< Hosea 4 >

1 Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ẹ̀yin ọmọ Israẹli, nítorí pé Olúwa fi ẹ̀sùn kan ẹ̀yin tí ń gbé ní ilẹ̀ náà. “Kò sí ìwà òtítọ́, kò sí ìfẹ́, Kò sí ìmọ̀ Ọlọ́run ní ilẹ̀ náà,
Ascultaţi cuvântul DOMNULUI, voi copii ai lui Israel; fiindcă DOMNUL are o ceartă cu locuitorii ţării, pentru că nu este adevăr, nici milă, nici cunoaştere de Dumnezeu în ţară.
2 àfi èpè, irọ́ pípa àti ìpànìyàn olè jíjà àti panṣágà. Wọ́n rú gbogbo òfin, ìtàjẹ̀ sílẹ̀ sì ń gorí ìtàjẹ̀ sílẹ̀.
Prin înjurături şi minciună şi ucidere şi furt şi comiterea de adulter, ei se răspândesc, şi sângele atinge sânge.
3 Nítorí èyí, ilẹ̀ náà ń ṣọ̀fọ̀, gbogbo olùgbé ibẹ̀ sì ń ṣòfò dànù. Ẹranko igbó àti ẹyẹ ojú ọ̀run àti ẹja inú omi ló ń kú.
De aceea ţara va jeli şi fiecare ce locuieşte în ea va lâncezi, împreună cu fiarele câmpului şi păsările cerului; da, peştii mării de asemenea vor fi luaţi.
4 “Ṣùgbọ́n kí ẹnikẹ́ni má ṣe mú ẹ̀sùn wá, kí ẹnìkan má sì ṣe fi ẹ̀sùn kan ẹnìkejì nítorí àwọn ènìyàn rẹ̀ dàbí àwọn ti ń fi ẹ̀sùn kan àlùfáà.
Totuşi să nu se certe nimeni, nici să nu se mustre, pentru că poporul tău este asemenea celor ce se ceartă cu preotul.
5 Ẹ ń ṣubú lọ́sàn án àti lóru àwọn wòlíì yín sì ń ṣubú pẹ̀lú yín. Èmi ó pa ìyá rẹ run,
De aceea vei cădea ziua şi profetul de asemenea va cădea cu tine noaptea, şi eu voi nimici pe mama ta.
6 àwọn ènìyàn mi ń ṣègbé nítorí pé wọn kò ní ìmọ̀. “Nítorí pé ẹ ti kọ ìmọ̀ sílẹ̀. Èmi náà kọ̀ yín ní àlùfáà mi; nítorí pé ẹ ti kọ òfin Ọlọ́run yín sílẹ̀, Èmi náà yóò gbàgbé àwọn ọmọ yín.
Poporul meu este nimicit din lipsă de cunoaştere, pentru că tu ai respins cunoaşterea, eu de asemenea te voi respinge, ca să nu îmi fii preot; văzând că ai uitat legea Dumnezeului tău, eu de asemenea îi voi uita pe copiii tăi.
7 Bí àwọn àlùfáà ṣe ń pọ̀ sí i bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ṣe ń dẹ́ṣẹ̀ sí mi. Wọ́n yí ògo mi padà sí ohun ìtìjú
Cu cât s-au înmulţit, cu atât au păcătuit împotriva mea, de aceea le voi schimba gloria în ruşine.
8 wọ́n ń jẹun nípa ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ènìyàn mi, wọ́n sì ń gbádùn nínú ìwà búburú wọn.
Ei mănâncă păcatul poporului meu şi îşi pun inima în nelegiuirea lor.
9 Yóò sì ṣe gẹ́gẹ́ bí ènìyàn ṣe rí náà ni àwọn àlùfáà rí. Èmi ó jẹ gbogbo wọn ní yà nítorí ọ̀nà wọn. Èmi ó sì san án fún wọn gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ wọn.
Precum poporul, aşa va fi şi preotul; şi îi voi pedepsi pentru căile lor şi îi voi răsplăti pentru facerile lor.
10 “Wọn ó máa jẹun ṣùgbọ́n wọn kò ní yó; wọn ó ṣe àgbèrè ṣùgbọ́n, wọn kò ni pọ̀ sí i, nítorí pé wọ́n ti kọ Olúwa sílẹ̀, wọ́n sì ti fi ara wọn
Fiindcă vor mânca şi nu vor avea destul; vor curvi şi nu se vor înmulţi, pentru că au încetat să ia seama la DOMNUL.
