀lé òrìṣà.
Ephraim is oppressed. He is crushed in judgment, because he was content to walk after man's command.
12 Mo dàbí kòkòrò aṣọ sí Efraimu, Mo sì dàbí ìdin ara Juda.
Therefore I am to Ephraim as a moth, and to the house of Judah as rottenness.
13 “Nígbà ti Efraimu ri àìsàn rẹ̀, tí Juda sì rí ojú egbò rẹ̀ ni Efraimu bá tọ ará Asiria lọ, ó sì ránṣẹ́ sí ọba ńlá náà fún ìrànlọ́wọ́. Ṣùgbọ́n kò le è wò ó sàn bẹ́ẹ̀ ni kò le wo ojú egbò rẹ̀ jinná.
When Ephraim saw his sickness, and Judah saw his wound, then Ephraim went to Assyria, and sent to king Jareb. But he is not able to heal you, nor will he cure you of your wound.
14 Nítorí pé, èmi ó dàbí kìnnìún sí Efraimu, bí i kìnnìún ńlá sí ilé Juda. Èmi ó fà wọ́n ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ èmi ó sì lọ; Èmi ó gbé wọn lọ, láìsí ẹni tí yóò gbà wọ́n sílẹ̀.
For I will be to Ephraim as a lion, and as a young lion to the house of Judah. I, even I, will tear and go away, I will carry off, and there shall be none to deliver.
15 Nígbà náà ni èmi ó padà lọ sí ààyè mi títí di ìgbà tí wọn ó fi gbà pé àwọn jẹ̀bi wọn yóò sì wá ojú mi nínú ìpọ́njú wọn, wọn ó fi ìtara wá mi.”
I will go and return to my place, till they acknowledge their offense, and seek my face. In their affliction they will seek me earnestly.

< Hosea 5 >