11 fún àgbèrè; wọ́n fi ara wọn fún wáìnì àtijọ́, àti tuntun èyí tó gba òye àwọn ènìyàn mi sọnù.
Curvia şi vinul şi vinul nou iau inima.
12 Wọ́n ń gba ìmọ̀ràn lọ́wọ́ ère igi ọ̀pá igi sì ń dá wọn lóhùn. Ẹ̀mí àgbèrè ti mú wọn ṣìnà wọ́n sì jẹ́ aláìṣòótọ́ sí Ọlọ́run wọn.
Poporul meu cere sfat de la trunchiurile lor şi toiagul lor le vesteşte; fiindcă duhul curviilor i-a făcut să rătăcească şi curvind, s-au îndepărtat de sub Dumnezeul lor.
13 Wọ́n ń rú ẹbọ lórí àwọn òkè ńlá, wọ́n sì ń sun ọrẹ tùràrí lórí àwọn òkè kékeré, lábẹ́ igi óákù, àti igi Poplari àti igi ẹlimuati onírúurú igi tí ìbòjú rẹ̀ dára. Nítorí náà àwọn ọmọbìnrin yín yóò ṣe àgbèrè àti àwọn àfẹ́sọ́nà yín yóò ṣe àgbèrè.
Ei sacrifică pe vârfurile munţilor şi ard tămâie pe dealuri, sub stejari şi plopi şi ulmi, pentru că umbra lor este bună; de aceea fiicele voastre vor curvi şi soţiile voastre vor comite adulter.
14 “Èmi kò ní jẹ àwọn ọmọbìnrin yín ní yà nígbà tí wọ́n bá ṣe àgbèrè tàbí àwọn àfẹ́sọ́nà ọmọ yín, nígbà tí wọ́n bá ṣe àgbèrè nítorí pé àwọn ọkùnrin pàápàá ń bá alágbèrè kẹ́gbẹ́. Wọ́n sì ń rú ẹbọ pẹ̀lú àwọn alágbèrè ojúbọ òrìṣà. Nítorí náà, ènìyàn tí kò bá ní òye yóò parun!
Nu voi pedepsi pe fiicele voastre când vor curvi, nici pe soţiile voastre când comit adulter; fiindcă ele însele trag deoparte cu curve şi sacrifică cu prostituatele; de aceea poporul care nu înţelege va cădea.
15 “Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé o ṣe àgbèrè ìwọ Israẹli, ìdájọ́ yìí wà fún un yín. Ẹ má ṣe jẹ́ kí Juda di ẹlẹ́bi. “Ẹ má ṣe lọ sí Gilgali. Ẹ má sì ṣe gòkè lọ sí Beti-Afeni ẹ má sì búra pé, ‘Bí Olúwa ti wà láààyè nítòótọ́!’
Deşi tu, Israele, curveşti, totuşi Iuda să nu se poticnească; şi nu veniţi până la Ghilgal, nici nu urcaţi încă la Bet-Aven, nici nu juraţi: DOMNUL trăieşte.
16 Àwọn ọmọ Israẹli ṣe agídí bí alágídí ọmọ màlúù. Báwo wá ni Olúwa ṣe fẹ́ bọ́ wọn bí àgùntàn ní pápá oko tútù?
Fiindcă Israel decade ca o viţea care dă înapoi; acum DOMNUL îi va paşte ca pe un miel într-un loc larg.
17 Efraimu ti darapọ̀ mọ́ òrìṣà, ẹ fi sílẹ̀!
Efraim s-a alipit de idoli, lăsaţi-l în pace.
18 Bí ohun mímu wọn bá tilẹ̀ tán, wọ́n tún tẹ̀síwájú nínú àgbèrè. Àwọn olórí wọn fẹ́ràn ohun ìtìjú ju ohun ìyìn lọ.
Băutura lor este acră, au curvit în continuu; conducătorii ei iubesc cu ruşine: Daţi.
19 Ìjì ni yóò gbá wọn lọ. Gbogbo ìrúbọ wọn yóò sì kó ìtìjú bá wọn.
Vântul l-a legat în aripile lui şi ei se vor ruşina din cauza sacrificiilor lor.

< Hosea 4 >